< Psaumes 96 >

1 Chantez à l'Éternel un cantique nouveau, chantez à l'Éternel, vous toutes les contrées!
Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa, ẹ kọrin sí Olúwa gbogbo ayé.
2 Chantez à l'Éternel, bénissez son nom, annoncez son salut de jour en jour!
Ẹ kọrin sí Olúwa, yin orúkọ rẹ̀ ẹ sọ ti ìgbàlà rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́.
3 Racontez sa gloire parmi les nations, et ses merveilles parmi tous les peuples!
Ẹ sọ ti ògo rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrín gbogbo ènìyàn.
4 Car Dieu est grand et digne d'une grande louange; Il est plus redoutable que tous les dieux;
Nítorí títóbi ní Olúwa ẹni tí ìyìn tọ́ sí; òun ní o yẹ kí a bẹ̀rù ju gbogbo òrìṣà lọ.
5 car tous les dieux des peuples sont des idoles, et l'Éternel a fait les Cieux.
Nítorí asán ni gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
6 Devant sa face c'est splendeur et majesté, gloire et magnificence, dans son Sanctuaire.
Ọlá àti ọláńlá wà ní iwájú rẹ̀ agbára àti ògo wà ní ibi mímọ́ rẹ̀.
7 Tribus des peuples, rendez à l'Éternel, rendez à l'Éternel l'honneur et la louange!
Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìbátan ènìyàn, ẹ fi agbára àti ògo fún Olúwa.
8 Rendez à l'Éternel l'honneur dû à son nom! d Apportez des offrandes, et entrez dans ses parvis!
Ẹ fi ògo tí ó tọ́ sí Olúwa fún un; ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá rẹ̀.
9 Adorez l'Éternel avec une pompe sainte! Tremblez devant lui, vous toutes les contrées!
Ẹ máa sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́ rẹ̀; ẹ wárìrì níwájú rẹ̀ gbogbo ayé.
10 Dites parmi les peuples: « L'Éternel règne; aussi le monde est ferme et ne chancelle point. Il juge les nations avec justice. »
Sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, “Olúwa jẹ ọba.” A fi ìdí ayé múlẹ̀, tí kò sì lè yí; ẹni tí yóò fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ ènìyàn.
11 Que les Cieux se réjouissent, et que la terre tressaille; que la mer s'émeuve avec tout ce qu'elle enserre;
Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, kí ayé sì pariwo jẹ́ kí pápá òkun kí ó hó pẹ̀lú ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀.
12 que les campagnes s'égaient avec tout ce qui les couvre; qu'ainsi les arbres des forêts frémissent tous d'allégresse
Jẹ́ kí oko kún fún ayọ̀, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀; nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóò máa yọ̀.
13 au devant de l'Éternel! Car Il vient, car il vient pour juger la terre. Il jugera le monde avec justice, et les peuples, selon sa vérité.
Wọn yóò kọrin níwájú Olúwa, nítorí tí ó ń bọ̀ wá, ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé. Yóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé àti ti àwọn ènìyàn ni yóò fi òtítọ́ rẹ̀ ṣe.

< Psaumes 96 >