< 1 Samuel 29 >
1 Toutes les troupes des Philistins s’assemblèrent donc à Aphec; mais Israël aussi campa près de la fontaine de Jezraël.
Àwọn Filistini sì kó gbogbo ogun wọn jọ sí Afeki: Israẹli sì dó ni ibi ìsun omi tí ó wà ní Jesreeli.
2 Or, les satrapes des Philistins marchaient avec des compagnies de cent et de mille hommes; mais David et ses hommes étaient à l’arrière-garde avec Achis.
Àwọn ìjòyè Filistini sì kọjá ní ọ̀rọ̀ọ̀rún àti lẹgbẹẹgbẹ̀rún; Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pẹ̀lú Akiṣi sì kẹ́yìn.
3 Les princes des Philistins dirent à Achis: Que veulent dire ces Hébreux? Et Achis répondit aux princes des Philistins: Est-ce que vous ne connaissez pas David, qui a été serviteur de Saül, roi d’Israël, qui est avec moi depuis nombre de jours et même d’années, et dans lequel je n’ai rien trouvé, depuis le jour qu’il s’est réfugié auprès de moi jusqu’à ce jour-ci?
Àwọn ìjòyè Filistini sì béèrè wí pé, “Kín ni àwọn Heberu ń ṣe níhìn-ín yìí?” Akiṣi sì wí fún àwọn ìjòyè Filistini pé “Dafidi kọ yìí, ìránṣẹ́ Saulu ọba Israẹli, tí ó wà lọ́dọ̀ mi láti ọjọ́ wọ̀nyí tàbí láti ọdún wọ̀nyí, èmi kò ì tì í rí àṣìṣe kan ni ọwọ́ rẹ̀ láti ọjọ́ tí ó ti dé ọ̀dọ̀ mi títí di òní yìí.”
4 Mais les princes des Philistins s’irritèrent contre lui, et lui dirent: Que cet homme s’en retourne; qu’il demeure dans son lieu, dans lequel vous l’avez établi, et qu’il ne descende pas avec nous au combat, afin qu’il ne devienne point notre ennemi, lorsque nous aurons commencé à combattre; car comment pourra-t-il apaiser son seigneur autrement qu’avec nos têtes?
Àwọn ìjòyè Filistini sì bínú sí i; àwọn ìjòyè Filistini sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí ọkùnrin yìí padà kí ó sì lọ sí ipò rẹ̀ tí ó fi fún un, kí ó má sì jẹ́ kí ó bá wa sọ̀kalẹ̀ lọ sí ogun, kí ó má ba à jásí ọ̀tá fún wa ni ogun, kín ni òun ó fi ba olúwa rẹ̀ làjà, orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọ́?
5 N’est-ce pas ce David, en l’honneur duquel on chantait dans les chœurs: Saül a frappé sur ses mille, et David sur ses dix mille?
Ṣé èyí ni Dafidi tiwọn torí rẹ̀ gberin ara wọn nínú ijó wí pé, “‘Saulu pa ẹgbẹ̀rún rẹ̀, Dafidi si pa ẹgbẹgbàarùn-ún tirẹ̀.’”
6 Achis donc appela David, et lui dit: Le Seigneur vit! tu es droit et bon en ma présence, et ta sortie et ton entrée est avec moi dans le camp; et je n’ai trouvé en toi rien de mal, depuis le jour que tu es venu vers moi jusqu’à ce jour-ci; mais tu ne plais pas aux satrapes.
Akiṣi sì pe Dafidi, ó sì wí fún un pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ìwọ jẹ́ olóòótọ́ àti ẹni ìwà rere lójú mi, ní àlọ rẹ àti ààbọ̀ rẹ pẹ̀lú mi ní ogun: nítorí pé èmi ko tí ì ri búburú kan lọ́wọ́ rẹ́ láti ọjọ́ ti ìwọ ti tọ̀ mí wá, títí o fi dì òní yìí ṣùgbọ́n lójú àwọn ìjòyè, ìwọ kò ṣe ẹni tí ó tọ́.
7 Retourne-t’en donc, et va en paix, et n’offense pas les yeux des satrapes des Philistins.
Ǹjẹ́ yípadà kí o sì máa lọ ní àlàáfíà, kí ìwọ má ṣe bà àwọn Filistini nínú jẹ́.”
8 Et David demanda à Achis: Qu’ai-je donc fait, et qu’avez-vous trouvé en moi, votre serviteur, depuis le jour que j’ai été en votre présence jusqu’à ce jour-ci, pour que je ne vienne point, et que je ne combatte point contre les ennemis de mon seigneur roi?
Dafidi sì wí fún Akiṣi pé, “Kín ni èmi ṣe? Kín ni ìwọ sì rí lọ́wọ́ ìránṣẹ́ rẹ láti ọjọ́ ti èmi ti ń gbé níwájú rẹ títí di òní yìí, tí èmi kì yóò fi lọ bá àwọn ọ̀tá ọba jà.”
9 Mais répondant, Achis dit à David: Je sais que tu es bon à mes yeux comme un ange de Dieu; mais les princes des Philistins ont dit: Il ne montera point avec nous au combat.
Akiṣi sì dáhùn, ó sì wí fún Dafidi pé, “Èmi mọ̀ pé ìwọ ṣe ẹni rere lójú mi, bi angẹli Ọlọ́run; ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Filistini wí pé, ‘Òun kì yóò bá wa lọ sí ogun.’
10 Ainsi lève-toi, dès le matin, toi et les serviteurs de ton seigneur qui sont venus avec toi; et lorsque vous vous serez levés pendant la nuit, et qu’il aura commencé à faire jour, partez.
Ǹjẹ́, nísinsin yìí dìde ní òwúrọ̀ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ tí ó bá ọ wá, ki ẹ si dìde ní òwúrọ̀ nígbà tí ilẹ̀ bá mọ́ kí ẹ sì máa lọ.”
11 C’est pourquoi David se leva pendant la nuit, lui et ses hommes, pour partir dès le matin, et retourner dans la terre des Philistins; mais les Philistins montèrent à Jezraël.
Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì dìde ní òwúrọ̀ láti padà lọ sí ilẹ̀ àwọn Filistini. Àwọn Filistini sì gòkè lọ sí Jesreeli.