< Josué 5 >
1 Et lorsque tous les Rois des Amoréens qui étaient au delà du Jourdain à l'occident, et tous les Rois des Cananéens des côtes de la mer, apprirent que l'Éternel avait desséché les eaux du Jourdain devant les enfants d'Israël, jusqu'à ce que nous fussions passés, ils tremblèrent et n'eurent plus aucun courage pour tenir tête aux enfants d'Israël.
Nígbà tí gbogbo àwọn ọba Amori ti ìlà-oòrùn Jordani àti gbogbo àwọn ọba Kenaani tí ń bẹ létí òkun gbọ́ bí Olúwa ti mú Jordani gbẹ ní iwájú àwọn ọmọ Israẹli títí ti a fi kọjá, ọkàn wọn pami, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ìgboyà mọ́ láti dojúkọ àwọn ọmọ Israẹli.
2 Dans ce même temps l'Éternel dit à Josué: Fais-toi des couteaux de pierre et recommence à circoncire de nouveau les enfants d'Israël.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Fi akọ òkúta ṣe abẹ kí o sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà ní ìgbà ẹ̀ẹ̀kejì.”
3 Et Josué se fit des couteaux de pierre et circoncit les enfants d'Israël à la colline des prépuces.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua sì ṣe abẹ akọ òkúta, ó sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà, ní Gibiati-Haralotu.
4 Or voici la raison pour laquelle Josué opéra une circoncision: tout le peuple sorti de l'Egypte, les hommes, les gens de guerre en totalité étaient morts dans le désert pendant la route lors de leur sortie d'Egypte.
Wàyí o, ìdí tí Joṣua fi kọ wọ́n nílà nìyìí. Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó ti Ejibiti jáde wá, gbogbo àwọn ọkùnrin ogun kú ní aginjù ní ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
5 Car tout le peuple à sa sortie se composait de circoncis; mais tout le peuple né dans le désert pendant la route lors de la sortie d'Egypte n'avait pas été circoncis.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, gbogbo àwọn ọkùnrin tó jáde láti Ejibiti ni a ti kọ ní ilà, síbẹ̀ gbogbo ènìyàn tí a bí nínú aginjù lẹ́yìn tí wọ́n jáde ní Ejibiti ni wọn kò kọ ní ilà.
6 En effet, pendant quarante ans, les enfants d'Israël durent errer dans le désert jusqu'à l'extinction de toute cette engeance de gens de guerre, sortis de l'Egypte, pour n'avoir pas obéi à la voix de l'Éternel; ce qui fit que l'Éternel leur jura qu'il ne leur permettrait pas de voir le pays que l'Éternel avait juré à leurs pères de nous donner, pays découlant de lait et de miel.
Àwọn ará Israẹli rìn ní aginjù fún ogójì ọdún títí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó tó ogun n jà nígbà tí wọ́n kúrò ni Ejibiti fi kú, nítorí wọn kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa. Nítorí Olúwa ti búra fún wọn pé wọn kò ní rí ilẹ̀ tí òun ṣe ìlérí fún àwọn baba wọn láti fi fun wa, ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin.
7 Et l'Éternel leur substitua leurs fils; ceux-ci furent donc circoncis par Josué, parce qu'ils étaient non circoncis; car on ne les avait pas circoncis en route.
Bẹ́ẹ̀ ni ó gbé àwọn ọmọ wọn dìde dípò wọn, àwọn wọ̀nyí sì ni Joṣua kọ ní ilà. Wọ́n wà ní aláìkọlà nítorí a kò tí ì kọ wọ́n ní ilà ní ojú ọ̀nà.
8 Et quand tous ces individus eurent subi en totalité la circoncision, ils restèrent sur leur séant dans le camp jusqu'à leur rétablissement.
Lẹ́yìn ìgbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọ ilà tan, wọ́n dúró ní ibi tí wọ́n wà ní ibùdó títí ilà wọn fi jinná.
9 Et l'Éternel dit à Josué: En ce jour je vous ai déchargés de l'opprobre des Égyptiens; alors ce lieu fut appelé du nom de Guilgal (décharge) et il l'a porté jusqu'aujourd'hui.
Nígbà náà ní Olúwa wí fún Joṣua pé, “Ní òní ni mo yí ẹ̀gàn Ejibiti kúrò ní orí yín.” Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní Gilgali títí ó fi di òní yìí.
10 Et les enfants d'Israël campèrent à Guilgal, et ils célébrèrent la Pâque le quatorzième jour du mois au soir dans les plaines de Jéricho.
Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù náà, nígbà tí wọ́n pàgọ́ ní Gilgali ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko, àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ọdún àjọ ìrékọjá.
11 Et ce jour-là même ils mangèrent des denrées du pays le lendemain de la Pâque, des azymes et du grain rôti.
Ní ọjọ́ kejì àjọ ìrékọjá, ní ọjọ́ náà gan an ni, wọ́n jẹ nínú àwọn ìre oko ilẹ̀ náà: àkàrà aláìwú, àti ọkà yíyan.
12 Et la manne cessa dès ce lendemain où ils mangèrent, des denrées du pays, et les enfants d'Israël n'eurent plus de manne dès lors, et ils se nourrirent des produits du pays de Canaan cette année-là.
Manna náà sì tan ní ọjọ́ kejì tí wọ́n jẹ oúnjẹ tí ilẹ̀ náà mú jáde, kò sì sí manna kankan mọ́ fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n ní ọdún náà wọ́n jẹ ìre oko ilẹ̀ Kenaani.
13 Et comme Josué était devant Jéricho, il arriva qu'ayant levé les yeux il regardait; et voilà qu'un homme se tenait debout en face de lui, son épée nue à la main. Et Josué alla à lui et lui dit: Es-tu des nôtres ou de nos ennemis?
Nígbà tí Joṣua súnmọ́ Jeriko, ó wo òkè ó sì rí ọkùnrin kan tí ó dúró ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú idà ní ọwọ́ rẹ̀. Joṣua sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bi í pé, “Ǹjẹ́ ìwọ wà fún wa tàbí fún ọ̀tá a wa?”
14 Et il répondit: Non, mais je suis Chef d'Armée de l'Éternel; maintenant j'arrive… Alors Josué se jeta la face contre terre et se prosterna, et lui dit: Qu'est-ce que mon Seigneur veut dire à son serviteur?
“Kì í ṣe fún èyíkéyìí ó fèsì, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí olórí ogun Olúwa ni mo wá nísinsin yìí.” Nígbà náà ni Joṣua sì wólẹ̀ ní iwájú u rẹ̀ ní ìbẹ̀rù, ó sì bi í léèrè, “Kí ni Olúwa ní í sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀?”
15 Et le Chef d'Armée de l'Éternel dit à Josué: Ote tes sandales de tes pieds; car le lieu où tu te tiens est saint. Et ainsi fit Josué.
Olórí ogun Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí pé ibi tí ìwọ dúró sí yìí, ilẹ̀ mímọ́ ni.” Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀.