< Zacharie 8 >
1 Et la parole de l'Éternel des armées fut adressée en ces mots:
Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun si tún tọ́ mí wá.
2 Ainsi parle l'Éternel des armées: Pour Sion un grand zèle m'anime, et par un grand courroux je lui montre mon zèle.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Owú ńlá ńlá ni mo jẹ fún Sioni, pẹ̀lú ìbínú ńlá ńlá ni mo fi jowú fún un.”
3 Ainsi parle l'Éternel: Je reviens en Sion et fixe ma demeure au sein de Jérusalem; et Jérusalem sera nommée Cité fidèle, et la montagne de l'Éternel des armées Montagne sainte.
Báyìí ni Olúwa wí, “Mo yípadà sí Sioni èmi ó sì gbé àárín Jerusalẹmu. Nígbà náà ni a ó sì pé Jerusalẹmu ni ìlú ńlá òtítọ́; àti òkè ńlá Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni a ó pè ní òkè ńlá mímọ́.”
4 Ainsi parle l'Éternel des armées: Des vieillards et des femmes âgées s'assiéront encore dans les rues de Jérusalem, ayant chacun son bâton à la main à cause de leur grand âge;
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Arúgbó ọkùnrin, àti arúgbó obìnrin, yóò gbé ìgboro Jerusalẹmu, àti olúkúlùkù pẹ̀lú ọ̀pá ni ọwọ́ rẹ̀ fún ogbó.
5 et les rues de la ville seront remplies de jeunes garçons et de jeunes filles jouant dans ses rues.
Ìgboro ìlú yóò sì kún fún ọmọdékùnrin, àti ọmọdébìnrin, tí ń ṣiré ní ìta wọn.”
6 Ainsi parle l'Éternel des armées: Si la chose est impossible aux yeux des restes de ce peuple dans ces jours-là, sera-t-elle aussi impossible à mes yeux, dit l'Éternel des armées?
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Bí ó bá ṣe ìyanu ní ojú ìyókù àwọn ènìyàn yìí ni ọjọ́ wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó ha lè jẹ́ ìyanu ni ojú mi bí?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
7 Ainsi parle l'Éternel des armées: Voici, je sauverai mon peuple du pays du lever et du pays du coucher du soleil;
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Kíyèsi i, èmi ó gba àwọn ènìyàn mi kúrò ni ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti kúrò ni ilẹ̀ ìwọ̀-oòrùn.
8 et je les ramènerai, et ils habiteront au sein de Jérusalem, et ils seront mon peuple, et moi je serai leur Dieu en vérité et en justice.
Èmi ó sì mú wọn padà wá, wọn ó sì máa gbé àárín Jerusalẹmu. Wọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ní òtítọ́, àti ní òdodo.”
9 Ainsi parle l'Éternel des armées: Que vos mains reprennent force, à vous tous qui en ces jours entendîtes ces paroles de la bouche des prophètes, qui parurent au temps où fût fondée la maison de l'Éternel des armées, le temple pour être relevé.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Jẹ́ kí ọwọ́ yín le ẹ̀yin ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní ọjọ́ wọ̀nyí ni ẹnu àwọn wòlíì tí ó wà ni ọjọ́ tí a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun lélẹ̀, jẹ́ ki ọwọ́ rẹ̀ le kí a bá lè kọ́ tẹmpili.
10 Car avant ces jours-là l'homme ne retirait point le prix de sa peine, ni le bétail le prix de sa peine, et à ceux qui entraient et sortaient l'ennemi ne laissait point de paix, et je mettais aux prises les hommes les uns avec les autres.
Nítorí pé, ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, owó ọ̀yà ènìyàn kò tó nǹkan, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀yà ẹran pẹ̀lú, bẹ́ẹ̀ ni kò sí àlàáfíà fún ẹni ń jáde lọ, tàbí ẹni ti ń wọlé bọ, nítorí ìpọ́njú náà: nítorí mo dojú gbogbo ènìyàn, olúkúlùkù kọ aládùúgbò rẹ̀.
11 Mais maintenant je ne serai pas envers les restes de ce peuple, comme j'ai été dans les premiers jours, dit l'Éternel des armées.
Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí èmi kì yóò ṣè sí ìyókù àwọn ènìyàn yìí gẹ́gẹ́ bí tí ìgbà àtijọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
12 Car les semailles se feront en paix, la vigne donnera son fruit et la terre donnera son produit, et les Cieux donneront leur rosée, et je donnerai au reste de ce peuple la propriété de toutes ces choses;
“Nítorí irúgbìn yóò gbilẹ̀, àjàrà yóò ṣo èso rẹ̀, ilẹ̀ yóò sì hu ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan rẹ̀ jáde, àwọn ọ̀run yóò sì mu ìrì wọn wá; èmi ó sì mu kí èyí jẹ ogún ìní àwọn ìyókù ènìyàn yìí ni gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
13 et de même que vous fûtes parmi les peuples en malédiction, maison de Juda et maison d'Israël, de même je veux vous sauver, et vous serez en bénédiction. N'ayez point de peur, que vos mains se raffermissent!
Yóò sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí jẹ́ ègún láàrín àwọn kèfèrí, ẹ̀yin ilé Juda, àti ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó gbà yín sílẹ̀; ẹ̀yin o sì jẹ́ ìbùkún, ẹ má bẹ̀rù, ṣùgbọ́n jẹ́ ki ọwọ́ yín le.”
14 Car ainsi parle l'Éternel des armées: De même que je pensai à vous faire du mal, quand vos pères m'irritèrent, dit l'Éternel des armées, et que je n'en eus point de repentir,
Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Gẹ́gẹ́ bí mo ti rò láti ṣe yín níbi nígbà tí àwọn baba yín mú mi bínú,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, tí èmi kò sì ronúpìwàdà.
15 ainsi je pense de nouveau en ces jours à faire du bien à Jérusalem et à la maison de Juda. N'ayez point de peur!
“Bẹ́ẹ̀ ni èmi sì ti ro ọjọ́ wọ̀nyí láti ṣe rere fún Jerusalẹmu, àti fún ilé Juda: ẹ má bẹ̀rù.
16 Voici les choses que vous devez faire: parlez-vous vrai l'un à l'autre, rendez vos jugements dans vos Portes selon la vérité et en vue de la paix;
Wọ̀nyí ni nǹkan tí ẹ̀yin ó ṣe: ki olúkúlùkù yín kí ó máa ba ọmọnìkejì rẹ̀ sọ òtítọ́; ṣe ìdájọ́ tòótọ́ àti àlàáfíà ní àwọn ibodè yín.
17 que nul ne pense à mal contre son prochain dans son cœur, et n'aimez pas le faux serment, car ce sont tout autant de choses que je hais, dit l'Éternel.
Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ro ibi ni ọkàn rẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀; ẹ má fẹ́ ìbúra èké; nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo kórìíra,” ni Olúwa wí.
18 Et la parole de l'Éternel des armées me fut adressée en ces mots:
Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun sì tọ mi wá wí pé.
19 Ainsi parle l'Éternel des armées: Le jeûne du quatrième mois et le jeûne du cinquième, et le jeûne du septième et le jeûne du dixième se changeront pour la maison de Juda en joie et en allégresse, et en fêtes de bonheur… Mais aimez la vérité et la paix.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwẹ̀ oṣù kẹrin, karùn-ún, keje, àti tí ẹ̀kẹwàá, yóò jẹ́ ayọ̀ àti dídùn inú, àti àpéjọ àríyá fún ilé Juda; nítorí náà, ẹ fẹ́ òtítọ́ àti àlàáfíà.”
20 Ainsi parle l'Éternel des armées: Un jour encore viendront des peuples et les habitants de beaucoup de villes,
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Àwọn ènìyàn yóò sá à tún wa, àti ẹni tí yóò gbe ìlú ńlá púpọ̀.
21 et les habitants d'une ville aborderont ceux de l'autre en disant: Allons implorer l'Éternel et chercher l'Éternel des armées! Je veux aller aussi!
Àwọn ẹni tí ń gbé ìlú ńlá kan yóò lọ sí òmíràn, wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a yára lọ gbàdúrà kí a sì wá ojúrere Olúwa, àti láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi pẹ̀lú yóò sì lọ.’
22 Et beaucoup de peuples et de nombreuses nations viendront chercher l'Éternel des armées à Jérusalem et implorer l'Éternel.
Nítòótọ́, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn àti àwọn alágbára orílẹ̀-èdè yóò wá láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní Jerusalẹmu; àti láti gbàdúrà, àti láti wá ojúrere Olúwa.”
23 Ainsi parle l'Éternel des armées: En ces jours-là dix hommes de toutes les langues des nations saisiront le pan du manteau d'un Juif et diront: Nous voulons aller avec vous, car nous avons appris que Dieu est avec vous!
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni ọkùnrin mẹ́wàá láti inú gbogbo èdè àti orílẹ̀-èdè yóò dìímú, àní yóò di etí aṣọ ẹni tí i ṣe Júù mú, wí pé, ‘Àwa yóò ba ọ lọ, nítorí àwa tí gbọ́ pé, Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.’”