< 2 Chroniques 29 >
1 Ézéchias commença donc à régner à l’âge de vingt-cinq ans, et il en régna vingt-neuf dans Jérusalem; le nom de sa mère était Abia, fille de Zacharie.
Hesekiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
2 Et il fit ce qui était agréable en la présence du Seigneur, selon tout ce qu’avait fait David son père.
Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
3 C’est lui qui, au premier mois de la première année de son règne, ouvrit les battants des portes de la maison du Seigneur, et les rétablit;
Ní oṣù àkọ́kọ́ ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, ó sì ṣí àwọn ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tún wọn ṣe.
4 Et il fit venir les prêtres et les Lévites, et les assembla sur la place orientale.
Ó sì mú àwọn àlùfáà wá àti àwọn ọmọ Lefi, ó sì kó wọn jọ yíká ìta ìlà-oòrùn.
5 Et il leur dit: Ecoutez-moi, Lévites; sanctifiez-vous, purifiez la maison du Seigneur Dieu de vos pères, et ôtez toute impureté du sanctuaire.
Ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi, ẹ̀yin ọmọ Lefi! Ẹ ya ara yín sí mímọ́ nísinsin yìí kí ẹ sì ya ilé Olúwa Ọlọ́run sí mímọ́, kí ẹ sì kó ohun àìmọ́ baba mi jáde kúrò ní ibi mímọ́.
6 Nos pères ont péché, et ils ont fait le mal en la présence du Seigneur notre Dieu, en l’abandonnant: ils ont détourné leurs faces du tabernacle du Seigneur, et ils ont montré le dos.
Àwọn baba wa jẹ́ aláìṣòótọ́; wọ́n sì ṣe ohun àìtọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa, wọ́n sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Wọ́n sì yí ojú wọn padà kúrò ní ibùgbé Olúwa, wọ́n sì pa ẹ̀yìn wọn dà sí i.
7 Ils ont fermé les portes qui étaient dans le portique, et ont éteint les lampes; ils n’ont pas brûlé d’encens, et n’ont pas offert d’holocaustes dans le sanctuaire au Dieu d’Israël.
Wọ́n sì tún ti ìlẹ̀kùn ìloro náà pẹ̀lú, wọ́n sì pa fìtílà. Wọn kò sì sun tùràrí tàbí pèsè ẹbọ sísun si ibi mímọ́ si Ọlọ́run Israẹli.
8 C’est pourquoi la fureur du Seigneur a été excitée contre Juda et Jérusalem; il les a livrés à la commotion, à la mort et au sifflement, comme vous-mêmes le voyez de vos yeux.
Nítorí náà, ìbínú Olúwa ti ru sókè wá sórí Juda àti Jerusalẹmu ó sì ti fi wọ́n ṣe ohun èlò fún wàhálà, àti ìdààmú àti ẹ̀sín, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fi ojú rẹ̀ rí i.
9 Voilà que nos pères sont tombés sous le glaive, que nos fils, nos filles et nos femmes ont été emmenés captifs à cause de ce crime.
Ìdí nìyí tí àwọn baba wa ṣe ṣubú nípa idà àti ìdí tí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin àti àwọn aya wa tiwọn kó wọ́n ní ìgbèkùn.
10 Il me plaît donc maintenant que nous contractions alliance avec le Seigneur Dieu d’Israël, et il détournera de nous la fureur de sa colère.
Nísinsin yìí ó wà ní ọkàn mi láti bá Olúwa Ọlọ́run Israẹli dá májẹ̀mú. Bẹ́ẹ̀ ni kí ìbínú rẹ̀ kíkan kí ó lè yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.
11 Mes enfants, ne soyez point négligents: le Seigneur vous a choisis pour vous tenir devant lui, le servir, l’adorer et brûler pour lui de l’encens.
Àwọn ọmọ mi, ẹ má ṣe jáfara nísinsin yìí, nítorí tí Olúwa ti yàn yín láti dúró níwájú rẹ̀ láti sin, kí ẹ sì máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ àti láti sun tùràrí.”
12 Ainsi se levèrent les Lévites, Mahath, fils d’Amasaï, et Joël, fils d’Azarias, d’entre les descendants de Caath; mais d’entre les descendants de Mérari, Cis, fils d’Abdi, et Azarias, fils de Jalaléel; et d’entre les descendants de Gersom, Joab, fils de Zemma, et Eden, fils de Joab;
Nígbà náà àwọn ọmọ Lefi wọ̀nyí múra láti ṣe iṣẹ́: nínú àwọn ọmọ Kohati, Mahati ọmọ Amasai: àti Joẹli ọmọ Asariah; nínú àwọn ọmọ Merari, Kiṣi ọmọ Abdi àti Asariah ọmọ Jehaleeli; nínú àwọn ọmọ Gerṣoni, Joah, ọmọ Simma àti Edeni ọmọ Joah;
13 Mais d’entre les descendants d’Elisaphan, Samri et Jahiel; comme aussi les descendants d’Asaph, Zacharie et Mathanie;
nínú àwọn ọmọ Elisafani, Ṣimri àti Jeieli; nínú àwọn ọmọ Asafu, Sekariah àti Mattaniah;
14 Et d’entre les descendants d’Héman, Jahiel et Séméi; mais aussi les descendants d’Idithun, Séméias et Oziel.
nínú àwọn ọmọ Hemani, Jehieli àti Ṣimei; nínú àwọn ọmọ Jedutuni, Ṣemaiah àti Usieli.
15 Et ils assemblèrent leurs frères, puis ils se sanctifièrent et entrèrent, suivant l’ordre du roi et le commandement du Seigneur, pour purifier la maison de Dieu.
Nígbà tí wọ́n sì ti kó ara wọn jọ pọ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn, wọ́n sì ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì lọ láti gbá ilé Olúwa mọ́, gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ, ẹ tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Olúwa.
16 Les prêtres aussi entrèrent dans le temple du Seigneur pour le sanctifier, et ils ôtèrent toute impureté qu’ils trouvèrent au dedans, dans le vestibule de la maison du Seigneur, et que les Lévites enlevèrent et emportèrent dans le torrent de Cédron.
Àwọn àlùfáà sì wọ inú ilé Olúwa lọ́hùn ún lọ láti gbá a mọ́. Wọ́n sì gbé e jáde sí inú àgbàlá ilé Olúwa gbogbo ohun àìmọ́ tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa. Àwọn ọmọ Lefi sì mú u wọ́n sì gbangba odò Kidironi.
17 Or ils commencèrent au premier jour du premier mois à purifier, et au huitième jour du même mois ils entrèrent dans le portique du temple du Seigneur: ils purifièrent le temple durant huit jours; et, au seizième jour du même mois, ils achevèrent ce qu’ils avaient commencé.
Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìyàsímímọ́ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, àti ní ọjọ́ kẹjọ oṣù náà wọ́n sì dé ìloro Olúwa. Fún ọjọ́ mẹ́jọ mìíràn sí i, wọ́n sì ya ilé Olúwa sí mímọ́ fúnra rẹ̀. Wọ́n sì parí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kìn-ín-ní.
18 ils entrèrent aussi auprès du roi Ezéchias, et lui dirent: Nous avons sanctifié toute la maison du Seigneur, l’autel de l’holocauste, et ses vases, et même la table de proposition avec tous ses vases,
Nígbà náà wọn sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah láti lọ jábọ̀ fún un: “Àwa ti gbá ilé Olúwa mọ́, pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú gbogbo ohun ẹbọ rẹ̀, àti tábìlì àkàrà ìfihàn, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò.
19 Et tous les meubles du temple, qu’avait souillés le roi Achaz, durant son règne, après qu’il eut prévariqué; et voilà que tout a été posé devant l’autel du Seigneur.
A ti pèsè a sì ti yà sí mímọ́ gbogbo ohun èlò tí ọba Ahasi ti sọ di aláìmọ́ nínú àìṣòótọ́ rẹ̀ nígbà tí ó jẹ́ ọba; nísinsin yìí, wọ́n wà níwájú pẹpẹ Olúwa.”
20 Et le roi Ezéchias, se levant au point du jour, réunit tous les princes de la ville, et monta à la maison du Seigneur;
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọba Hesekiah sì kó olórí àwọn ìjòyè jọ, ó sì lọ sókè ilé Olúwa.
21 Et ils offrirent ensemble sept taureaux et sept béliers, sept agneaux et sept boucs, pour le péché, pour le royaume, pour le sanctuaire, pour Juda, et il dit aux prêtres descendants d’Aaron d’offrir ces victimes sur l’autel du Seigneur.
Wọ́n sì mú akọ màlúù méje wá, àti àgbò méje, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje àti òbúkọ méje gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ìjọba, fún ibi mímọ́ àti fún Juda. Ọba pàṣẹ fun àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, láti ṣe èyí lórí pẹpẹ Olúwa.
22 Ils tuèrent donc les taureaux, et les prêtres prirent le sang et le répandirent sur l’autel; ils tuèrent aussi les béliers, et ils en répandirent le sang sur l’autel; ils immolèrent aussi les agneaux, et ils répandirent sur l’autel le sang.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pa akọ màlúù, àwọn àlùfáà mú ẹ̀jẹ̀ náà, wọ́n sì fi wọ́n ara pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni nígbà tí wọ́n pa àgbò, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọ́n orí pẹpẹ. Nígbà náà wọ́n sì pa ọ̀dọ́-àgùntàn, wọ́n sì fi ẹ̀jẹ̀ wọn ara pẹpẹ.
23 Ils firent avancer les boucs pour le péché, devant le roi et toute la multitude, et ils posèrent leurs mains sur eux;
Òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni wọ́n gbé wá síwájú ọba àti ìjọ ènìyàn, wọ́n sì gbé ọwọ́ lé wọn.
24 Et les prêtres les immolèrent, et en répandirent le sang devant l’autel pour l’expiation de tout Israël; car c’est pour tout Israël que le roi avait commandé que l’holocauste se fît, et pour le péché.
Àwọn àlùfáà wọn sì pa òbúkọ, wọ́n sì gbé ẹ̀jẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún gbogbo Israẹli, nítorí ọba ti pàṣẹ kí a ṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli.
25 Il établit aussi les Lévites dans la maison du Seigneur, avec des cymbales, des psaltérions et des harpes, selon les prescriptions du roi David, de Gad, le Voyant, et de Nathan, le prophète; attendu que c’était un ordre du Seigneur par l’entremise de ses prophètes.
Ó sì mú àwọn Lefi dúró nínú ilé Olúwa pẹ̀lú Kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù ní ọ̀nà tí a ti paláṣẹ fún wọn láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Gadi aríran ọba àti Natani wòlíì. Èyí ni a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Olúwa láti ọwọ́ àwọn wòlíì rẹ̀.
26 Ainsi les Lévites s’y trouvèrent, tenant les instruments de David, et les prêtres les trompettes.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì dúró pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi, àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ìpè wọn.
27 Et Ezéchias commanda qu’on offrît les holocaustes sur l’autel; et, lorsque l’on offrait les holocaustes, ils commencèrent à chanter des louanges au Seigneur, à sonner des trompettes, et à faire retentir divers instruments que David, roi d’Israël, avait préparés.
Hesekiah sì pa á láṣẹ láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ, bí ẹbọ sísun náà ti bẹ̀rẹ̀, orin sí Olúwa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú ohun èlò orin Dafidi ọba Israẹli.
28 Or, toute la multitude adorant le Seigneur, les chantres et ceux qui tenaient les trompettes étaient à leur devoir, jusqu’à ce que l’holocauste fût achevé.
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà sì wólẹ̀ sìn, àwọn akọrin kọrin, àwọn afùnpè sì fọn ìpè, gbogbo wọ̀nyí sì wà bẹ́ẹ̀ títí ẹbọ sísun náà fi parí tán.
29 Et lorsque l’oblation fut finie, le roi s’inclina, et tous ceux qui étaient avec lui, et ils adorèrent.
Nígbà tí wọ́n sì ṣe ìparí ẹbọ rírú, ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ ara wọn ba, wọ́n sì sìn.
30 Et Ezéchias et les princes ordonnèrent aux Lévites de louer le Seigneur avec les paroles de David et d’Asaph, le Voyant; et ils le louèrent avec une grande joie, et, le genou courbé, ils adorèrent.
Pẹ̀lúpẹ̀lú Hesekiah ọba, àti àwọn ìjòyè pàṣẹ fún àwọn ọmọ Lefi, láti fi ọ̀rọ̀ Dafidi àti ti Asafu aríran, kọrin ìyìn sí Olúwa: wọ́n sì fi inú dídùn kọrin ìyìn, wọ́n sì tẹrí wọn ba, wọ́n sì sìn.
31 Mais Ezéchias ajouta encore ceci: Vous avez rempli vos mains pour le Seigneur; approchez, et offrez des victimes et des louanges dans la maison du Seigneur. Toute la multitude offrit donc des hosties, des louanges et des holocaustes avec un cœur dévoué.
Nígbà náà ni Hesekiah dáhùn, ó sì wí pé, nísinsin yìí, ọwọ́ yín kún fún ẹ̀bùn fún Olúwa, ẹ súnmọ́ ìhín, kí ẹ sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá sínú ilé Olúwa. Ìjọ ènìyàn sì mú ẹbọ àti ọrẹ-ọpẹ́ wá; àti olúkúlùkù tí ọkàn rẹ̀ fẹ́, mú ẹbọ sísun wá.
32 Quant au nombre des holocaustes qu’offrit la multitude, ce furent soixante-dix taureaux, cent béliers, et deux cents agneaux.
Iye ẹbọ sísun, tí ìjọ ènìyàn mú wá, sì jẹ́ àádọ́rin akọ màlúù, àti ọgọ́rùn-ún àgbò, àti igba ọ̀dọ́-àgùntàn, gbogbo wọ̀nyí sì ni fún ẹbọ sísun sí Olúwa.
33 Et ils consacrèrent au Seigneur six cents bœufs et trois mille moutons.
Àwọn ohun ìyàsímímọ́ sì jẹ́ ẹgbẹ̀ta màlúù, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn.
34 Or les prêtres étaient en petit nombre, et ils ne pouvaient suffire à enlever la peau des holocaustes: c’est pourquoi les Lévites, leurs frères, les aidèrent jusqu’à ce que l’ouvrage fût achevé et que les prêtres fussent sanctifiés; car les Lévites sont sanctifiés avec un rit plus facile que les prêtres.
Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà kò pọ̀ tó, wọn kò sì le bó gbogbo àwọn ẹran ẹbọ sísun náà: nítorí náà àwọn arákùnrin wọn, àwọn Lefi ràn wọ́n lọ́wọ́, títí iṣẹ́ náà fi parí, àti títí àwọn àlùfáà ìyókù fi yà wọ́n sí mímọ́: nítorí àwọn ọmọ Lefi ṣe olóòtítọ́ ní ọkàn ju àwọn àlùfáà lọ láti ya ara wọn sí mímọ́.
35 On offrit donc un très grand nombre d’holocaustes, les graisses des hosties pacifiques, et les libations des holocaustes, et l’on rétablit entièrement le culte de la maison du Seigneur.
Àti pẹ̀lú, àwọn ẹbọ sísun pàpọ̀jù, pẹ̀lú ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu fún ẹbọ sísun. Bẹ́ẹ̀ ni a sì tún bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìsìn ilé Olúwa.
36 Et Ezéchias se livra à l’allégresse, ainsi que tout le peuple, de ce que le service du Seigneur était entièrement rétabli; car il avait plu que cela se fît soudainement.
Hesekiah sì yọ̀, àti gbogbo ènìyàn pé, Ọlọ́run ti múra àwọn ènìyàn náà sílẹ̀, nítorí lójijì ni a ṣe nǹkan náà.