< 2 Chroniques 18 >

1 Josaphat fut donc riche, très illustre, et allié avec Achab.
Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
2 Et il descendit après quelques années vers lui à Samarie; et à son arrivée Achab tua un grand nombre de béliers et de bœufs, à cause de lui et de tout le peuple qui était venu avec lui, et il lui persuada de monter à Ramoth-Galaad.
Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
3 Achab, roi d’Israël, dit donc à Josaphat, roi de Juda: Venez avec moi à Ramoth-Galaad. Celui-ci lui répondit: Comme je suis, vous êtes vous-même: comme est votre peuple, ainsi est mon peuple; et nous serons avec vous dans cette guerre.
Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
4 Et Josaphat dit au roi d’Israël: Consultez, je vous en conjure, dès à présent, la parole du Seigneur.
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
5 Le roi d’Israël assembla donc quatre cents hommes, prophètes, et il leur dit: Devons-nous aller à Ramoth-Galaad pour combattre, ou nous tenir en repos? Mais ceux-ci: Montez, dirent-ils, et le Seigneur la livrera en la main du roi.
Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
6 Et Josaphat demanda: N’y a-t-il point ici un prophète du Seigneur, afin que nous le consultions aussi?
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
7 Et le roi d’Israël répondit à Josaphat: Il y a un homme par qui nous pouvons consulter la volonté du Seigneur; mais moi, je le hais, parce qu’il ne me prophétise point du bien, mais du mal en tout temps: or c’est Michée, fils de Jemla. Et Josaphat dit: Ô roi, ne parlez pas ainsi.
Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
8 Le roi d’Israël appela donc un des eunuques, et lui dit: Appelle à l’instant Michée, fils de Jemla.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
9 Or le roi d’Israël et Josaphat, roi de Juda, étaient assis chacun sur leur trône, vêtus avec une magnificence royale; et ils étaient assis dans une aire, près de la porte de Samarie, et tous les prophètes prophétisaient devant eux.
Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
10 Alors Sédécias, fils de Chanaana, se fit des cornes de fer, et dit: Voici ce que dit le Seigneur: Tu agiteras avec ces cornes la Syrie, jusqu’à ce que tu l’aies détruite.
Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
11 Et tous les prophètes prophétisaient de même, et disaient: Montez à Ramoth-Galaad, et vous prospérerez, et le Seigneur les livrera à la main du roi.
Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
12 Or le messager qui était allé pour appeler Michée lui dit: Voilà que les paroles des prophètes annoncent unanimement de bonnes choses au roi; je vous prie donc que votre parole ne diffère point des leurs, et dites des choses favorables.
Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
13 Michée lui répondit: Le Seigneur vit! tout ce que m’aura dit mon Dieu, c’est ce que je dirai.
Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
14 Il vint donc vers le roi, et le roi lui dit: Michée, devons-nous aller à Ramoth-Galaad pour combattre, ou nous tenir en repos? Michée lui répondit: Montez, car toutes choses seront prospères, et les ennemis seront livrés en vos mains.
Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
15 Et le roi reprit: Je t’adjure de nouveau et encore de nouveau de ne me dire que ce qui est vrai, au nom du Seigneur.
Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
16 Alors Michée dit: J’ai vu tout Israël dispersé dans les montagnes, comme les brebis sans pasteur; et le Seigneur a dit: Ceux-ci n’ont point de maîtres; que chacun retourne dans sa maison en paix.
Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
17 Et le roi d’Israël dit à Josaphat: Ne vous ai-je pas dit que cet homme ne me prophétise rien de bien, mais des choses qui sont mauvaises?
Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
18 Mais Michée: C’est pourquoi, dit-il, écoutez la parole du Seigneur: J’ai vu le Seigneur assis sur son trône, et toute l’armée du ciel se tenant près de lui, à droite et à gauche.
Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
19 Et le Seigneur a dit: Qui trompera Achab, roi d’Israël, afin qu’il monte et qu’il succombe à Ramoth-Galaad? Comme l’un disait d’une manière, et l’autre d’une autre,
Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
20 L’esprit malin s’avança, et s’arrêta devant le Seigneur, et lui dit: C’est moi qui le tromperai. Et le Seigneur: En quoi, lui dit-il, le tromperas-tu?
Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
21 Et celui-ci répondit: Je sortirai, et je serai un esprit menteur dans la bouche de tous ses prophètes. Et le Seigneur dit: Tu le tromperas, et tu prévaudras; sors, et fais ainsi.
“‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
22 Maintenant donc voilà que le Seigneur a mis un esprit de mensonge dans la bouche de tous vos prophètes, et le Seigneur a prononcé contre vous des malheurs.
“Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
23 Or Sédécias, fils de Chanaana, s’approcha, frappa la joue de Michée et dit: Par quelle voie, l’Esprit du Seigneur a-t-il passé de moi en toi pour te parler?
Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
24 Et Michée répondit: Vous le verrez vous-même, le jour que vous entrerez dans une chambre au sortir d’une chambre pour vous cacher.
Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
25 Alors le roi d’Israël ordonna, disant: Prenez Michée, et conduisez-le à Amon, prince de la ville, et à Joas, fils d’Amélech.
Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
26 Et vous leur direz: Voici ce que dit le roi: Envoyez cet homme dans la prison, et donnez-lui un peu de pain et un peu d’eau, jusqu’à ce que je revienne en paix.
Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
27 Et Michée dit: Si vous revenez en paix, le Seigneur n’a point parlé par moi. Et il ajouta: Peuples, écoutez tous.
Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
28 Ainsi le roi d’Israël et Josaphat, roi de Juda, montèrent à Ramoth-Galaad.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
29 Et le roi d’Israël dit à Josaphat: Je changerai d’habit, et c’est ainsi que j’irai au combat; mais, vous, revêtez-vous de vos vêtements. Ainsi, son habit changé, le roi d’Israël vint au combat.
Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
30 Or le roi de Syrie ordonna aux chefs de sa cavalerie, disant: Ne combattez point contre le plus petit ou contre le plus grand, mais seulement contre le roi d’Israël.
Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
31 C’est pourquoi, lorsque les chefs de la cavalerie virent Josaphat, ils dirent: C’est le roi d’Israël. Et ils l’environnèrent en combattant; mais lui cria vers le Seigneur, et le Seigneur le secourut, et les écarta de lui;
Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
32 Car, comme les chefs de la cavalerie virent que ce n’était point le roi d’Israël, ils le laissèrent.
Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
33 Or il arriva qu’un homme du peuple lança une flèche au hasard, et qu’il frappa le roi d’Israël entre le cou et les épaules; mais Achab dit au conducteur de son char: Tourne ta main, et tire-moi de la bataille, parce que je suis blessé.
Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
34 Et la guerre fut terminée en ce jour-là. Or le roi d’Israël se tint sur son char en face des Syriens, jusqu’au soir, et il mourut au soleil couchant.
Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.

< 2 Chroniques 18 >