< 1 Chroniques 28 >

1 David convoqua donc tous les princes d’Israël, les chefs des tribus et les préposés de ses troupes, lesquels servaient le roi; comme aussi les tribuns et les centurions, et ceux qui étaient à la tête des biens et des possessions du roi, ses enfants avec les eunuques, les puissants; de même que les plus vigoureux dans l’armée, et les réunit à Jérusalem.
Dafidi pe gbogbo àwọn oníṣẹ́ ti Israẹli láti péjọ ní Jerusalẹmu. Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà, àwọn alákòóso ìpín nínú iṣẹ́ bí ọba, àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn oníṣẹ́ tí ó wà ní ìdí bíbojútó gbogbo àwọn ẹrù àti ohun ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú ààfin àwọn oníṣẹ́ ààfin, àwọn ọkùnrin alágbára àti gbogbo àwọn ògbójú jagunjagun lápapọ̀.
2 Alors le roi, s’étant levé et se tenant debout, dit: Ecoutez-moi, mes frères et mon peuple: j’ai pensé à bâtir une maison dans laquelle reposerait l’arche de l’alliance du Seigneur, l’escabeau des pieds de notre Dieu, et, pour la bâtir, j’ai tout préparé.
Ọba Dafidi dìde dúró ní ẹsẹ̀ rẹ̀, o sì wí pé, “Fetísílẹ̀ sí mi, ẹ̀yin ará mi àti ẹ̀yin ènìyàn mi. Èmi ní o ni lọ́kàn mi láti kọ́ ilé gẹ́gẹ́ bí ibi ìsinmi fún àpótí ẹ̀rí tí Olúwa fún àpótí ìtìsẹ̀ Ọlọ́run wa, èmi sì gbèrò láti kọ́ ọ.
3 Mais Dieu m’a dit: Tu ne bâtiras point une maison à mon nom, parce que tu es un homme de guerre, et que tu as versé le sang.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ ilé fún orúkọ mi, nítorí ìwọ jẹ́ jagunjagun, ìwọ sì ti tàjẹ̀ sílẹ̀.’
4 Cependant le Seigneur Dieu d’Israël m’a choisi dans toute la maison de mon père pour que je fusse roi sur Israël à jamais; car c’est dans Juda qu’il a choisi des princes: en outre c’est dans la maison de Juda qu’il a choisi la maison de mon père, et entre les fils de mon père, il lui a plu de me choisir pour roi sur tout Israël.
“Síbẹ̀ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli yàn mí láti gbogbo ìdílé láti jẹ́ ọba lórí Israẹli, títí láé. Ó yan Juda gẹ́gẹ́ bí olórí, àti láti ilé Juda, ó yan ìdílé mi, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ baba à mí, ó tẹ́ Ẹ lọ́rùn láti fi mí ṣe ọba lórí gbogbo Israẹli.
5 Mais c’est aussi parmi mes fils (car le Seigneur m’a donné beaucoup de fils) qu’il a choisi Salomon, mon fils, pour qu’il s’assît sur le trône du règne du Seigneur sur Israël;
Nínú gbogbo àwọn ọmọ mi pẹ̀lú Olúwa ti fún mi ní púpọ̀, ó ti yan ọmọ mi Solomoni láti jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba ti Olúwa lórí Israẹli.
6 Et il m’a dit: Salomon, ton fils, bâtira ma maison et mes parvis; car c’est lui que j’ai choisi pour mon fils, et c’est moi qui serai son père.
Ó wí fún mi pé, Solomoni ọmọ rẹ ni ẹni tí yóò kọ́ ilé mi àti àwọn ààfin mi, nítorí tí èmi ti yàn án láti ṣe ọmọ mi èmi yóò sì jẹ́ baba a rẹ̀.
7 Et j’affermirai son règne à jamais, s’il persévère à accomplir mes préceptes et mes ordonnances comme aujourd’hui même.
Èmi yóò fi ìdí ìjọba rẹ̀ kalẹ̀ títí láé tí kò bá kọ̀ láti gbé àṣẹ àti òfin mi jáde, gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe é ní àsìkò yìí.
8 Maintenant donc, devant toute l’assemblée d’Israël, et notre Dieu l’entendant, gardez et recherchez tous les commandements du Seigneur notre Dieu, afin que vous possédiez la terre qui est remplie de biens, et que vous la laissiez à vos fils après vous pour jamais.
“Bẹ́ẹ̀ ni, nísinsin yìí, èmi pàṣẹ fún ọ ní ojú gbogbo Israẹli àti ní ti ìpéjọpọ̀ tí Olúwa, àti ní etí ìgbọ́ Ọlọ́run wa. Ṣọ́ra kó o sì tẹ̀lé gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ kí ìwọ kí ó le jogún ilẹ̀ dáradára yìí, kí o sì mú un lọ síwájú gẹ́gẹ́ bí ogún rẹ fún àwọn ìran ọmọ rẹ títí láé.
9 Et toi, Salomon, mon fils, connais le Dieu de ton père, et sers-le, avec un cœur parfait et un esprit qui agit volontairement; car le Seigneur scrute tous les cœurs et pénètre toutes les pensées des esprits. Si tu le cherches, tu le trouveras; mais si tu l’abandonnes, il te rejettera pour jamais.
“Àti ìwọ, ọmọ mi Solomoni, rántí Ọlọ́run baba à rẹ, kí o sì sìn ín pẹ̀lú tọkàntọkàn pẹ̀lú ìfọkànsí pẹ̀lú ọkàn tí ó pé, nítorí Olúwa ṣàwárí gbogbo ọkàn ó sì mọ gbogbo èrò. Tí ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i; ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ títí láé.
10 Maintenant donc que le Seigneur t’a choisi pour bâtir la maison du sanctuaire, sois fort, et agis.
Gbèrò báyìí nítorí tí Olúwa ti yàn ọ́ láti kọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ilé tí a yà sí mímọ́ fún Olúwa. Jẹ́ alágbára kí ó sì ṣe iṣẹ́ náà.”
11 Or David donna à Salomon, son fils, le plan du portique du temple, des celliers, du cénacle, des chambres secrètes, de la maison de propitiation;
Nígbà náà ni Dafidi fi àpẹẹrẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀ ti ìloro àti ti ilé Olúwa náà, kíkọ́ ọ rẹ̀, àti ti ibi ìṣúra rẹ̀, àti ti iyàrá òkè rẹ̀, àti ti ìyẹ̀wù rẹ̀ àti ti ibùjókòó àánú.
12 Comme aussi de tous les parvis qu’il avait en vue, des chambres tout autour, pour les trésors de la maison du Seigneur, et pour les trésors des choses saintes;
Ó fún un ní àwọn ètò gbogbo èyí tí ẹ̀mí ti fi sí ọkàn rẹ̀ fún ti ààfin ilé Olúwa àti gbogbo yàrá tí ó yíká fún ìṣúra ilé Ọlọ́run àti fún ìṣúra fún ohun yíyà sọ́tọ̀.
13 De la distribution des prêtres et des Lévites pour tous les ouvrages de la maison du Seigneur, et pour le soin de tous les vases consacrés au service du temple du Seigneur.
Ó fún un ní àwọn ìlànà fún ìpín ti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti fún gbogbo iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa àti fún gbogbo ohun èlò tí wọn ó lò nínú ìsìn rẹ̀.
14 Il lui donna l’or, selon le poids voulu, pour chaque vase de service; de plus, le poids de l’argent, selon la diversité des vases et des ouvrages en argent,
Ó yàn ìwọ̀n wúrà fún gbogbo ohun èlò wúrà tí a ó lò níbi oríṣìí ìsìn, àti ìwọ̀n fàdákà fún gbogbo ohun èlò fàdákà tí a ó lò fún oríṣìí ìsìn,
15 Et encore l’or pour les chandeliers d’or et pour leurs lampes, selon la mesure de chaque chandelier et des lampes. De même aussi pour les chandeliers d’argent et pour leurs lampes, il remit le poids de l’argent, selon la diversité de leur mesure.
ìwọ̀n wúrà fún ìdúró fìtílà àti fìtílà wọn, fún ìwọ̀n fún ọ̀kọ̀ọ̀kan ìdúró fìtílà àti fìtílà wọn; àti ìwọ̀n fàdákà ìdúró fìtílà fàdákà àti àwọn fìtílà rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlò ti gbogbo ìdúró fìtílà.
16 Il donna encore l’or pour les tables de proposition, selon la diversité des tables, et également de l’argent, pour les autres tables d’argent.
Ìwọ̀n ti wúrà fun tábìlì, tábìlì fún àkàrà tí a yà sọ́tọ̀; ìwọ̀n fàdákà fún àwọn tábìlì fàdákà;
17 De plus, pour les fourchettes, les fioles, les encensoirs d’un or très pur, et pour les petits lions, il distribua le poids pour chaque petit lion, selon la grandeur de leur mesure. De même aussi pour les lions d’argent, il mit à part un poids d’argent différent.
ìwọ̀n kìkì wúrà fún àwọn àmúga ìjẹun, àwọn ìbùwọ́n ọpọ́n àti àwọn ìkòkò ìpọnmi; ìwọ̀n wúrà fún gbogbo àwopọ̀kọ́ fàdákà;
18 Mais pour l’autel sur lequel se brûle le parfum, il donna de l’or très pur, pour qu’on en fît une représentation du quadrige et des chérubins, étendant leurs ailes et couvrant l’arche de l’alliance du Seigneur.
àti ìwọ̀n ìdá wúrà fún pẹpẹ tùràrí ó fún un ní ètò fún kẹ̀kẹ́, ìyẹn ni pé àwọn ìdúró kérúbù wúrà tí wọ́n tan iye wọn ká, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí Olúwa.
19 Toutes ces choses, dit David, me sont venues écrites de la main du Seigneur, afin que je comprisse tous les ouvrages de ce modèle.
“Gbogbo èyí,” ni Dafidi wí pé, “Èmi ní kíkọ sílẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa sórí mi, ó sì fún mí ní ìmọ̀ nínú gbogbo iṣẹ́ ètò yìí.”
20 David dit encore à Salomon, son fils: Agis courageusement, fortifie-toi, et fais; ne crains point et ne t’épouvante pas; car le Seigneur mon Dieu sera avec toi: il ne te laissera et ne t’abandonnera point que tu n’aies achevé tous les ouvrages pour le service de la maison du Seigneur.
Dafidi tún sọ fún Solomoni ọmọ rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára kí o sì gbóyà, kí o sì ṣe iṣẹ́ náà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí dààmú, nítorí Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run mi, wà pẹ̀lú rẹ. Òun kì yóò sì já ọ kule tàbí kọ ọ sílẹ̀ títí gbogbo iṣẹ́ fún ìsìn ní ti ilé Olúwa yóò fi parí.
21 Voilà la division des prêtres et des Lévites, lesquels sont auprès de toi pour tous les services de la maison du Seigneur; ils sont prêts, et ils savent accomplir tes ordres, les princes aussi bien que le peuple.
Ìpín àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ṣetán fún gbogbo iṣẹ́ ilé Olúwa. Gbogbo ọkùnrin tí ó ní ìfẹ́ sí i tí ó sì ní òye oríṣìíríṣìí iṣẹ́. Yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ náà. Àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn yóò gbọ́rọ̀ sí gbogbo àṣẹ rẹ.”

< 1 Chroniques 28 >