< 2 Chroniques 8 >
1 Or, vingt ans s’étant accomplis après que Salomon eut bâti la maison du Seigneur et sa propre maison,
Lẹ́yìn ogún ọdún lásìkò ìgbà tí Solomoni kọ́ ilé Olúwa àti ilé òun fúnra rẹ̀.
2 Il bâtit les villes qu’Hiram lui avait données, et y fit habiter les enfants d’Israël.
Solomoni tún ìlú tí Hiramu ti fi fún un kọ́, ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jọ níbẹ̀ kí wọn kí ó lè máa gbé nínú ibẹ̀.
3 Il s’en alla aussi à Emath-Suba, et s’en empara.
Nígbà náà Solomoni lọ sí Hamati-Ṣoba ó sì borí rẹ̀.
4 Et il bâtit Palmyre dans le désert, et les autres villes très fortifiées, il les bâtit en Emath.
Ó sì tún kọ́ Tadmori ní aginjù àti gbogbo ìlú ìṣúra tí ó ti kọ́ ní Hamati.
5 Il construisit aussi Béthoron la haute, et Béthoron la basse, villes murées, ayant des portes, des verrous et des serrures;
Ó sì tún kọ́ òkè Beti-Horoni àti ìsàlẹ̀ Beti-Horoni gẹ́gẹ́ bí ìlú olódi, pẹ̀lú ògiri àti pẹ̀lú ìlẹ̀kùn àti ọ̀pá ìdábùú.
6 Et de plus Balaath. toutes les villes très fortes qui étaient à Salomon, toutes les villes des quadriges, et les villes de la cavalerie: tout ce que Salomon voulut et décida, il le bâtit, dans Jérusalem, et sur le Liban, et dans tout le pays de sa domination.
Àti gẹ́gẹ́ bí Baalati àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti gbogbo ìlú fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti fún àwọn ẹṣin rẹ̀ ohunkóhun tí ó bá yẹ ní kókó ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo àyíká agbègbè tí ó ń darí.
7 Quant à tout le peuple qui était resté des Héthéens, des Amorrhéens, des Phérézéens, des Hévéens et des Jébuséens, qui n’étaient point de la race d’Israël,
Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kúrò láti ara àwọn ará Hiti, ará Amori, ará Peresi, ará Hifi àti ará Jebusi àwọn ènìyàn wọ̀nyí wọn kì í ṣe àwọn ará Israẹli,
8 Mais des enfants et des descendants de ceux que les enfants d’Israël n’avaient point tués, Salomon les rendit dépendants et tributaires jusqu’à ce jour.
èyí ni wí pé, àwọn ọmọ wọn tí ó kù sílé ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò parun àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.
9 Pour les enfants d’Israël, il ne les employa pas à travailler aux ouvrages du roi; car c’étaient des hommes de guerre, les premiers chefs et les commandants de ses quadriges et de sa cavalerie.
Ṣùgbọ́n Solomoni kò mú ọmọ ọ̀dọ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, wọn jẹ́ ọ̀gágun rẹ̀, olùdarí àwọn oníkẹ̀kẹ́ àti olùdarí kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
10 Or tous les princes de l’armée du roi Salomon étaient au nombre de deux cent cinquante, qui instruisaient le peuple.
Wọ́n sì tún jẹ́ olórí aláṣẹ fún ọba Solomoni, àádọ́ta ó lé nígba àwọn alákòóso lórí àwọn ènìyàn.
11 Quant à la fille de Pharaon, il la transporta de la cité de David dans la maison qu’il lui avait bâtie; car le roi dit: Ma femme n’habitera pas dans la maison de David, roi d’Israël, parce quelle a été sanctifiée, du moment que l’arche du Seigneur y est entrée.
Solomoni gbé ọmọbìnrin Farao sókè láti ìlú Dafidi lọ sí ibi tí ó ti kọ́ fún un, nítorí ó wí pé, “Aya mi kò gbọdọ̀ gbé nínú ilé Dafidi ọba Israẹli nítorí ibi tí àpótí ẹ̀rí Olúwa bá tí wọ̀, ibi mímọ́ ni.”
12 Alors Salomon offrit des holocaustes au Seigneur sur l’autel du Seigneur, qu’il avait construit devant le portique,
Lórí pẹpẹ Olúwa tí ó ti kọ́ níwájú ìloro náà, Solomoni sì rú ẹbọ sísun sí Olúwa,
13 Pour qu’on y offrît chaque jour des sacrifices, selon le commandement de Moïse, aux jours du sabbat, aux calendes, et aux jours de fête, trois fois par an, c’est-à-dire à la solennité des azymes, à la solennité des semaines et à la solennité des tabernacles.
nípa ìlànà ojoojúmọ́ fún ẹbọ rírú tí a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Mose wá fún ọjọ́ ìsinmi, oṣù tuntun àti lẹ́rìn mẹ́ta lọ́dún, ní àjọ àìwúkàrà, ní àjọ ọ̀sẹ̀ méje àti àjọ àgọ́.
14 Et il établit, selon les prescriptions de David, son père, les devoirs des prêtres dans leur ministère, les Lévites dans leur ordre, pour chanter des louanges et servir devant les prêtres, suivant le rite de chaque jour, et les portiers, d’après la distribution qui en avait été faite pour chaque porte; ainsi, en effet, l’avait ordonné David, l’homme de Dieu.
Ní pípamọ́ pẹ̀lú ìlànà baba rẹ̀ Dafidi, ó sì yan ipa àwọn àlùfáà fún iṣẹ́ wọn àti àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ adarí láti máa yin àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ àwọn àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìlànà ojoojúmọ́. Ó sì tún yàn àwọn olùṣọ́nà nípa pípín sí olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà, nítorí èyí ni Dafidi ènìyàn Ọlọ́run ti paláṣẹ.
15 Touchant les commandements du roi, ni les prêtres ni les Lévites n’omirent rien de tout ce qu’il avait ordonné, et par rapport à la garde des trésors,
Wọn kò sì yà kúrò nínú àṣẹ ọba sí àwọn àlùfáà tàbí sí àwọn ọmọ Lefi, nínú ohunkóhun, àti pẹ̀lú ti ìṣúra.
16 Salomon eut toutes les dépenses préparées depuis le jour qu’il jeta les fondements de la maison jusqu’au jour où il l’acheva.
Gbogbo iṣẹ́ Solomoni ni a gbé jáde láti ọjọ́ ìfi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ ìparí. Bẹ́ẹ̀ ni ilé Olúwa sì parí.
17 Alors Salomon alla à Asiongaber et à Aïlath, sur le bord de la mer Rouge, qui est dans la terre d’Edom.
Nígbà náà ni Solomoni lọ sí Esioni-Geberi àti Elati ní Edomu létí òkun.
18 Or Hiram lui envoya, par l’entremise de ses serviteurs, des vaisseaux et des matelots connaissant la mer, et ils allèrent avec les serviteurs de Salomon à Ophir, et ils emportèrent de là quatre cent cinquante talents d’or, et ils les portèrent au roi Salomon.
Hiramu sì fi ọ̀kọ̀ ránṣẹ́ sì i nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin tí ó mòye Òkun. Èyí pẹ̀lú àwọn ènìyàn Solomoni, lọ sí Ofiri wọ́n sì gbé àádọ́ta lé ní irinwó tálẹ́ǹtì wúrà wá, padà èyí tí wọ́n sì mú tọ ọba Solomoni wá.