< Colossiens 4 >
1 Vous, maîtres, fournissez à vos esclaves ce qui est juste, équitable; vous savez que vous avez, vous aussi, un maître au ciel.
Ẹyin ọ̀gá, ẹ máa fi èyí tí ó tọ́ tí ó sì dọ́gba fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ yín; kí ẹ sì mọ̀ pé ẹ̀yin pẹ̀lú ní Olúwa kan ní ọ̀run.
2 Dans vos prières montrez de la persévérance, de la vigilance, de la reconnaissance.
Ẹ fi ara yín jì fún àdúrà gbígbà, kí ẹ ṣọ́ra kí ẹ sì máa dúpẹ́;
3 En même temps, priez pour nous, que Dieu nous ouvre une porte, que nous parlions, que nous prêchions le mystère du Christ. C'est pour lui que je porte la chaîne;
ẹ máa gbàdúrà fún wa pẹ̀lú, kí Ọlọ́run lè ṣí ìlẹ̀kùn fún wa fún ọ̀rọ̀ náà, láti máa sọ ohun ìjìnlẹ̀ Kristi, nítorí èyí tí mo ṣe wà nínú ìdè pẹ̀lú.
4 demandez que je le fasse connaître comme je dois l'annoncer.
Ẹ gbàdúrà pé kí èmi le è máa kéde rẹ̀ kedere gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ fún mi.
5 Conduisez-vous avec prudence envers ceux du dehors, et profitez bien des moments opportuns.
Ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n ní ti bí ẹ ti ń ṣe pẹ̀lú àwọn tí ń bẹ lóde, kí ẹ sì máa ṣe ṣí àǹfààní tí ẹ bá nílò.
6 Que vos paroles soient toujours aimables, pleines de saveur, de manière à savoir répondre à chacun comme il faut.
Ẹ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ yín kí ó dàpọ̀ mọ́ oore-ọ̀fẹ́ nígbà gbogbo, èyí tí a fi iyọ̀ dùn, kí ẹ̀yin kí ó le mọ́ bí ẹ̀yin ó tí máa dá olúkúlùkù ènìyàn lóhùn.
7 Vous apprendrez tout ce qui me concerne personnellement par Tychique, mon bien-aimé frère, mon aide fidèle, mon collègue dans l'oeuvre du Seigneur.
Gbogbo bí nǹkan ti rí fún mi ní Tikiku yóò jẹ́ kí ẹ mọ̀. Òun jẹ́ arákùnrin olùfẹ́ àti olóòtítọ́ ìránṣẹ́ àti ẹlẹgbẹ́ nínú Olúwa,
8 Je vous l'envoie tout exprès pour cela, pour que vous sachiez où en sont nos affaires, et qu'il console vos coeurs.
ẹni tí èmí ń rán sí yín nítorí èyí kan náà, kí ẹ̀yin lè mọ́ bí a ti wà, kí òun kí ó lè tu ọkàn yín nínú.
9 Avec lui est notre fidèle et bien-aimé frère, Onésime, l'un de vos compatriotes. Ils vous informeront de tout ce qui se passe ici.
Òun sì ń bọ̀ pẹ̀lú Onesimu, arákùnrin olóòtítọ́ àti olùfẹ́, ẹni tí í ṣe ọ̀kan nínú yín. Àwọn ní yóò sọ ohun gbogbo tí à ń ṣe níhìn-ín yìí fún un yín.
10 Vous avez les salutations d'Aristarque, mon compagnon de prison, et celles de Marc, le cousin de Barnabas (vous avez reçu des avis à son sujet; quand il viendra vous voir, faites-lui bon accueil),
Aristarku, ẹlẹgbẹ́ mí nínú túbú kí i yín, àti Marku, ọmọ arábìnrin Barnaba. (Nípasẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ti gba àṣẹ; bí ó bá sì wá sí ọ̀dọ̀ yín, ẹ gbà á.)
11 celles de Jésus dit Justus. Ce sont les seuls circoncis qui aient travaillé avec moi pour le Royaume de Dieu; ils ont été pour moi une véritable force.
Àti Jesu, ẹni tí à ń pè ní Justu, ẹni tí ń ṣe ti àwọn onílà. Àwọn wọ̀nyí nìkan ni olùbáṣiṣẹ́ mí fún ìjọba Ọlọ́run, àwọn ẹni tí ó tí jásí ìtùnú fún mi.
12 Vous avez aussi les salutations de votre compatriote Épaphras; c'est un serviteur de Jésus-Christ; il lutte sans cesse pour vous dans ses prières, pour que vous persistiez dans votre parfaite et entière soumission à toute la volonté de Dieu.
Epafira, ẹni tí ń ṣe ọ̀kan nínú yín àti ìránṣẹ́ Kristi Jesu kí i yín. Òun fi ìwàyáàjà gbàdúrà nígbà gbogbo fún un yín, kí ẹ̀yin kí ó lè dúró ní pípé nínú ohun gbogbo nínú ìfẹ́ Ọlọ́run.
13 Je lui rends le témoignage qu'il est plein de sollicitude pour vous ainsi que pour les frères de Laodicée et de Hiérapolis.
Nítorí mo jẹ́rìí rẹ̀ pé ó ń ṣiṣẹ́ kárakára fún yín, àti fún àwọn tí ó wà ní Laodikea, àti àwọn tí ó wà ní Hirapoli.
14 Vous avez les salutations de mon bien-aimé Luc, le médecin, et celles de Démas.
Luku, arákùnrin wa ọ̀wọ́n, oníṣègùn, àti Dema ki í yín.
15 Nous saluons nos frères de Laodicée ainsi que Nymphas et l'Église qui s'assemble dans leur maison.
Ẹ kí àwọn ará tí ó wà ní Laodikea, àti Nimpa, àti ìjọ tí ó wà ní ilé rẹ̀.
16 Quand vous aurez lu cette lettre, ayez soin qu'elle soit lue aussi de l'Église de Laodicée et lisez à votre tour celle qu'on vous enverra de Laodicée.
Nígbà tí a bá sì ka ìwé yìí ní àárín yín tan, kí ẹ mú kí a kà á pẹ̀lú nínú ìjọ Laodikea; ẹ̀yin pẹ̀lú sì ka èyí tí ó ti Laodikea wá.
17 Dites à Archippe: Prends garde de bien remplir le ministère que tu as reçu de la part du Seigneur.
Kí ẹ sì wí fún Arkippu pe, “Kíyèsi iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ìwọ ti gbà nínú Olúwa kí o sì ṣe é ní kíkún.”
18 Je vous salue en écrivant moi-même: Paul. N'oubliez pas que je suis en prison. La grâce soit avec vous.
Ìkíni láti ọwọ́ èmi Paulu. Ẹ máa rántí ìdè mi. Kí oore-ọ̀fẹ́ kí ó wà pẹ̀lú yín.