< 1 Chroniques 18 >

1 Or il arriva après cela que David battit les Philistins et les humilia, qu’il enleva Geth et ses filles de la main des Philistins,
Ní àkókò kan, Dafidi kọlu àwọn ará Filistini, ó sì ṣẹ́gun wọn. Ó sì mú Gati àti àwọn ìletò agbègbè rẹ̀ kúrò lábẹ́ ìdarí àwọn ará Filistini.
2 Qu’il battit aussi Moab, et que les Moabites devinrent serviteurs de David, lui offrant des présents.
Dafidi borí àwọn ará Moabu, wọ́n sì di ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n sì mú owó òde wá.
3 En ce temps, David battit encore Adarézer, roi de Soba, contrée d’Hémath, lorsqu’il alla pour étendre son empire jusqu’au fleuve d’Euphrate.
Síbẹ̀, Dafidi sì kọlu Hadadeseri ọba Soba ní Hamati, bí ó ti ń lọ láti fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ létí odò Eufurate.
4 David lui prit donc mille quadriges, et sept mille cavaliers, et vingt mille hommes de pied; il coupa les nerfs des jambes à tous les chevaux des chariots, excepté cent quadriges qu’il réserva pour lui.
Dafidi fi agbára gba ẹgbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ àti ogún ẹgbẹ̀rún ológun ilẹ̀. Ó sì já gbogbo ọgọ́rùn-ún iṣan ẹsẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin náà.
5 Or vint encore le Syrien de Damas, pour porter secours à Adarézer, roi de Soba; mais David lui tua aussi vingt-deux mille hommes.
Nígbà ti àwọn ará Siria ti Damasku wá láti ran Hadadeseri ọba Soba lọ́wọ́, Dafidi lu ẹgbẹ̀rún méjìlélógún wọn bọ lẹ̀.
6 Et il mit des soldats dans Damas, pour que la Syrie aussi lui fût assujettie et offrît des présents. Et le Seigneur l’assista dans tous les lieux où il alla.
Ó sì fi àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ sínú ìjọba Siria ti Damasku, àwọn ará Siria sì ń sìn ní abẹ́ rẹ̀, wọ́n sì mú owó ìṣákọ́lẹ̀ wá. Olúwa sì ń fún Dafidi ní ìṣẹ́gun ní ibi gbogbo tí ó bá lọ.
7 David prit aussi les carquois d’or qu’avaient les serviteurs d’Adarézer, et il les porta à Jérusalem;
Dafidi mú àpáta wúrà tí àwọn ìjòyè Hadadeseri gbé, ó sì gbé wọn wá sí Jerusalẹmu.
8 Et, de plus, une grande quantité d’airain de Thébath et de Chun, villes d’Adarézer, avec quoi Salomon fit la mer d’airain, et les colonnes, et les vases d’airain.
Láti Tibhati àti Kuni, àwọn ìlú Hadadeseri, Dafidi kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ idẹ tí Solomoni lò láti fi ṣe okùn idẹ, àwọn òpó àti oríṣìí ohun èlò idẹ.
9 Or, lorsque Thoü, roi d’Hémath, eut appris que David avait battu toute l’armée d’Adarézer, roi de Soba,
Nígbà tí Tou ọba Hamati gbọ́ pé Dafidi ti borí gbogbo ọmọ-ogun Hadadeseri ọba Soba.
10 Il envoya Adoram, son fils, au roi David, pour lui demander la paix, et lui témoigner sa joie de ce qu’il avait battu et vaincu entièrement Adarézer; car Thoü était ennemi d’Adarézer.
Ó rán ọmọ rẹ̀ Hadoramu sí ọba Dafidi láti kí i àti láti lọ bá a yọ̀ lórí ìṣẹ́gun rẹ̀ nínú ogun lórí Hadadeseri, tí ó wà lójú ogun pẹ̀lú Tou. Hadoramu mú oríṣìíríṣìí ohun èlò ti wúrà àti fàdákà àti idẹ wá.
11 Mais quant à tous les vases d’or, d’argent et d’airain, David, le roi, les consacra au Seigneur avec l’argent et l’or qu’il avait pris sur toutes les nations, tant sur l’Iduméen, Moab et les enfants d’Ammon, que sur les Philistins et Amalec.
Ọba Dafidi ya ohun èlò wọ́n yí sí mímọ́ fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe pẹ̀lú fàdákà àti wúrà tí ó ti mú láti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí: Edomu àti Moabu, ará Ammoni àti àwọn ará Filistini àti Amaleki.
12 De plus, Abisaï, fils de Sarvia, battit Edom dans la vallée des Salines; c’est-à-dire dix-huit mille Iduméens.
Abiṣai ọmọ Seruiah lu ẹgbàá mẹ́sàn ará Edomu bolẹ̀ ní àfonífojì Iyọ̀.
13 Et il établit en Edom une garnison, pour que l’Idumée fût assujettie à David; et le Seigneur conserva David dans tous les lieux où il alla.
Ó fi ẹgbẹ́ ogun sí Edomu, gbogbo àwọn ará Edomu sì ń sìn ní abẹ́ Dafidi. Olúwa fún Dafidi ní ìṣẹ́gun ní gbogbo ibí tí ó bá lọ.
14 David régna donc sur tout Israël, et il rendait des jugements et la justice à tout son peuple.
Dafidi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli, ó sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Mais Joab, fils de Sarvia, commandait l’armée; et Josaphat, fils d’Ahilud, tenait les registres.
Joabu ọmọ Seruiah jẹ́ olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi jẹ́ akọ̀wé ìrántí;
16 Et Sadoc, fils d’Achitob, et Abimélech, fils d’Abiathar, étaient prêtres, et Susa, scribe.
Sadoku ọmọ Ahitubu àti Abimeleki ọmọ Abiatari jẹ́ àwọn àlùfáà; Ṣafṣa jẹ́ akọ̀wé;
17 Mais Banaïas, fils de Joïada, commandait les légions des Céréthiens et des Phélétiens; mais les fils de David étaient les premiers auprès du roi.
Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ́ olórí àwọn Kereti àti Peleti; àwọn ọmọ Dafidi sì ni àwọn olóyè oníṣẹ́ ní ọ̀dọ̀ ọba.

< 1 Chroniques 18 >