< 1 Rois 14 >

1 En ce temps-là, Abia, fils de Jéroboam, fut malade,
Ní àkókò náà Abijah ọmọ Jeroboamu sì ṣàìsàn,
2 Et Jéroboam dit à sa femme: Lève-toi, change de vêtement, pour qu’on ne sache point que tu es femme de Jéroboam, et va à Silo, où est Ahias le prophète, qui m’a dit que je devais régner sur ce peuple.
Jeroboamu sì wí fún aya rẹ̀ pé, “Lọ, sì pa ara rẹ dà, kí wọn kí ó má ba à mọ̀ ọ́n ní aya Jeroboamu. Nígbà náà ni kí o lọ sí Ṣilo. Ahijah wòlíì wà níbẹ̀; ẹni tí ó sọ fún mi pé, èmi yóò jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn yìí.
3 Prends aussi en ta main dix pains, une galette et un vase de miel, et va vers lui; car lui-même t’indiquera ce qui doit arriver à cet enfant.
Mú ìṣù àkàrà mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, àti àkàrà wẹ́wẹ́ àti ìgò oyin, kí o sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Òun yóò sì sọ fún ọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọkùnrin náà.”
4 La femme de Jéroboam fit comme il avait dit; et, se levant, elle alla à Silo, et vint dans la maison d’Ahias; mais celui-ci ne pouvait voir, parce que ses yeux s’étaient obscurcis à cause de sa vieillesse.
Bẹ́ẹ̀ ni aya Jeroboamu sì ṣe bí ó ti wí, ó sì lọ sí ilé Ahijah ní Ṣilo. Ahijah kò sì ríran; ojú rẹ̀ ti fọ́ nítorí ogbó rẹ̀.
5 Or le Seigneur dit à Ahias: Voilà que la femme de Jéroboam vient te consulter sur son fils qui est malade: tu lui diras ceci et cela. Comme donc elle entrait, et dissimulait qui elle était,
Ṣùgbọ́n Olúwa ti sọ fún Ahijah pé, “Kíyèsi i, aya Jeroboamu ń bọ̀ wá béèrè nípa ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí ó ṣàìsàn, báyìí báyìí ni kí ìwọ kí ó wí fún un. Nígbà tí ó bá dé, yóò ṣe ara rẹ̀ bí ẹlòmíràn.”
6 Ahias entendit le bruit de ses pieds lorsqu’elle entrait à la porte, et il dit: Entrez, femme de Jéroboam: pourquoi feignez-vous d’être une autre? Pour moi, je vous suis envoyé comme un messager funeste.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí, nígbà tí Ahijah sì gbọ́ ìró ẹsẹ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Wọlé wá, aya Jeroboamu. Kí ló dé tí ìwọ fi ṣe ara rẹ bí ẹlòmíràn? A ti fi iṣẹ́ búburú rán mi sí ọ.
7 Allez, et dites à Jéroboam: Voici ce que dit le Seigneur Dieu d’Israël: Je t’ai élevé du milieu du peuple, et je t’ai établi chef sur mon peuple Israël;
Lọ, sọ fún Jeroboamu pé báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi sì gbé ọ ga láti inú àwọn ènìyàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
8 Et j’ai divisé le royaume de la maison de David et te l’ai donné; et tu n’as point été comme mon serviteur David, qui a gardé mes commandements, et qui m’a suivi en tout son cœur, faisant tout ce qui était agréable en ma présence;
Mo fa ìjọba náà ya kúrò ní ilé Dafidi, mo sì fi fún ọ ṣùgbọ́n, ìwọ kò dàbí Dafidi ìránṣẹ́ mi, tí ó pa àṣẹ mi mọ́, tí ó sì tọ̀ mí lẹ́yìn tọkàntọkàn rẹ̀, láti ṣe kìkì èyí tí ó tọ́ ní ojú mi.
9 Mais tu as fait plus de maux que tous ceux qui ont été avant toi, et tu t’es fait des dieux étrangers et jetés en fonte, pour me provoquer au courroux, et tu m’as rejeté derrière toi.
Ìwọ sì ti ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú rẹ lọ. Ìwọ sì ti ṣe àwọn ọlọ́run mìíràn fún ara rẹ, àwọn òrìṣà tí a gbẹ́; o sì ti mú mi bínú, o sì ti gbé mi sọ sí ẹ̀yìn rẹ.
10 C’est pourquoi voilà que j’amènerai des maux sur la maison de Jéroboam, et je frapperai de Jéroboam celui qui urine contre une muraille, celui qui est renfermé, et celui qui est le dernier dans Israël; et je nettoyerai les restes de la maison de Jéroboam, comme on a coutume de nettoyer le fumier, jusqu’à ce que tout soit net.
“‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jeroboamu. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jeroboamu, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Israẹli. Èmi yóò mú ilé Jeroboamu kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.
11 Ceux de Jéroboam qui mourront dans la ville, les chiens les mangeront, et ceux qui mourront dans la campagne, les oiseaux du ciel les dévoreront, parce que c’est le Seigneur qui a parlé.
Ajá yóò jẹ ẹni Jeroboamu tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní igbó ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’
12 Vous donc, levez-vous, et allez en votre maison; et, à l’entrée même de vos pieds dans la ville, l’enfant mourra,
“Ní ti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.
13 Et tout Israël le pleurera et l’ensevelira; car c’est le seul de Jéroboam qui sera porté dans un sépulcre, parce qu’il a été trouvé en lui quelque chose de bon par le Seigneur Dieu d’Israël dans la maison de Jéroboam.
Gbogbo Israẹli yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jeroboamu, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní ilé Jeroboamu.
14 Mais le Seigneur s’est établi un roi sur Israël, qui frappera la maison de Jéroboam en ce jour et en ce temps;
“Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fúnra rẹ̀ lórí Israẹli tí yóò ké ilé Jeroboamu kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsin yìí.
15 Et le Seigneur Dieu frappera Israël comme le roseau a coutume d’être agité dans l’eau, et il arrachera Israël de la bonne terre qu’il a donnée à leurs pères, et il les dispersera au-delà du fleuve, parce qu’ils se sont fait des bois sacrés pour irriter le Seigneur.
Olúwa yóò kọlu Israẹli, yóò sì dàbí koríko ti ń mì nínú omi. Yóò sì fa Israẹli tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò Eufurate, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère Aṣerah.
16 Et le Seigneur livrera Israël à cause des péchés de Jéroboam, qui a péché et qui a fait pécher Israël.
Yóò sì kọ Israẹli sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀.”
17 C’est pourquoi la femme de Jéroboam se leva, s’en alla, et vint à Thersa; et lorsqu’elle entrait sur le seuil de la porte de sa maison, l’enfant mourut,
Nígbà náà ni aya Jeroboamu sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tirsa. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.
18 Et on l’ensevelit. Et tout Israël le pleura, selon la parole du Seigneur qu’il avait dite par l’entremise de son serviteur Ahias, le prophète.
Wọ́n sì sin ín, gbogbo Israẹli sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ahijah wòlíì.
19 Mais le reste des actions de Jéroboam, comment il combattit, et comment il régna, voilà que c’est écrit dans le Livre des actions des jours des rois d’Israël.
Ìyókù ìṣe Jeroboamu, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jẹ ọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli.
20 Or les jours durant lesquels Jéroboam régna furent de vingt-deux ans, et il dormit avec ses pères, et Nadab, son fils, régna en sa place.
Jeroboamu sì jẹ ọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nadabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
21 Cependant Roboam, fils de Salomon régnait sur Juda. Roboam avait quarante-un ans lorsqu’il commença à régner, et il régna dix-sept ans dans la ville de Jérusalem, que le Seigneur avait choisie d’entre toutes les tribus d’Israël pour y établir son nom. Or le nom de sa mère était Naama, l’Ammanite.
Rehoboamu ọmọ Solomoni sì jẹ ọba ní Juda. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jerusalẹmu, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama, ará Ammoni.
22 Et Juda fit le mal aux yeux du Seigneur, et ils l’irritèrent au-delà de tout ce qu’avaient fait leurs pères, dans les péchés dont ils s’étaient rendus coupables,
Juda sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.
23 Car ils se firent, eux aussi, des autels, des statues et des bois sacrés sur toute colline élevée et sous tout arbre couvert de feuillage.
Wọ́n sì tún kọ́ ibi gíga fún ara wọn, àti ère òkúta àti òpó Aṣerah lórí gbogbo òkè gíga, àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
24 Il y eut aussi des efféminés dans leur terre, et ils commirent toutes les abominations de ces nations que le Seigneur avait détruites devant la face des enfants d’Israël.
Àwọn tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà wà ní ilẹ̀ náà, àwọn ènìyàn náà sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde kúrò níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
25 Or en la cinquième année du règne de Roboam, Sésac, roi d’Egypte, monta à Jérusalem,
Ó sì ṣe ní ọdún karùn-ún Rehoboamu, Ṣiṣaki ọba Ejibiti kọlu Jerusalẹmu.
26 Et il enleva les trésors de la maison du Seigneur et les trésors du roi, et il pilla tout, même les boucliers d’or qu’avait faits Salomon,
Ó sì kó ìṣúra ilé Olúwa lọ àti ìṣúra ilé ọba. Gbogbo rẹ̀ ni ó kó lọ, pẹ̀lú asà wúrà tí Solomoni ti ṣe.
27 En la place desquels le roi Roboam fit des boucliers d’airain, et il les mit entre les mains des chefs des scutaires, et de ceux qui veillaient devant la porte de la maison du roi.
Rehoboamu ọba sì ṣe asà idẹ ní ipò wọn, ó sì fi wọ́n sí ọwọ́ olórí àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlẹ̀kùn ilé ọba.
28 Et lorsque le roi entrait dans la maison du Seigneur, ceux dont l’office était de marcher devant lui portaient ces boucliers, et ensuite ils les reportaient dans l’arsenal des scutaires.
Nígbàkígbà tí ọba bá sì lọ sí ilé Olúwa, wọ́n á rù wọ́n, wọ́n á sì mú wọn padà sínú yàrá olùṣọ́.
29 Mais le reste des actions de Roboam, et tout ce qu’il a fait, voilà que c’est écrit dans le Livre des actions des jours des rois de Juda.
Ní ti ìyókù ìṣe Rehoboamu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda bí?
30 Et il y eut guerre entre Roboam et Jéroboam durant tous leurs jours.
Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní ọjọ́ wọn gbogbo.
31 Et Roboam dormit avec ses pères, et il fut enseveli avec eux dans la cité de David. Le nom de sa mère était Naama l’Ammanite, et Abiam son fils régna en sa place.
Rehoboamu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama; ará Ammoni. Abijah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< 1 Rois 14 >