< 1 Chroniques 13 >

1 Or David tint conseil avec les tribuns, les centurions et tous les princes,
Dafidi sì gbèrò pẹ̀lú olúkúlùkù àwọn ìjòyè rẹ̀, àwọn aláṣẹ ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn aláṣẹ ọgọ́rùn-ún
2 Et il dit à toute l’assemblée d’Israël: Si elles vous plaisent, et si c’est du Seigneur, notre Dieu, qu’elles viennent, les paroles que je vais dire, envoyons à nos autres frères dans toutes les contrées d’Israël, et aux prêtres et aux Lévites qui habitent dans les faubourgs des villes, afin qu’ils s’assemblent près de nous,
Dafidi sì wí fún gbogbo àwọn ìjọ Israẹli pé, tí ó bá dára lójú yín àti tí ó bá ṣe jẹ́ àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa, jẹ́ kí a ránṣẹ́ sí ọ̀nà jíjìn àti gbígbòòrò sí àwọn arákùnrin wa tókù ní gbogbo àwọn agbègbè ìlú Israẹli àti pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn nínú ìlú wọn àti pápá oko tútù, láti wá kó ara wọn jọ pọ̀ sọ́dọ̀ wa.
3 Et que nous ramenions l’arche de notre Dieu chez nous; car nous ne nous en sommes pas occupés aux jours de Saül.
Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa padà sọ́dọ̀ wa, nítorí wí pé àwa kò ṣe ìwádìí nípa rẹ̀ ní àsìkò ìjọba Saulu.
4 Et toute la multitude répondit, qu’il en fût ainsi; car ce discours avait plu à tout le peuple.
Gbogbo ìjọ náà sì gbà láti ṣe èyí nítorí ó dàbí wí pé ó tọ lójú gbogbo àwọn ènìyàn.
5 David rassembla donc tout Israël, depuis Sihor d’Egypte jusqu’à l’entrée d’Emath, afin que l’on ramenât l’arche de Dieu de Cariathiarim.
Nígbà náà ni Dafidi pe gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ, láti ọ̀dọ̀ Ṣihori ní Ejibiti lọ sí Lebo ní ọ̀nà à bá wọ Hamati, láti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run padà láti Kiriati-Jearimu.
6 Et David monta, et tout homme d’Israël, vers la colline de Cariathiarim, qui est en Juda; pour en apporter l’arche du Seigneur Dieu, assis sur les chérubins, où son nom a été invoqué.
Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ lọ sí Baalahi ti Juda (Kiriati-Jearimu) láti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run Olúwa tí a fi orúkọ rẹ̀ pè, tí ó jókòó láàrín kérúbù gòkè wá.
7 On mit donc l’arche de Dieu sur un char neuf, en la retirant de la maison d’Abinadab: et Oza et son frère conduisaient le char.
Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run láti ilé Abinadabu lórí kẹ̀kẹ́ tuntun, Ussa àti Ahio ń ṣọ́ ọ.
8 Or David et tout Israël jouaient devant Dieu de toute leur force, au milieu des cantiques, des harpes, des psaltérions, des tambours, des cymbales et des trompettes.
Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ni wọ́n ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú gbogbo agbára wọn níwájú Ọlọ́run, pẹ̀lú orin àti pẹ̀lú dùùrù, ohun èlò orin olókùn, tambori, kimbali pẹ̀lú ìpè.
9 Mais, lorsqu’on fut parvenu à l’aire de Chidon, Oza tendit sa main pour soutenir l’arche; car un bœuf bondissant l’avait fait un peu pencher.
Nígbà tí wọ́n dé sí ilẹ̀ ìpakà Kidoni, Ussa sì na ọwọ́ rẹ̀ síta láti di àpótí ẹ̀rí Olúwa mú, nítorí màlúù kọsẹ̀.
10 C’est pourquoi le Seigneur fut irrité contre Oza, et le frappa, parce qu’il avait touché l’arche: et il mourut là devant le Seigneur.
Ìbínú Olúwa, sì ru sí Ussa, ó sì lù ú bolẹ̀ nítorí o ti fi ọwọ́ rẹ̀ lórí àpótí ẹ̀rí. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kú síbẹ̀ níwájú Ọlọ́run.
11 Et David fut contristé de ce que le Seigneur avait divisé Oza; et il appela ce lieu: Division d’Oza, comme il a été appelé jusqu’au présent jour.
Nígbà náà Dafidi sì bínú nítorí ìbínú Olúwa ké jáde lórí Ussa, àti títí di òní, wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Peresi-Usa.
12 Et il craignit le Seigneur en ce moment-là, disant: Comment pourrai-je introduire chez moi l’arche de Dieu?
Dafidi sì bẹ̀rù Ọlọ́run ní ọjọ́ náà, ó sì béèrè pé, báwo ni èmi náà ó ṣe gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ mi?
13 Et pour ce motif, il ne la conduisit point chez lui, c’est-à-dire dans la cité de David: mais il la fit conduire en la maison d’Obédédom, le Géthéen.
Kò gbé àpótí ẹ̀rí náà wá sí ọ̀dọ̀ ará rẹ̀ ní ìlú ti Dafidi dípò èyí, ó sì gbé e yà sí ilé Obedi-Edomu ará Gitti.
14 L’arche de Dieu demeura ainsi dans la maison d’Obédédom pendant trois mois, et le Seigneur bénit sa maison et tout ce qu’il avait.
Àpótí ẹ̀rí Olúwa sì wà lọ́dọ̀ àwọn ará ilé Obedi-Edomu ní ilé rẹ̀ fún oṣù mẹ́ta, Olúwa sì bùkún agbo ilé àti gbogbo ohun tí ó ní.

< 1 Chroniques 13 >