< 1 Chroniques 6 >
1 Les fils de Lévi furent Gerson, Caath et Mérari;
Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
2 Les fils de Caath, Amram, Isaar, Hébron et Oziel;
Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni, àti Usieli.
3 Les fils d’Amram, Aaron, Moïse et Marie; les fils d’Aaron Nadab et Abiu, Eléazar et Ithamar.
Àwọn ọmọ Amramu: Aaroni, Mose àti Miriamu. Àwọn ọmọkùnrin Aaroni: Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
4 Eléazar engendra Phinéès, et Phinéès engendra Abisué.
Eleasari jẹ́ baba Finehasi, Finehasi baba Abiṣua
5 Abisué engendra Bocci, et Bocci engendra Ozi.
Abiṣua baba Bukki, Bukki baba Ussi,
6 Ozi engendra Zaraïas, et Zaraïas engendra Méraïoth.
Ussi baba Serahiah, Serahiah baba Meraioti,
7 Méraïoth engendra Amarias, et Amarias engendra Achitob.
Meraioti baba Amariah, Amariah baba Ahitubu
8 Achitob engendra Sadoc, et Sadoc engendra Achimaas.
Ahitubu baba Sadoku, Sadoku baba Ahimasi,
9 Achimaas engendra Azarias, Azarias engendra Johanan.
Ahimasi baba Asariah, Asariah baba Johanani,
10 Johanan engendra Azarias: ce fut lui qui remplit les fonctions du sacerdoce dans la maison que bâtit Salomon à Jérusalem.
Johanani baba Asariah. (Òhun ni ó sìn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà nínú ilé Olúwa tí Solomoni kọ́ sí Jerusalẹmu).
11 Or Azarias engendra Amarias, et Amarias engendra Achitob.
Asariah baba Amariah Amariah baba Ahitubu
12 Achitob engendra Sadoc, et Sadoc engendra Sellum.
Ahitubu baba Sadoku. Sadoku baba Ṣallumu,
13 Sellum engendra Helcias, et Helcias engendra Azarias.
Ṣallumu baba Hilkiah, Hilkiah baba Asariah,
14 Azarias engendra Saraïas, et Saraïas engendra Josédec.
Asariah baba Seraiah, pẹ̀lú Seraiah baba Josadaki.
15 Or Josédec sortit du pays, quand le Seigneur déporta Juda et Jérusalem par l’entremise de Nabuchodonosor.
A kó Josadaki lẹ́rú nígbà tí Olúwa lé Juda àti Jerusalẹmu kúrò ní ìlú nípasẹ̀ Nebukadnessari.
16 Les fils de Lévi furent donc Gerson, Caath et Mérari;
Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
17 Les fils de Gerson, Lobni et Séméi;
Wọ̀nyí ni àwọn orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
18 Les fils de Caath, Amram, Isaar, Hébron et Oziel;
Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
19 Les fils de Mérari, Moholi et Musi. Mais voici la parenté des enfants de Lévi, selon leurs familles:
Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ará Lefi tí a kọ ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí baba wọn.
20 Gerson, dont le fils, Lobni, dont le fils, Jahath, dont le fils, Zamma,
Ti Gerṣoni: Libni ọmọkùnrin rẹ̀, Jahati. Ọmọkùnrin rẹ̀, Simma ọmọkùnrin rẹ̀,
21 Dont le fils, Joab, dont le fils, Addo, dont le fils, Zara, dont le fils, Jethraï;
Joah ọmọkùnrin rẹ̀, Iddo ọmọkùnrin rẹ̀, Sera ọmọkùnrin rẹ̀ àti Jeaterai ọmọkùnrin rẹ̀.
22 Les fils de Caath: Aminadab, son fils, dont le fils, Coré, dont le fils Asir,
Àwọn ìran ọmọ Kohati: Amminadabu ọmọkùnrin rẹ̀, Kora ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
23 Dont le fils, Elcana, dont le fils, Abiasaph, dont le fils, Asir,
Elkana ọmọkùnrin rẹ̀, Ebiasafi ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
24 Dont le fils, Thahath, dont le fils, Uriel, dont le fils, Ozias, dont le fils, Saül.
Tahati ọmọkùnrin rẹ̀, Urieli ọmọkùnrin rẹ̀, Ussiah ọmọkùnrin rẹ̀ àti Saulu ọmọkùnrin rẹ̀.
25 Les fils d’Elcana: Amasaï, Achimoth,
Àwọn ìran ọmọ Elkana: Amasai, Ahimoti
26 Et Elcana; les fils d’Elcana: Sophaï, son fils, dont le fils, Nahath,
Elkana ọmọ rẹ̀, Sofai ọmọ rẹ̀ Nahati ọmọ rẹ̀,
27 Dont le fils, Eliab, dont le fils, Jéroham, dont le fils, Elcana.
Eliabu ọmọ rẹ̀, Jerohamu ọmọ rẹ̀, Elkana ọmọ rẹ̀ àti Samuẹli ọmọ rẹ̀.
28 Les fils de Samuel: le premier-né, Vasseni, et Abia;
Àwọn ọmọ Samuẹli: Joẹli àkọ́bí àti Abijah ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì.
29 Mais les fils de Mérari, Moholi, dont le fils, Lobni, dont le fils, Séméi, dont le fils, Oza,
Àwọn ìran ọmọ Merari: Mahili, Libni ọmọ rẹ̀. Ṣimei ọmọ rẹ̀, Ussa ọmọ rẹ̀.
30 Dont le fils, Sammaa, dont le fils, Haggia, dont le fils, Asaïa.
Ṣimea ọmọ rẹ̀, Haggiah ọmọ rẹ̀ àti Asaiah ọmọ rẹ̀.
31 Voilà ceux que David établit sur les chantres de la maison du Seigneur, depuis que l’arche eut été placée.
Èyí ní àwọn ọkùnrin Dafidi tí a fi sí ìdí orin nínú ilé Olúwa lẹ́yìn tí àpótí ẹ̀rí ti wá láti sinmi níbẹ̀.
32 Et ils servaient devant le tabernacle de témoignage, chantant, jusqu’à ce que Salomon eût bâti la maison du Seigneur dans Jérusalem; mais ils exerçaient ce ministère suivant leur rang.
Wọ́n jíṣẹ́ pẹ̀lú orin níwájú àgọ́ ìpàdé títí tí Solomoni fi kọ́ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu. Wọ́n ṣe iṣẹ́ ìsìn wọn ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà tí a fi lélẹ̀ fún wọn.
33 Or voici ceux qui servaient avec leurs fils d’entre les fils de Caath: Héman, le chantre, fils de Johel, fils de Samuel,
Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ó sìn pẹ̀lú ọmọ wọn. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ará Kohati: Hemani olùkọrin, ọmọ Joẹli, ọmọ Samuẹli,
34 Fils d’Elcana, fils de Jéroham, fils d’Eliel, fils de Thohu,
ọmọ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elieli, ọmọ Toha,
35 Fils de Suph, fils d’Elcana, fils de Mahath, fils d’Amasa,
ọmọ Sufu, ọmọ Elkana, ọmọ Mahati, ọmọ Amasai,
36 Fils d’Elcana, fils de Joël, fils d’Azarias, fils de Sophonias,
ọmọ Elkana, ọmọ Joẹli, ọmọ Asariah, ọmọ Sefaniah,
37 Fils de Thahath, fils d’Asir, fils d’Abiasaph, fils de Coré,
ọmọ Tahati, ọmọ Asiri, ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora,
38 Fils d’Isaar, fils de Caath, fils de Lévi, fils d’Israël.
ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli;
39 Et son frère Asaph, qui se tenait à sa droite; Asaph, fils de Barachias, fils de Samaa,
Hemani sì darapọ̀ mọ́ Asafu, ẹni tí o sìn ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀: Asafu ọmọ Berekiah, ọmọ Ṣimea,
40 Fils de Michaël, fils de Basaïas, fils de Melchias,
ọmọ Mikaeli, ọmọ Baaseiah, ọmọ Malkiah
41 Fils d’Athanaï, fils de Zara, fils d’Adaïa,
ọmọ Etini, ọmọ Sera, ọmọ Adaiah,
42 Fils d’Ethan, fils de Zamma, fils de Séméi,
ọmọ Etani, ọmọ Simma, ọmọ Ṣimei,
43 Fils de Jeth, fils de Gerson, fils de Lévi;
ọmọ Jahati, ọmọ Gerṣoni, ọmọ Lefi;
44 Mais les fils de Mérari, leurs frères, qui se tenaient à la gauche, étaient: Ethan, fils de Cusi, fils d’Abdi, fils de Maloch,
láti ìbákẹ́gbẹ́ wọn, àwọn ará Merari wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀: Etani ọmọ Kiṣi, ọmọ Abdi, ọmọ Malluki,
45 Fils d’Hasabias, fils d’Amasias, fils d’Helcias,
ọmọ Haṣabiah, ọmọ Amasiah, ọmọ Hilkiah,
46 Fils d’Amasaï, fils de Boni, fils de Somer,
ọmọ Amisi, ọmọ Bani, ọmọ Ṣemeri,
47 Fils de Moholi, fils de Musi, fils de Mérari, fils de Lévi.
ọmọ Mahili, ọmọ Muṣi, ọmọ Merari, ọmọ Lefi.
48 Les Lévites, leurs frères, étaient aussi désignés pour tout le service du tabernacle de la maison du Seigneur.
Àwọn Lefi ẹgbẹ́ wọn ni wọn yan àwọn iṣẹ́ yòókù ti àgọ́ fún, èyí tí í ṣe ilé Ọlọ́run.
49 Mais Aaron et ses fils offraient ce qui se brûle sur l’autel de l’holocauste et sur l’autel du parfum, pour toute l’œuvre du Saint des Saints, et afin qu’ils priassent pour Israël, selon tout ce qu’avait ordonné Moïse, serviteur de Dieu.
Ṣùgbọ́n Aaroni àti àwọn ìran ọmọ rẹ̀ jẹ́ àwọn tí ó gbé ọrẹ kalẹ̀ lórí pẹpẹ ẹbọ sísun àti lórí pẹpẹ tùràrí ní ìbátan pẹ̀lú gbogbo ohun tí a ṣe ní Ibi Mímọ́ Jùlọ. Ṣíṣe ètùtù fún Israẹli, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run ti pàṣẹ.
50 Or ceux-ci sont les fils d’Aaron: Eléazar, son fils, dont le fils, Phinéès, dont le fils, Abisué,
Wọ̀nyí ni àwọn ìránṣẹ́ Aaroni: Eleasari ọmọ rẹ̀, Finehasi ọmọ rẹ̀, Abiṣua ọmọ rẹ̀,
51 Dont le fils, Bocci, dont le fils, Ozi, dont le fils, Zaraïas,
Bukki ọmọ rẹ̀, Ussi ọmọ rẹ̀, Serahiah ọmọ rẹ̀,
52 Dont le fils, Méraïoth, dont le fils, Amarias, dont le fils, Achitob,
Meraioti ọmọ rẹ̀, Amariah ọmọ rẹ̀, Ahitubu ọmọ rẹ̀,
53 Dont le fils, Sadoc, dont le fils Achimaas.
Sadoku ọmọ rẹ̀ àti Ahimasi ọmọ rẹ̀.
54 Et voici leurs habitations dans les bourgs et les environs, c’est-à-dire les habitations des enfants d’Aaron, selon les familles des Caathites; car c’est à eux qu’elles étaient échues par le sort.
Wọ̀nyí ni ibùgbé wọn tí a pín fún wọn gẹ́gẹ́ bí agbègbè wọn (tí a fi lé àwọn ìran ọmọ Aaroni lọ́wọ́ tí ó wá láti ẹ̀yà Kohati, nítorí kèké alákọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
55 On leur donna donc Hébron, dans la terre de Juda, et ses faubourgs tout autour;
A fún wọn ní Hebroni ní Juda pẹ̀lú àyíká pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
56 Mais les campagnes de la ville et les villages, on les donna à Caleb, fils de Jéphoné.
Ṣùgbọ́n àwọn pápá àti ìletò tí ó yí ìlú ńlá náà ká ni a fi fún Kalebu ọmọ Jefunne.
57 Quant aux fils d’Aaron, on leur donna les villes de refuge, Hébron, et Lobna et ses faubourgs;
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìran ọmọ Aaroni ni a fún ní Hebroni (ìlú ti ààbò), àti Libina, Jattiri, Eṣitemoa,
58 Jéther aussi et Esthémo, avec leurs faubourgs; et même Hélon et Dabir, avec leurs faubourgs,
Hileni, Debiri,
59 Et encore Asan et Bethsémès, et leurs faubourgs;
Aṣani, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
60 Et de la tribu de Benjamin, Gabée et ses faubourgs, Almath avec ses faubourgs, comme aussi Anathoth avec ses faubourgs; en tout, treize villes, selon leurs familles.
Àti láti inú ẹ̀yà Benjamini, a fún wọn ní Gibeoni, Geba, Alemeti àti Anatoti lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn. Àwọn ìlú wọ̀nyí, tí a pín láàrín àwọn ẹ̀yà Kohati jẹ́ mẹ́tàlá ní gbogbo rẹ̀.
61 Mais aux enfants de Caath, qui restaient de sa famille, on donna en possession, sur la demi-tribu de Manassé, dix villes;
Ìyókù àwọn ìran ọmọ Kohati ní a pín ìlú mẹ́wàá fún láti àwọn ìdílé ní ti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase.
62 Et aux enfants de Gersom, selon leurs familles, sur la tribu d’Issachar, sur la tribu d’Aser, sur la tribu de Nephthali, et sur la tribu de Manassé, en Basan, treize villes.
Àwọn ìran ọmọ Gerṣoni, sí ìdílé ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ẹ̀yà àwọn ẹ̀yà Isakari, Aṣeri àti Naftali, àti láti apá ẹ̀yà Manase tí ó wà ní Baṣani.
63 Quant aux enfants de Mérari, on leur donna par le sort, selon leurs familles, sur la tribu de Ruben, sur la tribu de Gad, et sur la tribu de Zabulon, douze villes.
Sebuluni àwọn ìran ọmọ Merari, ìdílé sí ìdílé, ní a pín ìlú méjìlá fún láti ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
64 Ainsi les enfants d’Israël donnèrent aux Lévites ces villes et leurs faubourgs;
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli fún àwọn ará Lefi ní ìlú wọ̀nyí pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
65 Et ils donnèrent par le sort sur la tribu des enfants de Juda, et sur la tribu des enfants de Siméon, et sur la tribu des enfants de Benjamin, ces mêmes villes qu’ils appelèrent de leurs noms,
Láti ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini ni a pín ìlú tí a ti dárúkọ wọn sẹ́yìn fún.
66 Et pour ceux qui étaient de la famille des enfants de Caath, il y eut des villes dans leur territoire de la tribu d’Ephraïm.
Lára àwọn ìdílé Kohati ni a fún ní ìlú láti ẹ̀yà Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìlú agbègbè wọn.
67 Ils leur donnèrent donc j des villes de refuge, Sichem avec ses faubourgs, dans la montagne d’Ephraïm, et Gazer avec ses faubourgs;
Ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, a fún wọn ní Ṣekemu (ìlú ńlá ti ààbò), àti Geseri
68 Jecmaam aussi avec ses faubourgs, et Béthoron également;
Jokimeamu, Beti-Horoni.
69 En outre, Hélon avec ses faubourgs, et Gethremmon de la même manière.
Aijaloni àti Gati-Rimoni lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
70 Mais sur la demi-tribu de Manassé, Aner et ses faubourgs, et Baalam et ses faubourgs, furent donnés, savoir, à ceux qui restaient de la famille de Caath.
Pẹ̀lú láti apá ààbọ̀ ẹ̀yà Manase àwọn ọmọ Israẹli fún Aneri àti Bileamu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn, fún ìyókù àwọn ìdílé Kohati.
71 Et aux enfants de Gersom, sur la famille de la demi-tribu de Manassé, ce fut Gaulon en Basan et ses faubourgs, et Astharoth avec ses faubourgs,
Àwọn ará Gerṣoni gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ààbọ̀ ẹ̀yà ti Manase wọ́n gba Golani ní Baṣani àti pẹ̀lú Aṣtarotu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù wọn.
72 Sur la tribu d’Issachar, Cédés et ses faubourgs, et Dabéreth avec ses faubourgs;
Láti ẹ̀yà Isakari wọ́n gba Kedeṣi, Daberati
73 Ramoth aussi et ses faubourgs, et Anem avec ses faubourgs;
Ramoti àti Anenu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
74 Mais sur la tribu d’Aser, Masal avec ses faubourgs, et Abdon également;
Láti ẹ̀yà Aṣeri wọ́n gba Maṣali, Abdoni,
75 Hucac aussi et ses faubourgs, et Rohob avec ses faubourgs;
Hukoki àti Rehobu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
76 Mais sur la tribu de Nephthali, Cédés en Galilée et ses faubourgs, Hamon avec ses faubourgs, et Cariathaïm et ses faubourgs.
Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Naftali wọ́n gba Kedeṣi ní Galili, Hammoni àti Kiriataimu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
77 De plus, aux enfants de Mérari, qui restaient encore, furent donnés, sur la tribu de Zabulon, Remmono et ses faubourgs, et Thabor avec ses faubourgs;
Àwọn ará Merari (ìyókù àwọn ará Lefi) gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ẹ̀yà Sebuluni wọ́n gba Jokneamu, Karta, Rimoni àti Tabori, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
78 Au delà du Jourdain, vis-à-vis de Jéricho, contre l’orient du Jourdain, ce fut sur la tribu de Ruben: Bosor, dans le désert, avec ses faubourgs, et Jassa avec ses faubourgs;
Láti ẹ̀yà Reubeni rékọjá Jordani ìlà-oòrùn Jeriko wọ́n gba Beseri nínú aginjù Jahisa,
79 Cadémoth aussi et ses faubourgs, et Méphaat avec ses faubourgs;
Kedemoti àti Mefaati, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
80 De même que sur la tribu de Gad, Ramoth en Galaad et ses faubourgs, et Manaïm avec ses faubourgs;
Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Gadi wọ́n gba Ramoti ní Gileadi Mahanaimu,
81 Et de plus, Hésébon avec ses faubourgs, et Jézer avec ses faubourgs.
Heṣboni àti Jaseri lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.