< 1 Rois 8 >
1 Alors s’assemblèrent tous les anciens d’Israël avec les princes des tribus, et les chefs des familles des enfants d’Israël, auprès du roi Salomon dans Jérusalem, pour transporter l’arche de l’alliance du Seigneur de la cité de David, c’est-à-dire, de Sion.
Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
2 Et tout Israël vint ensemble auprès du roi Salomon, dans le mois d’Ethanim, au jour solennel: c’est le septième mois.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
3 Tous les anciens d’Israël vinrent donc, et les prêtres emportèrent l’arche,
Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
4 Et ils emportèrent l’arche du Seigneur, et le tabernacle d’alliance, et tous les vases du sanctuaire qui étaient dans le tabernacle; et les prêtres et les lévites les portaient.
wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
5 Or le roi Salomon, et toute la multitude d’Israël, qui était venue auprès de lui, marchait avec lui devant l’arche, et ils immolaient des brebis et des bœufs, sans prix et sans nombre.
àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
6 Et les prêtres portèrent l’arche de l’alliance du Seigneur en son lieu, dans l’oracle du temple, dans le Saint des saints, sous les ailes des chérubins.
Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
7 Car les chérubins étendaient leurs ailes au-dessus du lieu de l’arche, et ils couvraient l’arche, et les leviers par en haut.
Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
8 Et comme les leviers passaient en dehors, et que leurs extrémités paraissaient hors du sanctuaire devant l’oracle, ils ne paraissaient plus extérieurement, et ils sont demeurés là jusqu’au présent jour.
Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
9 Or, il n’y avait rien autre chose dans l’arche que les deux tables de pierre que Moïse y avait mises à Horeb, quand le Seigneur fit alliance avec les enfants d’Israël, lorsqu’ils sortirent de la terre d’Egypte.
Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
10 Mais il arriva que, quand les prêtres furent sortis du sanctuaire, la nuée remplit la maison du Seigneur;
Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
11 Et les prêtres ne pouvaient pas s’y tenir, ni remplir leur ministère à cause de la nuée; car la gloire du Seigneur avait rempli la maison du Seigneur.
Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
12 Alors Salomon dit: Le Seigneur a dit qu’il habiterait dans la nuée.
Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
13 Ô Dieu, j’ai bâti cette maison pour votre demeure, et pour votre trône très affermi à jamais.
Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
14 Et le roi tourna sa face, et bénit toute l’assemblée d’Israël: car toute l’assemblée d’Israël était présente.
Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
15 Et Salomon dit: Béni le Seigneur Dieu d’Israël! lui qui a parlé de sa bouche à David mon père, et par ses mains a accompli sa parole, disant:
Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
16 Depuis le jour que j’ai retiré de l’Egypte mon peuple Israël, je n’ai point choisi de ville d’entre toutes les tribus d’Israël, afin qu’on me bâtît une maison et que mon nom y fût; mais j’ai choisi David, afin qu’il fût chef de mon peuple Israël.
‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
17 Et David mon père voulut bâtir une maison au nom du Seigneur Dieu d’Israël;
“Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
18 Mais le Seigneur dit à David mon père: Quand tu as pensé en ton cœur à bâtir une maison à mon nom, tu as bien fait, en t’occupant de cela en ton esprit.
Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
19 Cependant ce ne sera pas toi qui me bâtiras une maison; mais ton fils, qui sortira de tes flancs, sera celui qui bâtira une maison à mon nom.
Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
20 Le Seigneur a continué la parole qu’il a dite: j’ai succédé à David mon père, je me suis assis sur le trône d’Israël, comme l’a dit le Seigneur, et j’ai bâti une maison au nom du Seigneur Dieu d’Israël.
“Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
21 Et j’ai établi là le lieu de l’arche, dans laquelle est l’alliance du Seigneur, qu’il fit avec nos pères, quand ils sortirent de la terre d’Egypte.
Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
22 Or Salomon se tint debout devant l’autel du Seigneur, en présence de toute l’assemblée d’Israël, et il étendit ses mains vers le ciel,
Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
23 Et il dit: Seigneur Dieu d’Israël, il n’y a point de Dieu semblable à vous en haut, dans le ciel, et en bas, sur la terre: c’est vous qui conservez l’alliance et la miséricorde à vos serviteurs, qui marchaient devant vous en tout leur cœur;
Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
24 Qui avez gardé à votre serviteur, David mon père, ce que vous lui avez promis: vous l’avez dit de votre bouche et accompli par vos mains, comme ce jour le prouve.
O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
25 Maintenant donc, Seigneur Dieu d’Israël, conservez à votre serviteur David, mon père, ce que vous lui avez promis, disant: On ne t’enlèvera pas devant moi un homme qui doit s’asseoir sur le trône d’Israël, pourvu néanmoins que tes fils gardent leur voie, afin qu’ils marchent devant moi, comme toi tu as marché en ma présence.
“Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
26 Et maintenant, Seigneur Dieu d’Israël, qu’elles soient accomplies, les paroles que vous avez dites à votre serviteur, David mon père.
Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
27 Est-il donc croyable que Dieu habite véritablement sur la terre? Car, si le ciel et les cieux des cieux ne vous peuvent contenir, combien moins cette maison que j’ai bâtie?
“Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
28 Mais portez vos regards sur la prière de votre serviteur, et sur ses supplications. Seigneur mon Dieu: écoutez l’hymne et la prière que votre serviteur fait devant vous aujourd’hui,
Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
29 Afin que vos yeux soient ouverts sur cette maison nuit et jour; sur la maison de laquelle vous avez dit: Mon nom sera là; afin que vous exauciez la prière que vous fait en ce lieu votre serviteur;
Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
30 Afin que vous exauciez la prière de votre serviteur, et de votre peuple Israël, quelque chose qu’ils demandent en ce lieu: et vous exaucerez dans le lieu de votre habitation, dans le ciel, et lorsque vous aurez exaucé vous serez propice.
Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
31 Si un homme pèche contre son prochain, s’il a quelque serment par lequel il s’est lié, et qu’il vienne à cause de ce serment devant votre autel, dans votre maison,
“Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
32 Vous écouterez dans le ciel, et vous agirez et vous jugerez vos serviteurs, condamnant l’impie, ramenant sa voie sur sa tête, justifiant le juste, et lui rendant selon sa justice.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
33 Si votre peuple Israël fuit devant ses ennemis (parce qu’il lui arrivera de pécher contre vous), et que, faisant pénitence et rendant gloire à votre nom, ils viennent, et vous prient et vous implorent dans cette maison,
“Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
34 Exaucez-les dans le ciel, et remettez le péché de votre peuple Israël, et ramenez-les dans la terre que vous avez donnée à leurs pères.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
35 Si le ciel est fermé, s’il ne pleut point à cause de leurs péchés, et que, priant en ce lieu, ils fassent pénitence pour honorer votre nom, et qu’ils se convertissent, et quittent leurs péchés à cause de leur affliction,
“Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
36 Exaucez-les dans le ciel, et remettez les péchés de vos serviteurs et de votre peuple Israël: montrez-leur la voie droite par laquelle ils doivent marcher; et répandez de la pluie sur votre terre que vous avez donnée à votre peuple en possession.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
37 Si une famine se lève sur la terre, ou une peste, ou un air corrompu, ou la rouille, ou la sauterelle ou la nielle, et que votre peuple soit affligé par son ennemi, assiégeant ses portes, par toute sorte de plaies et toute sorte d’infirmités;
“Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
38 Dans tout anathème et toute imprécation qui arrivera à un homme, quel qu’il soit, de votre peuple Israël: si quelqu’un reconnaît la plaie de son cœur, et qu’il étende ses mains dans cette maison,
nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
39 Vous l’exaucerez dans le ciel, dans le lieu de votre habitation; vous lui redeviendrez propice, et vous ferez en sorte d’accorder à chacun selon toutes ses voies, comme vous verrez son cœur (parce que vous seul, vous connaissez le cœur de tous les enfants des hommes),
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
40 Afin qu’ils vous craignent durant tous les jours qu’ils vivront sur la face de la terre que vous avez donnée à nos pères.
Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
41 De plus, lorsque l’étranger lui-même, qui n’est point de votre peuple Israël, viendra d’une terre lointaine, à cause de votre nom (car on entendra parler de votre grand nom, de votre main puissante, et de votre bras
“Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
42 Etendu en tous lieux): lors donc qu’il viendra, et qu’il priera en ce lieu,
nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
43 Vous l’exaucerez dans le ciel, dans votre demeure stable, et vous ferez toutes les choses pour lesquelles l’étranger vous invoquera, afin que tous les peuples de la terre apprennent à craindre votre nom, comme le fait votre peuple Israël, et qu’ils éprouvent que votre nom a été invoqué sur cette maison que j’ai bâtie.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
44 Si votre peuple sort pour la guerre contre ses ennemis, et que, dans la voie, partout où vous les aurez envoyés, ils vous prient, tournés vers la cité que vous avez choisie, et vers la maison que j’ai bâtie à votre nom,
“Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
45 Vous exaucerez aussi dans le ciel leurs prières et leurs supplications, et vous leur ferez justice.
nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
46 Que s’ils pèchent contre vous (car il n’y a point d’homme qui ne pèche), et qu’irrité, vous les livriez aux mains de leurs ennemis, qu’ils soient emmenés captifs dans la terre des ennemis, ou près ou loin;
“Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
47 Qu’ils fassent pénitence en leur cœur dans le lieu de la captivité, et que, convertis, ils vous prient dans leur captivité, disant: Nous avons péché, nous avons agi iniquement, nous nous sommes conduits en impies;
bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
48 Qu’ils reviennent à vous en tout leur cœur et en toute leur âme dans la terre de leurs ennemis, dans laquelle ils ont été emmenés captifs, et qu’ils vous prient, tournés du côté de leur terre que vous avez donnée à leurs pères, de la ville que vous avez choisie, et du temple que j’ai bâti à votre nom,
bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
49 Vous exaucerez dans le ciel, dans le lieu stable de votre trône, leurs prières et leurs supplications; vous leur ferez justice;
nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
50 Vous deviendrez propice à votre peuple qui a péché contre vous, en pardonnant toutes leurs iniquités par lesquelles ils ont prévariqué contre vous, et vous leur ferez miséricorde devant ceux qui les auront emmenés captifs, afin qu’ils aient pitié d’eux.
Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
51 Car c’est votre peuple et votre héritage, que vous avez retirés de l’Egypte, du milieu de la fournaise de fer.
nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
52 Que vos yeux soient ouverts aux supplications de votre serviteur et de votre peuple Israël, afin que vous les exauciez dans toutes les choses pour lesquelles ils vous invoqueront.
“Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
53 Car c’est vous qui les avez séparés de tous les peuples de la terre pour votre héritage, comme vous l’avez dit par Moïse, votre serviteur, lorsque vous avez retiré nos pères de l’Egypte, ô Seigneur Dieu.
Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
54 Or, il arriva que, lorsque Salomon, priant le Seigneur, eut achevé toutes ces prières et ces supplications, il se leva de devant l’autel du Seigneur; car il avait mis les deux genoux en terre, et il avait étendu les mains vers le ciel.
Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
55 Il se tint donc debout, et il bénit toute l’assemblée d’Israël, à haute voix, disant:
Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
56 Béni le Seigneur, qui a donné du repos à son peuple Israël, selon tout ce qu’il a dit! Il n’est pas même tombé une seule parole touchant tous les biens qu’il nous a promis par Moïse son serviteur.
“Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
57 Que le Seigneur notre Dieu soit avec nous, comme il a été avec nos pères, ne nous abandonnant point, et ne nous rejetant point;
Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
58 Mais qu’il incline nos cœurs vers lui, afin que nous marchions dans toutes ses voies, et que nous gardions ses commandements, ses cérémonies, et toutes les ordonnances qu’il a prescrites à nos pères;
Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
59 Et que ces mêmes paroles, par lesquelles j’ai prié devant le Seigneur, approchent du Seigneur notre Dieu, jour et nuit, afin qu’il fasse justice à son serviteur et à son peuple Israël chaque jour;
Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
60 Afin que tous les peuples de la terre sachent que c’est le Seigneur qui est Dieu, et qu’il n’y en a point d’autre, excepté lui.
kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
61 Que notre cœur aussi soit parfait avec le Seigneur notre Dieu, afin que nous marchions dans ses décrets, et que nous gardions toujours ses commandements, comme nous faisons encore aujourd’hui.
Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
62 Ainsi le roi et tout Israël avec lui immolaient des victimes devant le Seigneur.
Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
63 Et Salomon tua les hosties pacifiques qu’il immola au Seigneur, vingt-deux mille bœufs et cent vingt mille brebis; et le roi et les enfants d’Israël dédièrent le temple du Seigneur.
Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
64 En ce jour-là, le roi consacra le milieu du parvis qui était devant la maison du Seigneur; car il offrit là l’holocauste, le sacrifice, et la graisse des hosties pacifiques, parce que l’autel d’airain qui était devant le Seigneur était trop petit et ne pouvait contenir l’holocauste, le sacrifice et la graisse des hosties pacifiques.
Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
65 Salomon fit donc en ce temps-là la fête célèbre, et tout Israël avec lui, une grande multitude étant accourue depuis l’entrée d’Emath jusqu’au fleuve d’Egypte, devant le Seigneur notre Dieu, durant sept jours et sept jours, c’est-à-dire durant quatorze jours.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
66 Et, au huitième jour, il renvoya les peuples, qui, bénissant le roi, s’en allèrent dans leurs tabernacles avec allégresse et le cœur joyeux, pour tous les biens qu’avait faits le Seigneur à David son serviteur et à Israël son peuple.
Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.