< Proverbes 5 >

1 Mon fils, fais attention à ma sagesse, et prête l'oreille à ma prudence,
Ọmọ mi, fiyèsí ọgbọ́n mi, kí o sì dẹtí rẹ sí òye mi,
2 pour garder les bonnes pensées, et conserver le jugement sur tes lèvres,
kí ìwọ sì lè ní ìṣọ́ra kí ètè rẹ sì le pa ìmọ̀ mọ́.
3 Car les lèvres de l'étrangère distillent du miel, et son palais est plus onctueux que l'huile;
Nítorí ètè àwọn àjèjì obìnrin a máa sun bi oyin, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì kúnná ju òróró lọ.
4 mais sa fin est plus amère que l'absinthe, elle est aiguë comme l'épée à deux tranchants.
Ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín, ó korò ju òróǹró lọ, ó mú bí idà olójú méjì.
5 Ses pieds descendent au séjour de la mort, et ses pas aboutissent aux Enfers. (Sheol h7585)
Ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà ikú ìgbésẹ̀ rẹ̀ lọ tààrà sí ibojì òkú. (Sheol h7585)
6 Pour que tu ne prennes point garde au chemin de la vie, ses voies s'égarent, et tu ne le sais pas.
Kí ìwọ má ba à já ipa ọ̀nà ìyè; ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla, ṣùgbọ́n kò tilẹ̀ mọ́.
7 Et maintenant, mes fils, écoutez-moi, et ne vous écartez pas des paroles de ma bouche.
Nítorí náà, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ dẹtí sí mi, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe yàgò kúrò nínú ọ̀rọ̀ tí mo sọ.
8 Prends ta route loin d'elle, et ne t'approche pas de la porte de sa maison,
Rìn ní ọ̀nà tí ó jìnnà sí ti rẹ̀, má ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀,
9 pour que tu ne livres pas à d'autres la fleur de tes jours, ni tes années à l'homme cruel;
àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò gbé gbogbo ọlá rẹ lé ẹlòmíràn lọ́wọ́ àti ọjọ́ ayé rẹ fún ìkà ènìyàn.
10 pour que des étrangers ne se rassasient pas de ton bien, et que le fruit de ton labeur n'aille pas en maison étrangère;
Kí a má ba à fi ọrọ̀ rẹ fún àjèjì ènìyàn, kí làálàá rẹ sì sọ ilé ẹlòmíràn di ọlọ́rọ̀.
11 pour que tu n'aies pas à gémir sur ta fin, quand ta chair et ton corps auront dépéri,
Ní ìgbẹ̀yìn ayé rẹ ìwọ yóò kérora, nígbà tí agbára rẹ àti ara rẹ bá ti joro tán.
12 disant: Comment ai-je pu haïr la discipline? comment mon cœur a-t-il repoussé la correction?
Ìwọ yóò wí pé, “Mo ti kórìíra ẹ̀kọ́ tó! Ọkàn mi ṣe wá kórìíra ìbáwí!
13 et n'écoutai-je point la voix de mes maîtres, et ne prêtai-je point l'oreille à mes instituteurs?
N kò gbọ́rọ̀ sí àwọn olùkọ́ mi lẹ́nu, tàbí kí n fetí sí àwọn tí ń kọ́ mi lẹ́kọ̀ọ́.
14 Peu s'en faut que je ne sois tombé dans tous les maux au milieu du peuple et de l'assemblée.
Mo ti bẹ̀rẹ̀ ìparun pátápátá ní àárín gbogbo àwùjọ ènìyàn.”
15 Bois l'eau de ta citerne, et celle qui coule de ta fontaine:
Mu omi láti inú kànga tìrẹ, omi tí ń sàn láti inú kànga rẹ.
16 sinon tes sources se répandront au dehors, et comme des ruisseaux couleront sur les places;
Ó ha yẹ kí omi ìsun rẹ kún àkúnya sí ojú ọ̀nà àti odò tí ń sàn lọ sí àárín ọjà?
17 ils seront pour toi seul, et non pour des étrangers en même temps que pour toi.
Jẹ́ kí wọn jẹ́ tìrẹ nìkan, má ṣe ṣe àjọpín wọn pẹ̀lú àjèjì láéláé.
18 Que ta source soit bénie, et fais ton bonheur de la femme de ta jeunesse,
Jẹ́ kí orísun rẹ kí ó ní ìbùkún; kí ìwọ ó sì máa yọ nínú aya ìgbà èwe rẹ.
19 biche aimable, gazelle gracieuse: que son sein t'enivre toujours, et de son amour sois constamment épris!
Abo àgbọ̀nrín tó dára, ìgalà tí ó wu ni jọjọ, jẹ́ kí ọmú rẹ̀ kí ó máa fi ayọ̀ fún ọ nígbà gbogbo, kí o sì máa yọ̀ nínú ìfẹ́ rẹ̀ nígbàkígbà.
20 Et pourquoi t'éprendrais-tu, mon fils, d'une étrangère, et embrasserais-tu le sein d'une inconnue?
Ọmọ mi, èéṣe tí ìwọ ó fi máa yọ̀ nínú ìfẹ́ obìnrin panṣágà, tí ìwọ ó sì fi dì mọ́ ìyàwó ẹlòmíràn?
21 Car les voies de l'homme sont découvertes devant Dieu, et Il observe tous ses sentiers.
Nítorí ọ̀nà ènìyàn kò fi ara sin rárá fún Olúwa Ó sì ń gbé gbogbo ọ̀nà rẹ̀ yẹ̀ wò.
22 L'impie se prend dans ses propres péchés, et il est retenu par les lacs de son iniquité.
Ìwà búburú ènìyàn búburú ni yóò mú kó bọ́ sínú okùn; okùn ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀ yóò sì dìímú.
23 Il mourra faute de discipline, et sa grande folie lui donnera le vertige.
Yóò kú ní àìgba ẹ̀kọ́ ìwà òmùgọ̀ ara rẹ̀ yóò sì mú kí ó máa ṣìnà kiri.

< Proverbes 5 >