< 1 Rois 13 >

1 Et voilà qu’un homme de Dieu vint avec les paroles du Seigneur, de Juda à Béthel, Jéroboam étant près de l’autel et jetant de l’encens.
Sì kíyèsi i, ènìyàn Ọlọ́run kan wá láti Juda sí Beteli nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, bì Jeroboamu sì ti dúró lẹ́bàá a pẹpẹ láti fi tùràrí jóná.
2 Et il s’écria contre l’autel, avec les paroles du Seigneur, et il dit: Autel, autel, le Seigneur dit ceci: Voilà qu’un fils naîtra dans la maison de David, du nom de Josias, et il immolera sur toi les prêtres des hauts lieux, qui maintenant brûlent sur toi de l’encens, et il brûlera sur toi des os d’hommes.
Ó sì kígbe sí pẹpẹ náà nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, “Pẹpẹ! Pẹpẹ! Báyìí ni Olúwa wí: ‘A ó bí ọmọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Josiah ní ilé Dafidi. Lórí rẹ ni yóò sì fi àwọn àlùfáà ibi gíga wọ̀n-ọn-nì tí ń fi tùràrí lórí rẹ̀ rú ẹbọ, a ó sì sun egungun ènìyàn lórí rẹ.’”
3 Et il donna en ce jour-là ce signe, disant: Ceci sera le signe que le Seigneur a parlé: Voilà que l’autel sera brisé, et que sera répandue la cendre qui est sur lui.
Ní ọjọ́ kan náà ènìyàn Ọlọ́run sì fún wọn ní àmì kan wí pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa ti kéde: kíyèsi i, pẹpẹ náà yóò ya, eérú tí ń bẹ lórí rẹ̀ yóò sì dànù.”
4 Or lorsque le roi eut entendu la parole que l’homme de Dieu avait dite en criant contre l’autel à Béthel, il étendit sa main de dessus l’autel, disant: Saisissez-le. Et sa main qu’il avait étendue contre le prophète se sécha, et il ne put pas la retirer à lui.
Nígbà tí Jeroboamu ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run, tí ó kígbe sí pẹpẹ náà ní Beteli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ jáde nínú pẹpẹ, ó sì wí pé, “Ẹ mú un!” ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ tí ó nà sí i sì kákò, bẹ́ẹ̀ ni kò sì le fà á padà mọ́.
5 L’autel aussi se brisa, et la cendre se répandit de l’autel, selon le signe que l’homme de Dieu avait prédit avec les paroles du Seigneur.
Lẹ́sẹ̀kan náà, pẹpẹ ya, eérú náà sì dànù kúrò lórí pẹpẹ náà gẹ́gẹ́ bí àmì tí ènìyàn Ọlọ́run ti fi fún un nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
6 Alors le roi dit à l’homme de Dieu: Implore la face du Seigneur ton Dieu, et prie pour moi, afin que ma main me soit rendue. Et l’homme de Dieu pria la face du Seigneur, et la main du roi revint à lui, et elle devint comme elle était auparavant.
Nígbà náà ní ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Bẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì gbàdúrà fún mi kí ọwọ́ mi lè padà bọ̀ sípò.” Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Olúwa, ọwọ́ ọba sì padà bọ̀ sípò, ó sì padà sí bí ó ti wà tẹ́lẹ̀.
7 Or le roi dit à l’homme de Dieu: Viens avec moi en ma maison pour dîner, et je te donnerai des présents.
Ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Wá bá mi lọ ilé, kí o sì wá nǹkan jẹ, èmi yóò sì fi ẹ̀bùn fún ọ.”
8 Et l’homme de Dieu répondit au roi: Quand vous me donneriez la moitié de votre maison, je n’irai point avec vous, et je ne mangerai point de pain ni ne boirai point d’eau en ce lieu;
Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run náà dá ọba lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá tilẹ̀ fún mi ní ìdajì ìní rẹ, èmi kì yóò lọ pẹ̀lú rẹ tàbí kí èmi jẹ oúnjẹ tàbí mu omi ní ibí yìí.
9 Car c’est ainsi qu’il m’a été commandé avec les paroles du Seigneur, qui a donné cet ordre: Tu ne mangeras point de pain, tu ne boiras point d’eau, et tu ne retourneras point par la voie par laquelle tu es venu.
Nítorí a ti pa á láṣẹ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi tàbí padà ní ọ̀nà náà tí o gbà wá.’”
10 Il s’en alla donc par une autre voie, et il ne retourna pas par le chemin par lequel il était venu à Béthel.
Bẹ́ẹ̀ ni ó gba ọ̀nà mìíràn, kò sì padà gba ọ̀nà tí ó gbà wá sí Beteli.
11 Or un certain vieux prophète habitait à Béthel, et ses fils vinrent vers lui, et lui racontèrent toutes les œuvres qu’avait faites l’homme de Dieu ce jour-là à Béthel; et les paroles qu’il avait dites au roi, ils les racontèrent à leur père.
Wòlíì àgbà kan wà tí ń gbé Beteli, ẹni tí àwọn ọmọ rẹ̀ dé, tí ó sì ròyìn gbogbo ohun tí ènìyàn Ọlọ́run náà ti ṣe ní Beteli ní ọjọ́ náà fún un. Wọ́n sì tún sọ fún baba wọn ohun tí ó sọ fún ọba.
12 Et leur père leur dit: Par quelle voie s’en est-il allé? Ses fils lui montrèrent la voie par laquelle s’en était allé l’homme de Dieu qui était venu de Juda.
Baba wọn sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ọ̀nà wo ni ó gbà?” Àwọn ọmọ rẹ̀ sì fi ọ̀nà tí ènìyàn Ọlọ́run láti Juda gbà hàn án.
13 Et il dit à ses fils: Préparez-moi l’âne. Et lorsque ceux-ci l’eurent préparé, il monta dessus.
Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi.” Nígbà tí wọ́n sì ti di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un tán, ó sì gùn ún.
14 Et il s’en alla après l’homme de Dieu, et il le trouva assis sous le térébinthe, et il lui dit: Es-tu l’homme de Dieu qui es venu de Juda? Celui-ci répondit; Je le suis.
Ó sì tẹ̀lé ènìyàn Ọlọ́run náà lẹ́yìn. Ó sì rí i tí ó jókòó lábẹ́ igi óákù kan, ó sì wí fún un pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá bí?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Èmi ni.”
15 Viens, dit-il, avec moi en ma maison pour manger du pain.
Nígbà náà ni wòlíì náà sì wí fún un pé, “Bá mi lọ ilé, kí o sì jẹun.”
16 L’homme de Dieu lui répondit: Je ne puis retourner ni aller avec toi, et je ne mangerai point de pain et ne boirai point d’eau en ce lieu;
Ènìyàn Ọlọ́run náà sì wí pé, “Èmi kò le padà sẹ́yìn tàbí bá ọ lọ ilé, tàbí kí èmi kí ó jẹ oúnjẹ tàbí mu omi pẹ̀lú rẹ níhìn-ín.
17 Parce que le Seigneur m’a parlé avec les paroles du Seigneur, disant: tu ne mangeras point de pain et ne boiras point d’eau là, et tu ne retourneras point par la voie par laquelle tu seras allé.
A ti sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi níhìn-ín tàbí kí o padà lọ nípa ọ̀nà tí ìwọ bá wá.’”
18 Cet homme lui répondit: Moi aussi, je suis prophète, semblable à toi, et un ange m’a parlé avec les paroles du Seigneur, disant: Ramène-le avec toi en ta maison, afin qu’il mange du pain et qu’il boive de l’eau. Il le trompa,
Wòlíì àgbà náà sì wí fún un pé, “Wòlíì ni èmi náà pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìwọ. Angẹli sì sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Mú un padà wá sí ilé rẹ, kí ó lè jẹ oúnjẹ àti kí ó lè mu omi.’” (Ṣùgbọ́n ó purọ́ fún un ni.)
19 Et le ramena avec lui: il mangea donc du pain en sa maison, et il but de l’eau.
Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà sì padà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì jẹ oúnjẹ ó sì mu omi ní ilé rẹ̀.
20 Et, lorsqu’ils étaient assis à table, la parole du Seigneur fut adressée au prophète qui l’avait ramené,
Bí wọ́n sì ti jókòó ti tábìlì, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ wòlíì tí ó mú un padà wá pé;
21 Et il cria à l’homme de Dieu qui était venu de Juda, disant: Voici ce que dit le Seigneur: Parce que tu n’as pas été obéissant à la parole du Seigneur, et que tu n’as point gardé le commandement que t’a prescrit le Seigneur ton Dieu,
Ó sì kígbe sí ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́, ìwọ kò sì pa àṣẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ mọ́.
22 Et que tu es retourné, et que tu as mangé du pain et bu de l’eau dans le lieu dans lequel je t’ai ordonné de ne point manger de pain et de ne point boire d’eau, ton cadavre ne sera pas porté dans le sépulcre de tes pères.
Ìwọ padà, ìwọ sì ti jẹ oúnjẹ, ìwọ sì ti mu omi níbi tí ó ti sọ fún ọ pé kí ìwọ kí ó má ṣe jẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Nítorí náà, a kì yóò sin òkú rẹ sínú ibojì àwọn baba rẹ.’”
23 Lors donc qu’il eut mangé et bu, le vieux prophète sella son âne pour le prophète qu’il avait ramené.
Nígbà tí ènìyàn Ọlọ́run sì ti jẹun tán àti mu omi tan, wòlíì tí ó ti mú u padà sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un.
24 Et lorsque celui-ci s’en fut allé, un lion le rencontra et le tua, et son cadavre était étendu dans le chemin: l’âne se tenait auprès de lui, et le lion se tenait auprès du cadavre.
Bí ó sì ti ń lọ ní ọ̀nà rẹ̀, kìnnìún kan pàdé rẹ̀ ní ọ̀nà, ó sì pa á, a sì gbé òkú rẹ̀ sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró tì í lẹ́gbẹ̀ẹ́.
25 Et voilà que des hommes qui passaient virent son cadavre étendu sur la voie, et le lion qui se tenait auprès du cadavre. Et ils vinrent, et le publièrent dans la ville dans laquelle ce vieux prophète demeurait.
Àwọn ènìyàn tí ó ń kọjá sì rí pé ó gbé òkú náà sọ sí ojú ọ̀nà, kìnnìún náà sì dúró ti òkú náà; wọ́n sì wá, wọ́n sì sọ ọ́ ní ìlú tí wòlíì àgbà náà ń gbé.
26 Ce qu’ayant appris, ce prophète qui l’avait détourné de sa voie, dit: C’est l’homme de Dieu qui a été désobéissant à la parole du Seigneur, et le Seigneur l’a livré au lion, qui l’a brisé et l’a tué, selon la parole que le Seigneur lui avait dite.
Nígbà tí wòlíì tí ó mú un padà wá láti ọ̀nà rẹ̀ sì gbọ́ èyí, ó sì wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run náà ni tí ó ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́. Olúwa sì ti fi lé kìnnìún lọ́wọ́, tí ó sì fà á ya, tí ó sì pa á, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti kìlọ̀ fún un.”
27 Et il dit à ses fils: Sellez-moi l’âne. Lorsque ceux-ci l’eurent sellé,
Wòlíì náà sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi,” wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀.
28 Et que lui s’en fut allé, il trouva le cadavre étendu sur la voie, et l’âne et le lion qui se tenaient auprès du cadavre: le lion ne mangea pas du cadavre et ne fit pas de mal à l’âne.
Nígbà náà ni ó sì jáde lọ, ó sì rí òkú náà tí a gbé sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Kìnnìún náà kò sì jẹ òkú náà, tàbí fa kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà ya.
29 Le prophète prit donc le cadavre de l’homme de Dieu, le mit sur l’âne, et le ramena dans la ville du vieux prophète, pour le pleurer.
Nígbà náà ni wòlíì náà gbé òkú ènìyàn Ọlọ́run náà, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì gbé e padà wá sí ìlú ara rẹ̀ láti ṣọ̀fọ̀ fún un àti láti sin ín.
30 Et il mit son cadavre dans son sépulcre; et ils le pleurèrent, disant: Hélas! hélas! mon frère!
Nígbà náà ni ó gbé òkú náà sínú ibojì ara rẹ̀, wọ́n sì ṣọ̀fọ̀ lórí rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ó ṣe, arákùnrin mi!”
31 Et lorsqu’ils l’eurent pleuré, il dit à ses fils: Lorsque je serai mort, ensevelissez-moi dans le sépulcre dans lequel l’homme de Dieu est enseveli; mettez mes os auprès de ses os.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú rẹ̀ tán, ó sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Nígbà tí mo bá kú, ẹ sin mí ní ibojì níbi tí a sin ènìyàn Ọlọ́run sí; ẹ tẹ́ egungun mi lẹ́bàá egungun rẹ̀.
32 Car certainement il arrivera ce qu’il a prédit avec les paroles du Seigneur, contre l’autel qui est à Béthel, et contre tous les temples des hauts lieux qui sont dans les villes de Samarie.
Nítorí iṣẹ́ tí ó jẹ́ nípa ọ̀rọ̀ Olúwa sí pẹpẹ tí ó wà ní Beteli àti sí gbogbo ojúbọ lórí ibi gíga tí ń bẹ ní àwọn ìlú Samaria yóò wá sí ìmúṣẹ dájúdájú.”
33 Après cela, Jéroboam ne revint point de ses voies très mauvaises; mais au contraire, il fit des derniers du peuple des prêtres des hauts lieux: à quiconque le voulait il remplissait sa main, et celui-ci devenait prêtre des hauts lieux.
Lẹ́yìn nǹkan yìí, Jeroboamu kò padà kúrò nínú ọ̀nà búburú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tún yan àwọn àlùfáà sí i fún àwọn ibi gíga nínú gbogbo àwọn ènìyàn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ di àlùfáà, a yà á sọ́tọ̀ fún ibi gíga wọ̀nyí.
34 Et c’est pour ce motif que pécha la maison de Jéroboam, et qu’elle fut détruite et exterminée de la surface de la terre.
Èyí sì ni ẹ̀ṣẹ̀ ilé Jeroboamu, èyí tí ó yọrí sí ìṣubú rẹ̀, a sì pa á run kúrò lórí ilẹ̀.

< 1 Rois 13 >