< 1 Rois 4 >

1 Or le roi Salomon régnait sur tout Israël;
Solomoni ọba sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli.
2 Et voici les principaux officiers qu’il avait: Azarias, fils de Sadoc, le prêtre;
Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè rẹ̀: Asariah ọmọ Sadoku àlùfáà:
3 Elihoreph et Ahia, fils de Sisa, étaient scribes; Josaphat, fils d’Ahilud, tenait les registres;
Elihorefu àti Ahijah àwọn ọmọ Ṣisa akọ̀wé; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi ni akọ̀wé ìlú;
4 Banaïas, fils de Joïada, commandait l’armée; Sadoc et Abiathar étaient prêtres;
Benaiah ọmọ Jehoiada ni olórí ogun; Sadoku àti Abiatari ni àwọn àlùfáà;
5 Azarias, fils de Nathan, prêtre, commandait à ceux qui étaient toujours auprès du roi; Zabud, fils de Nathan, était ami du roi;
Asariah ọmọ Natani ni olórí àwọn agbègbè; Sabudu ọmọ Natani, àlùfáà àti olùgba ọba ní ìmọ̀ràn;
6 Et Ahisar, intendant de la maison; et Adoniram, fils d’Abda, surintendant des tributs.
Ahiṣari ni olùtọ́jú ààfin; Adoniramu ọmọ Abida ni ó ń ṣe olórí iṣẹ́-ìlú.
7 Et Salomon avait douze préposés sur tout Israël, qui fournissaient les vivres au roi et à sa maison; car à chaque mois dans l’année, chacun donnait tout ce qui était nécessaire.
Solomoni sì tún ní ìjòyè méjìlá lórí gbogbo agbègbè Israẹli, tí wọ́n ń pèsè oúnjẹ fún ọba àti agbo ilé rẹ̀. Olúkúlùkù ní láti pèsè fún oṣù kan ní ọdún.
8 Voici leurs noms: Benhur était préposé sur la montagne d’Ephraïm;
Orúkọ wọn ni wọ̀nyí: Bene-Huri ní ìlú olókè Efraimu.
9 Bendécar, à Maccès, à Salébim, à Bethsamès, à Elon et à Béthanan;
Bene-Dekeri ní Makasi, Ṣaalbimu, Beti-Ṣemeṣi, àti Eloni Beti-Hanani;
10 Benhésed, à Aruboth: Socho était à lui, et toute la terre d’Hépher.
Bene-Hesedi, ní Aruboti (tirẹ̀ ni Soko àti gbogbo ilẹ̀ Heferi ń ṣe);
11 Bénabinadad, à qui était tout le Néphat-Dor, avait Tapheth, fille de Salomon, pour femme.
Bene-Abinadabu, ní Napoti (Dori; òun ni ó fẹ́ Tafati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
12 Bana, fils d’Ahilud, gouvernait Thanac, Mageddo, et tout le Bethsan, qui est près de Sarthana, au-dessous de Jezraël, depuis Bethsan jusqu’à Abelméhula vis-à-vis de Jecmaan.
Baana ọmọ Ahiludi, ní Taanaki àti Megido, àti ní gbogbo Beti-Ṣeani tí ń bẹ níhà Saretani ní ìsàlẹ̀ Jesreeli, láti Beti-Ṣeani dé Abeli-Mehola títí dé ibi tí ń bẹ ní ìkọjá Jokimeamu.
13 Bengaber était à Ramoth-Galaad; et il avait les bourgs de Jaïr, fils de Manassé, en Galaad; c’est lui qui était préposé dans toute la contrée d’Argob, qui est en Basan, sur soixante cités grandes et murées, qui avaient des verrous d’airain.
Ọmọ Geberi ní Ramoti Gileadi (tirẹ̀ ni àwọn ìletò Jairi ọmọ Manase tí ń bẹ ní Gileadi, tirẹ̀ sì ni agbègbè Argobu, tí ń bẹ ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú tí ó tóbi pẹ̀lú odi tí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ irin).
14 Ahinadab, fils d’Addo, était préposé sur Manaïm;
Ahinadabu ọmọ Iddo ní Mahanaimu
15 Achimaas, sur Nephthali; et lui aussi eut Basémath, fille de Salomon, en mariage;
Ahimasi ní Naftali (ó fẹ́ Basemati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
16 Baana, fils d’Husi, sur Aser et sur Baloth;
Baana ọmọ Huṣai ní Aṣeri àti ní Aloti;
17 Josaphat, fils de Pharué, sur Issachar;
Jehoṣafati ọmọ Parua ni ó wà ní Isakari;
18 Séméi, fils d’Ela, sur Benjamin;
Ṣimei ọmọ Ela ni Benjamini;
19 Gaber, fils d’Uri, sur la terre de Galaad, sur la terre de Séhon, roi des Amorrhéens, et d’Og, roi de Basan, sur tout ce qui était en cette terre.
Geberi ọmọ Uri ní Gileadi (orílẹ̀-èdè Sihoni ọba àwọn ará Amori àti orílẹ̀-èdè Ogu ọba Baṣani). Òun nìkan ni ìjòyè lórí ilẹ̀ náà.
20 Juda et Israël étaient innombrables comme le sable de la mer par leur multitude, mangeant, buvant et se réjouissant.
Àwọn ènìyàn Juda àti ti Israẹli pọ̀ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn tí ń bẹ ní etí Òkun; wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu, wọ́n sì ń yọ ayọ̀.
21 Or, Salomon avait sous sa domination tous les royaumes, depuis le fleuve de la terre des Philistins jusqu’à la frontière d’Egypte; ils lui offrirent des présents et le servirent durant tous les jours de sa vie.
Solomoni sì ń ṣàkóso lórí gbogbo àwọn ìjọba láti odò Eufurate títí dé ilẹ̀ àwọn ará Filistini, àti títí dé etí ilẹ̀ Ejibiti. Àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń mú owó òde wá, wọ́n sì ń sin Solomoni ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
22 Or, les vivres de Salomon étaient chaque jour trente cors de fleur de farine et soixante cors de farine ordinaire;
Oúnjẹ Solomoni fún ọjọ́ kan jásí ọgbọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná àti ọgọ́ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun,
23 Dix bœufs gras, vingt bœufs de pâturage, cent béliers, outre la venaison des cerfs, des chevreuils, des bubales et de la volaille.
Màlúù mẹ́wàá tí ó sanra, àti ogún màlúù láti inú pápá wá, àti ọgọ́rùn-ún àgùntàn àti ewúrẹ́, láìka àgbọ̀nrín àti èsúró, àti ogbúgbu, àti ẹyẹ tí ó sanra.
24 Car c’est lui qui dominait sur toute la contrée qui était au-delà du fleuve, depuis Taphsa jusqu’à Gaza, et sur tous les rois de ces contrées; et il avait la paix de toutes parts alentour.
Nítorí òun ni ó ṣàkóso lórí gbogbo agbègbè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn odò Eufurate, láti Tifisa títí dé Gasa, lórí gbogbo àwọn ọba ní ìhà ìhín odò, ó sì ní àlàáfíà ní gbogbo ìlú tí ó yí i káàkiri.
25 Et Juda et Israël habitaient sans aucune crainte, chacun sous sa vigne et sous son figuier, depuis Dan jusqu’à Bersabée, durant tous les jours de Salomon.
Nígbà ayé Solomoni, Juda àti Israẹli, láti Dani títí dé Beerṣeba, wọ́n ń gbé ní àlàáfíà, olúkúlùkù lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀.
26 Et Salomon avait quarante mille écuries pour les chevaux des chariots, et douze mille cavaliers.
Solomoni sì ní ẹgbàajì ilé ẹṣin fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin.
27 Les susdits préposés par le roi les nourrissaient; mais ils fournissaient aussi ce qui était nécessaire à la table du roi Salomon avec un grand soin et en son temps.
Àwọn ìjòyè agbègbè, olúkúlùkù ní oṣù rẹ̀, ń pèsè oúnjẹ fún Solomoni ọba àti gbogbo àwọn tí ń wá sí ibi tábìlì ọba, wọ́n sì rí i pé ohun kankan kò ṣẹ́kù.
28 Ils portaient aussi l’orge et la paille pour les chevaux et les bestiaux, au lieu où était le roi, selon l’ordre qu’ils avaient reçu.
Wọ́n tún máa ń mú ọkà barle àti koríko fún ẹṣin àti fún ẹṣin sísáré wá pẹ̀lú sí ibi tí ó yẹ, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí ìlànà tirẹ̀.
29 Dieu donna aussi à Salomon une sagesse et une prudence très grande, et une étendue de cœur, comme le sable qui est sur le rivage de la mer.
Ọlọ́run sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, àti òye ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, àti ìmọ̀ gbígbòòrò òye tí a kò le è fiwé iyanrìn tí ó wà létí Òkun.
30 Et la sagesse de Salomon surpassait la sagesse de tous les Orientaux et de tous les Egyptiens;
Ọgbọ́n Solomoni sì pọ̀ ju ọgbọ́n ọkùnrin ìlà-oòrùn lọ, ó sì pọ̀ ju gbogbo ọgbọ́n Ejibiti lọ.
31 Il était plus sage que tous les hommes, plus sage qu’Ethan l’Ezrahite, qu’Héman, Chalcol et Dorda, enfants de Mahol; et il était renommé dans toutes les nations des environs.
Ó sì ní òye ju gbogbo ènìyàn lọ, ju Etani, ará Esra, àti Hemani àti Kalkoli, àti Darda àwọn ọmọ Maholi lọ. Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè yíká.
32 Salomon dit trois mille paraboles, et ses cantiques furent au nombre de mille et cinq.
Ó sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta òwe, àwọn orin rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé márùn-ún.
33 Et il discourut sur les arbres, depuis le cèdre qui est sur le Liban, jusqu’à l’hysope qui sort de la muraille, et traita des bestiaux, des oiseaux, des reptiles et des poissons.
Ó sì sọ̀rọ̀ ti igi, láti kedari tí ń bẹ ní Lebanoni dé Hísópù tí ń dàgbà lára ògiri. Ó sì tún sọ ti àwọn ẹranko àti ti àwọn ẹyẹ, àti ohun tí ń rákò àti ti ẹja.
34 Et on venait de chez tous les peuples pour entendre la sagesse de Salomon, et de la part de tous les rois de la terre qui apprenaient sa sagesse.
Àwọn ènìyàn sì ń wá láti gbogbo orílẹ̀-èdè láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọba ayé láti wá gbọ́ nípa ọgbọ́n rẹ̀.

< 1 Rois 4 >