< Jérémie 41 >

1 Et il arriva au septième mois que Ismaël, fils de Néthania, fils d'Élisama, de la famille royale, et l'un des Grands du roi, ayant dix hommes avec lui, vint auprès de Gédalia, fils d'Achikam, à Mitspa, et là ils mangèrent ensemble à Mitspa.
Ní oṣù keje Iṣmaeli, ọmọ Netaniah ọmọ Eliṣama, nínú irú-ọmọ ọba, àti àwọn ìjòyè ọba, àti àwọn ọkùnrin mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n tọ Gedaliah ọmọ Ahikamu wá ní Mispa; níbẹ̀ ni wọ́n jùmọ̀ jẹun ní Mispa.
2 Alors Ismaël, fils de Néthania, se leva avec les dix hommes qui l'accompagnaient, et ils frappèrent Gédalia, fils d'Achikam, fils de Schaphan, avec l'épée et le tuèrent, lui que le roi de Babel avait préposé sur le pays;
Iṣmaeli ọmọ Netaniah àti àwọn ọkùnrin mẹ́wàá tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀, sì dìde wọ́n kọlu Gedaliah ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani pẹ̀lú idà. Wọ́n sì pa á, ẹni tí ọba Babeli ti fi jẹ baálẹ̀ lórí ilẹ̀ náà.
3 et Ismaël frappa aussi tous les Juifs qui étaient avec Gédalia à Mitspa, et les Chaldéens, hommes de guerre, qui s'y trouvaient.
Iṣmaeli sì tún pa gbogbo àwọn Júù tí wọ́n wà pẹ̀lú Gedaliah ní Mispa, àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun Babeli tí wọ́n wà níbẹ̀ bákan náà.
4 Et deux jours après le meurtre de Gédalia, tandis que chacun l'ignorait,
Ní ọjọ́ kejì tí wọ́n pa Gedaliah kí ó tó di wí pé ẹnikẹ́ni mọ̀,
5 il vint des hommes de Sichem, de Silo et de Samarie, au nombre de quatre-vingts, ayant la barbe coupée, et les habits déchirés, et des incisions sur le corps, et des offrandes, et de l'encens en leurs mains, pour les porter à la maison de l'Éternel.
àwọn ọgọ́rin ọkùnrin wá láti Ṣekemu, Ṣilo àti Samaria, wọ́n fa irùngbọ̀n wọn, wọ́n ya aṣọ wọn, wọ́n ṣá ara wọn lọ́gbẹ́, wọ́n mú ẹbọ ọpẹ́ àti tùràrí wá sí ilé Olúwa.
6 Alors Ismaël, fils de Néthania, sortit de Mitspa à leur rencontre; et en marchant il pleurait; et les ayant atteints il leur dit: Venez auprès de Gédalia, fils d'Achikam!…
Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah jáde kúrò láti Mispa láti lọ pàdé wọn. Ó sì ń sọkún bí ó ti ṣe ń lọ, nígbà tí ó pàdé wọn, ó wí pé, “Ẹ wá sọ́dọ̀ Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu.”
7 Et quand ils furent parvenus au milieu de la ville, Ismaël, fils de Néthania, les massacra, et les jeta dans une fosse, aidé des hommes qui l'accompagnaient.
Nígbà tí wọ́n dé ìlú náà; Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa wọ́n, wọ́n sì sọ òkú wọn sínú ihò kan.
8 Cependant parmi eux il se trouva dix hommes qui dirent à Ismaël. Ne nous fais pas mourir, car nous avons du blé, de l'orge, de l'huile et du miel enfouis sous terre dans les champs. Alors il les laissa, et ne les fit point mourir avec leurs frères.
Ṣùgbọ́n mẹ́wàá nínú wọn sọ fún Iṣmaeli pé, “Má ṣe pa wá! Àwa ní ọkà àti barle, òróró àti oyin ní ìpamọ́ nínú oko.” Nítorí náà, ó fi wọ́n sílẹ̀: kò sì pa wọ́n pẹ̀lú àwọn yòókù.
9 Or la fosse où Ismaël avait jeté tous les cadavres des hommes qu'il avait tués en même temps que Gédalia, était celle qu'avait faite le roi Asa en vue de Baësa, roi d'Israël: c'est celle-là qu'Ismaël, fils de Néthania, remplit de cadavres.
Nísinsin yìí, ihò náà tí ó kó gbogbo ara àwọn ọkùnrin tí ó ti pa pẹ̀lú Gedaliah sí ni ọba Asa ń lò gẹ́gẹ́ bí i ààbò nítorí ọba Baaṣa ti Israẹli. Iṣmaeli ọmọ Netaniah sì ti kó òkú kún inú rẹ̀.
10 Et Ismaël emmena tout le reste du peuple de Mitspa, les filles du roi et tout le peuple resté à Mitspa, que Nébuzaradan, chef des satellites, avait commis à Gédalia, fils d'Achikam, Ismaël, fils de Néthania, les emmena captifs, et il se mit en marche pour passer chez les Ammonites.
Iṣmaeli sì kó gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní Mispa nígbèkùn, ọmọbìnrin ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn tókù síbẹ̀ lórí àwọn tí Nebusaradani balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti fi yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ṣe olórí. Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah kó wọn ní ìgbèkùn, ó sì jáde rékọjá sí ọ̀dọ̀ àwọn Ammoni.
11 Cependant Jochanan, fils de Karéah, et tous les chefs de l'armée qui étaient avec lui, à l'ouïe de tous les crimes qu'avait commis Ismaël, fils de Néthania,
Nígbà tí Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀ gbọ́ nípa gbogbo ìpànìyàn náà tí Iṣmaeli ọmọ Netaniah ti ṣe.
12 prirent tous leurs hommes, et se mirent en marche pour attaquer Ismaël, fils de Néthania, et ils l'atteignirent aux grandes eaux de Gabaon.
Wọ́n kó gbogbo àwọn ọkùnrin wọn, wọ́n sì, lọ bá Iṣmaeli ọmọ Netaniah jà. Wọ́n pàdé rẹ̀ ní odò kan lẹ́bàá Gibeoni.
13 Et quand tout le peuple qui était avec Ismaël, aperçut Jochanan, fils de Karéah, et tous les chefs de l'armée avec lui, ils se réjouirent;
Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn Iṣmaeli tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀ rí Johanani ọmọkùnrin Karea àti àwọn olórí ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì yọ̀.
14 et tout le peuple qu'Ismaël avait emmené de Mitspa, fit volte-face, et revint, et joignit Jochanan, fils de Karéah;
Gbogbo àwọn ènìyàn tí Iṣmaeli ti kó ní ìgbèkùn ní Mispa yípadà, wọ́n sì lọ sọ́dọ̀ Johanani ọmọ Karea.
15 mais Ismaël, fils de Néthania, échappa avec huit hommes à Jochanan, et se rendit chez les Ammonites.
Ṣùgbọ́n Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah àti àwọn mẹ́jọ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀ bọ́ lọ́wọ́ Johanani, wọ́n sì sálọ sí Ammoni.
16 Alors Jochanan, fils de Karéah, et tous les chefs de l'armée qui étaient avec lui prirent tout le reste du peuple qu'il avait recouvré sur Ismaël, fils de Néthania, depuis Mitspa, après que celui-ci eut tué Gédalia, fils d'Achikam, hommes et gens de guerre, et femmes, et enfants, et eunuques, qu'il ramena de Gabaon;
Lẹ́yìn náà Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí wọn wà pẹ̀lú rẹ̀ sì kó gbogbo àwọn tí ó kù ní Mispa; àwọn tí ó ti rí gbà lọ́wọ́ Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah; lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa Gedaliah ọmọ Ahikamu. Àwọn ọmọ-ogun, àwọn obìnrin, àwọn ọmọdé àti àwọn olórí ilé ẹjọ́ tí ó ti kó wa láti Gibeoni.
17 et ils se mirent en marche, et prirent leur étape à l'hôtellerie de Chimham près de Bethléhem, afin d'aller en Egypte
Wọ́n sì kúrò níbẹ̀, wọ́n dúró ní Geruti Kimhamu ní ẹ̀bá Bẹtilẹhẹmu ní ọ́nà ìrìnàjò wọn sí Ejibiti.
18 pour fuir les Chaldéens; car ils les redoutaient, parce que Ismaël, fils de Néthania, avait tué Gédalia, fils d'Achikam, que le roi de Babel avait préposé sur le pays.
Láti gba àwọn Babeli sílẹ̀. Wọ́n bẹ̀rù wọn nítorí wí pé, “Iṣmaeli ọmọ Netaniah ti pa Gedaliah ọmọ Ahikamu èyí tí ọba Babeli ti yàn gẹ́gẹ́ bí i gómìnà lórí ilẹ̀ náà.”

< Jérémie 41 >