< Ézéchiel 25 >

1 Et la parole de l'Éternel me fut adressée en ces mots:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Fils de l'homme, tourne ton visage contre les enfants d'Ammon et prophétise contre eux,
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
3 et dis aux enfants d'Ammon: Écoutez la parole du Seigneur, l'Éternel! Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Parce que tu as dit: « Ah! ah! » à la vue de mon sanctuaire profané et du pays d'Israël désolé, et de la maison de Juda menée en captivité;
Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
4 pour cela, voici, je te donne aux enfants de l'Orient en propriété, pour qu'ils établissent leurs parcs au milieu de toi, et y fixent leurs demeures; ils mangeront tes fruits et boiront ton lait:
kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
5 et je ferai de Rabbah un pâturage pour les chameaux, et [du pays] des enfants d'Ammon une bergerie pour les brebis, et vous saurez que je suis l'Éternel.
Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
6 Car ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Parce que tu as battu des mains et frappé du pied, et qu'avec tout ton orgueil tu t'es réjouie de cœur à la vue du pays d'Israël;
Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
7 pour cela, voici, j'étends ma main contre toi, et te livre en proie aux nations, et te retranche du nombre des peuples, et t'extermine du milieu des pays; je t'anéantis, afin que tu saches que je suis l'Éternel.
nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
8 Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Parce que Moab et Séir disent: Voici, la maison de Juda est comme tous les autres peuples!
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
9 pour cela, voici j'ouvre le flanc de Moab, depuis les villes, depuis toutes ses villes, ornement du pays, Beth-Jésimoth, Baal-Meon et jusqu'à Kiriathaïm,
nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
10 aux enfants de l'Orient, en même temps que le pays des enfants d'Ammon, et je le leur donnerai en propriété, afin qu'il ne soit plus fait mention des enfants d'Ammon parmi les peuples;
Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
11 et sur Moab j'exécuterai mes jugements, afin qu'ils sachent que je suis l'Éternel.
Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
12 Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Parce que Édom s'est conduit envers la maison de Juda par un esprit de vengeance, et s'est rendu coupable, et a tiré vengeance d'elle;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
13 pour cela, ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: J'étendrai ma main contre Édom, et en exterminerai les hommes et les bêtes, et j'en ferai un désert de Théman à Dedan; ils périront par l'épée.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
14 Et j'exécuterai mes vengeances sur Édom par le bras de mon peuple d'Israël, et il traitera Édom selon ma colère et mon courroux, et ils ressentiront mes vengeances, dit le Seigneur, l'Éternel.
Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Parce que les Philistins ont agi par vengeance et qu'ils se sont vengés orgueilleusement et de cœur, avec la volonté de détruire, par suite d'une haine éternelle;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
16 pour cela, ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Voici, j'étends ma main contre les Philistins, et j'extirperai les Crétites, et détruirai ce qui reste sur la côte de la mer,
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
17 et j'exercerai sur eux de grandes vengeances en châtiant avec fureur, afin qu'ils sachent que je suis l'Éternel, quand j'exercerai mes vengeances sur eux.
Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”

< Ézéchiel 25 >