< 2 Chroniques 36 >

1 Le peuple du pays prit donc Joachaz, fils de Josias, et l’établit roi en la place de son père à Jérusalem.
Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah wọn sì fi jẹ ọba ní Jerusalẹmu ni ipò baba rẹ̀.
2 Joachaz avait vingt-trois ans lorsqu’il commença à régner, et il régna trois mois à Jérusalem.
Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta.
3 Mais le roi d’Égypte, étant venu à Jérusalem, le déposa, et condamna le pays à cent talents d’argent et à un talent d’or.
Ọba Ejibiti yọ kúrò lórí ìtẹ́ ní Jerusalẹmu, ó sì bù fún un lórí Juda, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì fàdákà àti tálẹ́ǹtì wúrà kan.
4 Et il établit Eliakim, son frère, roi en sa place sur Juda et sur Jérusalem, et il changea son nom en Joakim; mais Joachaz lui-même, il le prit avec lui et l’emmena en Égypte.
Ọba Ejibiti sì mú Eliakimu, arákùnrin Joahasi, jẹ ọba lórí Juda àti Jerusalẹmu, ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu, ṣùgbọ́n Neko mú Joahasi arákùnrin Eliakimu lọ sí Ejibiti.
5 Joakim avait vingt-cinq ans lorsqu’il commença à régner, et il régna onze ans à Jérusalem; mais il fit le mal devant le Seigneur son Dieu.
Jehoiakimu sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjìlá. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
6 Contre lui monta Nabuchodonosor, roi des Chaldéens, et il l’emmena enchaîné à Babylone,
Nebukadnessari ọba Babeli sì mú un, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti mú un lọ sí Babeli.
7 Dans laquelle il transporta aussi les vases du Seigneur, et il les mit dans son temple.
Nebukadnessari kó nínú ohun èlò ilé Olúwa lọ si Babeli pẹ̀lú, ó sì fi wọn sí ààfin rẹ̀ ní Babeli.
8 Mais le reste des actions de Joakim, et de ses abominations qu’il fit, et ce qui fut découvert en lui, est contenu dans le Livre des rois de Juda et d’Israël. Joachin son fils régna en sa place.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoiakimu, àwọn ohun ìríra tí ó ṣe àti gbogbo ohun tí a rí nípa rẹ̀, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Israẹli àti Juda. Jehoiakini ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
9 Joachin avait huit ans lorsqu’il commença à régner, et il régna trois mois et dix jours à Jérusalem, et il fit le mal en la présence du Seigneur.
Jehoiakini sì jẹ́ ẹni ọdún méjìdínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ́ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta àti ọjọ́ mẹ́wàá ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa.
10 Et lorsque le cours de l’année fut révolu, le roi Nabuchodonosor envoya des troupes qui l’emmenèrent à Babylone, emportant en même temps les vases les plus précieux de la maison du Seigneur. Or il établit Sédécias, son oncle, roi sur Juda et sur Jérusalem.
Ní àkókò òjò, ọba Nebukadnessari ránṣẹ́ sí i ó sì mú un wá sí Babeli, pẹ̀lú ohun èlò dáradára láti ilé Olúwa, ó sì mú arákùnrin Jehoiakini, Sedekiah, jẹ ọba lórí Juda àti Jerusalẹmu.
11 Sédécias avait vingt et un ans lorsqu’il commença à régner, et il régna onze ans à Jérusalem.
Sedekiah jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá.
12 Et il fit le mal en la présence du Seigneur son Dieu, et il ne rougit point en face de Jérémie, le prophète, qui lui parlait par l’ordre du Seigneur.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, kò sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Jeremiah wòlíì ẹni tí ó sọ̀rọ̀ Olúwa.
13 Il se détacha même du roi Nabuchodonosor, qui l’avait adjuré par Dieu; il endurcit sa tête et son cœur pour ne point retourner au Seigneur Dieu d’Israël.
Ó sì tún ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Nebukadnessari pẹ̀lú, ẹni tí ó mú kí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra. Ó sì di ọlọ́run líle, ó sì mú ọkàn rẹ̀ le láti má lè yípadà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
14 Et même tous les princes des prêtres, et le peuple, prévariquèrent iniquement suivant toutes les abominations des nations, et profanèrent la maison du Seigneur, qu’il avait sanctifiée pour lui à Jérusalem.
Síwájú sí i gbogbo àwọn olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn sì di ẹni tí ń dẹ́ṣẹ̀ gidigidi, pẹ̀lú gbogbo ìríra àwọn orílẹ̀-èdè wọ́n sì sọ ilé Olúwa di èérí, tí ó ti yà sí mímọ́ ní Jerusalẹmu.
15 Or le Seigneur Dieu de leurs pères s’adressait à eux par l’entremise de ses envoyés, se levant durant la nuit, et les avertissant chaque jour, parce qu’il ménageait son peuple et sa demeure.
Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn ránṣẹ́ sí wọn láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ síwájú àti síwájú sí i, nítorí tí ó ní ìyọ́nú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ àti sí ibùgbé rẹ̀.
16 Mais eux se moquaient des envoyés de Dieu, faisaient peu de cas de ses paroles, et raillaient les prophètes, jusqu’à ce que la fureur du Seigneur montât contre son peuple, et qu’il n’y eût aucun remède.
Ṣùgbọ́n wọ́n ń kùn sí àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ọ̀rọ̀ rẹ̀, wọ́n fi àwọn wòlíì rẹ̀ ṣẹ̀sín títí tí ìbínú Olúwa fi ru sórí wọn, sí àwọn ènìyàn rẹ̀ kò sì ṣí àtúnṣe.
17 Car il amena contre eux le roi des Chaldéens, qui tua leurs jeunes hommes par le glaive dans la maison de son sanctuaire; et il n’eut pitié ni de l’adolescent, ni de la vierge, ni du vieillard, ni même de l’homme décrépit: mais il les livra tous entre ses mains,
Ó sì mú wá sórí wọn ọba àwọn ará Babeli tí wọ́n bá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn jà pẹ̀lú idà ní ilẹ̀ ibi mímọ́, kò sì ní ìyọ́nú sí àgbà ọkùnrin tàbí ọ̀dọ́mọdébìnrin, wúńdíá, tàbí arúgbó. Ọlọ́run sì fi gbogbo wọn lé Nebukadnessari lọ́wọ́.
18 Et quant à tous les vases de la maison du Seigneur, tant les grands que les petits, et les trésors du temple, du roi et des princes, il les transporta à Babylone.
Ó sì mú gbogbo ohun èlò láti ilé Ọlọ́run lọ sí Babeli, ńlá àti kékeré àti ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ọba àti ìjòyè rẹ̀.
19 Les ennemis incendièrent la maison de Dieu, détruisirent le mur de Jérusalem; brûlèrent toutes les tours; et tout ce qu’il y avait de précieux, ils le détruisirent.
Wọ́n sì fi iná sun ilé Ọlọ́run, wọ́n sì wó gbogbo ògiri ilé Jerusalẹmu, wọ́n sì jó gbogbo ààfin wọn, wọ́n sì ba gbogbo ohun èlò ibẹ̀ jẹ́.
20 Si quelqu’un avait échappé au glaive, conduit à Babylone, il était esclave du roi et de ses enfants, jusqu’à ce que régnât le roi de Perse,
Ó sì kó èyí tí ó kù lọ sí Babeli àwọn tí ó rí ibi sá kúrò lẹ́nu idà wọ́n sì di ìránṣẹ́ fún un àti àwọn ọmọ rẹ̀ títí tí ìjọba Persia fi gba agbára.
21 Et que fût accomplie la parole du Seigneur annoncée par la bouche de Jérémie, et que la terre célébrât ses sabbats; car pendant tous les jours de la désolation, elle fit le sabbat, jusqu’à ce que fussent accomplis les soixante-dix ans.
Ilẹ̀ náà sì gbádùn ìsinmi rẹ̀, ní gbogbo ìgbà ìdahoro, òun sì ń sinmi títí àádọ́rin ọdún fi pé ní ìmúṣẹ ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ láti ẹnu Jeremiah.
22 Mais en la première année de Cyrus, roi des Perses, pour accomplir la parole du Seigneur qu’il avait dite par la bouche de Jérémie, le Seigneur suscita l’esprit de Cyrus, roi des Perses, qui commanda de publier dans tout son royaume un édit, même par écrit, disant:
Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi ọba Persia, kí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a tẹnu Jeremiah sọ bá à le ṣẹ pé, Olúwa run ẹ̀mí Kirusi ọba Persia láti ṣe ìkéde ní gbogbo ìjọba rẹ̀, ó sì kọ ọ́ sínú ìwé pẹ̀lú.
23 Voici ce que dit Cyrus, roi des Perses: Le Seigneur Dieu du ciel m’a donné tous les royaumes de la terre, et lui-même m’a ordonné de lui bâtir une maison dans Jérusalem, qui est dans la Judée. Qui d’entre vous est de tout son peuple? Que le Seigneur son Dieu soit avec lui, et qu’il monte.
“Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia sọ wí pé: “‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mí ní gbogbo ìjọba ayé yìí, ó sì ti yàn mí láti kọ́ ilé Olúwa fún òun ní Jerusalẹmu ti Juda. Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín le gòkè lọ pẹ̀lú rẹ̀; kí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ kí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.’”

< 2 Chroniques 36 >