< 1 Chroniques 5 >

1 Voici les fils de Ruben, premier-né d’Israël (car c’est lui qui était son premier-né; mais lorsqu’il eut violé le lit nuptial de son père, son droit d’aînesse fut donné aux fils de Joseph, fils d’Israël; et Ruben ne fut plus réputé premier-né.
Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí.
2 Quant à Juda, qui était le plus vaillant parmi ses frères, des princes ont germé de son tronc; mais le droit d’aînesse fut attribué à Joseph).
Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu),
3 Voici donc les fils de Ruben, premier-né d’Israël: Enoch et Phallu, Esron et Carmi.
àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku àti Pallu, Hesroni àti Karmi.
4 Les fils de Joël: Samaïa, dont le fils, Gog, dont le fils, Séméi,
Àwọn ọmọ Joẹli: Ṣemaiah ọmọ rẹ̀, Gogu ọmọ rẹ̀, Ṣimei ọmọ rẹ̀.
5 Dont le fils, Micha, dont le fils, Réia, dont le fils, Baal,
Mika ọmọ rẹ̀, Reaiah ọmọ rẹ̀, Baali ọmọ rẹ̀.
6 Dont le fils, Bééra, que Thelgathphalnasar, roi des Assyriens, emmena captif, et qui fut prince dans la tribu de Ruben.
Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.
7 Mais ses frères et toute sa parenté, quand ils furent dénombrés, avaient pour chefs Jéhiel et Zacharie.
Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn: Jeieli àti Sekariah ni olórí,
8 Or Bala, fils d’Azaz, fils de Samma, fils de Joël, habita lui-même à Aroër, jusqu’à Nébo et Béelméon.
àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joẹli. Wọ́n tí ń gbé Aroeri àní títí dé Nebo àti Baali-Meoni.
9 Il habita aussi contre le côté oriental jusqu’à l’entrée du désert et jusqu’au fleuve d’Euphrate; car ils possédaient un grand nombre de bestiaux dans la terre de Galaad.
Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.
10 Mais, dans les jours de Saül, ils combattirent contre les Agaréens, les tuèrent et habitèrent en leur place dans leurs tabernacles, dans toute la contrée qui regarde Galaad.
Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.
11 Quant aux enfants de Gad, ils habitèrent vis-à-vis d’eux dans la terre de Basan, jusqu’à Selcha.
Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:
12 Joël était à la tête, et Saphan, le second; mais Janaï et Saphat dans Basan.
Joẹli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ Janai, àti Ṣafati ni Baṣani.
13 Et leurs frères, selon les maisons de leur parenté, étaient Michaël, Mosollam, Sébé, Joraï, Jachan, Zié et Héber, sept en tout.
Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní: Mikaeli, Meṣullamu Ṣeba, Jorai, Jaka, Sia àti Eberi méje.
14 Ceux-ci furent fils d’Abihaïl, fils d’Huri, fils de Jara, fils de Galaad, fils de Michaël, fils de Jésési, fils de Jeddo, fils de Buz.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado, ọmọ Busi.
15 Leurs frères furent encore les fils d’Abdiel, fils de Guni, chacun chef de maison dans ses familles.
Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.
16 Et ils habitèrent en Galaad, dans Basan, et ses bourgades, et dans tous les faubourgs de Saron, jusqu’aux limites.
Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.
17 Tous ceux-ci furent dénombrés dans les jours de Joathan, roi de Juda, et dans les jours de Jéroboam, roi d’Israël.
Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.
18 Les enfants de Ruben, de Gad, et de la demi-tribu de Manassé, furent des gens de guerre, portant des boucliers et des glaives, tendant l’arc, et formés aux combats, au nombre de quarante-quatre mille sept cent soixante, marchant à la bataille.
Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì ènìyàn, tí ó jáde lọ sí ogún náà.
19 Ils combattirent contre les Agaréens; mais les Ituréens, Naphis et Nodab
Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu.
20 Leur donnèrent du secours. Et les Agaréens furent livrés entre leurs mains, ainsi que tous ceux qui avaient été avec eux, parce qu’ils invoquèrent Dieu, lorsqu’ils combattaient; et il les exauça, parce qu’ils avaient cru en lui.
Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
21 Et ils prirent tout ce que possédaient ces peuples: cinquante mille chameaux, deux cent cinquante mille brebis, deux mille ânes, et cent mille âmes d’hommes.
Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún.
22 De plus, beaucoup de blessés succombèrent: car c’était la guerre du Seigneur. Et ils habitèrent là en leur place jusqu’à la transmigration.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.
23 Les enfants de la demi-tribu de Manassé aussi possédèrent le pays depuis les confins de Basan jusqu’à Baal, Hermon et Sanir, et la montagne d’Hermon, parce que leur nombre était grand.
Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.
24 Et voici les princes de la maison de leur parenté: Epher, Jési, Eliel, Ezriel, Jérémie, Odoïa, et Jédiel, hommes très braves, et puissants, et princes renommés dans leurs familles.
Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.
25 Cependant ils abandonnèrent le Dieu de leurs pères, et forniquèrent, en allant après les dieux des peuples de ce pays que Dieu avait détruits devant eux.
Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.
26 Mais le Dieu d’Israël suscita l’esprit de Phul, roi des Assyriens, et l’esprit de Thelgathphalnasar, roi d’Assur; et il transféra Ruben, Gad et la demi-tribu de Manassé, et les emmena à Lahéla, à Habor, à Ara, et sur le fleuve de Gozan, jusqu’à ce jour.
Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (èyí ni Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.

< 1 Chroniques 5 >