< Josué 7 >

1 Or les enfants d'Israël se rendirent coupables de soustraction de choses dévouées. Car Achan, fils de Charmi, fils de Zabdi, fils de Zérah de la Tribu de Juda, prit de ce qui était dévoué, et la colère de l'Éternel s'alluma contre les enfants d'Israël.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera, ẹ̀yà Juda, mú nínú wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ará Israẹli.
2 Cependant de Jéricho Josué envoya des hommes vers Aï qui est située près de Beth-Aven à l'orient de Béthel, en leur disant: Allez en avant et explorez le pays. Et ces hommes s'avancèrent et reconnurent Aï.
Joṣua rán àwọn ọkùnrin láti Jeriko lọ sí Ai, tí ó súnmọ́ Beti-Afeni ní ìlà-oòrùn Beteli, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ gòkè lọ kí ẹ sì ṣe ayọ́lẹ̀wò.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn arákùnrin náà lọ, wọ́n sì yọ́ Ai wò.
3 Et étant revenus auprès de Josué, ils lui dirent: Il n'y a pas lieu de mettre tout le peuple en campagne; deux ou trois mille hommes environ n'ont qu'à marcher et ils réduiront Aï; n'en donne pas la fatigue à tout le peuple, car il n'y a que peu de monde.
Nígbà tí wọ́n padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua, wọ́n wí pé, “Kì í ṣe gbogbo àwọn ènìyàn ni ó ni láti gòkè lọ bá Ai jà. Rán ẹgbẹ̀rún méjì tàbí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti gbà á, kí ó má ṣe dá gbogbo àwọn ènìyàn ní agara, nítorí ìba ọkùnrin díẹ̀ ní ó wà níbẹ̀.”
4 On ne fit donc marcher contre elle dans tout le peuple que trois mille hommes; mais ils prirent la fuite devant les hommes d'Aï.
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin lọ; ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Ai lé wọn sá.
5 Et les hommes d'Aï en tuèrent environ trente-six, et les poursuivirent depuis la porte jusqu'à Schebarim et les défirent à la descente; et le courage se fondit et s'écoula comme l'eau.
Àwọn ènìyàn Ai sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli láti ibodè ìlú títí dé Ṣebarimu, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pami.
6 Et Josué déchira ses vêtements, et fut prosterné la face contre terre devant l'Arche de l'Éternel jusqu'au soir, lui et les Anciens d'Israël, et ils lancèrent la poussière en l'air sur leurs têtes.
Joṣua sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Israẹli sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí wọn.
7 Et Josué dit: Ah! Seigneur, Éternel, pourquoi as-tu fait passer le Jourdain à ce peuple, pour nous livrer aux mains des Amoréens, pour nous perdre? si seulement nous nous étions contentés de rester au delà du Jourdain!
Joṣua sì wí pé, “Háà, Olúwa Olódùmarè, nítorí kín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá Jordani, láti fi wọ́n lé àwọn ará Amori lọ́wọ́, láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdìkejì Jordani?
8 Je te le demande, ô mon Seigneur, que puis-je dire après qu'Israël a tourné le dos devant ses ennemis?
Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Israẹli sì ti sá níwájú ọ̀tá a rẹ̀?
9 Et les Cananéens et tous les habitants du pays vont l'apprendre et nous cerner et faire disparaître notre nom de la terre. Et que veux-tu faire pour ton grand Nom?
Àwọn Kenaani àti àwọn ènìyàn ìlú tí ó kù náà yóò gbọ́ èyí, wọn yóò sì yí wa ká, wọn yóò sì ké orúkọ wa kúrò ní ayé. Kí ni ìwọ ó ha ṣe fún orúkọ ńlá à rẹ?”
10 Et l'Éternel dit à Josué: Relève-toi! pourquoi t'es-tu jeté la face contre terre?
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Dìde! Kín ni ìwọ ń ṣe tí ó fi dojúbolẹ̀?
11 Israël a péché; et même ils ont transgressé mon alliance que je leur ai prescrite, et même retenu des choses dévouées, et même dérobé et dissimulé, et ils les ont cachées parmi leurs bagages.
Israẹli ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti ba májẹ̀mú mi jẹ́, èyí tí mo pàṣẹ fún wọn pé kí wọn pamọ́. Wọ́n ti mú nínú ohun ìyàsọ́tọ̀, wọ́n ti jí, wọ́n pa irọ́, wọ́n ti fi wọ́n sí ara ohun ìní wọn.
12 C'est pourquoi les enfants d'Israël ne peuvent tenir tête à leurs ennemis, et tournent le dos devant leurs ennemis; car ils sont sous l'anathème. Je ne serai plus désormais avec vous, si vous n'exterminez pas le sacrilège du milieu de vous.
Ìdí nì èyí tí àwọn ará Israẹli kò fi lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá wọn; wọ́n yí ẹ̀yìn wọn padà, wọ́n sì sálọ níwájú ọ̀tá a wọn nítorí pé àwọn gan an ti di ẹni ìparun. Èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín mọ́, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pa ohun ìyàsọ́tọ̀ run kúrò ní àárín yín.
13 Lève-toi, mets le peuple en état de sainteté et dis: Mettez-vous pour demain en état de sainteté; car ainsi parle l'Éternel, Dieu d'Israël: Il y a un anathème au milieu de toi, Israël; vous ne sauriez tenir tête à vos ennemis jusqu'à ce que vous ayez ôté l'anathème du milieu de vous.
“Lọ, ya àwọn ènìyàn náà sí mímọ́. Sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ fún ọ̀la, nítorí báyìí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, ohun ìyàsọ́tọ̀ kan ń bẹ ní àárín yín, Israẹli. Ẹ̀yin kì yóò lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá a yín títí ẹ̀yin yóò fi mú kúrò.
14 Vous vous présenterez donc le matin par Tribus, et la Tribu que tirera l'Éternel, s'avancera par familles, et la famille que l'Éternel tirera s'avancera par maisons, et la maison que tirera l'Éternel s'avancera par individus.
“‘Ní òwúrọ̀, kí ẹ mú ará yín wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Ẹ̀yà tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní agbo ilé kọ̀ọ̀kan, agbo ilé tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, ìdílé tí Olúwa bá sì mú yóò wá sí iwájú ní ẹni kọ̀ọ̀kan.
15 Et celui qui sera désigné comme sacrilège, sera brûlé au feu, lui et tout ce qui lui appartient, pour avoir transgressé l'alliance de l'Éternel et commis un forfait en Israël.
Ẹnikẹ́ni tí a bá ká mọ́ pẹ̀lú ohun ìyàsọ́tọ̀ náà, a ó fi iná pa á run, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní. Ó ti ba májẹ̀mú Olúwa jẹ́, ó sì ti ṣe nǹkan ìtìjú ní Israẹli!’”
16 Et Josué s'étant levé le matin fit approcher Israël par Tribus, et la Tribu de Juda fut désignée.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Joṣua mú Israẹli wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, a sì mú ẹ̀yà Juda.
17 Puis il fit approcher les familles de Juda, et on tira la famille de Zérah; et il fit approcher la famille de Zérah par individus, et Zabdi fut désigné,
Àwọn agbo ilé e Juda wá sí iwájú, ó sì mú agbo ilé Sera. Ó sì mú agbo ilé Sera wá síwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, a sì mú ìdílé Sabdi.
18 et il fit approcher la maison de celui-ci par individus, et Achan, fils de Charmi, fils de Zabdi, fils de Zérah, de la Tribu de Juda fut pris.
Joṣua sì mú ìdílé Simri wá síwájú ní ọkùnrin kọ̀ọ̀kan, a sì mú Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera ti ẹ̀yà Juda.
19 Et Josué dit à Achan: Mon fils! Rends gloire à l'Éternel, Dieu d'Israël, et fais-lui hommage, et avoue-moi ce que tu as fait, et ne te cache pas de moi.
Nígbà náà ní Joṣua sọ fún Akani pé, “Ọmọ mi fi ògo fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kí o sì fi ìyìn fún un. Sọ fún mi ohun tí ìwọ ti ṣe, má ṣe fi pamọ́ fún mi.”
20 Et Achan répondit à Josué et dit: C'est la vérité; j'ai péché contre l'Éternel, Dieu d'Israël; et voici, voici comment j'ai agi:
Akani sì dáhùn pé, “Òtítọ́ ni! Mo ti ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. Nǹkan tí mo ṣe nìyìí,
21 j'aperçus dans le butin un beau manteau de Sinéar et deux cents sicles d'argent et un lingot d'or du poids de cinquante sicles, et j'ai convoité cela, et l'ai pris; et voilà, ces objets sont enfouis dans la terre au milieu de ma tente, et l'argent est dessous.
nígbà tí mo rí ẹ̀wù Babeli kan tí ó dára nínú ìkógun, àti igba ṣékélì fàdákà àti odindi wúrà olóṣùnwọ́n àádọ́ta ṣékélì, mo ṣe ojúkòkòrò wọn mo sì mú wọn. Mo fi wọ́n pamọ́ ní abẹ́ àgọ́ mi àti fàdákà ní abẹ́ rẹ̀.”
22 Et Josué dépêcha des commissaires qui coururent à la tente; et voici, les objets étaient enfouis dans sa tente, et l'argent au-dessous.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ran àwọn òjíṣẹ́, wọ́n sì sáré wọ inú àgọ́ náà, ó sì wà níbẹ̀, a sì fi pamọ́ nínú àgọ́ ọ rẹ̀, àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.
23 Et les ayant enlevés de la tente ils les apportèrent à Josué et à tous les enfants d'Israël, et ils les étalèrent devant l'Éternel.
Wọ́n sì mú àwọn nǹkan náà jáde láti inú àgọ́ rẹ̀, wọ́n mú wọn wá fún Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fi wọ́n lélẹ̀ níwájú Olúwa.
24 Alors Josué fit saisir Achan, fils de Zérah, et l'argent et le manteau et le lingot d'or et ses fils et ses filles et son bœuf et son âne et ses brebis et sa tente et tout ce qui lui appartenait, de concert avec tout Israël, et on les fit monter au val d'Achor.
Nígbà náà ni Joṣua pẹ̀lú gbogbo Israẹli, mú Akani ọmọ Sera, fàdákà, ẹ̀wù àti wúrà tí a dà, àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, màlúù rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti àgùntàn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo ohun tí ó ni, wọ́n sì kó wọn lọ sí ibi àfonífojì Akori.
25 Et Josué dit: Pourquoi nous as-tu perdus? que l'Éternel te perde aujourd'hui! Et tout Israël le lapida, et les brûla au feu, et les assaillirent de pierres.
Joṣua sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ mú wàhálà yìí wá sí orí wa? Olúwa yóò mú ìpọ́njú wá sí orí ìwọ náà lónìí.” Nígbà náà ni gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sọ àwọn tókù ní òkúta pa tán, wọ́n sì jó wọn níná.
26 Et ils élevèrent sur lui un grand tas de pierres [demeuré] jusqu'aujourd'hui. Alors l'Éternel revint de son ardente colère. C'est pour cela que ce lieu a porté le nom de Val d'Achor (perdition) jusqu'aujourd'hui.
Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé Akani lórí títí di òní yìí. Nígbà náà ní Olúwa sì yí ìbínú gbígbóná rẹ̀ padà. Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní àfonífojì Akori láti ìgbà náà.

< Josué 7 >