< Deutéronome 13 >

1 S'il s'élève au milieu de vous quelque prophète ou songeur, et s'il t'annonce un signe ou un prodige
Bí wòlíì tàbí alásọtẹ́lẹ̀ nípa àlá lílá bá farahàn láàrín yín, tí ó sì ń kéde iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu,
2 et qu'arrive le signe ou le prodige dont il te parlait tout en te disant: Suivons d'autres dieux (que tu ne connais pas) et servons-les!
bí iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ bá ṣẹ tí òun sì wí pé, “ẹ wá ẹ jẹ́ kí a tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀ rí) “kí ẹ sì jẹ́ kí a máa sìn wọ́n,”
3 tu ne prêteras point l'oreille aux discours de ce prophète-là ou de ce songeur; car l'Éternel, votre Dieu, veut vous mettre à l'épreuve pour savoir si vous aimez l'Éternel, votre Dieu, de tout votre cœur et de toute votre âme.
ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ wòlíì tàbí àlá náà, Olúwa Ọlọ́run yín ń dán an yín wò ni, láti mọ̀ bóyá ẹ fẹ́ràn rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn an yín.
4 C'est l'Éternel, votre Dieu, que vous devez suivre, Lui que vous devez craindre, ses commandements que vous devez garder, et sa voix que vous devez écouter, et Lui que vous devez servir, et à Lui que vous devez vous attacher.
Olúwa Ọlọ́run yín ni kí ẹ tẹ̀lé, Òun ni kí ẹ bu ọlá fún, ẹ pa òfin rẹ̀ mọ́ kí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, ẹ sìn ín, kí ẹ sì dìímú ṣinṣin.
5 Ce prophète ou ce songeur-là sera mis à mort, parce qu'il a prêché la rébellion contre l'Éternel, votre Dieu, qui vous a retirés du pays d'Egypte et rachetés de la maison de servitude; afin de te faire dévier de la voie dans laquelle t'a ordonné de marcher l'Éternel, ton Dieu: ainsi vous ôterez le mal du milieu de vous.
Wòlíì náà tàbí alálàá náà ni kí ẹ pa, nítorí pé wàásù ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú yín jáde láti Ejibiti wá, tí ó sì rà yín padà lóko ẹrú. Ó ti gbìyànjú láti fà yín kúrò lójú ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín láti máa rìn. Ẹ gbọdọ̀ yọ ibi náà kúrò láàrín yín.
6 Si ton frère, fils de ta mère, ou ton fils ou ta fille, ou la femme, qui est entre tes bras, ou ton ami, qui est comme un autre toi-même, t'incite secrètement en disant: Allons et servons d'autres dieux (qui ne furent connus ni de toi ni de tes pères,
Bí arákùnrin tìrẹ gan an ọmọ ìyá rẹ tàbí ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí obìnrin, aya tí o fẹ́ràn jù, tàbí ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ bá tàn ọ́ jẹ níkọ̀kọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn” (ọlọ́run tí ìwọ tàbí baba rẹ kò mọ̀,
7 l'un des dieux des peuples de vos alentours, rapprochés ou éloignés de toi, d'un bout de la terre à l'autre),
ọlọ́run àwọn tí ó wà láyìíká yín, yálà wọ́n jìnnà tàbí wọ́n wà nítòsí, láti òpin ilẹ̀ kan dé òmíràn),
8 tu ne lui donneras pas ton assentiment, et ne l'écouteras pas; tu n'auras pour lui ni pitié, ni miséricorde, et tu ne le mettras pas à couvert;
má ṣe fetí sí i, má sì dá sí i, má ṣe dáàbò bò ó.
9 mais tu le feras mourir, ta main se lèvera la première sur lui pour lui donner la mort, et la main de tout le peuple ensuite,
Ṣùgbọ́n pípa ni kí o pa á. Ọwọ́ rẹ ni yóò kọ́kọ́ wà lára rẹ̀ láti pa á, lẹ́yìn náà ọwọ́ gbogbo ènìyàn.
10 et tu le lapideras à coups de pierres pour qu'il meure, parce qu'il a cherché à te détacher de l'Éternel, ton Dieu, qui t'a retiré du pays d'Egypte et de la maison de servitude;
Sọ ọ́ ní òkúta pa nítorí pé ó gbìyànjú láti fà ọ́ kúrò lẹ́yìn Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó mú ọ jáde ti Ejibiti wá kúrò ní oko ẹrú.
11 et que tout Israël entende et craigne, pour ne pas répéter un acte aussi criminel au milieu de toi.
Gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, kò sì sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí yóò dán irú ibi bẹ́ẹ̀ wò mọ́.
12 Si tu entends dire de l'une de tes villes que l'Éternel, ton Dieu, t'a données pour y habiter:
Bí ẹ̀yin bá gbọ́ tí a sọ nípa èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín láti máa gbé,
13 Des hommes perdus, sortis du milieu de toi, ont séduit les habitants de leur ville en disant: Allons et servons d'autres dieux (que vous ne connaissez pas),
pé àwọn ènìyàn búburú, ti farahàn láàrín yín, tí ó sì ti mú kí àwọn ènìyàn ìlú wọn ṣìnà lọ, tí wọ́n wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn.” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀.)
14 fais des perquisitions, des enquêtes, des interrogatoires exacts; et si voilà que c'est un fait avéré, si la chose est constatée, si cette abomination s'est commise dans ton sein,
Kí ẹ wádìí, ẹ béèrè, kí ẹ sì tọpinpin ọ̀rọ̀ náà dájúṣáká, bí ó bá jẹ́ òtítọ́ ni, tí ó sì hàn dájú pé ìwà ìríra yìí ti ṣẹlẹ̀ láàrín yín.
15 passe au fil de l'épée les habitants de cette ville-là; tu la dévoueras ainsi que tout ce qu'elle renferme et ses bestiaux, avec le tranchant de l'épée.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbé ìlú náà ni kí ẹ fi idà run pátápátá. Ẹ run ún pátápátá, àti ènìyàn àti ẹran ọ̀sìn inú rẹ̀.
16 Et tu réuniras toutes ses dépouilles au milieu de sa place, et tu brûleras au feu la ville et toutes ses dépouilles en holocauste à l'Éternel, ton Dieu; et elle restera ruine éternelle: elle ne sera point rebâtie.
Ẹ kó gbogbo ìkógun ìlú náà, sí àárín gbogbo ènìyàn, kí ẹ sun ìlú náà àti gbogbo ìkógun rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ó gbọdọ̀ wà ní píparun láéláé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ tún un kọ.
17 Et que rien de ce qui a été dévoué ne reste attaché à ta main, afin que l'Éternel revienne de son ardente colère, et te fasse miséricorde et ait pitié de toi, et te multiplie, comme Il l'a juré à tes pères,
A kò gbọdọ̀ rí ọ̀kan nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun wọ̀n-ọn-nì lọ́wọ́ yín, kí Olúwa ba à le yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀, yóò sì ṣàánú fún un yín, yóò sì bá a yín kẹ́dùn, yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i, bí ó ti fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá yín.
18 si tu obéis à la voix de l'Éternel, ton Dieu, en gardant tous ses commandements que je te prescris en ce jour, en faisant ce qui est droit aux yeux de l'Éternel, ton Dieu.
Nítorí pé ẹ̀yin gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ̀yin sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí mo ń fún un yín lónìí yìí, tí ẹ̀yin sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ̀.

< Deutéronome 13 >