< 2 Chroniques 13 >

1 En la dix-huitième année du règne de Jéroboam, Abia régna sur Juda.
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu, Abijah di ọba Juda.
2 Il régna trois ans à Jérusalem, et le nom de sa mère était Michaïa, fille d’Uriel de Gabaa; et il y eut guerre entre Abia et Jéroboam.
Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Mikaiah, ọmọbìnrin Urieli ti Gibeah. Ogun wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
3 Et comme Abia préparait le combat, et qu’il avait des hommes très vaillants, et quatre cent mille guerriers choisis. Jéroboam rangea vis-à-vis en bataille une armée de huit cent mille hommes, qui eux aussi étaient très forts aux combats.
Abijah lọ sí ojú ogun pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun ogún ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára, Jeroboamu kó ogun jọ pẹ̀lú ogójì ọ̀kẹ́ ọ̀wọ́ ogun tí ó lágbára.
4 Abia s’arrêta donc sur la montagne de Séméron, qui était en Ephraïm, et il dit: Ecoutez, Jéroboam, et tout Israël.
Abijah dúró lórí òkè Semaraimu ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, ó sì wí pé, Jeroboamu àti gbogbo Israẹli, ẹ gbọ́ mi!
5 Est-ce que vous ignorez que le Seigneur Dieu d’Israël a donné à David un royaume sur Israël pour toujours, à lui et à ses fils, par un pacte de sel?
Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti fún Dafidi àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ ni oyè ọba títí láé nípasẹ̀ májẹ̀mú iyọ̀?
6 Et Jéroboam, fils de Nabath, serviteur de Salomon, fils de David, s’est levé et s’est révolté contre son seigneur;
Síbẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, oníṣẹ́ Solomoni ọmọ Dafidi, ṣọ̀tẹ̀ sí ọ̀gá rẹ̀.
7 Et se sont réunis à lui des hommes de néant, fils de Bélial, et ils ont prévalu contre Roboam, fils de Salomon: or Roboam était sans expérience, d’un cœur craintif, et il ne put leur résister.
Àwọn ènìyàn lásán sì kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àwọn ọmọ ẹni búburú, wọ́n sì kẹ̀yìn sí Rehoboamu ọmọ Solomoni ní ìgbà tí ó sì kéré tí kò lè pinnu fúnra rẹ̀, tí kò lágbára tó láti takò wọ́n.
8 Maintenant donc, vous dites que vous pourrez résister au royaume du Seigneur, qu’il possède par les fils de David, et que vous avez une grande multitude de peuple et des veaux d’or que Jéroboam vous a faits pour vos dieux.
“Nísinsin yìí, ìwọ ṣètò láti kọ́ ìjọba Olúwa, tí ó wà lọ́wọ́ àwọn àtẹ̀lé Dafidi. Ìwọ jẹ́ ọmọ-ogun tí ó gbilẹ̀, ìwọ sì ní pẹ̀lú rẹ ẹgbọrọ màlúù wúrà ti Jeroboamu dà láti fi ṣe Ọlọ́run yín.
9 Et vous avez chassé les prêtres du Seigneur, fils d’Aaron, et les Lévites; et vous vous êtes fait à vous-mêmes des prêtres comme tous les peuples de la terre: quiconque vient, et consacre sa main avec un taureau d’entre les bœufs, et avec sept béliers, est fait prêtre de ceux qui ne sont point dieux.
Ṣùgbọ́n ṣé ìwọ kò lé àwọn àlùfáà Olúwa jáde, àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ará Lefi. Tí ó sì ṣe àwọn àlùfáà ti ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn ti ṣe? Ẹnikẹ́ni tí ó bá wá láti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò méjì lè jẹ́ àlùfáà ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run.
10 Mais notre Seigneur est Dieu, et nous ne l’abandonnons pas: des prêtres d’entre les fils d’Aaron servent le Seigneur, et les Lévites sont à leur place.
“Ní ti àwa, Olúwa ni Ọlọ́run wa, àwa kò sì ti ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Àwọn àlùfáà tí ó ń sin Olúwa jẹ́ àwọn ọmọ Aaroni àwọn ará Lefi sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́.
11 On offre aussi des holocaustes au Seigneur chaque jour, le soir et le matin, ainsi qu’un parfum composé selon les préceptes de la loi, et l’on expose des pains sur la table très pure; nous avons le chandelier d’or et ses lampes, pour qu’elles soient toujours allumées le soir: car nous, nous gardons fidèlement les préceptes du Seigneur notre Dieu, que vous, vous avez abandonné.
Ní àràárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́, wọ́n gbé ẹbọ sísun àti tùràrí olóòórùn dídùn síwájú Olúwa. Wọ́n gbé àkàrà jáde sórí tábìlì àsè mímọ́, wọ́n sì tan iná sí àwọn fìtílà lórí ìdúró ọ̀pá fìtílà wúrà ní gbogbo ìrọ̀lẹ́. A ń pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa mọ́. Ṣùgbọ́n ìwọ ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
12 Ainsi dans notre armée, le chef, c’est Dieu, et ses prêtres qui sonnent des trompettes, et les font retentir contre vous. Enfants d’Israël, ne combattez point contre le Seigneur Dieu de vos pères; car cela ne vous est point avantageux.
Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa; òun ni olórí wa. Àwọn àlùfáà rẹ̀ pẹ̀lú fèrè wọn yóò fọn ìpè ogun sí i yín. Ẹyin ọkùnrin Israẹli, ẹ má ṣe dojú ìjà kọ Olúwa Ọlọ́run baba yín nítorí ẹ̀yin kì yóò yege.”
13 Pendant qu’il disait ces choses. Jéroboam lui tendait par derrière des embûches; et, comme il se tenait en face des ennemis, il entourait de son armée Juda qui l’ignorait.
Nísinsin yìí, Jeroboamu ti rán àwọn ọ̀wọ́ ogun lọ yíká láti jagun ẹ̀yìn. Kí ó lè jẹ́ pé, tí òun bá wà níwájú Juda, bíba ní bùba á wà ní ẹ̀yìn wọn.
14 Mais Juda, ayant tourné la tête, vit que la guerre le menaçait par devant et par derrière; et il cria vers le Seigneur, et les prêtres commencèrent à sonner des trompettes.
Nígbà tí Juda sì bojú wo ẹ̀yìn, sì kíyèsi i, ogun ń bẹ níwájú àti lẹ́yìn, wọn sì ké pe Olúwa, àwọn àlùfáà sì fun ìpè.
15 Alors tous les hommes de Juda poussèrent de grands cris; or voici que, comme ils criaient, Dieu épouvanta Jéroboam et tout Israël, qui se trouvait en face d’Abia et de Juda.
Olúkúlùkù, ọkùnrin Juda sì fún ìpè ogun, ó sì ṣe, bí àwọn ọkùnrin Juda sì ti fun ìpè ogun, ni Ọlọ́run kọlu Jeroboamu àti gbogbo Israẹli níwájú Abijah àti Juda.
16 Ainsi les enfants d’Israël s’enfuirent devant Juda, et Dieu les livra en sa main.
Àwọn ọmọ Israẹli sálọ kúrò níwájú Juda, Ọlọ́run sì fi wọ́n lé wọn lọ́wọ́.
17 Abia les frappa, donc ainsi que son peuple, d’une grande plaie, et il tomba, blessés, du côté d’Israël, cinq cent mille des hommes forts.
Abijah àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ìdààmú ńlá jẹ wọ́n ní ìyà, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ọkùnrin tí a yàn ṣubú ní pípa nínú Israẹli.
18 Et les enfants d’Israël furent humiliés en ce temps-là, et les enfants de Juda reprirent entièrement courage, parce qu’ils avaient espéré dans le Seigneur Dieu de leurs pères.
Báyìí ni a rẹ àwọn ọmọ Israẹli sílẹ̀ ní àkókò náà, àwọn ọmọ Juda sì borí nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn.
19 Or Abia poursuivit Jéroboam fuyant, et il prit de ses villes: Béthel et ses filles, Jésana avec ses filles, Ephron aussi et ses filles.
Abijah sì lépa Jeroboamu, ó sì gba ìlú lọ́wọ́ rẹ̀, Beteli pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Jeṣana pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀, àti Efroni pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀.
20 Et Jéroboam ne fut plus assez fort pour résister dans les jours d’Abia; Dieu le frappa, et il mourut.
Bẹ́ẹ̀ ní Jeroboamu kò sì tún ní agbára mọ́ ní ọjọ́ Abijah. Olúwa sì lù ú ó sì kú.
21 Ainsi Abia, son empire affermi, prit quatorze femmes, et procréa vingt-deux fils et seize filles.
Abijah sì di alágbára, ó sì gbé obìnrin mẹ́tàlá ní ìyàwó, ó sì bi ọmọkùnrin méjìlélógún, àti ọmọbìnrin mẹ́rìndínlógún.
22 Le reste des actions, des voies et des œuvres d’Abia est écrit très exactement dans le livre d’Addo, le prophète.
Àti ìyókù ìṣe Abijah, àti ìwà rẹ̀, àti iṣẹ́ rẹ̀, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtumọ̀, wòlíì Iddo.

< 2 Chroniques 13 >