< 2 Chroniques 12 >
1 Et lorsque le royaume de Roboam fut fortifié et affermi, il abandonna la loi du Seigneur, lui et tout Israël avec lui.
Lẹ́yìn ìgbà tí a fi ìjọba Rehoboamu múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba, tí ó sì ti di alágbára, òun àti gbogbo Israẹli, pẹ̀lú rẹ̀ ni wọ́n pa òfin Olúwa tì.
2 Mais à la cinquième année du règne de Roboam, Sésac, roi d’Égypte, monta à Jérusalem (parce que les Israélites avaient péché contre le Seigneur)
Nítorí tí wọn kò ṣọ òtítọ́ sí Olúwa. Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu ní ọdún karùn-ún ti ọba Rehoboamu.
3 Avec mille et deux cents chariots et soixante mille cavaliers; et le bas peuple qui était venu d’Égypte avec lui était sans nombre; il se composait de Libyens, de Troglodytes et d’Ethiopiens.
Pẹ̀lú ẹgbàá mẹ́fà kẹ̀kẹ́ àti ọ̀kẹ́ mẹ́ta àwọn ọkùnrin ẹlẹ́ṣin àti àìníye ọ̀wọ́ ogun ti Libia, Sukki àti Kuṣi, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ láti Ejibiti.
4 Et il prit les villes les plus fortifiées dans Juda, et il vint jusqu’à Jérusalem.
Ó fi agbára mú àwọn ìlú ààbò ti Juda, pẹ̀lú wá sí Jerusalẹmu bí ó ti jìnnà tó.
5 Or Séméias, le prophète, vint trouver le roi Roboam et les princes de Juda, qui s’étaient réunis à Jérusalem, fuyant Sésac, et il leur dit: Voici ce que dit le Seigneur: Vous, vous m’avez abandonné, et moi, je vous ai abandonnés à la main de Sésac.
Nígbà náà, wòlíì Ṣemaiah wá sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí Juda tí wọ́n ti péjọ ní Jerusalẹmu nítorí ìbẹ̀rù Ṣiṣaki, ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ìwọ ti pa mí tì; nítorí náà èmi náà ti pa yín tì sí ọ̀dọ̀ Ṣiṣaki.”
6 Alors, consternés, les princes d’Israël et le roi dirent: Il est juste, le Seigneur.
Àwọn olórí Israẹli àti ọba rẹ̀ ará wọn sílẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Olódodo ni Olúwa.”
7 Et lorsque le Seigneur vit qu’ils étaient humiliés, la parole du Seigneur fut adressée à Séméias, disant: Puisqu’ils se sont humiliés, je ne les exterminerai point, je leur donnerai un peu de secours, et ma fureur ne s’épanchera pas sur Jérusalem par la main de Sésac;
Nígbà tí Olúwa rí i pé, wọ́n ti rẹ̀ ara wọn sílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa yí tọ Ṣemaiah lọ pé, “Níwọ́n ìgbà tí wọ́n ti rẹ ara wọn sílẹ̀, Èmi kì yóò pa wọ́n ṣùgbọ́n, yóò fún wọn ní ìtúsílẹ̀ tó bá yá. Ìbínú mi kì yóò dà sórí Jerusalẹmu ní ipasẹ̀ Ṣiṣaki.
8 Cependant ils le serviront, afin qu’ils sachent la différence de mon service et du service du royaume des nations.
Bí ó ti wù kí ó rí, wọn yóò sìn ní abẹ́ rẹ̀, kí wọn kí ó lè mọ̀ ìyàtọ̀ láàrín sí sìn mí àti sí sin àwọn ọba ilẹ̀ mìíràn.”
9 C’est pourquoi Sésac, roi d’Égypte, se retira de Jérusalem après avoir enlevé les trésors de la maison du Seigneur et de la maison du roi, et il emporta tout avec lui, même les boucliers d’or qu’avait faits Salomon,
Nígbà tí Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu, ó gbé àwọn ìṣúra ilé Olúwa, àti àwọn ìṣúra ààfin ọba. Ó gbé gbogbo rẹ̀, pẹ̀lú àwọn àpáta wúrà tí Solomoni dá.
10 À la place desquels le roi en fit d’airain, et les remit aux chefs des scutaires qui gardaient le vestibule du palais.
Bẹ́ẹ̀ ni, ọba Rehoboamu dá àwọn àpáta idẹ láti fi dípò wọn, ó sì fi èyí lé àwọn alákòóso àti olùṣọ́ tí ó wà ní ẹnu iṣẹ́ ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà ààfin ọba lọ́wọ́.
11 Et lorsque le roi entrait dans la maison du Seigneur, les scutaires venaient et les prenaient, puis ils les reportaient de nouveau dans leur arsenal.
Ìgbàkígbà tí ọba bá lọ sí ilé Olúwa, àwọn olùṣọ́ n lọ pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n ń gbé àwọn àpáta náà àti lẹ́yìn, wọ́n dá wọn padà sí yàrá ìṣọ́.
12 Ainsi donc, parce qu’ils s’étaient humiliés, la colère du Seigneur fut détournée d’eux, et ils ne furent pas entièrement détruits, attendu qu’il se trouva encore dans Juda de bonnes œuvres.
Nítorí ti Rehoboamu rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ìbínú Olúwa yí padà kúrò lórí rẹ̀, a kò sì pa á run pátápátá. Nítòótọ́, ìre díẹ̀ wà ní Juda.
13 Le roi Roboam se fortifia donc dans Jérusalem, et y régna; or il avait quarante et un ans quand il commença à régner, et il régna dix-sept ans à Jérusalem, ville que le Seigneur avait choisie d’entre toutes les tribus d’Israël pour y établir son nom: or le nom de sa mère était Naama, l’Ammanite.
Ọba Rehoboamu fi ara rẹ̀ lélẹ̀ gidigidi ní Jerusalẹmu, ó sì tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọba. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógójì nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba fún ọdún mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí Olúwa ti yàn jáde kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli ní èyí tí ó fẹ́ fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Naama, ará Ammoni.
14 Mais il fit le mal, et ne prépara point son cœur pour chercher le Seigneur.
O sì ṣe búburú, nítorí tí kò múra nínú ọkàn rẹ̀ láti wá Olúwa.
15 Or les actions de Roboam, les premières et les dernières, sont écrites dans les livres de Séméias, le prophète, et d’Addo, le Voyant, et rapportées exactement: et Roboam et Jéroboam se firent la guerre durant tous leurs jours.
Fún tí iṣẹ́ ìjọba Rehoboamu láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Ṣemaiah wòlíì àti ti Iddo, aríran tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá? Ìtẹ̀síwájú ogun jíjà sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu.
16 Et Roboam dormit avec ses pères, et il fut enseveli dans la cité de David; et Abia, son fils, régna en sa place.
Rehoboamu sun pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi. Abijah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.