< 1 Chroniques 7 >

1 Or les fils d’Issachar furent: Thola et Phua, Jasub et Siméron; quatre.
Àwọn ọmọ Isakari: Tola, Pua, Jaṣubu àti Ṣimroni, mẹ́rin ni gbogbo rẹ̀.
2 Les fils de Thola: Ozi, Raphaïa, Jériel, Jémaï, Jebsem et Samuel, princes dans les maisons de leurs familles. C’est de la race de Thola que, dans les jours de David, furent dénombrés des hommes très braves, au nombre de vingt-deux mille six cents.
Àwọn ọmọ Tola: Ussi, Refaiah, Jehieli, Jamai, Ibsamu àti Samuẹli olórí àwọn ìdílé wọn. Ní àkókò ìjọba, Dafidi, àwọn ìran ọmọ Tola tò lẹ́sẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọkùnrin alágbára ní ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀ta.
3 Les fils d’Ozi: Izrahia, duquel naquirent Michaël, Obadia, Johel et Jésia, tous cinq princes.
Àwọn ọmọ, Ussi: Israhiah. Àwọn ọmọ Israhiah: Mikaeli, Obadiah, Joẹli àti Iṣiah. Gbogbo àwọn márààrún sì jẹ́ olóyè.
4 Et il y avait avec eux, dans leurs familles et leurs peuples, prêts au combat, des hommes très braves, au nombre de trente-six mille, car ils eurent beaucoup de femmes et d’enfants.
Gẹ́gẹ́ bí ìtàn ìdílé wọn láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n ní ọkùnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógójì tí ó ti ṣe tan fún ogun, nítorí wọ́n ní ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ àti ìyàwó.
5 Leurs frères aussi, dans toute la parenté d’Issachar, étaient très vigoureux pour combattre; il y en eut quatre-vingt-sept mille de dénombrés.
Àwọn ìbátan tí ó jẹ́ alágbára akọni àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ti àwọn ìdílé Isakari, bí a ti tò ó lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínláàádọ́rin ni gbogbo rẹ̀.
6 Les fils de Benjamin furent Béla, Béchor et Jadihel; trois,
Àwọn ọmọ mẹ́ta Benjamini: Bela, Bekeri àti Jediaeli.
7 Les fils de Béla: Esbon, Ozi, Oziel, Jérimoth et Uraï; cinq princes de familles, et très vigoureux pour combattre: or leur nombre fut de vingt-deux mille et trente-quatre;
Àwọn ọmọ Bela: Esboni, Ussi, Usieli, Jerimoti àti Iri, àwọn márààrún. Àwọn ni olórí ilé baba ńlá wọn, akọni alágbára ènìyàn. A sì ka iye wọn nípa ìran wọn sí ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ènìyàn.
8 Les fils de Béchor: Zamira, Joas, Eliézer, Elioénaï, Amri, Jérimoth, Abia, Anathoth et Almath: tous ceux-là furent fils de Béchor.
Àwọn ọmọ Bekeri: Semirahi, Joaṣi, Elieseri, Elioenai, Omri, Jeremoti, Abijah, Anatoti àti Alemeti. Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ọmọ Bekeri.
9 Or on en dénombra, selon leurs familles, comme princes dans leur parenté, très braves pour les combats, vingt mille et deux cents.
Ìtàn ìdílé wọn láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn tí a kọ lẹ́sẹẹsẹ jẹ́ ti àwọn olórí ìdílé àti ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà ogún ó lé nígba ọkùnrin alágbára.
10 De plus, les fils de Jadihel: Balan; et les fils de Balan: Jéhus, Benjamin, Aod, Chanana, Zéthan, Tharsis et Ahisahar,
Ọmọ Jediaeli: Bilhani. Àwọn ọmọ Bilhani: Jeuṣi Benjamini, Ehudu, Kenaana, Setamu, Tarṣiṣi àti Ahiṣahari.
11 Tous ceux-là furent fils de Jadihel, princes dans leur parenté, hommes très braves, au nombre de dix-sept mille et deux cents, marchant aux combats.
Gbogbo àwọn ọmọ Jediaeli jẹ́ olórí. Àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́tàdínlógún ó lé nígba akọni ọkùnrin ni ó ti ṣetán láti jáde lọ sí ogun.
12 Sépham aussi et Hapham furent les fils de Hir; et Hasim, les fils d’Aher;
Àti Ṣuppimu, àti Huppimu, àwọn ọmọ Iri, àti Huṣimu, àwọn ọmọ Aheri.
13 Mais les fils de Nephthali: Jasiel, Guni, Jéser et Sellum, fils de Bala.
Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri àti Ṣallumu—ọmọ rẹ̀ nípa Biliha.
14 Or le fils de Manassé fut Esriel; et sa femme du second rang, la Syrienne, enfanta Machir, père de Galaad.
Àwọn ìran ọmọ Manase: Asrieli jẹ́ ìran ọmọ rẹ̀ ní ipasẹ̀ àlè rẹ̀ ará Aramu ó bí Makiri baba Gileadi.
15 Et Machir prit des femmes pour ses fils Happhim et Saphan; et il eut une sœur du nom de Maacha; mais le nom du second fut Salphaad; et il naquit à Salphaad des filles.
Makiri sì mú ìyàwó láti àárín àwọn ará Huppimu àti Ṣuppimu. Orúkọ arábìnrin rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka. Orúkọ ìran ọmọ mìíràn a máa jẹ́ Selofehadi, tí ó ní àwọn ọmọbìnrin nìkan ṣoṣo.
16 Et Maacha, femme de Machir, enfanta un fils qu’elle appela du nom de Pharès: or le nom du frère de Pharès fut Sarès, et les fils de Sarès: Ulam et Récen.
Maaka, ìyàwó Makiri bí ọmọkùnrin kan. Ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Peresi. Ó sì pe arákùnrin rẹ̀ ní Ṣereṣi, àwọn ọmọ rẹ̀ sì ní Ulamu àti Rakemu.
17 Mais le fils d’Ulam fut Badan; ceux-là sont les fils de Galaad, fils de Machir, fils de Manassé.
Ọmọ Ulamu: Bedani. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi ọmọ Makiri, ọmọ Manase.
18 Sa sœur. Reine, enfanta Homme-beau, et Abiézer et Mohola.
Arábìnrin rẹ̀. Hamoleketi bí Iṣhodi, Abieseri àti Mahila.
19 Et les fils de Sémida étaient Ahir, Séchem, Léci et Aniam;
Àwọn ọmọ Ṣemida sì jẹ́: Ahiani, Ṣekemu, Likki àti Aniamu.
20 Mais les fils d’Ephraïm: Suthala, Bared, son fils, Thahath, son fils, Elada, son fils, Thahath, son fils, le fils de celui-ci, Zabad,
Àwọn ìran ọmọ Efraimu: Ṣutelahi, Beredi ọmọkùnrin rẹ̀, Tahati ọmọ rẹ̀, Eleadah ọmọ rẹ̀. Tahati ọmọ rẹ̀
21 Elle fils de celui-ci, Suthala, et le fils de celui-ci, Ezer, ainsi qu’Elad; mais les hommes indigènes de Geth les tuèrent, parce qu’ils étaient descendus pour envahir leurs possessions.
Sabadi ọmọ, rẹ̀, àti Ṣutelahi ọmọ rẹ̀. Eseri àti Eleadi ni a pa nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin bíbí ìbílẹ̀ Gati nígbà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ fi agbára mú ohun ọ̀sìn wọn
22 C’est pourquoi Ephraïm, leur père, les pleura pendant un grand nombre de jours; et ses frères vinrent pour le consoler.
Efraimu baba wọn ṣọ̀fọ̀ fún wọn ní ọjọ́ púpọ̀, àwọn ìbátan rẹ̀ wá láti tù ú nínú.
23 Et il s’approcha de sa femme, qui conçut et eut un fils, et qui l’appela du nom de Béria, parce qu’il était né au milieu des maux de sa maison.
Nígbà náà, ó sùn pẹ̀lú, ìyàwó rẹ̀, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin kan. Ó sì sọ ọ́ ní Beriah nítorí òfò ti wà nínú ìdílé náà.
24 Mais sa fille fut Sara, qui bâtit Béthoron la Basse et la Haute, et Ozensara.
Ọmọbìnrin rẹ̀ sì jẹ́ Ṣerah, ẹni tí ó kọ́ ìsàlẹ̀ àti òkè Beti-Horoni àti Useni-Ṣerah pẹ̀lú.
25 Il eut encore pour fils, Rapha, Réseph, et Thalé, duquel naquit Thaan,
Refa jẹ́ ọmọ rẹ̀, Resefi ọmọ rẹ̀, Tela ọmọ rẹ̀, Tahani ọmọ rẹ̀,
26 Qui engendra Laadan; et le fils de celui-ci fut Ammiud, qui engendra Elizama,
Laadani ọmọ rẹ̀ Ammihudu ọmọ rẹ̀, Eliṣama ọmọ rẹ̀,
27 Duquel est né Nun, qui eut pour fils Josué.
Nuni ọmọ rẹ̀ àti Joṣua ọmọ rẹ̀.
28 Leur possession et leur habitation furent Béthel avec ses filles, Noran, contre l’orient, et contre le côté occidental. Gazer et ses filles, comme aussi Sichem avec ses filles, jusqu’à Aza avec ses filles.
Ilẹ̀ wọn àti ìfìdíkalẹ̀ wọn ni Beteli àti àwọn ìletò tí ó yíká, Narani lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, Geseri àti àwọn ìletò rẹ̀ lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Ṣekemu àti àwọn ìletò rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Ayahi àti àwọn ìletò.
29 Leur possession fut aussi, près des fils de Manassé, Bethsan et ses filles, Thanach et ses filles, Mageddo et ses filles, Dor et ses filles: c’est en ces lieux qu’habitèrent les fils de Joseph, fils d’Israël.
Lẹ́gbẹ̀ ìpínlẹ̀ ti Manase ni Beti-Ṣeani, Taanaki, Megido àti Dori lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìletò rẹ̀. Àwọn ìran ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli ń gbé nínú ìlú wọ̀nyí.
30 Les fils d’Aser furent Jemna, Jésua, Jessui et Baria, et Sara était leur sœur;
Àwọn ọmọ Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn sì jẹ́ Sera.
31 Mais les fils de Bari: Heber et Melchiel: c’est lui qui est père de Barsaïth.
Àwọn ọmọ Beriah: Heberi àti Malkieli, tí ó jẹ́ baba Barsafiti.
32 Or Héber engendra Jephlat, Somer et Hotham, et Suaa, leur sœur.
Heberi jẹ́ baba Jafileti, Ṣomeri àti Hotami àti ti arábìnrin wọn Ṣua.
33 Les fils de Jéphlat furent Phosech, Chamaal et Asoth; ce sont là les fils de Jéphlat.
Àwọn ọmọ Jafileti: Pasaki, Bimhali àti Asifati. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jafileti.
34 Mais les fils de Somer: Ahi, Roaga, Haba et Aram.
Àwọn ọmọ Ṣomeri: Ahi, Roga, Jahuba àti Aramu.
35 Et les fils d’Hélem, son frère: Supha, Jemna, Sellès et Amal.
Àwọn ọmọ arákùnrin rẹ̀ Helemu Sofahi, Imina, Ṣeleṣi àti Amali.
36 Les fils de Supha: Sué, Harnapher, Sual, Béri et Jamra,
Àwọn ọmọ Sofahi: Sua, Haniferi, Ṣuali, Beri, Imra.
37 Bosor, Hod, Samma, Salusa, Jéthran et Béra.
Beseri, Hodi, Ṣamma, Ṣilisa, Itrani àti Bera.
38 Les fils de Jéther: Jéphoné, Phaspha et Ara.
Àwọn ọmọ Jeteri: Jefunne, Pisifa àti Ara.
39 Et les fils d’Olla: Arée, Haniel et Résia.
Àwọn ọmọ Ulla: Arah, Hannieli àti Resia.
40 Tous ceux-là sont les fils d’Aser, et les princes des familles, chefs distingués et les plus braves des chefs: le nombre de ceux d’un âge propre à la guerre était de vingt-six mille.
Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ìran ọmọ Aṣeri—olórí ìdílé, àṣàyàn ọkùnrin, alágbára jagunjagun àti olórí nínú àwọn ìjòyè. Iye àwọn tí a kà yẹ fún ogun, gẹ́gẹ́ bí à ti ṣe kọ ọ́ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlá ọkùnrin.

< 1 Chroniques 7 >