< Nombres 35 >

1 Et l'Éternel parla à Moïse dans les plaines de Moab sur le Jourdain près de Jéricho, en ces termes:
Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní Jordani tí ó rékọjá láti Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Ordonne aux enfants d'Israël de donner aux Lévites, sur leurs propriétés héréditaires, des villes pour y habiter, et donnez aussi aux Lévites une banlieue autour de leurs villes.
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti fún àwọn Lefi ní ilẹ̀ láti gbé lára ogún tí àwọn ọmọ Israẹli yóò jogún. Kí ẹ sì fún wọn ní ilẹ̀ lára pápá oko tútù, káàkiri ìlú.
3 Et les villes leur serviront pour s'y loger, et les banlieues, pour recevoir leur bétail, leurs biens et tous leurs animaux.
Nígbà náà, wọn yóò ní ìlú tí wọn yóò gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn, ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú gbogbo ìní wọn.
4 Et les banlieues des villes que vous donnerez aux Lévites auront, à l'extérieur depuis la muraille de la ville, une étendue de deux mille coudées en circuit.
“Ilẹ̀ pápá oko tútù káàkiri ìlú tí ẹ ó fi fún àwọn ọmọ Lefi, wíwọ̀n rẹ̀ yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ (1,500 ẹsẹ̀ bàtà) láti ògiri ìlú náà.
5 Et en dehors de la ville vous mesurerez au côté oriental deux mille coudées, et au côté méridional deux mille coudées, et au côté occidental deux mille coudées, et au côté septentrional deux mille coudées, la ville étant au centre: telles seront les banlieues des villes.
Lẹ́yìn ìlú náà, wọn ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́ lápá ibi ìhà ìlà-oòrùn, ẹgbẹ̀rún méjì ẹsẹ̀ bàtà ní ìhà gúúsù, ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà àríwá, kí ìlú náà sì wà ní àárín. Wọn yóò ní agbègbè yìí gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ pápá oko tútù fún ìlú náà.
6 Et parmi les villes que vous donnerez aux Lévites, il y aura six villes de Refuge que vous destinerez à recevoir le meurtrier fugitif et en sus desquelles vous donnerez encore quarante-deux villes:
“Mẹ́fà lára ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ ìlú ààbò, tí ẹni tí ó bá pa ènìyàn yóò sá sí. Ní àfikún, ẹ fún wọn ní méjìlélógójì ìlú sí i.
7 toutes les villes que vous donnerez aux Lévites seront donc au nombre de quarante-huit, chacune avec sa banlieue.
Ní gbogbo rẹ̀, kí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi ní méjìdínláàádọ́ta ìlú lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
8 Et quant aux villes que vous donnerez sur les propriétés des enfants d'Israël, vous prendrez plus de celui qui a plus, et moins de celui qui a moins; chacun donnera de ses villes aux Lévites le nombre proportionné au lot qu'il aura en partage.
Ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi láti ara ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli jogún, olúkúlùkù kí ó fi nínú ìlú rẹ̀ fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní rẹ̀ tí ó ní. Gba púpọ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní púpọ̀ àti díẹ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní díẹ̀.”
9 Et l'Éternel parla à Moïse en ces termes:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
10 Parle aux enfants d'Israël et leur dis: Quand après le passage du Jourdain vous entrerez dans le pays de Canaan,
“Sọ̀rọ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí ẹ bá rékọjá odò Jordani sí Kenaani,
11 vous choisirez des villes propres à servir de villes de Refuge où puisse se réfugier l'homicide qui aura tué une personne par mégarde.
yan àwọn ìlú kan láti jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìlú ààbò fún yín, kí apani tó pa ènìyàn ní àìmọ̀ máa sálọ síbẹ̀.
12 Et ces villes vous seront un asile contre le vengeur du sang, afin qu'un homicide ne meure pas jusqu'à ce qu'il ait comparu devant l'Assemblée pour être jugé.
Wọn yóò jẹ́ ibi ìsásí kúrò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san, kí ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn má ba à kú kí ó tó dúró níwájú àwọn ìjọ àwọn ènìyàn ní ìdájọ́.
13 Et les villes que vous désignerez seront au nombre de six villes de Refuge.
Mẹ́fà nínú ìlú tí ẹ ó fi fún wọn yóò jẹ́ ìlú ààbò fún yín.
14 Vous désignerez trois villes au delà du Jourdain, et trois villes dans le pays de Canaan: elles seront villes de Refuge:
Yan ìlú mẹ́ta ní ìhà ti Jordani, kí ẹ sì yan ìlú mẹ́ta ní ìhà Kenaani tí yóò máa jẹ́ ìlú ìsásí.
15 ces six villes serviront d'asile aux enfants d'Israël, et à l'étranger et au domicilié pour que s'y réfugie quiconque aura tué une personne par mégarde.
Ìlú mẹ́fà yìí yóò jẹ́ ìlú ìsásí fún àwọn ọmọ Israẹli, fún àjèjì àti ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbé láàrín wọn, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn ní àìmọ̀ sálọ síbẹ̀.
16 Si c'est avec un instrument de fer qu'il l'a frappée jusqu'à donner la mort, il est meurtrier: le meurtrier est mis à mort.
“‘Bí ọkùnrin kan bá fi ohun èlò irin lu ènìyàn tí ó kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa, apànìyàn náà.
17 Et si en frappant il tenait une pierre qui pût donner la mort, et que la mort ait suivi, il est meurtrier: le meurtrier est mis à mort.
Tàbí tí ènìyàn bá mú òkúta tí ó lè pa ènìyàn lọ́wọ́ tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa apànìyàn náà.
18 Ou si en frappant il tenait un morceau de bois qui pût donner la mort et que la mort ait suivi, il est meurtrier: le meurtrier est mis à mort.
Tàbí tí ènìyàn bá mú ohun èlò igi ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì lẹ̀ ẹ́ pa ènìyàn, tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni; pípa ní a ó pa apànìyàn náà.
19 C'est le vengeur du sang qui donnera la mort au meurtrier; s'il le rencontre, il le tuera.
Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà; tí ó bá bá a, yóò pa á.
20 Et si par haine il a fait tomber quelqu'un, ou lui a lancé quelque objet avec intention et que la mort ait suivi;
Tí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń yan odì pẹ̀lú ìríra tí ẹlòmíràn tàbí ju nǹkan sí i pẹ̀lú èrò, tí ó sì kú.
21 ou si par inimitié il l'a frappé de la main à le faire mourir; celui qui a frappé sera mis à mort; il est meurtrier; le vengeur du sang tuera le meurtrier, s'il le rencontre.
Tàbí pẹ̀lú ìjà gbangba lù ú pẹ̀lú ìkùùkuu tí ó sì kú, pípa ni a ó pa ẹni bẹ́ẹ̀; apànìyàn ni. Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà tí ó bá bá a.
22 Mais si par aventure, sans inimitié, il a fait tomber quelqu'un, ou lui a lancé un objet quelconque sans intention,
“‘Ṣùgbọ́n bí ó bá fi nǹkan gún un lójijì láìṣọ̀ta, tàbí tí ó sọ ohunkóhun lù ú láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ ṣe
23 ou si avec une pierre quelconque qui peut donner la mort, il l'a frappé sans voir, ou qu'il ait fait tomber la pierre sur lui et ainsi l'ait tué, sans être toutefois son ennemi ni avoir cherché à lui faire du mal,
tàbí, láìri, ju òkúta sí tí ó lè pa á, tí ó sì kú, nígbà tí kì í ṣe ọ̀tá rẹ̀, láti ṣe é léṣe.
24 que l'Assemblée juge entre celui qui a porté le coup et le vengeur du sang, d'après ces règles,
Àwọn àpéjọ gbọdọ̀ dájọ́ láàrín rẹ̀ àti olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà.
25 et que l'Assemblée sauve l'homicide des mains du vengeur du sang et le fasse rentrer dans la ville de Refuge où il s'était réfugié, et qu'il y reste jusqu'à la mort du Grand-Prêtre qui a reçu l'onction d'huile sainte.
Àpéjọ gbọdọ̀ dá ààbò bo ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn, kí a sì rán an padà lọ sí ìlú ìsásí tí ó ti wá. Ó gbọdọ̀ dúró níbẹ̀ títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú, ẹni tí a fi àmì òróró yàn.
26 Mais si l'homicide sort au delà des limites de la ville de Refuge où il s'est réfugié,
“‘Ṣùgbọ́n ti ẹni tí a fi sùn kan bá jáde kọjá ààlà ìlú ìsásí tí ó sá sí.
27 et que le vengeur du sang le trouve en dehors des limites de la ville de Refuge, et que le vengeur du sang tue l'homicide, il n'est pas coupable de meurtre.
Tí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ sì ri ní ìta ìlú náà, olùgbẹ̀san lè pa ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn láìjẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn.
28 Car il doit rester dans sa ville de Refuge jusqu'à la mort du Grand-Prêtre, et ce n'est qu'après la mort du Grand-Prêtre qu'il peut rentrer dans son pays d'héritage.
Ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn gbọdọ̀ dúró nínú ìlú ìsásí títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú; lẹ́yìn ikú olórí àlùfáà, ni ó tó lè padà sí ibi tí dúkìá rẹ̀ wà.
29 Et que ceci soit pour vous une règle de droit pour toutes vos générations et partout où vous serez établis.
“‘Wọ̀nyí ni ó jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún yín ní ìran yín tó ń bọ̀, ní ibikíbi tí ẹ bá ń gbé.
30 Lorsqu'un homme quelconque aura commis un meurtre sur un autre, on mettra à mort le meurtrier sur la déclaration de témoins; mais la déposition d'un seul témoin à charge ne suffit pas pour une sentence de mort.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn gbọdọ̀ kú gẹ́gẹ́ bí apànìyàn lórí ìjẹ́rìí àwọn ènìyàn. Ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo. Kì yóò jẹ́rìí sí ẹnìkan láti pa.
31 Et vous n'accepterez aucune rançon pour la vie d'un meurtrier digne de mort, mais il subira la mort.
“‘Má ṣe gba ohun ìràpadà fún ẹ̀mí apànìyàn, tí ó jẹ̀bi kí ó kú. Ṣùgbọ́n pípa ni kí a pa á.
32 Et vous n'accepterez point de rançon pour le laisser fuir dans sa ville de Refuge et en revenir et habiter dans le pays après la mort du Prêtre.
“‘Má ṣe gba ìràsílẹ̀ fún ẹnikẹ́ni tí ó bá lọ sí ìlú ìsásí, pe kí ó padà máa gbé ní ilẹ̀ tirẹ̀ kí ó tó di ìgbà ikú olórí àlùfáà.
33 Et vous ne profanerez point le pays où vous êtes, car le sang profane le pays, et pour le pays l'expiation ne peut être faite du sang qui y a été versé, que par le sang de celui qui l'a versé.
“‘Má ṣe sọ ilẹ̀ tí ẹ wà di àìmọ́. Ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́. Àtúnṣe kì yóò sí fún ilẹ̀ tí a ti ta ẹ̀jẹ̀ lé lórí, àyàfi ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó ta á sílẹ̀.
34 Et tu ne souilleras pas le pays que vous habitez, au sein duquel je réside, car moi l'Éternel je réside au milieu des enfants d'Israël.
Má ṣe sọ di àìmọ́, ilẹ̀ tí ẹ ń gbé, àti èyí tí mo ń gbé, nítorí Èmi Olúwa ń gbé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.’”

< Nombres 35 >