< 1 Chroniques 12 >

1 Ceux-ci aussi vinrent vers David à Sicéleg, lorsqu’il fuyait encore Saül, fils de Cis; c’étaient des hommes très forts et d’excellents combattants,
Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin tí ó wá sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Siklagi, nígbà tí ó sá kúrò níwájú Saulu ọmọ Kiṣi (wọ́n wà lára àwọn jagunjagun ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti ibi ìjà.
2 Tendant l’arc, et des deux mains jetant les pierres de la fronde et dirigeant les flèches: ils étaient frères de Saül, de la tribu de Benjamin.
Wọ́n sì mú wọn pẹ̀lú ìtẹríba wọ́n sì lágbára láti ta ọfà tàbí láti ta kànnàkànnà òkúta ní ọwọ́ òsì tàbí ní ọwọ́ ọ̀tún, wọ́n sì jẹ́ ìbátan ọkùnrin Saulu láti ẹ̀yà Benjamini):
3 Le premier était Ahiézer, ensuite Joas, les fils de Samaa, le Gabaathite, puis Jaziel, et Phallet, les fils d’Azmoth, Baracha et Jéhu, l’Anathothite;
Ahieseri olórí wọn àti Joaṣi àwọn ọmọ Ṣemaah ará Gibeah: Jeṣieli àti Peleti ọmọ Asmafeti, Beraka, Jehu ará Anatoti.
4 De plus Samaïas, le Gabaonite, le plus vaillant parmi les trente, et qui les commandait; Jérémie, Jéhéziel, Johanan, et Jézabad, le Gadérothite;
Àti Iṣmaiah ará Gibeoni, ọkùnrin alágbára kan lára àwọn ọgbọ̀n ẹni tí ó jẹ́ olórí nínú àwọn ọgbọ̀n; Jeremiah, Jahasieli, Johanani, Josabadi ará Gedera,
5 Eluzaï, Jérimuth, Baalia, Samaria et Saphatia, l’Haruphite;
Elusai, Jerimoti, Bealiah, Ṣemariah àti Ṣefatia ará Harufiti;
6 Elcana, Jésia, Azaréel, Joézer, et Jesbaam de Caréhim;
Elkana, Iṣiah, Asareeli, Joeseri àti Jaṣobeamu ará Kora;
7 De plus Joéla et Zabadia, les fils de Jéroham, de Gédor.
àti Joẹla, àti Sebadiah àwọn ọmọ Jerohamu láti Gedori.
8 Mais d’entre les Gaddites aussi passèrent à David, lorsqu’il était caché dans le désert, des hommes très vigoureux, et excellents combattants, tenant un bouclier et une lance; leur face était comme la face d’un lion, et ils étaient agiles comme des chevreuils sur les montagnes.
Díẹ̀ lára àwọn ará Gadi yà sọ́dọ̀ Dafidi ní ibi gíga ní aginjù. Wọ́n sì jẹ́ onígboyà ológun tí ó múra fún ogun tí ó sì lágbára láti di asà àti ẹṣin mú. Ojú wọn sì dàbí ojú kìnnìún, wọ́n sì yára bí àgbọ̀nrín lórí àwọn òkè.
9 Ezer était le premier, Obdias, le second, Eliab, le troisième,
Eseri sì jẹ́ ìjòyè, Obadiah sì jẹ́ igbákejì akọgun, Eliabu ẹlẹ́ẹ̀kẹta,
10 Masmana, le quatrième, Jérémie, le cinquième,
Miṣimana ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀karùnún
11 Ethi, le sixième, Eliel, le septième,
Attai ẹlẹ́ẹ̀kẹfà, Elieli èkeje,
12 Johanan, le huitième, Elzébad, le neuvième,
Johanani ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ Elsabadi ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án
13 Jérémie, le dixième, Machbanaï, le onzième.
Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá àti Makbannai ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá.
14 Ceux-là, fils de Gad, étaient princes de l’armée: le moindre commandait cent soldats; et le plus grand, mille.
Àwọn ará Gadi wọ́n sì jẹ́ olórí ogun; ẹni tí ó kéré jù sì jẹ́ àpapọ̀ ọgọ́rùn-ún, àti fún ẹni tí ó pọ̀jù fún ẹgbẹ̀rún.
15 Ce sont eux qui passèrent le Jourdain au premier mois, quand il a accoutumé de déborder sur ses rives, et qui mirent en fuite tous ceux qui demeuraient dans les vallées, vers le côté oriental et occidental.
Àwọn ni ẹni tí ó rékọjá Jordani ní oṣù àkọ́kọ́ nígbà tí ó kún bo gbogbo bèbè rẹ̀, wọ́n sì lé gbogbo àwọn tí ó ń gbé nínú àfonífojì, lọ sí ìlà-oòrùn àti níhà ìwọ̀-oòrùn.
16 Il y en eut aussi qui vinrent même de Benjamin et de Juda dans la forteresse, dans laquelle se trouvait David.
Ìyókù ará Benjamini àti àwọn díẹ̀ ọkùnrin láti Juda lọ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní ibi gíga.
17 Et David sortit au-devant d’eux, et dit: Si c’est pacifiquement que vous êtes venus vers moi, afin de me secourir, que mon cœur s’unisse à vous; mais si vous me tendez un piège dans l’intérêt de mes ennemis, quoique je n’aie point d’iniquité en mes mains, que le Dieu de nos pères voie et juge.
Dafidi sì lọ láti lọ pàdé wọn ó sì wí fún wọn pé, “Tí ẹ bá wá sọ́dọ̀ mi lálàáfíà, láti ràn mí lọ́wọ́ mo ṣetán láti mú un yín wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú mi ṣùgbọ́n tí ẹ bá wá láti dá mi sí fún àwọn ọ̀tá mi nígbà tí ọwọ́ mi bá mọ́ kúrò nínú ìwà agbára, kí Ọlọ́run àwọn baba wa kí ó sì ri kí ó sì ṣe ìdájọ́.”
18 Alors un esprit remplit Amasaï, le premier entre les trente, et il répondit: Nous sommes à vous, ô David, et avec vous, ô fils d’Isaï. Paix, paix à vous, et paix à vos partisans! car votre Dieu vous aide. David les reçut donc et les établit chefs des troupes.
Nígbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ wa sórí Amasai ìjòyè àwọn ọgbọ̀n, ó sì wí pé, “Tìrẹ ni àwa ń ṣe, ìwọ Dafidi! Àwa pẹ̀lú rẹ, ìwọ ọmọ Jese! Àlàáfíà, àlàáfíà fún ọ, àti àlàáfíà fún àwọn tí ó ràn ó lọ́wọ́, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gbà wọ́n ó sì mú wọn jẹ olórí ẹgbẹ́ ogun.
19 Il y en eut aussi de Manassé qui passèrent à David, quand il venait avec les Philistins contre Saül pour se battre; mais il ne combattit pas avec eux, parce qu’un conseil ayant été tenu, les princes des Philistins le renvoyèrent, disant: Au péril de notre tête, il retournera vers son maître, Saül.
Díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin Manase sì yà sí ọ̀dọ̀ Dafidi nígbà tí ó lọ pẹ̀lú àwọn ará Filistini láti bá Saulu jà. (Òun àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ wọn kò sì ran ará Filistini lọ́wọ́ nítorí, lẹ́yìn tiwọn sọ̀rọ̀ papọ̀, àwọn olórí wọn rán wọn jáde, wọ́n sì wí pé, “Yóò jẹ́ ìparun fún wa tí ó bá padà tọ ọ̀gá rẹ̀ Saulu lọ.”)
20 Quand donc il revint à Sicéleg, passèrent à lui de Manassé, Ednas, Jozabad, Jédihel, Michaël, Ednas, Jozabad, Eliu et Salathi, chefs de mille soldats en Manassé.
Nígbà tí Dafidi lọ sí Siklagi, àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin ti Manase ẹni tí ó sì yà sọ́dọ̀ rẹ̀. Adina, Josabadi, Jediaeli, Mikaeli, Josabadi, Elihu àti Siletai, àwọn olórí ìrẹ́pọ̀ ti ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní Manase.
21 Ce sont eux qui donnèrent du secours à David contre les voleurs; car ils étaient tous des hommes très braves; et ils furent faits princes dans l’armée.
Wọ́n sì ran Dafidi lọ́wọ́ lórí ẹgbẹ́ ogun náà, nítorí gbogbo wọn ni akọni ènìyàn àwọn sì tún ni olórí nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
22 Enfin il venait tous les jours des troupes vers David, pour le secourir, jusque-là que leur grand nombre devint comme une armée de Dieu.
Ọjọ́ dé ọjọ́ ni àwọn ọkùnrin wá láti ran Dafidi lọ́wọ́, títí tí ó fi ní àwọn ológun ńlá, bí ogun Ọlọ́run.
23 Voici aussi le nombre des princes de l’armée qui vinrent vers David lorsqu’il était à Hébron, pour lui transférer le royaume de Saül, selon la parole du Seigneur:
Àwọn wọ̀nyí sì ni iye ọkùnrin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun àwọn ẹni tí ó wá sọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni láti yí ìjọba Dafidi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
24 Les fils de Juda, portant le bouclier et la lance, six mille huit cents, prêts au combat.
Ọkùnrin Juda, tí o ń gbé asà àti ọ̀kọ̀, ẹgbàáta lé lẹ́gbẹ̀rin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun.
25 D’entre les fils de Siméon, très braves pour combattre, sept mille cent.
Àwọn ọkùnrin Simeoni, akọni tó mú fún ogun sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ó lé ọgọ́rùn-ún;
26 D’entre les fils de Lévi, quatre mille six cents.
àwọn ọkùnrin Lefi ẹgbàajì ó le ẹgbẹ̀ta,
27 De plus, Joïada, prince de la race d’Aaron, et avec lui trois mille sept cents hommes.
pẹ̀lú Jehoiada, olórí ìdílé Aaroni pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn,
28 Sadoc aussi, jeune homme d’un excellent naturel, et la maison de son père, vingt-deux princes.
àti Sadoku akọni ọ̀dọ́mọkùnrin, pẹ̀lú àwọn méjìlélógún ìjòyè láti ọ̀dọ̀ àwọn ìdílé rẹ̀;
29 Mais d’entre les fils de Benjamin, frères de Saül, trois mille hommes; car une grande partie d’entre eux suivait encore la maison de Saül.
àwọn arákùnrin Benjamini ìbátan ọkùnrin Saulu ẹgbẹ̀rún mẹ́ta, ọ̀pọ̀ nínú àwọn ẹni tí ó si kù ní olóòtítọ́ sí ilé Saulu títí di ìgbà náà;
30 Et d’entre les fils d’Ephraïm, vingt mille huit cents, d’une très grande force, hommes renommés dans leur parenté.
àwọn arákùnrin Efraimu, ògbójú akọni, ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n nílé baba wọn ogún ẹgbẹ̀rún ó le ẹgbẹ̀rin;
31 Et de la demi-tribu de Manassé, dix-huit mille vinrent, chacun selon son nom, pour établir David roi.
àwọn ọkùnrin nínú ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, tí a yàn nípa orúkọ láti wá àti láti yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba, ẹgbàá mẹ́sàn.
32 Comme aussi il vint d’entre les fils d’Issachar des hommes instruits, qui connaissaient tous les temps, afin d’ordonner ce que devait faire Israël: les principaux étaient au nombre de deux cents, et tout le reste de leur tribu suivait leur conseil.
Àti ní ti àwọn ọmọ Isakari, àwọn ẹni tí ó ní òye àkókò, láti mọ ohun tí Israẹli ìbá máa ṣe; olórí wọn jẹ́ ìgbà; àti gbogbo àwọn ìbátan wọn ń bẹ ní ìkáwọ́ wọn.
33 Mais ceux de Zabulon qui sortaient pour le combat, et qui se tenaient dans la bataille munis d’armes guerrières, vinrent au nombre de cinquante mille au secours de David, sans duplicité de cœur.
Àwọn ọkùnrin Sebuluni, àti àwọn jagunjagun tí ó ti nípa ogun múra fún ogun pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ohun èlò ìjà, láti ran Dafidi lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn tí kò fi iyèméjì ṣe ìjólóòótọ́ wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
34 Et de Nephthali, mille princes, et avec eux des hommes armés d’une lance et d’un bouclier, au nombre de trente-sept mille.
Àwọn ọkùnrin Naftali, ẹgbẹ̀rún ìjòyè àpapọ̀ pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún. Ọkùnrin tí wọ́n gbé asà àti ọ̀kọ̀ wọn.
35 De Dan aussi, préparés au combat, vingt-huit mille six cents;
Àwọn ọkùnrin Dani, tí wọ́n ṣetán fún ogun ẹgbàá mẹ́tàlá.
36 Et d’Aser, sortant pour le combat, et en bataille provoquant l’ennemi, quarante mille.
Àwọn ọkùnrin Aṣeri, àwọn tí ó ti ní ìmọ̀ ogun múra fún ogun ọ̀kẹ́ méjì.
37 Mais au-delà du Jourdain, des fils de Ruben et de Gad, et de la demi-tribu de Manassé, munis d’armes guerrières, cent vingt mille.
Láti ìlà-oòrùn Jordani, ọkùnrin Reubeni, Gadi, àti ìdajì ẹ̀yà Manase, dìmọ́ra pẹ̀lú gbogbo onírúurú ohun èlò ìjà ọ̀kẹ́ mẹ́fà.
38 Tous ces hommes de guerre, disposés à combattre, vinrent avec un cœur parfait à Hébron, pour établir David roi sur tout Israël; et de plus tout le reste d’Israël avait un même cœur pour que David fût fait roi.
Gbogbo èyí ni àwọn ọkùnrin ológun tí ó fi ara wọn fún ogun láti ṣe iṣẹ́ fún nínú ẹgbẹ́. Wọ́n wá sí Hebroni tí ó kún fún ìpinnu láti fi Dafidi jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. Gbogbo àwọn ìyókù lára àwọn ọmọ Israẹli sì jẹ́ onínú kan láti fi Dafidi jẹ ọba.
39 Et ils furent là près de David durant trois jours, mangeant et buvant; car leurs frères avaient tout préparé;
Àwọn ọkùnrin náà lo ọjọ́ mẹ́ta níbẹ̀ pẹ̀lú Dafidi, wọ́n jẹ, wọ́n sì ń mu, nítorí ìdílé wọn ti pèsè oúnjẹ fún wọn.
40 Mais de plus, ceux qui étaient proche d’eux, jusqu’à Issachar, à Zabulon et à Nephthali, apportaient des pains sur les ânes, les chameaux, les mulets et les bœufs, pour qu’ils s’en nourrissent; de la farine, des figues, des raisins secs, du vin, de l’huile, des bœufs et des béliers en toute abondance; car c’était une joie en Israël.
Àwọn aládùúgbò láti ọ̀nà jíjìn gẹ́gẹ́ bí Isakari, Sebuluni àti Naftali gbé oúnjẹ wá lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, lórí ràkunmí, àti lórí ìbáaka àti lórí màlúù, àní oúnjẹ ti ìyẹ̀fun, èso àjàrà gbígbẹ, èso ọ̀pọ̀tọ́, àkàrà dídùn, ọtí wáìnì, òróró, màlúù àti àgùntàn, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ wà ní Israẹli.

< 1 Chroniques 12 >