< Philémon 1 >
1 Paul, prisonnier de Jésus-Christ, et le frère Timothée à Philémon, notre bien-aimé et notre collaborateur,
Èmi Paulu, ẹni tí a fi sẹ́wọ̀n nítorí pé ó ń wàásù ìyìnrere Jesu Kristi àti Timotiu arákùnrin wa, Sí Filemoni ọ̀rẹ́ wa ọ̀wọ́n àti alábáṣiṣẹ́ wa,
2 à notre soeur Appia, à Archippe, notre compagnon d'armes, et à l'église qui s'assemble dans ta maison.
sí Affia arábìnrin wa, sí Arkippu ẹni tó jẹ́ jagunjagun fún àgbélébùú náà àti sí ìjọ àwọn Kristiani tí ó ń pàdé nínú ilé rẹ:
3 Grâce et paix vous soient accordées par Dieu notre Père et par le Seigneur Jésus-Christ.
Oore-ọ̀fẹ́ fún un yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti Jesu Kristi.
4 Je rends sans cesse grâce à mon Dieu quand ton souvenir se présente à moi dans mes prières.
Èmi máa ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nígbà tí mo bá rántí rẹ nínú àdúrà mi,
5 J'apprends, en effet, ta foi au Seigneur Jésus et ton amour pour tous les fidèles,
nítorí mo ń gbọ́ nípa ìgbàgbọ́ rẹ nínú Jesu Olúwa àti nípa ìfẹ́ rẹ sí àwọn ènìyàn mímọ́.
6 et je demande que ta foi se communique et porte des fruits et que tu saches ce qui pour nous est le bien, en vue de Christ!
Èmi ń gbàdúrà pé, bí ìwọ ti ń ṣe alábápín nínú ìgbàgbọ́ rẹ pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn, pé kí ìgbàgbọ́ náà lè mú ọkàn wọn dúró gbọingbọin, gẹ́gẹ́ bí wọn ti rí àwọn ọ̀rọ̀ ohun rere tí ó ń bẹ nínú ayé rẹ, èyí tí ó ti ọ̀dọ̀ Kristi wá.
7 Ton amour, en effet, nous a causé beaucoup de joie et de consolation; car les coeurs des fidèles ont été tranquillisés par toi, frère.
Ìfẹ́ rẹ ti fún mi ní ayọ̀ púpọ̀ àti ìgboyà, nítorí ìwọ, arákùnrin ti tu ọkàn àwọn ènìyàn mímọ́ lára.
8 Aussi aurais-je le droit en Christ de te prescrire en toute confiance ce que tu dois faire;
Nítorí náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nínú Kristi mo ní ìgboyà púpọ̀ láti pàṣẹ ohun ti ó yẹ kí ó ṣe fún ọ,
9 mais je préfère m'adresser à toi au nom de cet amour, et en mon nom, au nom de Paul, un vieillard, et, dans ce moment, un prisonnier de Jésus-Christ.
síbẹ̀ nítorí ìfẹ́ èmí kúkú bẹ̀ ọ́. Èmi gẹ́gẹ́ bí Paulu, arúgbó, àti nísinsin yìí òǹdè Jesu Kristi.
10 Je t'adresse donc une prière pour mon fils, que j'ai engendré dans les fers, pour Onésime.
Èmí bẹ̀ ọ́ nítorí ọmọ mi Onesimu, ẹni tí ó di ọmọ nígbà tí mo wà nínú ìdè.
11 Il s'appelle Utile, et il ne te servait à rien autrefois. A l'avenir il nous servira beaucoup à tous les deux.
Nígbà kan rí, kò wúlò fún ọ, ṣùgbọ́n ní báyìí, ó ti wúlò fún ọ àti fún èmi pàápàá.
12 Je te le renvoie, lui, c'est-à-dire la meilleure partie de moi-même.
Èmi rán an nísinsin yìí, àní ẹni ọkàn mi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ.
13 Je voulais le retenir auprès de moi, pour qu'au lieu de te servir, il me servît pendant que je suis prisonnier pour l'Évangile;
Èmi ìbá fẹ́ láti dá a dúró sọ́dọ̀ mi níhìn-ín, kí ó ba à dípò rẹ láti máa ràn mí lọ́wọ́ nígbà tí mo wà nínú ìdè nítorí ìyìnrere
14 mais je n'ai rien voulu faire sans ton avis, afin de ne pas t'obliger à lui faire du bien, et de te laisser entièrement libre.
ṣùgbọ́n èmi kò fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀ rárá láìgba ìyọ̀ǹda ní ọwọ́ rẹ, kí oore tí ìwọ bá ṣe má ba à jẹ́ ìfipámúniṣe bí kò ṣe ìfìfẹ́ṣe.
15 Peut-être n'a-t-il été séparé de toi un moment qu'afin que tu le retrouves à jamais (aiōnios )
Bóyá ìdí rẹ̀ tí òun fi yẹra kúrò lọ́dọ̀ rẹ fún ìgbà díẹ̀ ni pé kí ìwọ kí ó lè gbà á padà sọ́dọ̀ títí láé. (aiōnios )
16 non plus comme esclave, mais comme frère bien-aimé au lieu d'esclave; oui, bien-aimé de moi d'abord et plus encore de toi et selon la nature et selon le Seigneur!
Kì í wá ṣe bí ẹrú mọ́, ṣùgbọ́n bí ẹni ti ó sàn ju ẹrú lọ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin. Ó ṣọ̀wọ́n fún mi jọjọ, ṣùgbọ́n ó ṣọ̀wọ́n fún ọ jù nípa ti ara àti gẹ́gẹ́ bí arákùnrin nínú Olúwa.
17 Si donc tu me considères comme ton ami, reçois-le comme moi-même.
Nítorí náà bí ìwọ bá kà mí sí ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tẹ́wọ́ gbà á bí ìwọ yóò ti tẹ́wọ́ gbà mí.
18 S'il t'a fait quelque tort, s'il te doit quelque chose, passe-le à mon compte.
Bí ó bá ti ṣe ọ́ ní ibi kan tàbí jẹ ọ́ ní gbèsè ohun kan, kà á sí mi lọ́rùn.
19 Moi, Paul, — j'écris ceci de ma main — je te rembourserai, sans te rappeler que tu es mon débiteur et que tu l'es de ta propre personne.
Èmi Paulu, ni mo fi ọwọ́ ara mi kọ ìwé yìí; èmi yóò san án padà láì tilẹ̀ ní í sọ nípa pé ìwọ pàápàá jẹ mi ní gbèsè ara rẹ.
20 Allons, frère, fais-moi ce plaisir dans le Seigneur! Tranquillise mon coeur en Christ!
Èmi ń fẹ́ arákùnrin, pé kí èmi kí ó lè ni àǹfààní kan láti ọ̀dọ̀ rẹ nínú Olúwa; fi ayọ̀ rẹ kún ọkàn mi nínú Kristi.
21 Je t'écris convaincu de ton obéissance, certain même que tu iras au delà de ce que je te demande.
Ìgbẹ́kẹ̀lé ti mo ní pé ìwọ yóò gbọ́rọ̀, ni mo fi kọ ìwé yìí ránṣẹ́ sí ọ. Mo mọ̀ dájú pé ìwọ yóò ṣe ju bí mo ti béèrè lọ.
22 En même temps, prépare-toi à me recevoir; car j'espère vous être rendu, grâce à vos prières.
Ó ku ohun kan, ṣe ìtọ́jú iyàrá àlejò rẹ sílẹ̀ fún mi, nítorí mo ní ìgbàgbọ́ pé a óò tú mi sílẹ̀ fún yín ní ìdáhùn sí àdúrà yín.
23 Épaphras, mon compagnon de chaînes en Jésus-Christ, te salue
Epafira, òǹdè ẹlẹgbẹ́ mi nínú Kristi Jesu kí ọ.
24 ainsi que Marc, Aristarque, Démas, Luc, mes collaborateurs.
Marku kí ọ pẹ̀lú Aristarku, Dema àti Luku, àwọn alábáṣiṣẹ́ mi.
25 La grâce de notre Seigneur Jésus-Christ soit avec votre esprit.
Kí oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa wà pẹ̀lú ẹ̀mí yín.