< 1 Rois 12 >

1 Or Roboam vint à Sichem; car c’est là que tout Israël s’était assemblé pour l’établir roi.
Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
2 Mais Jéroboam, fils de Nabath, pendant qu’il était encore réfugié en Egypte, loin de la présence du roi Salomon, ayant appris sa mort, revint de l’Egypte.
Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
3 Car on envoya et on l’appela. Jéroboam vint donc, et toute la multitude d’Israël; et ils parlèrent à Roboam, disant:
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
4 Votre père nous a imposé un joug très dur: vous donc maintenant, tempérez un peu le gouvernement très dur de votre père, et le joug très pesant qu’il nous a imposé, et nous vous servirons.
“Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
5 Roboam leur répondit: Allez jusqu’au troisième jour, et revenez vers moi. Or, lorsque le peuple s’en fut allé,
Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
6 Le roi Roboam tint conseil avec les anciens qui étaient auprès de Salomon son père, lorsqu’il vivait encore, et il demanda: Quel conseil me donnez-vous, afin que je réponde à ce peuple?
Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
7 Ceux-ci répondirent: Si vous obéissez maintenant à ce peuple, si vous vous soumettez et que vous cédiez à leur demande, et que vous leur disiez des paroles de douceur, ils vous seront soumis pour toujours.
Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
8 Roboam abandonna le conseil que les anciens lui avaient donné, et consulta les jeunes gens qui avaient été nourris avec lui et qui étaient auprès de lui;
Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
9 Et il leur dit: Quel conseil me donnez-vous, afin que je réponde à ce peuple, qui m’a dit: Allégez le joug qu’a imposé votre père sur nous?
Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
10 Et ces jeunes gens qui avaient été nourris avec lui, lui répondirent: C’est ainsi que vous parlerez à ce peuple qui vous a parlé, disant: Votre père a appesanti notre joug; vous, soulagez-nous. C’est ainsi que vous leur parlerez: Mon plus petit doigt est plus gros que le dos de mon père.
Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
11 Ainsi donc mon père a imposé sur vous un joug pesant; mais moi j’ajouterai à votre joug: mon père vous a déchirés avec des verges; mais moi je vous déchirerai avec des scorpions.
Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
12 Jéroboam vint donc, et tout le peuple, vers Roboam, le troisième jour, comme Roboam l’avait déclaré, disant: Revenez vers moi au troisième jour.
Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
13 Et le roi répondit au peuple des choses dures, abandonnant le conseil que les anciens lui avaient donné,
Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
14 Et il leur parla selon le conseil des jeunes gens, disant: Mon père a appesanti votre joug; mais moi j’ajouterai à votre joug: mon père vous a déchirés avec des verges; mais moi je vous déchirerai avec des scorpions.
Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
15 Et le roi n’écouta point le peuple, parce que le Seigneur s’était détourné de lui, pour effectuer la parole qu’il avait dite par l’entremise d’Ahias, le Silonite, à Jéroboam, fils de Nabath.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
16 C’est pourquoi le peuple, voyant que le roi n’avait point voulu les écouter, lui répondit, disant: Quelle part avons-nous avec David? ou quel héritage avec le fils d’Isaï? Va dans tes tabernacles, Israël; maintenant voyez votre maison, ô David. Et Israël s’en alla dans ses tabernacles.
Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
17 Mais c’est sur tous les enfants d’Israël qui demeuraient dans les villes de Juda, que régna Roboam.
Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
18 Le roi Roboam envoya ensuite Aduram, qui était surintendant des tributs; et tout Israël le lapida, et il mourut. Or le roi Roboam, se hâtant, monta sur son char, et s’enfuit à Jérusalem.
Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
19 Et Israël s’est tenu séparé de la maison de David jusqu’au présent jour.
Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
20 Or il arriva que, lorsque tout Israël eut ouï que Jéroboam était revenu, on envoya, et on l’appela, l’assemblée s’étant réunie, et on l’établit roi sur tout Israël, et nul ne suivit la maison de David, excepté la seule tribu de Juda.
Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
21 Mais Roboam vint à Jérusalem, assembla toute la maison de Juda et la tribu de Benjamin, au nombre de cent quatre-vingt mille hommes de guerre choisis, pour combattre contre la maison d’Israël, et remettre le royaume à Roboam, fils de Salomon.
Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
22 Alors la parole du Seigneur fut adressée à Séméias, homme de Dieu, disant:
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
23 Parle à Roboam, fils de Salomon, roi de Juda, à toute la maison de Juda et de Benjamin, et au reste du peuple, disant:
“Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
24 Voici ce que dit le Seigneur: Vous ne monterez point et vous ne ferez point la guerre contre vos frères, les enfants d’Israël: que chaque homme retourne en sa maison, car c’est par moi qu’a été fait ceci. Ils écoutèrent la parole du Seigneur, et ils s’en retournèrent comme leur avait ordonné le Seigneur.
‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
25 Or Jéroboam bâtit Sichem sur la montagne d’Ephraïm, et il y habita; et, étant sorti de là, il bâtit Phanuel.
Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
26 Et Jéroboam dit en son cœur: Maintenant le royaume retournera à la maison de David,
Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
27 Si ce peuple monte à Jérusalem pour sacrifier dans la maison du Seigneur: et le cœur de ce peuple se tournera vers son seigneur Roboam, roi de Juda, et ils me tueront et retourneront à lui.
Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
28 Et, ayant réfléchi mûrement à son dessein, il fit deux veaux d’or, et dit au peuple: Ne montez plus à Jérusalem; Israël, voici tes dieux qui t’ont retiré de la terre d’Egypte.
Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
29 Or il en plaça un à Béthel et l’autre à Dan.
Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
30 Et cela devint un sujet de péché; car le peuple allait pour adorer ce veau jusqu’à Dan.
Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
31 Et il fit des temples sur les hauts lieux, et des prêtres des derniers du peuple, qui n’étaient point d’entre les enfants de Lévi.
Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
32 Il ordonna aussi un jour solennel dans le huitième mois, le quinzième jour du mois, à l’imitation du jour de solennité qui se célébrait en Juda. Et, montant à l’autel, il fit de même à Béthel pour sacrifier aux veaux qu’il avait fabriqués; et il établit dans Béthel les prêtres des hauts lieux qu’il avait bâtis.
Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
33 Et il monta à l’autel qu’il avait construit dans Béthel, le quinzième jour du huitième mois, qu’il avait établi selon son gré; et il fit une solennité aux enfants d’Israël, et monta à l’autel pour brûler de l’encens.
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.

< 1 Rois 12 >