< Psaumes 101 >
1 Cantique de David. Je vais chanter la bonté et la droiture; c'est toi, Éternel, que je célébrerai.
Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
2 Je m'appliquerai à suivre une voie innocente: ô puissé-je y parvenir! J'agirai dans l'innocence du cœur au sein de ma maison.
Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
3 Je ne mettrai devant mes yeux aucune chose indigne; je hais la conduite des transgresseurs, sur moi elle n'aura pas de prise.
Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
4 Que le cœur pervers se tienne loin de moi, je ne veux pas connaître le méchant.
Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
5 Je détruirai celui qui en secret calomnie son ami; je ne supporte pas celui dont l'œil est altier et le cœur enflé.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
6 Mes yeux se porteront vers les hommes sûrs du pays, pour les faire habiter avec moi; ceux qui suivent une voie innocente, seront mes serviteurs.
Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
7 Il ne s'assiéra pas dans ma maison celui qui fait des fraudes; celui qui ment ne pourra demeurer sous mes yeux.
Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
8 Chaque jour je veillerai à arracher les impies du pays, à bannir de la cité de l'Éternel tous ceux qui font le mal.
Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.