< Osée 4 >

1 Écoutez la parole de l'Éternel, enfants d'Israël! car l'Éternel fait le procès aux habitants du pays; car il n'y a ni vérité, ni amour, ni connaissance de Dieu dans le pays.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli, nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà. “Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́, Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà,
2 On jure et l'on ment, l'on est homicide, et voleur et adultère; ils font des violences; au meurtre succède le meurtre.
àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn olè jíjà àti panṣágà. Wọ́n rú gbogbo òfin, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
3 Aussi, le pays est en deuil, et tous ses habitants dans la langueur, et les bêtes des champs et les oiseaux des Cieux, même les poissons de la mer disparaissent.
Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù. Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹja inú omi ló ń kú.
4 Mais que nul ne conteste, et que nul ne reprenne! car ton peuple est comme ceux qui contestent contre les sacrificateurs.
“Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá, kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà.
5 Ainsi tu tomberas de jour, et avec toi le prophète aussi tombera de nuit, et je détruirai ta mère.
Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín. Èmi ó pa ìyá rẹ run,
6 Mon peuple est détruit faute d'avoir la connaissance… Et toi, puisque tu dédaignes la connaissance, je te dédaignerai aussi, et tu ne seras plus mon sacrificateur, et puisque tu oublies la loi de ton Dieu, j'oublierai aussi tes enfants.
àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀. “Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀. Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi; nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀, Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
7 Plus ils s'accroissent, plus ils pèchent contre moi: je changerai leur gloire en ignominie.
Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
8 Du péché de mon peuple ils tirent leur subsistance, et de son crime ils sont avides.
wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi, wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
9 Aussi en sera-t-il du peuple comme du sacrificateur, et je les châtierai de leur conduite et je leur rendrai ce qu'ils ont fait.
Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí. Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn. Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
10 Ils mangeront et ne seront point rassasiés; ils seront impudiques et ne se multiplieront pas, car ils abandonnent le culte de l'Éternel.
“Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó; wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i, nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa sílẹ̀, wọ́n sì ti fi ara wọn
11 L'impudicité et le vin et le moût ôtent le sens.
fún àgbèrè; wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́, àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù.
12 Mon peuple interroge son bois, et c'est son bâton qui l'avise, car l'esprit d'impudicité les a séduits; adultères, ils désertent leur Dieu.
Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn. Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
13 Sur les cimes des montagnes ils sacrifient, et sur les collines ils encensent, sous le chêne et le peuplier et le térébinthe, parce que l'ombrage en est beau; c'est pourquoi vos filles sont impudiques et vos brus adultères.
Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré, lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára. Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.
14 Je ne saurais punir vos filles de s'être prostituées, ni vos brus d'avoir commis adultère; car eux-mêmes vont à l'écart avec des prostituées et sacrifient avec des courtisanes, et le peuple insensé court à sa perte.
“Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín, nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́. Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà. Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!
15 Si tu es impudique, ô Israël, que Juda ne se rende pas coupable! ne venez point à Guilgal! et ne montez point à Bethaven, et ne jurez point par la vie de l'Éternel!
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli, ìdájọ́ yìí wà fún un yín. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi. “Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali. Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
16 Car telle une génisse indocile, telle Israël est indocile; maintenant l'Éternel les laissera paître comme des agneaux dans un pays ouvert.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí bí alágídí ọmọ màlúù. Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
17 Éphraïm s'est alliée aux idoles: laisse-la faire!
Efraimu ti darapọ̀ mọ́ òrìṣà, ẹ fi sílẹ̀!
18 sitôt qu'est enlevée la table où ils boivent, ils se livrent aux impudicités; leurs princes ont pour l'infamie un amour singulier.
Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán, wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè. Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
19 Le vent l'emporte de ses ailes, et ils sont confus de leurs sacrifices.
Ìjì ni yóò gbá wọn lọ. Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.

< Osée 4 >