< Ézéchiel 43 >
1 Et il me conduisit à la porte, à la porte qui donnait à l'orient.
Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà mú mi gba ti ẹnu-ọ̀nà tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn,
2 Et voici, la gloire du Dieu d'Israël s'avançait de l'orient, et son retentissement était comme le retentissement des grandes eaux,
mo sì ri ògo Ọlọ́run Israẹli ń bọ láti ìhà ìlà-oòrùn. Ohùn rẹ̀ dàbí híhó omi, ìtànṣán ògo rẹ̀ sì bo ilẹ̀.
3 et la terre était éclairée de sa splendeur. Et c'était un aspect comme celui de la vision que j'avais eue, comme la vision que j'avais eue, lorsque je vins annoncer la ruine de la ville, et c'était une vision pareille à celle que j'avais eue près du fleuve Chébar. Et je tombai sur mon visage.
Ó sì dàbí ìran tí mo rí, gẹ́gẹ́ bí ìran tí mo rí nígbà tí mo wá láti pa ìlú náà run; ìran náà sì dà bí ìran tí mo rí lẹ́bàá odò Kebari, mo sì dojú mi bolẹ̀.
4 Et la gloire de l'Éternel entra dans la maison par la porte qui donnait à l'orient,
Ògo Olúwa gba ọ̀nà tí o dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn wọ inú ilé Ọlọ́run wá.
5 et l'Esprit me souleva et me transporta dans le parvis intérieur, et voici, la gloire de l'Éternel remplissait la maison;
Mo ni ìrusókè ẹ̀mí, ó sì mú mi lọ inú ilé ìdájọ́, sì kíyèsi ògo Olúwa kún inú ilé Ọlọ́run.
6 et j'entendis quelqu'un qui me parlait depuis la maison, et un homme se tenait à côté de moi.
Nígbà tí ọkùnrin náà dúró ní ẹ̀gbẹ́ mi, mo gbọ́ ẹnìkan tí ó bá mi sọ̀rọ̀ láti inú ilé Ọlọ́run.
7 Et Il me dit: Fils de l'homme, c'est ici la place de mon trône, et la place de la plante de mes pieds, où je résiderai parmi les enfants d'Israël, éternellement. Et la maison d'Israël ne déshonorera plus mon saint nom, ni eux, ni leurs rois, par leur impudicité, et par les cadavres de leurs rois sur leurs tertres,
Ó sì wí pé, “Ọmọ ènìyàn, èyí yìí ni ibi ìgúnwà mi àti ibi tí ó wà fún àtẹ́lẹsẹ̀ mi. Ibi yìí ni èmi yóò máa gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli títí láéláé. Ilé Israẹli kò ní ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mọ́ láéláé àwọn tàbí àwọn ọba wọn nípa àgbèrè àti àwọn ère aláìlẹ́mìí àwọn ọba wọn ní ibi gíga.
8 quand ils mettaient leurs seuils à côté de mon seuil et leurs portes près de mes portes, tandis qu'il y a un mur entre moi et eux; et ainsi, ils souillèrent mon saint nom par les abominations qu'ils commirent; c'est pourquoi je les ai détruits dans ma colère.
Nígbà tí wọ́n ba gbé ìloro ilé wọn kángun sí ìloro ilé mi àti ìlẹ̀kùn wọn sì ẹ̀gbẹ́ ìlẹ̀kùn mi, pẹ̀lú ògiri nìkan ní àárín èmi pẹ̀lú wọn, wọ́n ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ìwà ìríra wọn. Nígbà náà ni mo pa wọ́n run ní ìbínú mi.
9 Maintenant leur impudicité et les cadavres de leurs rois demeureront loin de moi, et j'habiterai au milieu d'eux éternellement.
Nísinsin yìí jẹ́ kí wọn mú ìwà àgbèrè wọn àti àwọn ère aláìlẹ́mìí àwọn ọba wọn kúrò ni iwájú mi, èmi yóò sì gbé àárín wọn láéláé.
10 Or toi, fils de l'homme, montre à la maison d'Israël cette maison, afin qu'ils rougissent de leurs crimes, et qu'ils mesurent l'édifice.
“Ọmọ ènìyàn, ṣàpèjúwe ilé Ọlọ́run náà fún àwọn ènìyàn Israẹli kí ojú ẹ̀ṣẹ̀ wọn, lè tì wọ́n sì jẹ́ kí wọn wo àwòrán ilé náà,
11 Et s'ils rougissent de tout ce qu'ils ont fait, expose-leur le plan de cette maison, et sa disposition, et ses issues et ses entrées, et toute sa disposition et toutes ses règles, et toute sa disposition et toutes ses lois, et mets-en sous leurs yeux la description, afin qu'ils retiennent son plan dans son entier, et toutes ses règles, et qu'ils s'y conforment.
tí ojú gbogbo ohun tí wọn ti ṣe bá tì wọ́n, jẹ́ kí wọ́n mọ̀ àwòrán ilé Ọlọ́run náà bí wọ́n ṣe tò ó lẹ́sẹẹsẹ, àbájáde àti àbáwọlé rẹ̀ gbogbo àwòrán àti gbogbo òfin àti ìlànà rẹ̀. Kọ ìwọ̀nyí sílẹ̀ ní iwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ́ olóòtítọ́ si àwòrán rẹ̀, kí wọ́n sì tẹ̀lé gbogbo òfin rẹ̀.
12 Telle est la loi de la maison. Sur le sommet de la montagne, dans toute l'étendue de son enceinte, que tout soit un lieu très saint. Voici, c'est là la loi de la maison.
“Èyí yìí ní òfin ilé Ọlọ́run náà. Gbogbo àyíká lórí òkè gíga ní yóò jẹ́ ibi mímọ́ jùlọ. Bí èyí ni òfin tẹmpili náà.
13 Et voici les mesures de l'autel en coudées, la coudée d'une coudée et une palme: le foyer une coudée, et une coudée de largeur; et le rebord qui terminait son contour avait un empan de largeur; tel est le support de l'autel.
“Ìwọ̀nyí ni wíwọ̀n pẹpẹ ìrúbọ ní gígùn ìgbọ̀nwọ́, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ni jíjìn, ó sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ni ìbú, igun rẹ̀ yípo àti etí rẹ̀ jẹ́ ìbú àtẹ́lẹwọ́ kan. Èyí yìí sì ni gíga pẹpẹ ìrúbọ náà.
14 Et depuis la base de terre jusqu'à la première partie rentrante il y aura deux coudées, et une coudée de largeur; et depuis cette partie rentrante qui est plus petite, jusqu'à la plus grande, il y aura quatre coudées, et en largeur une coudée.
Láti ìsàlẹ̀ rẹ̀ ni ilẹ̀ títí dé ìsàlẹ̀ igun rẹ̀, ó jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjì ni gíga o sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ní ìbú. Láti igun rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ títí dé igun rẹ̀ ti òkè tí ó yípo pẹpẹ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní gíga, igun náà sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan ní ìbú.
15 Et le harel aura quatre coudées, et au-dessus de l'ariel seront les quatre cornes:
Ibi ìdáná pẹpẹ ìrúbọ náà jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin ní gíga, ìwo mẹ́rẹ̀ẹ̀rin sì yọrí jáde sókè láti ibi ìdáná.
16 et l'ariel aura douze coudées de longueur sur douze coudées de largeur, en carré, et à ses quatre côtés.
Ibi ìdáná pẹpẹ náà jẹ́ igun mẹ́rin mẹ́rin lọ́gbọọgba, ìgbọ̀nwọ́ méjìlá ní gígùn, o sì jẹ ìgbọ̀nwọ́ méjìlá ní ìbú.
17 Et la partie rentrante [supérieure] aura quatorze coudées de longueur sur quatorze coudées de largeur à ses quatre côtés, et le rebord qui terminera son contour aura une demi-coudée, et sa base sera d'une coudée tout autour, et son escalier tourné à l'orient.
Igun ni apá òkè náà jẹ́ igun mẹ́rin lọ́gbọọgba, ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rìnlá ní gígùn, ó sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rìnlá ní ìbú, pẹ̀lú etí tí ó jẹ́ ìdajì ìgbọ̀nwọ́, ìsàlẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan yípo. Àtẹ̀gùn pẹpẹ ìrúbọ náà dojúkọ ìlà-oòrùn.”
18 Et il me dit: Fils de l'homme, ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Ce sont les règlements de l'autel pour le temps où on le fera, afin d'y sacrifier les holocaustes, et d'y répandre le sang.
Lẹ́yìn náà, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ̀nyí yóò jẹ́ òfin fún ìrúbọ ẹbọ sísun àti wíwọ̀n ẹ̀jẹ̀ sórí pẹpẹ nígbà tí a bá mọ pẹpẹ tán.
19 Aux prêtres, aux lévites de la race de Tsadok, qui s'approchent de moi pour me servir, dit le Seigneur, l'Éternel, tu donneras un jeune taureau comme victime pour le péché,
Ẹ̀yin ní láti mú ọ̀dọ́ akọ màlúù gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrékọjá fún àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi, tí ìdílé Sadoku tí ó wá sí agbègbè láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ fún mi ní Olúwa Olódùmarè wí.
20 et tu prendras de son sang, et tu l'en teindras à ses quatre cornes, et aux quatre angles de la partie rentrante, et au rebord qui l'entoure, et ainsi tu en feras la purification et l'expiation.
Ẹ ni láti mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, kí ẹ sì fi sórí ìwo mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà lórí pẹpẹ, àti lórí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ìjókòó náà àti sí gbogbo etí rẹ̀ yípo, ìwọ yóò sì sọ pẹpẹ di mímọ́, ìwọ yóò sì ṣe ètùtù rẹ̀.
21 Et tu prendras le taureau expiatoire, et le brûleras dans un lieu déterminé de la maison en dehors du sanctuaire.
Ìwọ gbọdọ̀ mú akọ màlúù fún ìrékọjá, ìwọ yóò sì sun ún ní apá ibi tí a sàmì sí ní agbègbè ilé Ọlọ́run ní ìta ibi mímọ́.
22 Et le second jour, tu offriras un bouc sans défaut en expiation du péché, et on fera l'expiation de l'autel, comme on l'aura faite avec le taureau.
“Ní ọjọ́ kejì ìwọ yóò fi ewúrẹ́, òbúkọ aláìlábàwọ́n fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, a sì gbọdọ̀ sọ pẹpẹ di mímọ́ gẹ́gẹ́ bí a ti ṣọ́ di mímọ́ pẹ̀lú akọ màlúù.
23 Et quand tu auras terminé l'expiation, tu offriras un jeune taureau sans défaut, et un bélier du troupeau, sans défaut,
Nígbà tí ìwọ bá parí ìsọdimímọ́, ìwọ yóò fi ọ̀dọ́ akọ màlúù àti ọ̀dọ́ àgbò aláìlábàwọ́n láti inú agbo fún ìrúbọ.
24 et tu les offriras à l'Éternel; et les prêtres répandront du sel sur eux et les offriront en holocauste à l'Éternel.
Ìwọ yóò mú wọn lọ sí iwájú Olúwa, àwọn àlùfáà ni yóò fi iyọ̀ wọ́n wọn, wọn yóò sì fi wọ́n rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
25 Pendant sept jours tu sacrifieras journellement un bouc comme victime expiatoire; et ils sacrifieront un jeune taureau et un bélier du troupeau sans défaut.
“Fún ọjọ́ méje, ìwọ ní láti pèsè akọ ewúrẹ́ kan lójoojúmọ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀; ìwọ yóò sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù àti àgbò láti inú agbo, méjèèjì yóò sì jẹ́ aláìlábàwọ́n.
26 Pendant sept jours ils feront l'expiation de l'autel, et sa purification et sa consécration:
Fún ọjọ́ méje wọn yóò jẹ́ ètùtù fún pẹpẹ, wọn yóò sì sọ ọ́ di mímọ́; nípa bẹ́ẹ̀ wọn yóò yà á sọ́tọ̀.
27 et ces jours étant accomplis, le huitième jour et dès lors les prêtres offriront sur l'autel vos holocaustes et vos offrandes, et je vous recevrai favorablement, dit le Seigneur, l'Éternel.
Ní ìparí ọjọ́ wọ̀nyí, láti ọjọ́ mẹ́jọ síwájú, àwọn àlùfáà ni yóò gbé àwọn ẹbọ sísun rẹ àti ẹbọ ìdàpọ̀ rẹ̀ kalẹ̀ lórí pẹpẹ. Lẹ́yìn náà, èmi yóò tẹ́wọ́gbà yín ní Olúwa Olódùmarè wí.”