< Apocalypse 10 >
1 Et je vis un autre ange puissant, descendant du ciel, enveloppé d'un nuage, et l'arc-en-ciel était sur sa tête, et son visage était comme le soleil, et ses pieds comme des colonnes de feu.
Mó sì rí angẹli mìíràn alágbára ò ń ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, a fi àwọsánmọ̀ wọ̀ ọ́ ni aṣọ; òṣùmàrè sì ń bẹ ní orí rẹ̀, ojú rẹ̀ sì dàbí oòrùn, àti ẹsẹ̀ rẹ̀ bí ọ̀wọ́n iná.
2 Et il tenait dans sa main un petit livre, et il mit son pied droit sur la mer, et le gauche sur la terre.
Ó sì ní ìwé kékeré kan tí a ṣí ní ọwọ́ rẹ̀; ó sì fi ẹsẹ̀ rẹ̀ ọ̀tún lé Òkun, àti ẹsẹ̀ rẹ̀ òsì lé ilẹ̀.
3 Et il cria d'une voix forte comme rugit un lion, et lorsqu'il cria les sept tonnerres firent retentir leurs voix,
Ó sì ké lóhùn rara, bí ìgbà tí kìnnìún bá bú ramúramù. Nígbà tí ó sì ké, àwọn àrá méje náà fọhùn.
4 et lorsque les sept tonnerres parlèrent j'allais écrire, et j'entendis une voix venant du ciel, qui disait: « Scelle ce dont ont parlé les sept tonnerres et ne l'écris point. »
Nígbà tí àwọn àrá méje fọhùn, mo múra àti kọ̀wé, mo sì gbọ́ ohùn láti ọ̀run wá ń wí fún pé, “Fi èdìdì di ohun tí àwọn àrá méje náà sọ, má sì ṣe kọ wọ́n sílẹ̀.”
5 Et l'ange, que j'avais vu se tenir debout sur la mer et sur la terre, éleva sa main vers le ciel,
Angẹli náà tí mo rí tí ó dúró lórí Òkun àti lórí ilẹ̀, sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run.
6 et il jura par Celui qui vit aux siècles des siècles, qui a créé le ciel et les choses qui y sont: « Il n'y aura plus de délai, (aiōn )
Ó sì fi ẹni tí ń bẹ láààyè láé àti láé búra, ẹni tí o dá ọ̀run, àti ohun tí ń bẹ nínú rẹ̀, ayé ohun tí ń bẹ nínú rẹ̀ pé, “Kí yóò si ìjáfara mọ́. (aiōn )
7 mais dans les jours de la voix du septième ange, quand il sera sur le point de sonner, alors aura été accompli le mystère de Dieu, selon la bonne nouvelle qu'il a donnée à Ses esclaves les prophètes. »
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ ohùn angẹli keje, nígbà tí yóò ba fún ìpè, nígbà náà ni ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí o tí sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì ni a ó mú ṣẹ.”
8 Et la voix, que j'avais entendue venant du ciel, je l'entendis me parler derechef et me dire: « Va, prends le livre qui est ouvert dans la main de l'ange qui se tient debout sur la mer et sur la terre. »
Ohùn náà tí mo gbọ́ láti ọ̀run tún ń ba mi sọ̀rọ̀, ó sì wí pé, “Lọ, gba ìwé tí o ṣí lọ́wọ́ angẹli tí o dúró lórí Òkun àti lórí ilẹ̀.”
9 Et j'allai vers l'ange, lui disant de me donner le petit livre, et il me dit: « Prends-le et avale-le, et il aigrira ton cœur, mais dans ta bouche il sera doux comme du miel. »
Mo sì tọ angẹli náà lọ, mo sì wí fún pé, “Fún mi ní ìwé kékeré náà.” Ó sì wí fún mi pé, “Gbà kí o sì jẹ ẹ́ tan: yóò dàbí oyin.”
10 Alors je pris le petit livre de la main de l'ange, et je l'avalai, et il fut dans ma bouche doux comme du miel; et quand je l'eus mangé, mon estomac en fut aigri.
Mo sì gba ìwé kékeré náà ni ọwọ́ angẹli náà mo sì jẹ ẹ́ tan; ó sì dùn lẹ́nu mi bí oyin; bí mo sì tí jẹ ẹ́ tan, inú mi korò.
11 Et ils me disent: « Il faut que tu prophétises derechef sur des peuples, et des nations, et des langues, et des rois nombreux. »
A sì wí fún mi pé, “Ìwọ ó sì tún sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àti orílẹ̀ àti èdè, àti àwọn ọba.”