< 2 Samuel 3 >

1 Et la lutte fut longue entre la maison de Saül et la maison de David; mais David allait se renforçant de plus en plus, tandis que la maison de Saül allait s'affaiblissant de plus en plus.
Ogun náà sì pẹ́ títí láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi: agbára Dafidi sì ń pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n ìdílé Saulu ń rẹ̀yìn sí i.
2 Et il naquit à David des fils à Hébron, et son premier-né fut Amnon, d'Ahinoam de Jizréel,
Dafidi sì bí ọmọkùnrin ní Hebroni: Amnoni ni àkọ́bí rẹ̀ tí Ahinoamu ará Jesreeli bí fún un.
3 et son deuxième, Chileab, d'Abigaïl, femme de Nabal, le Carmélite; et le troisième, Absalom, fils de Maacha, fille de Thalmaï, roi de Gessur;
Èkejì rẹ̀ sì ni Kileabu, tí Abigaili aya Nabali ará Karmeli bí fún un; ẹ̀kẹta sì ni Absalomu ọmọ tí Maaka ọmọbìnrin Talmai ọba Geṣuri bí fún un.
4 et le quatrième Adonia, fils de Haggith; et le cinquième Sephatia, fils d'Abital;
Ẹ̀kẹrin sì ni Adonijah ọmọ Haggiti; àti ẹ̀karùnún ni Ṣefatia ọmọ Abitali;
5 et le sixième Jithream, de Egla, femme de David. Tels sont ceux qui naquirent à David à Hébron.
Ẹ̀kẹfà sì ni Itreamu, tí Egla aya Dafidi bí fún un. Wọ̀nyí ni a bí fún Dafidi ni Hebroni.
6 Et pendant qu'il y eut guerre entre la maison de Saül et la maison de David, Abner tint ferme pour la maison de Saül.
Ó sì ṣe, nígbà tí ogun wà láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi, Abneri sì dì alágbára ní ìdílé Saulu.
7 Or Saül avait eu une concubine, nommée Ritspa, fille d'Aia. Et [Isboseth] dit à Abner: Pourquoi es-tu entré chez la concubine de mon père?
Saulu ti ní àlè kan, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Rispa, ọmọbìnrin Aiah: Iṣboṣeti sì bi Abneri léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wọlé tọ àlè baba mi lọ.”
8 Et Abner fut fort irrité du langage d'Isboseth et il dit: Suis-je une tête de chien qui tienne pour Juda? Aujourd'hui je rends de bons services à la maison de Saül, ton père, à ses frères et à ses amis, et je ne t'ai point livré aux mains de David; et aujourd'hui tu me prends à partie à propos d'un écart avec cette femme!
Abneri sì bínú gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ti Iṣboṣeti sọ fún un, ó sì wí pé, “Èmi jẹ́ bí orí ajá ti Juda bí? Di òní yìí ni mo ṣàánú fún ìdílé Saulu baba rẹ, àti fún àwọn arákùnrin rẹ̀, àti fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, tí èmi kò sì fi ọ́ lé Dafidi lọ́wọ́, ìwọ sì kà ẹ̀ṣẹ̀ sí mí lọ́rùn nítorí obìnrin yìí lónìí?
9 Qu'ainsi Dieu traite Abner et plus mal encore! oui, comme l'Éternel en a fait le serment à David,
Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe Abneri, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí Olúwa ti búra fún Dafidi, bí èmi kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ fún un.
10 ainsi travaillerai-je dans son intérêt au transfert de la souveraineté ôtée à la maison de Saül, et à l'élévation du trône de David sur Israël et sur Juda de Dan à Béerseba.
Láti mú ìjọba náà kúrò ní ìdílé Saulu, àti láti gbé ìtẹ́ Dafidi kalẹ̀ lórí Israẹli, àti lórí Juda, láti Dani títí ó fi dé Beerṣeba.”
11 Et Isboseth ne put plus répliquer un mot à Abner dont il avait peur.
Òun kò sì lè dá Abneri lóhùn kan nítorí tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
12 Sur-le-champ Abner dépêcha vers David des émissaires pour lui dire: A qui est le pays? et de plus: Fais ton traité avec moi, et voici tu auras l'aide de ma main pour tourner Israël de ton côté.
Abneri sì rán àwọn oníṣẹ́ sí Dafidi nítorí rẹ̀ wí pé, “Ti ta ni ilẹ̀ náà ń ṣe? Bá mi ṣe àdéhùn, èmi yóò si kó gbogbo Israẹli tọ̀ ọ́ wá.”
13 Et il répondit: Bien! Je traiterai avec toi; je n'exige de toi qu'une condition: tu ne reverras pas mon visage, à moins de m'amener préalablement Michal, fille de Saül, quand tu viendras te présenter devant moi.
Òun sì wí pé, “Ó dára, èmi ó bá ọ ṣe àdéhùn, ṣùgbọ́n ohun kan ni èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, èyí ni pé, ìwọ kì yóò rí ojú mi, àfi bí ìwọ bá kọ́ mú Mikali ọmọbìnrin Saulu wá, nígbà tí ìwọ bá wá, láti rí ojú mi.”
14 Et David envoya des délégués à Isboseth, fils de Saül, avec ce message: Rends-moi ma femme Michal, que je me suis fiancée au prix de cent prépuces de Philistins.
Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Iṣboṣeti ọmọ Saulu pé, “Fi Mikali obìnrin mi lé mi lọ́wọ́, ẹni tí èmi ti fi ọgọ́rùn-ún awọ iwájú orí àwọn Filistini fẹ́.”
15 Et Isboseth la fit prendre chez le mari, Paltiel, fils de Laïs.
Iṣboṣeti sì ránṣẹ́, ó sì gbà á lọ́wọ́ ọkùnrin tí a ń pè ní Paltieli ọmọ Laiṣi.
16 Et son mari l'accompagna et alla pleurant derrière elle jusqu'à Bahurim. Là Abner lui dit: Va, rebrousse! Et il rebroussa.
Ọkọ rẹ̀ sì ń bà a lọ, ó ń rìn, ó sì ń sọkún lẹ́yìn rẹ̀ títí ó fi dé Bahurimu Abneri sì wí fún un pé, “Padà sẹ́yìn!” Òun sì padà.
17 Et Abner était entré en pourparler avec les Anciens d'Israël et avait dit: Ce n'est pas d'aujourd'hui que vous, cherchez à avoir David pour Roi.
Abneri sì bá àwọn àgbàgbà Israẹli sọ̀rọ̀ pé, “Ẹ̀yin ti ń ṣe àfẹ́rí Dafidi ní ìgbà àtijọ́, láti jẹ ọba lórí yín.
18 Agissez maintenant, car l'Éternel a dit touchant David: C'est par la main de David, mon serviteur, que Je sauverai mon peuple d'Israël de la main des Philistins et de la main de tous ses ennemis.
Ǹjẹ́ ẹ ṣe, nítorí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi pé, ‘Láti ọwọ́ Dafidi ìránṣẹ́ mi lé mi ó gba Israẹli ènìyàn mi là kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a wọn.’”
19 Et Abner s'étant aussi abouché avec les Benjaminites, alla de même redire en entier aux oreilles de David à Hébron la résolution d'Israël et de toute la maison de Benjamin.
Abneri sì sọ̀rọ̀ létí Benjamini: Abneri sì lọ sọ létí Dafidi ní Hebroni, gbogbo èyí tí ó dára lójú Israẹli, àti lójú gbogbo ilé Benjamini.
20 Abner arriva donc chez David à Hébron avec une escorte de vingt hommes, et David fit un festin à Abner et à son escorte.
Abneri sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, ogún ọmọkùnrin sì lọ pẹ̀lú rẹ̀ Dafidi sì ṣe àsè fún Abneri àti fún àwọn ọmọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.
21 Et Abner dit à David: Je vais me mettre en mouvement et partir et réunir auprès de mon Seigneur le Roi la totalité des Israélites, afin qu'ils fassent un accord avec toi, et tu régneras en tous points selon ton désir. Et David congédia Abner qui s'en alla sain et sauf.
Abneri sì wí fún Dafidi pé, “Èmi ó dìde, èmi ó sì lọ, èmi ó sì kó gbogbo Israẹli jọ sọ́dọ̀ ọba olúwa mi, wọn ó sì bá a ṣe àdéhùn, ìwọ ó sì jẹ ọba gbogbo wọn bí ọkàn rẹ ti ń fẹ́.” Dafidi sì rán Abneri lọ; òun sì lọ ní àlàáfíà.
22 Et voilà que les serviteurs de David et Joab revinrent de leur expédition, ramenant avec eux un butin considérable. Or Abner n'était plus chez David à Hébron. Celui-ci l'avait congédié, et il s'en était allé sain et sauf.
Sì wò ó, àwọn ìránṣẹ́ Dafidi àti Joabu sì ti ibi ìlépa ẹgbẹ́ ogun kan bọ̀, wọ́n sì mú ìkógun púpọ̀ bọ̀; ṣùgbọ́n Abneri kò sí lọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni; nítorí tí òun ti rán an lọ, òun sì ti lọ ní àlàáfíà.
23 Et au retour de Joab et de toute la troupe qui l'accompagnait, on fit à Joab ce rapport: Abner, fils de Ner, est venu chez le Roi, qui l'a laissé partir, et il s'en est allé sain et sauf.
Nígbà tí Joabu àti gbogbo ogun tí ó pẹ̀lú rẹ̀ sì dé, wọ́n sì sọ fún Joabu pé Abneri, ọmọ Neri ti tọ ọba wá, òun sì ti rán an lọ, ó sì ti lọ ní àlàáfíà.
24 Alors Joab entra chez le Roi et dit: Qu'as-tu fait? Voici, Abner est venu chez toi; pourquoi donc l'as-tu laissé partir et s'en aller?
Joabu sì tọ ọba wá, ó sì sọ pé, “Kí ni ìwọ ṣe yìí? Wò ó, Abneri tọ̀ ọ́ wá; èéha ti ṣe tí ìwọ sì fi rán an lọ? Òun sì ti lọ.
25 Tu connais Abner, fils de Ner! c'est pour te surprendre qu'il est venu, pour étudier tes allures, et savoir tout ce que tu fais.
Ìwọ mọ Abneri ọmọ Neri, pé ó wá láti tàn ọ́ jẹ ni, àti láti mọ ìjáde lọ rẹ, àti wíwọlé rẹ́ àti láti mọ gbogbo èyí tí ìwọ ń ṣe.”
26 Et Joab ayant quitté David envoya des émissaires après Abner et ils le firent rebrousser depuis la citerne de Hasira, et cela à l'insu de David.
Nígbà tí Joabu sì jáde kúrò lọ́dọ̀ Dafidi, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ láti lépa Abneri, wọ́n sì pè é padà láti ibi kànga Sira, Dafidi kò sì mọ̀.
27 Abner étant ainsi revenu à Hébron, Joab le tira à part dans l'intérieur de la porte pour l'entretenir en secret, et là il lui porta dans le ventre un coup qui le tua, vengeant ainsi le meurtre d'Hasahel, son frère.
Abneri sì padà sí Hebroni, Joabu sì bá a tẹ̀ láàrín ojú ọ̀nà láti bá a sọ̀rọ̀ ní àlàáfíà, ó sì gún un níbẹ̀ lábẹ́ inú, ó sì kú, nítorí ẹ̀jẹ̀ Asaheli arákùnrin rẹ̀.
28 Et David l'ayant appris plus tard dit: Ni à moi, ni à mon règne ne pourra jamais être imputé de par l'Éternel le meurtre d'Abner, fils de Ner:
Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi sì gbọ́ ọ, ó sì wí pé, “Èmi àti ìjọba mi sì jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú Olúwa títí láé, ní ti ẹ̀jẹ̀ Abneri ọmọ Neri,
29 qu'il retombe sur la tête de Joab et sur toute la maison de son père, et que la maison de Joab ne soit jamais purgée d'hommes ayant un flux immonde, de lépreux, de perclus, de tués par l'épée et de gens manquant de pain.
jẹ́ kí ó wà ní orí Joabu, àti ní orí gbogbo ìdílé baba rẹ̀; kí a má sì fẹ́ ẹni ó tí ní ààrùn ìsun, tàbí adẹ́tẹ̀, tàbí ẹni tí ń tẹ ọ̀pá, tàbí ẹni tí a ó fi idà pa, tàbí ẹni tí ó ṣe aláìní oúnjẹ kù ní ilé Joabu.”
30 Or Joab et Abisaï, son frère, avaient donné la mort à Abner parce qu'il avait tué Hasahel, leur frère, à Gabaon dans la bataille.
(Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì pa Abneri, nítorí pé òun ti pa Asaheli arákùnrin wọn ní Gibeoni ní ogun.)
31 Et David dit à Joab et à tout le peuple qui était avec lui: Déchirez vos habits et revêtez le cilice et célébrez le deuil d'Abner. Et le roi David suivit le cercueil.
Dafidi sì wí fún Joabu àti fún gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ fa aṣọ yín ya, kí ẹ̀yin sì mú aṣọ ọ̀fọ̀, kí ẹ̀yin sì sọkún níwájú Abneri.” Dafidi ọba tìkára rẹ̀ sì tẹ̀lé pósí rẹ̀.
32 Et Abner reçut la sépulture à Hébron, et le Roi laissant éclater sa voix, pleura au tombeau d'Abner, et tout le peuple pleura.
Wọ́n sì sin Abneri ní Hebroni, ọba sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì sọkún ní ibojì Abneri; gbogbo àwọn ènìyàn náà sì sọkún.
33 Et le Roi chanta une complainte sur Abner en ces mots: Est-ce de la mort de l'impie que devait mourir Abner?…
Ọba sì sọkún lórí Abneri, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ Abneri ó yẹ kí ó kú bí aṣiwèrè?
34 Tu n'avais ni les mains garrottées, ni les pieds serrés dans les fers!… Tu as péri, comme on périt sous les coups du crime!
A kò sá à dè ọ́ lọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò kan ẹsẹ̀ rẹ ní àbà. Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń ṣubú níwájú àwọn ìkà ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ ṣubú.” Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì tún sọkún lórí rẹ̀.
35 Et tout le peuple ne fit que le pleurer, davantage. Et tout le peuple se présenta dans le but de faire prendre à David de la nourriture encore de jour, mais David fit ce serment: Qu'ainsi Dieu me fasse et pis encore si avant le coucher du soleil je goûte du pain ou d'un mets quelconque!
Nígbà tí gbogbo ènìyàn sì wá láti gba Dafidi ní ìyànjú kí ó jẹun, nígbà tí ọjọ́ sì ń bẹ, Dafidi sì búra wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí èmi yóò bá tọ́ oúnjẹ wò, tàbí nǹkan mìíràn títí oòrùn yóò fi wọ̀!”
36 Tout le peuple reconnut alors [sa sincérité] qui lui plut; tout ce que faisait le Roi était au gré de tout le peuple.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì kíyèsi i, ó sì dára lójú wọn, gbogbo èyí tí ọba ṣe sì dára lójú gbogbo àwọn ènìyàn náà.
37 Et en ce jour tout le peuple et tout Israël acquit la conviction que ce n'était pas de par le Roi que Abner, fils de Ner, avait été assassiné.
Gbogbo àwọn ènìyàn náà àti gbogbo Israẹli sì mọ̀ lọ́jọ́ náà pé, kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti pa Abneri ọmọ Neri.
38 Et le Roi dit à ses serviteurs: Ne sentez-vous pas qu'aujourd'hui un grand capitaine est tombé en Israël,
Ọba sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ pé olórí àti ẹni ńlá kan ni ó ṣubú lónìí ní Israẹli.
39 et que pour le moment je suis faible et que je viens de recevoir l'onction de Roi? Ces hommes, les fils de Tseruïa, sont trop durs pour moi. Que l'Éternel paie au méchant le salaire dû à sa méchanceté.
Èmi sì ṣe aláìlágbára lónìí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi èmi jẹ ọba; àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ọmọ Seruiah sì le jù mí lọ: Olúwa ni yóò san án fún ẹni tí ó ṣe ibi gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀!”

< 2 Samuel 3 >