< Néhémie 6 >
1 Et lorsque Saneballat et Tobie et Gésem, l'Arabe, et nos autres ennemis eurent appris que j'avais restauré les murs, et qu'il n'y restait plus de brèche, quoique jusqu'à ce moment-là je n'y eusse point encore posé les battants aux portes,
Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
2 Saneballat et Gésem m'adressèrent ce message: Viens, et ayons une conférence dans les bourgs du val d'Ono! Or ils pensaient à me faire un mauvais parti.
Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé, “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.” Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi;
3 Alors je leur dépêchai des messagers pour leur dire: Une grande affaire m'occupe et je ne puis descendre: pourquoi faire cesser l'ouvrage en me relâchant et en descendant auprès de vous?
bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé, “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
4 Et ils me firent faire le même message quatre fois, et je leur renvoyai la même réponse.
Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
5 Alors Saneballat m'adressa le même message une cinquième fois par son écuyer, porteur d'une lettre ouverte.
Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀
6 Elle était conçue en ces termes: « Parmi les nations court ce bruit, et Gasmu dit: Toi et les Juifs vous pensez à vous révolter; c'est pourquoi tu relèves les murs, et tu dois devenir leur roi d'après ces dires.
tí a kọ sínú un rẹ̀ pé, “A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn
7 Tu as aussi aposté des prophètes pour te proclamer à Jérusalem en disant: Roi de Juda! Et maintenant ces propos viendront aux oreilles du roi. Viens donc afin que nous nous concertions ensemble! »
àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘Ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”
8 Et je lui envoyai ce message: Il ne s'est rien fait dans le sens que tu dis; mais c'est une imagination de ton cœur.
Mo dá èsì yìí padà sí i pé, “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”
9 Car tous ils voulaient nous intimider, et ils se disaient: De guerre lasse ils quitteront l'ouvrage qui ne s'achèvera pas. Eh bien! ô Dieu, prête force à mes mains!
Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.” Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”
10 Et j'entrai chez Semaïa, fils de Delaia, fils de Meheitabéel, or il s'était renfermé. Et il dit: Réunissons-nous dans la Maison de Dieu, dans l'intérieur du Temple, et fermons les portes du Temple, car il vient des gens pour t'assassiner, et c'est cette nuit qu'ils arrivent pour t'assassiner.
Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”
11 Et je dis: Un homme comme moi fuirait! Et quel est mon pareil qui pénétrerait dans le Temple et resterait en vie? Je n'entre point.
Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!”
12 Et je reconnus, et voilà que ce n'était pas Dieu qui l'envoyait, et il prononçait une prophétie contre moi parce que Saneballat et Tobie l'avaient soudoyé.
Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.
13 Et le but pour lequel il avait été soudoyé, c'était que je prisse peur et agisse en conséquence, et commisse un péché, et que, m'étant fait un mauvais nom, ils eussent de quoi me calomnier.
Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.
14 O mon Dieu, garde de Tobie et de Saneballat un souvenir conforme à leurs œuvres, et aussi de la prophétesse Noadia et des autres prophètes qui prétendaient m'intimider!
A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí.
15 Et le mur fut achevé le vingt-cinq Elul au bout de cinquante-deux jours.
Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli, láàrín ọjọ́ méjìléláàádọ́ta.
16 Et quand tous nos ennemis l'apprirent, tous les peuples d'alentour prirent peur, et ils furent extrêmement découragés, et ils comprirent que cette œuvre s'était accomplie de par notre Dieu.
Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.
17 Et il y eut aussi dans ce même temps beaucoup de nobles Juifs qui adressèrent des lettres à Tobie et en reçurent de Tobie.
Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.
18 Car plusieurs en Juda s'étaient conjurés avec lui. Car il était beau-frère de Sechania, fils d'Arach, et son fils Jochanan avait épousé la fille de Mesullam, fils de Béréchia.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah.
19 Même ils parlaient devant moi de ses bonnes qualités, et ils lui rapportaient mes discours. C'est pourquoi Tobie envoya des lettres pour m'intimider.
Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.