< 2 Chroniques 20 >

1 Après cela les enfants de Moab et les enfants d’Ammon, et avec eux des Ammonites, s’assemblèrent contre Josaphat pour combattre contre lui.
Lẹ́yìn èyí, àwọn ọmọ Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni àti díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Mehuni wá láti gbé ogun ti Jehoṣafati.
2 Et des messagers vinrent et l’annoncèrent à Josaphat, disant: Une grande multitude vient contre vous des lieux qui sont au-delà de la mer et de la Syrie, et voilà qu’ils s’arrêtent à Asasonthamar, qui est Engaddi.
Àwọn díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin wá láti sọ fún Jehoṣafati, “Àwọn ọ̀pọ̀ ọ̀wọ́ ogun ń bọ̀ wá bá ọ láti apá kejì Òkun láti Siria. Ó ti wà ní Hasason Tamari náà” (èyí tí í ṣe En-Gedi).
3 Or, Josaphat, saisi de crainte, s’appliqua entièrement à prier le Seigneur, et publia un jeûne dans tout Juda.
Nípa ìró ìdágìrì, Jehoṣafati pinnu láti wádìí lọ́wọ́ Olúwa, ó sì kéde àwẹ̀ kíákíá fún gbogbo Juda.
4 Et Juda s’assembla pour prier le Seigneur, et même tous sortirent de leurs villes pour l’implorer,
Àwọn ènìyàn Juda sì kó ara wọn jọ pọ̀ láti wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa; pẹ̀lúpẹ̀lú, wọ́n wá láti gbogbo ìlú ní Juda láti wá a.
5 Et lorsque Josaphat se fut levé au milieu de Juda et de Jérusalem dans la maison du Seigneur, devant le parvis nouveau,
Nígbà náà Jehoṣafati dìde dúró níwájú àpéjọ Juda àti Jerusalẹmu ní ilé Olúwa níwájú àgbàlá tuntun.
6 Il dit: Seigneur Dieu de nos pères, c’est vous qui êtes Dieu dans le ciel, et qui dominez sur tous les royaumes des nations: dans votre main sont la force et la puissance, et personne ne peut vous résister.
O sì wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ìwọ kì ha ṣe Ọlọ́run tí ń bẹ ní ọ̀run? Ìwọ ń ṣe alákòóso lórí gbogbo ìjọba àwọn orílẹ̀-èdè. Agbára àti ipá ń bẹ ní ọwọ́ rẹ, kò sì sí ẹnìkan tí ó lè kò ọ́ lójú.
7 N’est-ce pas vous, notre Dieu, qui avez tué tous les habitants de cette terre devant votre peuple Israël, et qui l’avez donnée à la postérité d’Abraham, votre ami pour toujours?
Ìwọ ha kọ́ Ọlọ́run wa, tí o ti lé àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí jáde níwájú àwọn ènìyàn Israẹli, tí o sì fi fún irú-ọmọ Abrahamu ọ̀rẹ́ rẹ láéláé?
8 Et ils y ont habité, et ils y ont construit un sanctuaire à votre nom, disant:
Wọ́n ti ń gbé nínú rẹ̀ wọ́n sì ti kọ́ sínú rẹ ibi mímọ́ fún orúkọ rẹ wí pé,
9 S’il fond sur nous des maux, un glaive de jugement, une peste, et une famine, nous nous tiendrons en votre présence devant cette maison, dans laquelle a été invoqué votre nom, et nous crierons vers vous dans nos tribulations, et vous nous exaucerez, et vous nous sauverez.
‘Tí ibi bá wá sí orí wa, bóyá idà ìjìyà tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn àwọn yóò dúró níwájú rẹ níwájú ilé yìí tí ń jẹ́ orúkọ rẹ, àwa yóò sì sọkún jáde, ìwọ yóò sì gbọ́ wa. Ìwọ yóò sì gbà wá là?’
10 Maintenant donc, voilà que les enfants d’Ammon et de Moab, et les habitants de la montagne de Séir, au milieu desquels vous ne permîtes pas à Israël de passer lorsqu’ils sortaient d’Égypte; mais ils se détournèrent d’eux, et ils ne les tuèrent pas.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn ọkùnrin nìyí láti Ammoni, Moabu àti òkè Seiri, agbègbè ibi ti ìwọ kò ti gba àwọn ọmọ Israẹli láyè láti gbóguntì nígbà tí wọn wá láti Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn, wọn kò sì pa wọ́n run.
11 Voilà que ces peuples agissent tout autrement, et ils s’efforcent de nous chasser de la possession que vous nous avez donnée.
Sì kíyèsi i, bí wọ́n ti san án padà fún wa; láti wá lé wa jáde kúrò nínú ìní rẹ, tí ìwọ ti fi fún wa láti ní.
12 Ô notre Dieu, ne les jugerez-vous pas? Certes, nous n’avons pas une assez grande force pour que nous puissions résister à cette multitude qui vient fondre sur nous. Mais, comme nous ignorons ce que nous devons faire, il ne nous reste qu’à diriger nos yeux vers vous.
Ọlọ́run wa, ṣé ìwọ kò ní ṣe ìdájọ́ fún wọn? Nítorí àwa kò ní agbára láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí tí ń bọ̀ wá kó wa. Àwa kò mọ̀ ohun tó yẹ ká ṣe, ṣùgbọ́n ojú wa wà ní ọ̀dọ̀ rẹ.”
13 Or tout Juda était debout devant le Seigneur, avec leurs petits enfants, leurs femmes et leurs autres enfants.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Juda, pẹ̀lú àwọn aya wọn àti ọmọ wọn àti àwọn kéékèèké, dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.
14 Là était aussi Jahaziel, fils de Zacharie, fils de Banaïas, fils de Jéhiel, fils de Mathanias, Lévite de la famille d’Asaph; et l’Esprit de Dieu descendit sur lui au milieu de la multitude;
Nígbà náà, ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jahasieli ọmọ Sekariah, ọmọ Benaiah, ọmọ Jeieli, ọmọ Mattaniah ọmọ Lefi àti ọmọ Asafu, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe dìde dúró láàrín àpéjọ ènìyàn.
15 Et il dit: Ecoutez, vous tous, Juda, et vous qui habitez Jérusalem, et vous aussi, roi Josaphat: Voici ce que vous dit le Seigneur: Ne craignez point, et ne redoutez point cette multitude; car ce n’est pas votre combat, mais celui de Dieu.
Ó sì wí pé, “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ọba Jehoṣafati àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní Juda àti Jerusalẹmu! Èyí ní ohun tí Olúwa sọ wí pé kí a ṣe: ‘Ẹ má ṣe bẹ̀rù tàbí fòyà nítorí ọ̀pọ̀ ogun ńlá yìí. Nítorí ogun náà kì í ṣe tiyín, ṣùgbọ́n ti Ọlọ́run ni.
16 Demain vous descendrez contre eux; car ils doivent monter par le coteau du nom de Sis, et vous les trouverez à l’extrémité du torrent qui est contre le désert de Jéruel.
Ní ọ̀la, ẹ sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ, wọn yóò gòkè pẹ̀lú, ẹ̀yin yóò sì rí wọn ní ìpẹ̀kun odò náà, níwájú aginjù Jerueli.
17 Ce ne sera pas vous qui combattrez; mais seulement soyez résolus, et vous verrez le secours du Seigneur sur vous, ô Juda et Jérusalem: ne craignez point et ne vous effrayez point; demain vous marcherez contre eux, et le Seigneur sera avec vous.
Ẹ̀yin kò ní láti bá ogun yìí jà. ẹ dúró ní ààyè yín; ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì rí ìgbàlà Olúwa tí yóò fi fún yín, ìwọ Juda àti Jerusalẹmu. Ẹ má ṣe bẹ̀rù; ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ jáde lọ láti lọ dojúkọ wọ́n ní ọ̀la, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú yín.’”
18 Josaphat donc, et Juda, et tous les habitants de Jérusalem, tombèrent inclinés vers la terre devant le Seigneur, et l’adorèrent.
Jehoṣafati tẹ orí rẹ̀ ba sílẹ̀ pẹ̀lú ojú rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu wólẹ̀ níwájú láti sin Olúwa.
19 Et les Lévites d’entre les enfants de Caath et d’entre les enfants de Coré louaient le Seigneur Dieu d’Israël avec une voix forte et élevée.
Nígbà náà díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ọmọ Kohati àti àwọn ọmọ Kora sì dìde dúró wọ́n sì sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, pẹ̀lú ohùn ariwo ńlá.
20 Et lorsqu’au matin ils se furent levés, ils sortirent par le désert de Thécué; et, lorsqu’ils étaient en marche, Josaphat, debout au milieu d’eux, dit: Ecoutez-moi, hommes de Juda, et vous tous, habitants de Jérusalem: mettez votre confiance dans le Seigneur votre Dieu, et vous serez en sûreté; croyez à ses prophètes, et toutes choses seront prospères.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù wọ́n jáde lọ sí aginjù Tekoa. Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń jáde lọ, Jehoṣafati dìde dúró ó sì wí pé, “Ẹ gbọ́ mi, Juda àti ènìyàn Jerusalẹmu! Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Olúwa Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì borí, ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn wòlíì rẹ̀ ẹ̀yìn yóò sì ṣe rere.”
21 Et il donna ses avis au peuple, et il établit les chantres du Seigneur pour le louer dans leurs diverses bandes, marcher devant l’armée, et d’une voix unanime dire: Rendez gloire au Seigneur, parce que sa miséricorde est éternelle.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá àwọn ènìyàn náà gbèrò tán, Jehoṣafati yàn wọ́n láti kọrin sí Olúwa àti láti fi ìyìn fún ẹwà ìwà mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ó tì ń jáde lọ sí iwájú ogun ńlá náà, wí pé, “Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí àánú rẹ̀ dúró títí láéláé.”
22 Et lorsqu’ils eurent commencé à chanter ainsi des louanges, le Seigneur tourna tous les desseins des ennemis contre eux-mêmes, c’est-à-dire des enfants d’Ammon et de Moab, et des habitants de la montagne de Séir qui étaient sortis pour combattre contre Juda; et ils furent battus.
Bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí kọrin àti ìyìn, Olúwa rán ogun ẹ̀yìn sí àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu àti òkè Seiri tí ó ń gbógun ti Juda, wọ́n sì kọlù wọ́n.
23 Car les fils d’Ammon et de Moab se levèrent contre les habitants de la montagne de Séir, pour les massacrer et les exterminer; et lorsqu’ils eurent achevé, s’étant aussi tournés contre eux-mêmes, ils tombèrent sous leurs coups mutuels.
Àwọn ọkùnrin Ammoni àti Moabu dìde dúró sí àwọn ọkùnrin tí ń gbé òkè Seiri láti pa wọ́n run túútúú. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti pa àwọn ọkùnrin láti òkè Seiri, wọ́n sì ran ra wọn lọ́wọ́ láti pa ara wọn run.
24 Or, lorsque Juda fut venu à l’échauguette qui regarde le désert, il vit de loin tout le pays dans une grande étendue plein de cadavres, et qu’il ne restait personne qui eût pu échapper à la mort.
Nígbà tí àwọn ènìyàn Juda jáde sí ìhà ilé ìṣọ́ ní aginjù, wọn ń wo àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn, òkú nìkan ni wọ́n rí tí ó ṣubú sí ilẹ̀, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí ààyè sá.
25 Josaphat vint donc, et tout le peuple avec lui, pour enlever les dépouilles des morts, et ils trouvèrent, parmi les cadavres, des meubles divers, des vêtements aussi et des vases très précieux, et ils les pillèrent; en sorte qu’ils ne purent tout emporter, ni enlever durant trois jours les dépouilles, à cause de la quantité du butin.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoṣafati àti àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ láti kó ìkógun wọn, wọ́n sì rí lára wọn ọ̀pọ̀ iyebíye ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ju èyí tí wọ́n lè kó lọ. Ọ̀pọ̀ ìkógun sì wà níbẹ̀, èyí tí ó gbà wọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta láti gbà pọ̀.
26 Or, le quatrième jour, ils s’assemblèrent dans la vallée de la Bénédiction; car, parce qu’ils y avaient béni le Seigneur, ils appelèrent ce lieu vallée de Bénédiction, jusqu’au présent jour.
Ní ọjọ́ kẹrin, wọn kó ara jọ pọ̀ ní àfonífojì ìbùkún, níbi tí wọ́n ti ń fi ìbùkún fún Olúwa. Ìdí nìyí tí wọ́n fi ń pe ibẹ̀ ní àfonífojì ìbùkún títí di òní.
27 Ensuite tout homme de Juda, et tous les habitants de Jérusalem, et Josaphat à leur tête, retournèrent à Jérusalem dans une grande allégresse, parce que le Seigneur leur avait donné de la joie au sujet de leurs ennemis.
Nígbà náà wọ́n darí pẹ̀lú Jehoṣafati, gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu padà pẹ̀lú ayọ̀ sí Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti fún wọn ní ìdí láti yọ̀ lórí àwọn ọ̀tá wọn.
28 Ils entrèrent donc à Jérusalem dans la maison du Seigneur avec des psaltérions, des harpes et des trompettes.
Wọ́n sì wọ Jerusalẹmu, wọ́n sì lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn àti dùùrù àti ìpè.
29 Mais la terreur du Seigneur fondit sur tous les royaumes des pays voisins, lorsqu’ils eurent appris que le Seigneur avait combattu contre les ennemis d’Israël.
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run wá si orí gbogbo ìjọba ilẹ̀ náà nígbà tí wọ́n gbọ́ bí Olúwa ti bá àwọn ọ̀tá Israẹli jà.
30 Et le royaume de Josaphat se reposa, et Dieu lui donna la paix alentour.
Bẹ́ẹ̀ ni ìjọba Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ ti fún un ni ìsinmi ní gbogbo àyíká.
31 Josaphat régna donc sur Juda; et il avait trente-cinq ans, lorsqu’il commença à régner: or il régna vingt-cinq ans à Jérusalem; et le nom de sa mère était Azuba, fille de Sélahi.
Báyìí ni Jehoṣafati jẹ ọba lórí Juda. Ó sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì. Nígbà tí ó di ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
32 Et il marcha dans les voies de son père Asa, et il ne s’en détourna point, faisant ce qui était agréable devant le Seigneur.
Ó sì rin ọ̀nà baba rẹ̀ Asa kò sì yà kúrò nínú rẹ̀, ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa.
33 Cependant il ne détruisit pas les hauts lieux, et le peuple n’avait pas encore dirigé son cœur vers le Seigneur Dieu de ses pères.
Ní ibi gíga, pẹ̀lúpẹ̀lú, kò mu wọn kúrò, gbogbo àwọn ènìyàn náà kò sì fi ọkàn wọn fún Ọlọ́run àwọn baba wọn.
34 Or le reste des actions de Josaphat, des premières et des dernières, est écrit dans l’histoire que Jéhu, fils d’Hanani, a insérée dans les Livres des rois d’Israël.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoṣafati, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sí inú ìwé ìtàn ti Jehu ọmọ Hanani, tí a kọ sí inú ìwé àwọn ọba Israẹli.
35 Après cela, Josaphat, roi de Juda, contracta amitié avec Ochozias, roi d’Israël, dont les œuvres furent très impies.
Nígbà tí ó yá, Jehoṣafati ọba Juda da ara rẹ̀ pọ̀ pẹ̀lú Ahasiah, ọba Israẹli, ẹni tí ó jẹ̀bi ìwà búburú.
36 Et il contribua à ce qu’ils fissent des vaisseaux, qui iraient à Tharsis; ils firent donc une flotte à Asiongaber.
Ó sì gbà pẹ̀lú rẹ̀ láti kan ọkọ̀ láti lọ sí Tarṣiṣi, lẹ́yìn èyí wọ́n kan ọkọ̀ ní Esioni-Geberi.
37 Mais Eliézer, fils de Dodaü de Marésa, prophétisa à Josaphat, disant: Parce que vous avez fait alliance avec Ochozias, le Seigneur Dieu a frappé vos œuvres, et vos vaisseaux ont été brisés, et ils n’ont pu aller à Tharsis.
Elieseri ọmọ Dodafahu ti Meraṣa sọtẹ́lẹ̀ sí Jehoṣafati, wí pe, “Nítorí tí ìwọ ti da ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, Olúwa yóò pa ohun ti ìwọ ti ṣe run.” Àwọn ọkọ̀ náà sì fọ́, wọn kò sì le lọ sí ibi ìtajà.

< 2 Chroniques 20 >