< Zacharie 14 >

1 Voici, un jour arrive pour l'Éternel, et tes dépouilles seront partagées dans ton sein;
Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀, a ó sì pín ìkógun rẹ̀ láàrín rẹ̀.
2 et je rassemblerai toutes les nations contre Jérusalem pour y porter la guerre, et la ville sera prise, et les maisons pillées, et les femmes déshonorées; et la moitié delà ville s'en ira captive, mais le reste du peuple ne sera point exterminé de la ville.
Nítorí èmi ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí Jerusalẹmu fún ogun; a ó sì ko ìlú náà, a ó sì kó àwọn ilé, a ó sì ba àwọn obìnrin jẹ́, ààbọ̀ ìlú náà yóò lọ sí ìgbèkùn, a kì yóò sì gé ìyókù àwọn ènìyàn náà kúrò ni ìlú náà.
3 Alors l'Éternel s'avancera, et livrera bataille à ces nations-là, comme à la journée où Il livra bataille le jour de la mêlée.
Nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ, yóò sì bá àwọn orílẹ̀-èdè náà jà, gẹ́gẹ́ bí í ti ìjà ní ọjọ́ ogun.
4 Et en ce jour-là ses pieds poseront sur la montagne des Oliviers, située en face de Jérusalem à l'orient; et la montagne des Oliviers se fendra par le milieu, de l'orient à l'occident, pour former une vallée très grande, et une moitié de la montagne reculera vers le nord, et une moitié vers le midi.
Ẹsẹ̀ rẹ̀ yóò sì dúró ni ọjọ́ náà lórí òkè Olifi, tí ó wà níwájú Jerusalẹmu ni ìlà-oòrùn, òkè Olifi yóò sì là á sí méjì, sí ìhà ìlà-oòrùn àti ìhà ìwọ̀-oòrùn, àfonífojì ńlá ńlá yóò wà: ìdajì òkè náà yóò sì ṣí síhà àríwá, àti ìdajì rẹ̀ síhà gúúsù.
5 Et vous fuirez par la vallée de mes montagnes, car la vallée des montagnes s'étendra jusqu'à Atsal, et vous fuirez comme vous avez fui devant le tremblement de terre, au temps de Hosias, roi de Juda. Et l'Éternel, mon Dieu, viendra, et tous ses Saints avec lui.
Ẹ̀yin ó sì sá sí àfonífojì àwọn òkè mi, nítorí pé àfonífojì òkè náà yóò dé Aseli: nítòótọ́, ẹ̀yin ó sá bí ẹ tí sá fún ìmìmì-ilẹ̀ ni ọjọ́ Ussiah ọba Juda: Olúwa Ọlọ́run mi yóò sì wá, àti gbogbo àwọn Ẹni mímọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
6 Et en ce jour-là il n'y aura point de lumière, les splendeurs s'éclipseront:
Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìmọ́lẹ̀ kì yóò mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ṣókùnkùn.
7 et ce sera un seul jour; (l'Éternel sait ce qu'il sera) il ne fera ni jour ni nuit, mais au temps du soir la clarté paraîtra.
Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ ọjọ́ kan mímọ́ fún Olúwa, kì í ṣe ọ̀sán, kì í ṣe òru; ṣùgbọ́n yóò ṣe pé, ni àṣálẹ́ ìmọ́lẹ̀ yóò wà.
8 Et en ce jour-là des eaux vives jailliront de Jérusalem, et une moitié ira à la mer orientale et une moitié à la mer occidentale, et cela été et hiver.
Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, omi ìyè yóò tí Jerusalẹmu sàn lọ; ìdajì wọn síhà Òkun ìlà-oòrùn, àti ìdajì wọn síhà okùn ẹ̀yìn: nígbà ẹ̀rùn àti nígbà òtútù ni yóò rí bẹ́ẹ̀.
9 Et l'Éternel régnera sur tout le pays; en ce jour-là il n'y aura qu'un seul Éternel; et il n'y aura que son nom seul.
Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí gbogbo ayé; ni ọjọ́ náà ni Olúwa kan yóò wa orúkọ rẹ̀ nìkan náà ni orúkọ.
10 Tout le pays sera transformé, assimilé à la plaine, de Géba à Rimmon au midi de Jérusalem, qui sera éminente et assise sur son sol, de la porte de Benjamin jusqu'au lieu de la première porte, jusqu'à la porte de l'angle, et de la tour de Hananéel aux pressoirs du roi.
A ó yí gbogbo ilẹ̀ padà bi pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan láti Geba dé Rimoni lápá gúúsù Jerusalẹmu: yóò di bí aginjù, ṣùgbọ́n a ó sì gbé Jerusalẹmu sókè, yóò sì gbe ipò rẹ̀, láti ibodè Benjamini títí dé ibi ibodè èkínní, dé ibodè igun nì, àti láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé ibi ìfúntí wáìnì ọba.
11 Et ils y habiteront, et il n'y aura plus d'interdit, et Jérusalem siégera en sécurité.
Ènìyàn yóò sì máa gbé ibẹ̀, kì yóò sì sí ìparun mọ́; ṣùgbọ́n a ó máa gbé Jerusalẹmu láìléwu.
12 Or, voici la plaie qu'infligera l'Éternel à tous les peuples qui auront marché contre Jérusalem: Il fera tomber en pourriture la chair de chacun tandis qu'il est debout sur ses pieds, et leurs yeux tomberont en pourriture dans leurs cavités, et leur langue tombera en pourriture dans leur bouche.
Èyí ni yóò sì jẹ́ ààrùn tí Olúwa yóò fi kọlu gbogbo àwọn ènìyàn ti ó tí ba Jerusalẹmu jà; ẹran-ara wọn yóò rù nígbà tí wọn dúró ni ẹsẹ̀ wọn, ojú wọn yóò sì rà ni ihò wọn, ahọ́n wọn yóò sì bàjẹ́ ni ẹnu wọn.
13 Et en ce jour-là il y aura un grand trouble de par l'Éternel parmi eux, l'un saisira la main de l'autre, et l'un lèvera la main sur la main de l'autre.
Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò wà láàrín wọn; wọn ó sì di ọwọ́ ara wọn mú, ọwọ́ èkínní yóò sì dìde sì ọwọ́ èkejì rẹ̀.
14 Et Juda combattra aussi dans Jérusalem, et les richesses de toutes les nations d'alentour, or et argent et vêtements en grande abondance, seront ramassées.
Juda pẹ̀lú yóò sì jà ni Jerusalẹmu: ọrọ̀ gbogbo àwọn kèfèrí tí ó wà káàkiri ni a ó sì kójọ, wúrà àti fàdákà, àti aṣọ, ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
15 Et pareille sera la plaie infligée aux chevaux, aux mulets, aux chameaux et aux ânes, et à tous les bestiaux qui seront dans ces camps, pareille a cette plaie-là.
Bẹ́ẹ̀ ni ààrùn ẹṣin, ìbáaka, ìbákasẹ, àti tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, yóò sì wà, àti gbogbo ẹranko tí ń bẹ nínú àgọ́.
16 Et tous ceux qui survivront, de toutes les nations qui auront marché contre Jérusalem, monteront chaque année pour adorer le Roi, l'Éternel des armées, et célébrer la fête des Tabernacles.
Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ẹni tí o kù nínú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó dìde sí Jerusalẹmu yóò máa gòkè lọ lọ́dọọdún láti sìn ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
17 Et si des familles de la terre il en est qui ne montent pas à Jérusalem pour adorer le Roi, l'Éternel des armées, sur elles la pluie ne tombera pas.
Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí kì yóò gòkè wá nínú gbogbo ìdílé ayé sí Jerusalẹmu láti sín ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, òjò kì yóò rọ̀ fún wọn.
18 Et si la famille d'Egypte ne monte pas et ne vient pas, [la pluie ne tombera pas] non plus sur elle, mais ce sera la plaie que l'Éternel infligera aux nations qui ne monteront pas pour célébrer la fête des Tabernacles.
Bí ìdílé Ejibiti kò bá sì gòkè lọ, tí wọn kò sì wá, fi ara wọn hàn tí wọn kò ní òjò; ààrùn náà yóò wà, tí Olúwa yóò fi kọlù àwọn kèfèrí tí kò gòkè wá láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
19 Ce sera le péché de l'Egypte et le péché de tous les peuples qui ne monteront pas pour célébrer la fête des Tabernacles.
Èyí ni yóò sì jẹ́ ìyà Ejibiti, àti ìyà gbogbo orílẹ̀-èdè tí kò gòkè wá láti pa àsè àgọ́ mọ́.
20 En ce jour-là les clochettes des chevaux porteront: « Sainteté à l'Éternel! » Et les chaudières dans la maison de l'Éternel seront comme les vases des sacrifices devant l'autel.
Ní ọjọ́ náà ni “mímọ́ sí Olúwa” yóò wà lára ṣaworo ẹṣin: àti àwọn ìkòkò ni ilé Olúwa yóò sì dàbí àwọn ọpọ́n tí ń bẹ níwájú pẹpẹ.
21 Et toute chaudière en Jérusalem et en Juda sera « sainteté à l'Éternel des armées, » et tous ceux qui sacrifieront, viendront et en prendront et y cuiront [les viandes], et il n'y aura plus de Cananéen dans la maison de l'Éternel des armées en ce jour-là.
Nítòótọ́, gbogbo ìkòkò ni Jerusalẹmu àti ni Juda yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun: àti gbogbo àwọn tí ń rú ẹbọ yóò wá, wọn ó sì mú ìkòkò díẹ̀, wọn ó sì bọ ẹran wọn nínú rẹ̀, ni ọjọ́ náà ni àwọn Kenaani kò ní sí mọ́ ni ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

< Zacharie 14 >