< Ézéchiel 34 >
1 Et la parole de l'Éternel me fut adressée en ces mots:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ mi wá:
2 Fils de l'homme, prophétise contre les pasteurs d'Israël! prophétise et dis-leur, aux pasteurs: Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Malheur aux pasteurs d'Israël, qui sont pasteurs d'eux-mêmes! Les pasteurs ne devraient-ils pas être pasteurs du troupeau?
“Ọmọ ènìyàn, fi àsọtẹ́lẹ̀ tako Olùṣọ́-àgùntàn Israẹli; sọtẹ́lẹ̀ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn Israẹli tí ó ń tọ́jú ara wọn nìkan! Ṣé ó dára kí olùṣọ́-àgùntàn ṣaláì tọ́jú agbo ẹran?
3 Vous mangez la graisse et vous vous habillez de la laine, vous tuez ce qu'on a engraissé; mais vous ne paissez point les brebis;
Ìwọ jẹ wàrà. O sì wọ aṣọ olówùú sí ara rẹ, o sì ń pa ẹran tí ó wù ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò tọ́jú agbo ẹran.
4 vous ne fortifiez point celles qui sont faibles, et ne guérissez point les malades, et ne mettez point de bandage aux blessées, et ne ramenez point celles qui s'égarent, et ne cherchez point celles qui se perdent, et vous exercez sur elles une domination violente et tyrannique.
Ìwọ kò ì tí ì mú aláìlágbára lára le tàbí wo aláìsàn sàn tàbí di ọgbẹ́ fún ẹni tí o fi ara pa. Ìwọ kò í tí ì mú aṣáko padà tàbí wá ẹni tí ó nù. Ìwọ ṣe àkóso wọn ní ọ̀nà lílé pẹ̀lú ìwà òǹrorò.
5 Et ainsi elles se sont dispersées faute de pasteur, et sont devenues la proie de toutes les bêtes des champs, et elles ont été dispersées.
Nítorí náà wọn fọ́n káàkiri nítorí àìsí olùṣọ́-àgùntàn, nígbà tí wọ́n fọ́nká tán wọn di ìjẹ fún gbogbo ẹranko búburú.
6 Mes brebis sont errantes sur toutes les montagnes et sur toutes les hautes collines, et mes brebis sont éparses sur tout le pays; et personne qui s'en occupe et personne qui les cherche.
Àgùntàn mi n rin ìrìn àrè kiri ní gbogbo àwọn òkè gíga àti òkè kékeré. A fọ́n wọn ká gbogbo orí ilẹ̀ ẹni kankan kò sì wá wọn.
7 Aussi, pasteurs, écoutez la parole de l'Éternel!
“‘Nítorí náà, ìwọ olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
8 Par ma vie, dit le Seigneur, l'Éternel, parce que mes brebis sont devenues la proie, devenues la pâture de toutes les bêtes des champs, faute de pasteurs, et parce que mes pasteurs ne se sont point occupés de mes brebis, et n'ont été pasteurs que d'eux-mêmes, mais n'ont point été pasteurs de mes brebis;
Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè ní Olúwa Olódùmarè wí, nítorí pé agbo ẹran mi kò ní olùṣọ́-àgùntàn nítorí tí a kọ̀ wọ́n, tì wọ́n sì di ìjẹ fún ẹranko búburú gbogbo àti pé, nítorí tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn mi kò ṣe àwárí agbo ẹran mi, ṣùgbọ́n wọn ń ṣe ìtọ́jú ara wọn dípò ìtọ́jú agbo ẹran mi,
9 pour cela, pasteurs, écoutez la parole de l'Éternel!
nítorí náà, ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
10 Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: J'en veux aux pasteurs, et je leur redemanderai mes brebis, et les ferai cesser de paître mes brebis, et ils ne seront plus pasteurs d'eux-mêmes, et je retirerai mes brebis de leur bouche, afin qu'elles ne soient plus leur pâture.
Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìlòdì sí àwọn Olùṣọ́-àgùntàn, èmi yóò sì béèrè agbo ẹran mi lọ́wọ́ wọn. Èmi yóò sì mú wọn dẹ́kun àti máa darí agbo ẹran mi, tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà kò sì ní lè bọ́ ara wọn mọ́. Èmi yóò gba agbo ẹran mi kúrò ni ẹnu wọn, kì yóò sì jẹ́ oúnjẹ fún wọn mọ́.
11 Car ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Voici, je veux moi-même m'enquérir de mes brebis et m'occuper d'elles.
“‘Nítorí èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi fúnra mi yóò wá àgùntàn mi kiri, èmi yóò sì ṣe àwárí wọn.
12 Comme un pasteur s'occupe de son troupeau, quand il est au milieu de ses brebis éparses, ainsi je veux m'occuper de mon troupeau, et les retirer de tous les lieux où ils auront été dispersés au jour nébuleux et sombre,
Gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn ṣe fojú tó agbo ẹran rẹ̀ tí ó fọ́nká nígbà tí ó wà pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe fojú tó àgùntàn mi. Èmi yóò gbá wọn kúrò ni gbogbo ibi tí wọ́n fọ́nká sí ni ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn.
13 et les faire revenir du milieu des peuples, et les recueillir des pays divers et les ramener dans leur pays, et les paître sur les montagnes d'Israël, dans les vallées et dans tous les lieux habités du pays:
Èmi yóò mú wọn jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì kó wọn jọ láti inú àwọn ìlú, èmi yóò sì mú wọn wá sí ilẹ̀ ara wọn. Èmi yóò mú wọn jẹ ni orí àwọn òkè gíga Israẹli, ni àárín àwọn òkè àti ní gbogbo ibùdó ilẹ̀ náà.
14 je les ferai paître sur un bon pâturage, et leur pacage sera sur les hautes montagnes d'Israël; là elles reposeront dans un bon pacage, et auront de gras pâturages sur les montagnes d'Israël:
Èmi yóò ṣe ìtọ́jú wọn ní pápá oko tútù dáradára, àní orí àwọn òkè gíga ti Israẹli ni yóò jẹ́ ilẹ̀ ìjẹ koríko wọ́n. Níbẹ̀ wọn yóò dùbúlẹ̀ ní ilẹ̀ ìjẹ koríko dídára, níbẹ̀ wọn yóò jẹun ní pápá oko tútù tí ó dara ní orí òkè ti Israẹli.
15 je serai moi-même le pasteur de mes brebis, et moi-même je les parquerai, dit le Seigneur, l'Éternel;
Èmi fúnra mi yóò darí àgùntàn mi, èmi yóò mú wọn dùbúlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
16 je veux chercher les brebis perdues, et ramener celles qui sont égarées, et mettre un bandage aux blessées, et fortifier les malades; mais les brebis grasses et vigoureuses, je veux les détruire, et les paître comme la justice le veut.
Èmi yóò ṣe àwárí àwọn tí ó nú, èmi yóò mú àwọn tí ó ń rin ìrìn àrè kiri padà. Èmi yóò di ọgbẹ́ àwọn tí ó fi ara pa, èmi yóò sì fún àwọn aláìlágbára ni okun, ṣùgbọ́n àwọn tí ó sanra tí ó sì ni agbára ní èmi yóò parun. Èmi yóò ṣe olùṣọ́ àwọn agbo ẹran náà pẹ̀lú òdodo.
17 Vous donc, mes brebis! ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Voici, je serai juge entre brebis et brebis, entre béliers et boucs.
“‘Ní tìrẹ, agbo ẹran mi, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn, àti láàrín àgbò àti ewúrẹ́.
18 Est-ce trop peu pour vous, [brebis vigoureuses]? Vous broutez le meilleur pâturage, et ce qui reste de votre pâture, vous le foulez sous vos pieds; vous buvez une eau pure, et le reste vous le troublez avec vos pieds;
Ṣé oúnjẹ jíjẹ ní pápá oko tútù dídára kò tó yín! Ṣé ó jẹ́ dandan fún ọ láti fi ẹsẹ̀ tẹ pápá oko tútù rẹ tí ó kù? Ṣé omi tí ó tòrò kò tó fún yín ní mímu? Ṣe dandan ni kí ó fi ẹrẹ̀ yí ẹsẹ̀ yín?
19 et mes brebis sont réduites à brouter ce que vos pieds ont foulé, et à boire ce que vos pieds ont troublé.
Ṣé dandan ni kí agbo ẹran mi jẹ́ koríko tí ẹ ti tẹ̀ mọ́lẹ̀, kí wọn sì mú omi tí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ wọn sọ di ẹrẹ̀?
20 Aussi, ainsi leur parle le Seigneur, l'Éternel: Voici, moi-même je serai juge entre la brebis grasse et la brebis maigre.
“‘Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún wọn: Wò ó, èmi fúnra mi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn tí ó sanra àti èyí tí ó rù.
21 Parce que du flanc et de l'épaule vous heurtez, et que de vos cornes vous frappez toutes les brebis malades, jusqu'à ce que vous les ayez poussées dehors,
Nítorí ti ìwọ sún síwájú pẹ̀lú ìhà àti èjìká, tí ìwọ sì kan aláìlágbára àgùntàn pẹ̀lú ìwo rẹ títí ìwọ fi lé wọn lọ,
22 je porterai secours à mes brebis, afin qu'elles ne soient plus une proie, et je serai juge entre brebis et brebis.
Èmi yóò gba agbo ẹran mi là, a kì yóò sì kò wọ́n tì mọ́. Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn.
23 Et j'établirai sur elles un seul pasteur qui les fera paître, mon serviteur David; c'est lui qui les fera paître et sera leur pasteur,
Èmi yóò fi Olùṣọ́-àgùntàn kan ṣe olórí wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi, òun yóò sì tọ́jú wọn; òun yóò bọ́ wọn yóò sì jẹ́ Olùṣọ́-àgùntàn wọn.
24 et moi, l'Éternel, je serai leur Dieu, et mon serviteur David sera prince au milieu d'eux: c'est moi, l'Éternel, qui le dis.
Èmi Olúwa yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi yóò jẹ́ ọmọ-aládé láàrín wọn. Èmi Olúwa ní o sọ̀rọ̀.
25 Et je leur donnerai une alliance de paix, et j'exterminerai les bêtes sauvages du pays, afin qu'en sécurité ils habitent dans le désert, et dorment dans les forêts;
“‘Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, èmi yóò sì gba ilẹ̀ náà kúrò lọ́wọ́ ẹranko búburú, kí wọn kí o lè gbé ní aṣálẹ̀, kí àgùntàn sì gbé ní inú igbó ní àìléwu.
26 et je répandrai ma bénédiction sur eux et sur les alentours de ma colline, et ferai descendre la pluie en son temps, et ce seront des pluies fertilisantes,
Èmi yóò bùkún wọn àti ibi agbègbè ti ó yí òkè mi ká. Èmi yóò rán ọ̀wààrà òjò ni àkókò; òjò ìbùkún yóò sì wà.
27 et l'arbre des campagnes donnera son fruit et la terre donnera ses productions; et ils seront en sécurité dans leur pays, et ils sauront que je suis l'Éternel, quand j'aurai brisé les barres de leur joug, et les aurai tirés des mains de ceux qui les asservirent.
Àwọn igi igbó yóò mú èso wọn jáde, ilẹ̀ yóò sì mu irúgbìn jáde; A yóò sì dá ààbò bo àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ náà. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá já àwọn ohun tí ó ṣe okùnfà àjàgà, tí mo sì gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn tí ó fi wọ́n ṣe ẹrú.
28 Et ils ne seront plus en proie aux nations, ni la pâture des bêtes de la terre, et ils auront la sécurité dans leurs demeures, et nul ne leur inspirera de la terreur;
Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò lè kó wọn ní ẹrú mọ́, àwọn ẹranko búburú kì yóò lè pa wọn mọ́. Wọn yóò gbé ni àìléwu, kò sì ṣí ẹni kankan tí yóò le dẹ́rùbà wọ́n.
29 et j'établirai pour eux une plantation qui aura du renom, et ils ne seront plus enlevés par la famine dans le pays, et ne subiront plus l'opprobre des nations;
Èmi yóò pèsè ilẹ̀ ti o ní oríyìn fún èso rẹ̀ fún wọn, wọn kì yóò sì jìyà nípasẹ̀ ìyàn mọ́ ni ilẹ̀ náà tàbí ru ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè.
30 et ils reconnaîtront que moi, l'Éternel, leur Dieu, je suis près d'eux, et que, eux, maison d'Israël, ils sont mon peuple, dit le Seigneur, l'Éternel.
Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi wà pẹ̀lú wọn àti pé, àwọn ilé Israẹli jẹ́ ènìyàn mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
31 Pour vous, mon troupeau, troupeau dont je suis le Pasteur, vous êtes des hommes, mais je suis votre Dieu, dit le Seigneur, l'Éternel.
Ìwọ àgùntàn mi, àgùntàn pápá mi; ni ènìyàn, èmi sì ni Ọlọ́run rẹ; ni Olúwa Olódùmarè wí.’”