< Ézéchiel 48 >
1 Or, voici les noms des tribus. Depuis l'extrémité au nord, à côté du chemin de Hethlon, jusqu'à Hamath, Hatsar-Enon, frontière de Damas, vers le nord près de Hamath, que cela lui appartienne de l'orient à l'occident: Dan, une tribu.
“Ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn: “Ní òpin àríwá, Dani yóò ni ìpín kan; èyí yóò tẹ̀lé ọ̀nà Hetiloni lọ sí Lebo-Hamati; Hasari-Enani àti ààlà àríwá tí Damasku tí ó kángun sí Hamati yóò jẹ́ ara ààlà rẹ̀ láti ìhà ìlà-oòrùn títí lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
2 Et aux confins de Dan, de l'orient à l'occident: Asser, une tribu.
Aṣeri yóò ní ìpín kan; yóò jẹ́ ààlà agbègbè Dani láti ìlà-oòrùn lọ sí ìwọ̀-oòrùn.
3 Et aux confins d'Asser, de l'orient à l'occident: Nephthali, une tribu.
Naftali yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbègbè Aṣeri láti ìlà-oòrùn lọ sí ìwọ̀-oòrùn.
4 Et aux confins de Nephthali, de l'orient à l'occident: Manassé, une tribu.
Manase yóò ní ìpín; èyí yóò jẹ́ ààlà ti agbègbè Naftali láti ìlà-oòrùn sí ìwọ̀-oòrùn.
5 Et aux confins de Manassé, de l'orient à l'occident: Éphraïm, une tribu.
Efraimu yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbègbè Manase láti ìlà-oòrùn lọ sí ìwọ̀-oòrùn.
6 Et aux confins d'Éphraïm, de l'orient à l'occident: Ruben, une tribu.
Reubeni yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbègbè Efraimu láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀-oòrùn.
7 Et aux confins de Ruben, de l'orient à l'occident: Juda, une tribu.
Juda yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbègbè Reubeni láti ìlà-oòrùn lọ sí ìwọ̀-oòrùn.
8 Et à la frontière de Juda, de l'orient à l'occident, sera la portion que vous prélèverez, de vingt-cinq mille perches en largeur et en longueur, comme les autres lots, de l'orient à l'occident, et le sanctuaire sera à son centre.
“Ní agbègbè Juda, láti ìhà ìlà-oòrùn dé ìhà ìwọ̀-oòrùn ni yóò jẹ́ ìpín tí ìwọ yóò gbé kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn pàtàkì. Èyí tí yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní ìbú, gígùn rẹ̀ láti ìlà-oòrùn lọ sí ìwọ̀-oòrùn yóò jẹ́ bákan náà bí ọ̀kan nínú àwọn ìpín ìyókù; láti ìhà ìlà-oòrùn dé ìhà ìwọ̀-oòrùn, ibi mímọ́ yóò sì wà ní àárín gbùngbùn rẹ̀.
9 La portion que vous prélèverez pour l'Éternel aura vingt-cinq mille perches en longueur et dix mille en largeur.
“Ìpín pàtàkì tí ìwọ yóò fi fún Olúwa yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní gígùn àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìgbọ̀nwọ́ ni ìbú.
10 Et c'est aux prêtres qu'appartiendra cette portion sainte ayant au nord vingt-cinq mille perches, et à l'occident dix mille en largeur, et à l'orient dix mille en largeur, et au midi vingt-cinq mille en longueur. Et le sanctuaire de l'Éternel sera à son centre.
Èyí yóò jẹ́ ìpín ibi mímọ́ fún àwọn àlùfáà. Èyí yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ni gígùn ní ìhà àríwá, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìgbọ̀nwọ́ ni ìhà ìlà-oòrùn, ó sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn ní ìhà gúúsù. Ní àárín gbùngbùn rẹ̀ ní ilé fún Olúwa yóò wà.
11 Elle appartiendra aux prêtres consacrés, enfants de Tsadok, qui ont maintenu mon service, n'ont pas déserté, quand les enfants d'Israël désertèrent, comme les lévites ont déserté.
Èyí yóò wà fún àwọn àlùfáà tí a yà sí mímọ́, àwọn ọmọ Sadoku tí wọn jẹ́ olóòtítọ́ nínú sí sìn mí, tiwọn kò sì ṣáko lọ bí ti àwọn Lefi ṣe ṣe nígbà tí àwọn Israẹli ṣáko lọ.
12 Sur la portion du pays ils auront une portion très sainte, aux confins des lévites.
Èyí yóò jẹ́ ọrẹ pàtàkì fún wọn láti ara ìpín ibi mímọ́ ilẹ̀ náà, ìpín tí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ, tí ó jẹ́ ààlà agbègbè àwọn Lefi.
13 Et les lévites recevront parallèlement à la limite des prêtres vingt-cinq mille perches en longueur, et dix mille en largeur; totalité de la longueur, vingt-cinq mille, et de la largeur, dix mille.
“Ní àkọjúsí agbègbè àwọn àlùfáà, àwọn Lefi yóò pín ìpín kan tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìgbọ̀nwọ́ ní ìbú. Gígùn rẹ̀ ní àpapọ̀ yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́, àti inú rẹ̀ yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìgbọ̀nwọ́.
14 Ils n'en vendront et n'en échangeront rien; et les prémices du pays ne seront point aliénées, car elles sont consacrées à l'Éternel.
Wọn kò gbọdọ̀ tà tàbí pààrọ̀ ọ̀kankan nínú rẹ̀. Èyí yìí ni ó dára jùlọ lára ilẹ̀ náà, a kò sì gbọdọ̀ fi fún ẹlòmíràn nítorí pé ó jẹ́ mímọ́ fún Olúwa.
15 Et cinq mille perches qui restent en largeur, sur vingt-cinq mille [de longueur], formeront le terrain commun de la ville, pour les habitations et la banlieue, et la ville sera au centre.
“Agbègbè tí o ṣẹ́kù, tí ń ṣe ẹgbẹ̀rún márùn-ún ìgbọ̀nwọ́ ni ìbú àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn, yóò jẹ́ ibi àìmọ́ fun ìlú ńlá náà fún ilé gbígbé àti fún agbègbè. Ìlú ńlá náà yóò wà ní àárín rẹ̀,
16 Et voici ses dimensions: le côté du nord quatre mille cinq cents, et le côté du midi quatre mille cinq cents, et le côté de l'orient quatre mille cinq cents, et le côté de l'occident quatre mille cinq cents.
ìwọ̀nyí sì níbi a ṣe wọ́n ọ́n: ní ìhà àríwá ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ìgbọ̀nwọ́, ni ìhà gúúsù ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ìgbọ̀nwọ́, ní ìhà ìlà-oòrùn ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ìgbọ̀nwọ́ àti ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ìgbọ̀nwọ́.
17 Et la ville aura une banlieue: au nord deux cent cinquante, et au midi deux cent cinquante, et à l'orient deux cent cinquante, et à l'occident deux cent cinquante.
Ilẹ̀ ìjẹ fún àwọn ẹran ọ̀sìn fún ìlú ńlá náà yóò jẹ igba àti àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́ ní ìhà gúúsù, ìgbà àti ìgbà pẹ̀lú àádọ́ta ìgbọ̀nwọ́ ní ìhà ìwọ̀-oòrùn.
18 Et de ce qui restera en longueur, parallèlement à la portion sainte, dix mille perches à l'orient et dix mille à l'occident parallèlement à la portion sainte, son produit sera pour l'entretien des ouvriers de la ville;
Èyí tí ó kù ní agbègbè náà, tí ó jẹ́ àkọjúsí ìpín ibi mímọ́, gígùn rẹ̀ yóò sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìgbọ̀nwọ́ ni ìhà ìlà-oòrùn àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìgbọ̀nwọ́ ní ìhà ìwọ̀-oòrùn. Ìpèsè rẹ̀ yóò fi kún oúnjẹ fún àwọn òṣìṣẹ́ ìlú ńlá náà.
19 et il sera cultivé par les ouvriers de la ville, pris de toutes les tribus d'Israël.
Àwọn òṣìṣẹ́ láti ìlú ńlá náà, tí ó ń dá oko níbẹ̀ yóò wá láti gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli.
20 Toute la portion prélevée est de vingt-cinq mille [perches en longueur] sur vingt-cinq mille [en largeur]; vous ferez de la portion sainte un carré séparé où sera comprise la propriété de la ville.
Gbogbo ìpín náà yóò rí bákan náà ní ẹ̀gbẹ́ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, èyí yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan. Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn pàtàkì ìwọ yóò fi ìpín ibi mímọ́ sí ẹ̀gbẹ́ kan, papọ̀ mọ́ ohun ìní ìlú ńlá náà.
21 Et au prince appartiendra ce qui reste des deux côtés de la portion sainte et de la propriété de la ville, le long des vingt-cinq mille perches de la portion sainte jusqu'à la limite orientale, et à l'occident le long des vingt-cinq mille sur la limite occidentale; [cet espace] parallèle aux lots [des tribus] appartiendra au prince, et la portion sainte et le sanctuaire de la maison seront au milieu.
“Èyí tí ó ṣẹ́kù ni ẹ̀gbẹ́ méjèèjì agbègbè tí ó jẹ́ ìpín ibi mímọ́ àti ohun ìní ìlú ńlá náà yóò jẹ́ ti àwọn ọmọ-aládé. Èyí yóò lọ títí dé ìhà ìlà-oòrùn láti ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ti ìpín ibi mímọ́ títí dé ààlà ìlà-oòrùn. Agbègbè méjèèjì wọ̀nyí ni gígùn àwọn ìpín ẹlẹ́yàmẹ́yà yóò jẹ́ ti àwọn ọmọ-aládé, àti ìpín ibi mímọ́ pẹ̀lú tẹmpili yóò wa ní àárín wọn.
22 Or, de la part des lévites et de la propriété de la ville (qui coupent la propriété du prince) ce qui est entre la limite de Juda et la limite de Benjamin, appartiendra au prince.
Ilẹ̀ ìní àwọn Lefi àti ohun ìní ìlú ńlá náà yóò wà ni àárín agbègbè tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ-aládé. Agbègbè tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ-aládé yóò wà ní àárín ààlà tí Juda àti ààlà tí Benjamini.
23 Les autres tribus sont, de l'orient à l'occident: Benjamin, une tribu.
“Ní ti àwọn ẹ̀yà tí ó kù: “Benjamini yóò ní ìpín kan; èyí yóò wà láti ìhà ìlà-oòrùn títí dé ìhà ìwọ̀-oòrùn.
24 Et aux confins de Benjamin, de l'orient à l'occident: Siméon, une tribu.
Simeoni yóò ní ìpín kan: èyí yóò jẹ́ ààlà agbègbè Benjamini láti ìlà-oòrùn lọ sí ìwọ̀-oòrùn.
25 Et aux confins de Siméon, de l'orient à l'occident: Issaschar, une tribu.
Isakari yóò ní ìpín kan: èyí yóò jẹ́ ààlà agbègbè Simeoni láti ìlà-oòrùn sí ìwọ̀-oòrùn.
26 Et aux confins d'Issaschar, de l'orient à l'occident: Zabulon, une tribu.
Sebuluni yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbègbè Isakari láti ìlà-oòrùn sí ìwọ̀-oòrùn.
27 Et aux confins de Zabulon, de l'orient à l'occident: Gad, une tribu.
Gadi yóò ní ìpín; èyí yóò jẹ́ ààlà agbègbè Sebuluni láti ìlà-oòrùn sí ìwọ̀-oòrùn.
28 Et aux confins de Gad, du côté du midi, la frontière sera depuis Thamar aux Eaux de querelle, de Kadès jusqu'au fleuve, à la grande mer.
Ààlà tí gúúsù Gadi yóò dé gúúsù láti Tamari lọ sí odò Meriba Kadeṣi lẹ́yìn náà títí dé odo ti Ejibiti lọ sí Òkun ńlá.
29 Tel est le pays que vous devez partager au sort par héritages aux tribus d'Israël, et ce sont là leurs portions, dit le Seigneur, l'Éternel.
“Èyí ni ilẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi ìbò pín ní ogún fún àwọn ẹ̀yà Israẹli, wọ̀nyí sì ni ìpín wọn,” ní Olúwa Olódùmarè wí.
30 Et voici les issues de la ville: Du côté du nord, sa dimension sera de quatre mille cinq cents [perches],
“Ìwọ̀nyí ní yóò jẹ́ ẹnu-ọ̀nà àbájáde ìlú ńlá náà: “Bẹ̀rẹ̀ láti ìhà àríwá, ti ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó lè ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ìgbọ̀nwọ́ ni gígùn,
31 et les portes de la ville auront le nom des tribus d'Israël; il y en aura trois au nord: la porte de Ruben, une porte; la porte de Juda, une porte; la porte de Lévi, une porte.
ẹnu-ọ̀nà ìlú ńlá náà ní àwa yóò fi orúkọ àwọn ẹ̀yà Israẹli pè. Àwọn ọ̀nà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ní ìhà àríwá ní yóò jẹ́ ọ̀nà tí Reubeni, ọ̀nà tí Juda ọ̀nà tí Lefi.
32 Et du côté de l'orient quatre mille cinq cents perches, et trois portes: la porte de Joseph, une porte; la porte de Benjamin, une porte; la porte de Dan, une porte.
Ní ìhà ìlà-oòrùn, èyí tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn, ni ojú ọ̀nà mẹ́ta yóò wà: ọ̀nà Josẹfu, ọ̀nà tí Benjamini àti ọ̀nà tí Dani.
33 Et au midi quatre mille cinq cents perches de dimension, et trois portes: la porte de Siméon, une porte; la porte d'Issaschar, une porte; la porte de Zabulon, une porte.
Ní ìhà gúúsù, èyí tí wíwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó lè ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ìgbọ̀nwọ́ ní ojú ọ̀nà mẹ́ta yóò wà: ojú ọ̀nà Simeoni, ojú ọ̀nà Isakari àti ojú ọ̀nà Sebuluni.
34 A l'occident, quatre mille cinq cents perches, leurs portes au nombre de trois: la porte de Gad, une porte; la porte d'Asser, une porte; la porte de Nephthali, une porte.
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, èyí tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́rin ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ìgbọ̀nwọ́ ni gígùn, ní ojú ọ̀nà mẹ́ta yóò wà: ojú ọ̀nà Gadi, ojú ọ̀nà Aṣeri àti ojú ọ̀nà Naftali.
35 Circonférence, dix-huit mille perches: et le nom de la ville sera désormais « l'Éternel est ici. »
“Jíjìnnà rẹ̀ yípo yóò jẹ́ ẹgbàá mẹ́sàn ìgbọ̀nwọ́. “Orúkọ ìlú náà láti ìgbà náà yóò jẹ́: ‘Olúwa wà níbẹ̀.’”