< Psaumes 116 >
1 C'est mon bonheur que l'Éternel écoute ma voix, mes prières!
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Car Il a penché vers moi son oreille; aussi toute ma vie je veux l'invoquer.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 Les liens de la mort m'enveloppaient, j'étais atteint des angoisses des Enfers, je trouvais devant moi la détresse et la douleur. (Sheol )
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol )
4 Mais j'invoquai le nom de l'Éternel: « O Etemel, sauve mon âme! »
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 L'Éternel est clément et juste, et notre Dieu, plein de miséricorde.
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 L'Éternel garde les simples; j'étais affligé, et Il me fut secourable.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Rentre, mon âme, dans ton repos! car l'Éternel t'a fait du bien.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 Car Tu as affranchi mon âme de la mort, mes yeux des pleurs, mon pied de la chute.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 Je marcherai sous le regard de l'Éternel, sur la terre des vivants.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 J'ai cru, car j'ai parlé. J'avais beaucoup à souffrir!
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 Je disais dans mes alarmes: « Tous les hommes sont trompeurs. »
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 Comment rendrai-je à l'Éternel tous les bienfaits que j'ai reçus de lui?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 J'élèverai la coupe des délivrances, et j'invoquerai le nom de l'Éternel;
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 j'accomplirai mes vœux envers l'Éternel à la face de tout son peuple.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Aux yeux de l'Éternel, ce qui coûte, c'est la mort de ses bien-aimés.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 O exauce-moi, Éternel! car je suis ton serviteur, le fils de ta servante. Tu as détaché mes chaînes;
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 je t'offrirai le sacrifice de la reconnaissance, et j'invoquerai le nom de l'Éternel;
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 j'accomplirai mes vœux envers l'Éternel, à la face de tout son peuple,
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 dans les parvis de la maison de l'Éternel, dans ton sein, ô Jérusalem! Alléluia!
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.