< 2 Chroniques 21 >
1 Or Josaphat dormit avec ses pères, et il fut enseveli avec eux dans la cité de David, et son fils Joram régna en sa place.
Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
2 Joram eut pour frères les fils de Josaphat, Azarias, Jahiel, Zacharie, Azarias, Michaël et Saphatia; tous ceux-là furent fils de Josaphat, roi de Juda.
Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
3 Et leur père leur donna beaucoup de présents en argent et en or, ainsi que des pensions, et des villes très fortifiées dans Juda; mais le royaume, il le remit à Joram, parce qu’il était le premier-né.
Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
4 Joram se leva donc sur le royaume de son père, et, lorsqu’il se fut affermi, il tua par le glaive tous ses frères et quelques-uns des princes d’Israël.
Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
5 Joram avait trente-deux ans lorsqu’il commença à régner, et il régna huit ans à Jérusalem.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
6 Et il marcha dans les voies des rois d’Israël, comme avait fait la maison d’Achab: car la fille d’Achab était sa femme, et il fit le mal en la présence du Seigneur.
Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
7 Cependant le Seigneur ne voulut point perdre la maison de David, à cause de l’alliance qu’il avait faite avec lui, et parce qu’il lui avait promis qu’il lui donnerait une lampe à lui et à ses fils en tout temps.
Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
8 En ces jours-là, Edom se révolta pour n’être pas assujetti à Juda, et il s’établit un roi.
Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
9 Et lorsque Joram eut passé en Idumée avec ses principaux chefs et toute la cavalerie qui était avec lui, il se leva pendant la nuit, et il battit Edom qui l’avait environné, et tous les chefs de sa cavalerie.
Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
10 Cependant Edom s’est révolté jusqu’à ce jour pour n’être pas sous la domination de Juda. En ce temps-là Lobna aussi se retira pour n’être pas sous sa main; car il avait abandonné le Seigneur Dieu de ses pères;
Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
11 Et de plus il fit même des hauts lieux dans les villes de Juda, et il fit forniquer tous les habitants de Jérusalem, et prévariquer Juda.
Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
12 Or on lui apporta des lettres du prophète Élie, dans lesquelles il était écrit: Voici ce que dit le Seigneur Dieu de David, votre père: Parce que tu n’as pas marché dans les voies de Josaphat, ton père, et dans les voies d’Asa, roi de Juda,
Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
13 Mais que tu es entré dans le chemin des rois d’Israël, que tu as fait forniquer Juda et les habitants de Jérusalem, ayant imité la fornication de la maison d’Achab, et que de plus tu as tué tes frères mêmes, la maison de ton père, meilleure que toi,
Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
14 Voilà que le Seigneur te frappera d’une grande plaie, avec ton peuple, tes fils, tes femmes, et tout ce qui t’appartient;
Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
15 Mais toi, tu seras malade d’une très cruelle langueur, jusqu’à ce que tes entrailles sortent peu à peu chaque jour.
Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
16 Le Seigneur suscita donc contre Joram l’esprit des Philistins et des Arabes, qui confinent avec les Ethiopiens;
Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
17 Et ils montèrent dans la terre de Juda, et ils la ravagèrent, et ils pillèrent tout objet qui fut trouvé dans la maison du roi, et de plus, ils emmenèrent ses fils et ses femmes; et il ne lui resta de fils que Joachaz, le plus jeune de tous.
Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
18 Et par dessus tout cela, le Seigneur le frappa d’une maladie d’intestins incurable.
Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
19 Or un jour succédant à un autre jour, et des espaces de temps se déroulant, un cours de deux années fut accompli; alors, ainsi consumé par un si long dépérissement, qu’il répandait même ses entrailles, il fut quitte de la maladie en même temps que de la vie. Il mourut donc de cette infirmité très cruelle, et le peuple ne l’ensevelit point selon la coutume, en le brûlant, comme il avait fait à ses ancêtres.
Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
20 Il avait trente-deux ans lorsqu’il commença à régner, et il régna huit ans à Jérusalem; et il ne marcha pas droit. Or on l’ensevelit dans la cité de David, mais non pas dans le sépulcre des rois.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.