< 1 Samuel 26 >

1 Cependant les Ziphéens vinrent vers Saül à Gabaa, disant: Voici que David est caché sur la colline d’Hachila, qui est vis-à-vis du désert.
Nígbà náà ni àwọn ará Sifi tọ Saulu wá sí Gibeah, wọn wí pé, “Dafidi kò ha fi ara rẹ̀ pamọ́ níbi òkè Hakila, èyí tí ó wà níwájú Jeṣimoni?”
2 Et Saül se leva, et descendit au désert de Ziph, et avec lui trois mille hommes de l’élite d’Israël, pour chercher David dans le désert de Ziph.
Saulu sì dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Sifi ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àṣàyàn ènìyàn ni Israẹli sì pẹ̀lú rẹ̀ láti wá Dafidi ni ijù Sifi.
3 Et Saül campa à Gabaa d’Hachila, qui était vis-à-vis de la solitude, sur le chemin; mais David habitait dans le désert. Or, voyant que Saül était venu après lui dans le désert,
Saulu sì pàgọ́ rẹ̀ ní ibi òkè Hakila tí o wà níwájú Jeṣimoni lójú ọ̀nà, Dafidi sì jókòó ni ibi ijù náà, ó sì rí pé Saulu ń tẹ̀lé òun ni ijù náà.
4 Il envoya des espions, et il apprit que Saül y était venu très certainement.
Dafidi sì rán ayọ́lẹ̀wò jáde, ó sì mọ nítòótọ́ pé Saulu ń bọ̀.
5 David se leva donc secrètement, et il vint au lieu où était Saül; et lorsqu’il eut vu le lieu où dormait Saül, ainsi qu’Abner, fils de Ner, prince de sa milice, et Saül dormant dans sa tente, et toute la multitude autour de lui,
Dafidi sì dìde, ó sì wá sí ibi ti Saulu pàgọ́ sí: Dafidi rí ibi tí Saulu gbé dùbúlẹ̀ sí, àti Abneri ọmọ Neri, olórí ogun rẹ̀: Saulu sì dùbúlẹ̀ láàrín àwọn kẹ̀kẹ́, àwọn ènìyàn náà sì pàgọ́ wọn yí i ká.
6 David parla à Achimélech l’Héthéen, et à Abisaï, fils de Sarvia, frère de Joab, disant: Qui descendra avec moi vers Saül, dans le camp? Et Abisaï dit: Moi, je descendrai avec toi.
Dafidi sì dáhùn, ó sì wí fún Ahimeleki, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Hiti, àti fún Abiṣai ọmọ Seruiah ẹ̀gbọ́n Joabu, pé, “Ta ni yóò ba mi sọ̀kalẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Saulu ni ibùdó?” Abiṣai sì wí pé, “Èmi yóò ba ọ sọ̀kalẹ̀ lọ.”
7 David donc et Abisaï vinrent vers le peuple pendant la nuit, et ils trouvèrent Saül couché et dormant dans sa tente, sa lance fichée dans la terre, près de sa tête, et même Abner et le peuple dormant autour de lui,
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti Abiṣai sì tọ àwọn ènìyàn náà wá lóru: sì wò ó, Saulu dùbúlẹ̀ ó sì ń sùn láàrín kẹ̀kẹ́, a sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ gúnlẹ̀ ni ibi tìmùtìmù rẹ̀: Abneri àti àwọn ènìyàn náà sì dùbúlẹ̀ yí i ká.
8 Et Abisaï dit à David: Le Seigneur a enfermé ton ennemi aujourd’hui dans tes mains; maintenant donc je le percerai de la lance contre la terre une fois, et il n’y aura pas besoin d’un second coup.
Abiṣai sì wí fún Dafidi pé, “Ọlọ́run ti fi ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́ lónìí: ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, sá à jẹ́ kí èmi o fi ọ̀kọ̀ gún un mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan, èmi kì yóò gun un lẹ́ẹ̀méjì.”
9 Et David répondit à Abisaï: Ne le tue pas; car qui étendra sa main sur le christ du Seigneur, et sera innocent?
Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Má ṣe pa á nítorí pé ta ni lè na ọwọ́ rẹ̀ sí ẹni àmì òróró Olúwa kí ó sì wà láìjẹ̀bi?”
10 Et David ajouta: Le Seigneur vit! à moins que le Seigneur ne le frappe, ou que son jour ne soit venu de mourir, ou que, descendant au combat, il ne périsse;
Dafidi sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ Olúwa yóò pa á, tàbí ọjọ́ rẹ̀ yóò sì pé tí yóò kú, tàbí òun ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibi ìjà yóò sì ṣègbé níbẹ̀.
11 Que le Seigneur me soit propice, afin que je n’étende pas ma main sur le christ du Seigneur; maintenant donc, prends la lance, qui est près de sa tête, et sa coupe, et allons-nous-en.
Olúwa má jẹ́ kí èmi na ọwọ́ mi sí ẹni àmì òróró Olúwa. Ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, mú ọ̀kọ̀ náà tí ń bẹ níbi tìmùtìmù rẹ̀, àti ìgò omi kí a sì máa lọ.”
12 David prit donc la lance, et la coupe d’eau, qui était auprès de la tête de Saül, et ils s’en allèrent; et il n’y eut personne, qui les vît, qui entendît, et qui s’éveillât; mais tous dormaient, parce qu un profond sommeil du Seigneur s’était emparé d’eux.
Dafidi sì mú ọ̀kọ̀ náà àti ìgò omi náà kúrò níbi tìmùtìmù Saulu: wọ́n sì bá tiwọn lọ, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí i, tàbí tí ó mọ̀: kò sì sí ẹnìkan tí ó jí; gbogbo wọn sì sùn; nítorí pé oorun èjìká láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ti ṣubú lù wọ́n.
13 Et lorsque David eut passé de l’autre côté, et qu’il se fut arrêté au loin sur le sommet de la montagne, et qu’il y avait un grand intervalle entre eux,
Dafidi sì rékọjá sí ìhà kejì, ó sì dúró lórí òkè kan tí ó jìnnà réré; àlàfo kan sì wà láàrín méjì wọn.
14 David cria au peuple et à Abner, fils de Ner, disant: Est-ce que tu ne répondras pas, Abner? Et répondant, Abner dit: Qui es-tu, toi qui cries, et qui troubles le roi?
Dafidi sì kọ sí àwọn ènìyàn náà àti sí Abneri ọmọ Neri wí pé, “Ìwọ kò dáhùn, Abneri?” Nígbà náà ni Abneri sì dáhùn wí pé, “Ìwọ ta ni ń pe ọba?”
15 Et David dit à Abner: Est-ce que tu n’es pas homme? et quel autre est semblable à toi en Israël? Pourquoi donc n’as-tu pas gardé ton seigneur, le roi? car il est entré quelqu’un de la multitude pour tuer le roi ton seigneur.
Dafidi sì wí fún Abneri pé, “Alágbára ọkùnrin kọ́ ni ìwọ bí? Ta ni ó sì dàbí ìwọ ni Israẹli? Ǹjẹ́ èéṣe tí ìwọ kò tọ́jú ọba Olúwa rẹ? Nítorí ẹnìkan nínú àwọn ènìyàn náà ti wọlé wá láti pa ọba olúwa rẹ.
16 Ce n’est pas bien, ce que tu as fait; le Seigneur vit! Vous êtes des fils de mort, vous qui n’avez pas gardé votre seigneur, le christ du Seigneur: maintenant donc, vois où est la lance du roi, et où est la coupe d’eau, qui était près de sa tête?
Nǹkan tí ìwọ ṣe yìí kò dára. Bí Olúwa ti ń bẹ, o tọ́ kí ẹ̀yin ó kú, nítorí pé ẹ̀yin kò pa olúwa yín mọ́, ẹni àmì òróró Olúwa. Ǹjẹ́ sì wo ibi tí ọ̀kọ̀ ọba gbé wà, àti ìgò omi tí ó ti wà níbi tìmùtìmù rẹ̀.”
17 Or, Saül connut la voix de David, et dit: N’est-ce pas ta voix, mon fils David? Et David répondit: Ma voix, mon seigneur roi.
Saulu sì mọ ohùn Dafidi, ó sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí Dafidi ọmọ mi?” Dafidi sì wí pé, “Ohùn mi ni, olúwa mi, ọba.”
18 Et il ajouta: Pour quel motif mon seigneur persécute-t-il son serviteur? Qu’ai-je fait? ou quel mal est-il en ma main?
Òun sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ṣe ń lépa ìránṣẹ́ rẹ̀? Kín ni èmi ṣe? Tàbí ìwà búburú wo ni ó wà lọ́wọ́ mi.
19 Maintenant donc, écoutez, je vous prie, mon seigneur roi, les paroles de votre serviteur: Si le Seigneur vous excite contre moi, qu’il respire l’odeur d’un sacrifice; mais si ce sont les fils des hommes, ils sont maudits en la présence du Seigneur, eux qui m’ont rejeté aujourd’hui, afin que je n’habite point dans l’héritage du Seigneur, disant: Va, sers des dieux étrangers.
Ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, ọba, olúwa mi, gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ. Bí ó bá ṣe Olúwa bá ti rú ọ sókè sí mi, jẹ́ kí òun o gba ẹbọ; ṣùgbọ́n bí o bá sì ṣe pé ọmọ ènìyàn ni, ìfibú ni kí wọn ó jásí níwájú Olúwa; nítorí tí wọn lé mi jáde lónìí kí èmi má ba à ní ìpín nínú ilẹ̀ ìní Olúwa, wí pé, ‘Lọ sin àwọn ọlọ́run mìíràn.’
20 Et maintenant, que mon sang ne soit point versé sur la terre devant le Seigneur, parce que le roi d’Israël est sorti pour chercher une puce, comme on poursuit la perdrix sur les montagnes.
Ǹjẹ́ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ mi ó sàn sílẹ̀ níwájú Olúwa; nítorí ọba Israẹli jáde láti wá ẹ̀mí mi bi ẹni ń dọdẹ àparò lórí òkè ńlá.”
21 Et Saül dit: J’ai péché, reviens, mon fils David; car je ne te ferai plus de mal, parce que mon âme a été précieuse à tes yeux aujourd’hui: car il paraît que j’ai agi en insensé, et que j’ai ignoré beaucoup de choses.
Saulu sì wí pé, “Èmi ti dẹ́ṣẹ̀: yípadà, Dafidi ọmọ mi: nítorí pé èmi kì yóò wa ibi rẹ mọ́, nítorí tí ẹ̀mí mi sì ti ṣe iyebíye lójú rẹ lónìí: wò ó, èmi ti ń hùwà òmùgọ̀, mo sì ti ṣìnà jọjọ.”
22 Et répondant, David dit: Voici la lance du roi; qu’un de serviteurs du roi passe ici, et qu’il la prenne.
Dafidi sì dáhùn, ó sì wí pé, “Wò ó, ọ̀kọ̀ ọba! Kí ó sì jẹ́ kí ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rékọjá wá gbà á.
23 Mais le Seigneur rendra à chacun selon sa justice et sa foi; car le Seigneur vous a livré aujourd’hui à ma main, et je n’ai pas voulu étendre ma main sur le christ du Seigneur.
Kí Olúwa o san án fún olúkúlùkù bí òdodo rẹ̀ àti bí òtítọ́ rẹ̀: nítorí pé Olúwa tí fi ọ lé mi lọ́wọ́ lónìí, ṣùgbọ́n èmi kò fẹ́ nawọ́ mi sí ẹni àmì òróró Olúwa.
24 Et comme votre âme a été aujourd’hui élevée à mes yeux, ainsi soit élevée mon âme aux yeux du Seigneur, et qu’il me délivre de toute angoisse.
Sì wò ó, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀mí rẹ ti tóbi lónìí lójú mi, bẹ́ẹ̀ ni ki ẹ̀mí mi ó tóbi lójú Olúwa, kí ó sì gbà mí lọ́wọ́ ibi gbogbo.”
25 Saül donc dit à David; Bénis sois-tu, mon fils David; et tu achèveras certainement ce que tu feras, et tu pourras beaucoup. Or, David s’en alla en son chemin, et Saül retourna en sa demeure.
Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Alábùkún fún ni ìwọ, Dafidi ọmọ mi: nítòótọ́ ìwọ yóò sì ṣe nǹkan ńlá, nítòótọ́ ìwọ yóò sì borí.” Dafidi sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ, Saulu sì yípadà sí ibùgbé rẹ̀.

< 1 Samuel 26 >