< 2 Rois 15 >

1 La vingt-septième année de Jéroboam, roi d'Israël, Azaria, fils d'Amatsia, roi de Juda, devint roi.
Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n tí Jeroboamu ọba Israẹli, Asariah ọmọ Amasiah ọba Juda sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
2 Il avait seize ans à son avènement, et il régna cinquante-deux ans à Jérusalem. Or, le nom de sa mère était Jecholia de Jérusalem.
Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjìléláàádọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jekoliah; ó wá láti Jerusalẹmu.
3 Et il fit ce qui est droit aux yeux de l'Éternel tout comme avait fait Amatsia, son père.
Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Amasiah ti ṣe.
4 Seulement les tertres ne disparurent pas, le peuple offrait encore des victimes et de l'encens sur les tertres.
Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò ṣí wọn kúrò, àwọn ènìyàn náà tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ àti sun tùràrí níbẹ̀.
5 Et l'Éternel infligea une plaie au roi, qui fut lépreux jusqu'au jour de sa mort et demeura dans une infirmerie. Cependant Jotham, fils du roi, était préposé sur la Maison, rendant la justice au peuple du pays.
Olúwa sì kọlu ọba náà pẹ̀lú ẹ̀tẹ̀, títí di ọjọ́ tí ó kú, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀tọ̀. Jotamu, ọmọ ọba sì tọ́jú ààfin, ó sì ń darí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
6 Le reste des actes d'Azaria et toutes ses entreprises sont d'ailleurs consignés dans le livre des annales des rois de Juda.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Asariah, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda.
7 Et Azaria reposa avec ses pères et on lui donna la sépulture avec ses pères dans la ville de David, et Jotham, son fils, devint roi en sa place.
Asariah sinmi pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀. A sì sin ín sí ẹ̀bá wọn ní ìlú ńlá ti Dafidi. Jotamu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
8 Là trente-huitième année d'Azaria, roi de Juda, Zacharie, fils de Jéroboam, devint roi d'Israël à Samarie pour six mois.
Ní ọdún kejìdínlógójì Asariah ọba Juda. Sekariah ọmọ Jeroboamu di ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ ọba fún oṣù mẹ́fà.
9 Et il fit ce qui est mal aux yeux de l'Éternel comme avaient fait ses pères; il ne se départit point des péchés de Jéroboam, fils de Nebat, qui avait entraîné Israël à pécher.
Ó ṣe búburú lójú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba rẹ̀ tí ṣe. Kò sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá.
10 Et Sallum, fils de Jabès, conspira contre lui et fit main basse sur lui publiquement, et le tua et devint roi en sa place.
Ṣallumu ọmọ Jabesi dìtẹ̀ sí Sekariah. Ó dojúkọ ọ́ níwájú àwọn ènìyàn, ó sì pa á, ó sì jẹ ọba dípò rẹ̀.
11 Le reste des actes de Zacharie est d'ailleurs consigné dans le livre des annales des rois d'Israël.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Sekariah. Wọ́n kọ ọ́ sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
12 C'est la parole de l'Éternel qu'il avait dite à Jéhu en ces termes: Tu auras des fils de la quatrième génération assis au trône d'Israël, et il en fut ainsi.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ fún Jehu jẹ́ ìmúṣẹ: “Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
13 Sallum, fils de Jabès, devint roi la trente-neuvième année d'Hozias, roi de Juda, et régna un mois de temps à Samarie.
Ṣallumu ọmọ Jabesi di ọba ní ọdún kọkàndínlógójì Ussiah ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Samaria fún oṣù kan.
14 Et Menahem, fils de Gadi, s'avança de Thirtsa, et entra dans Samarie, et fit main basse sur Sallum, fils de Jabès, dans Samarie, et lui donna la mort et devint roi en sa place.
Nígbà náà Menahemu ọmọ Gadi lọ láti Tirsa sí Samaria. Ó dojúkọ Ṣallumu ọmọ Jabesi ní Samaria, ó pa á ó sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
15 Le reste des actes de Sallum, et sa conjuration qu'il avait formée, sont d'ailleurs consignés dans le livre des annales des rois d'Israël.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Ṣallumu, àti ìdìtẹ̀ tí ó dì, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
16 C'est alors que Menahem fit main basse sur Thiphsach et sur tous ceux qui y étaient, et sur tout son territoire à partir de Thirtsa; ce fut parce qu'on ne lui ouvrit pas qu'il porta ce coup; il y éventra toutes les femmes enceintes.
Ní ìgbà tí Menahemu ń jáde bọ̀ láti Tirsa, ó dojúkọ Tifisa àti gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ìlú ńlá àti agbègbè rẹ̀, nítorí wọn kọ̀ láti sí ẹnu ibodè. Ó yọ Tifisa kúrò lẹ́nu iṣẹ́, ó sì la inú gbogbo àwọn obìnrin aboyún.
17 La trente-neuvième année d'Azaria, roi de Juda, Menahem, fils de Gadi, devint roi d'Israël, pour dix ans à Samarie.
Ní ọdún kọkàndínlógójì ti Asariah ọba Juda, Menahemu ọmọ Gadi di ọba Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Samaria fún ọdún mẹ́wàá.
18 Et il fit ce qui est mal aux yeux de l'Éternel; il ne se départit point des péchés de Jéroboam, fils de Nebat, auxquels celui-ci avait entraîné Israël, toute sa vie durant.
Ó ṣe búburú lójú Olúwa, ní gbogbo ìjọba rẹ̀. Kò sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá.
19 Phul, roi d'Assyrie, fit invasion dans le pays, et Ménahem donna à Phul mille talents d'argent afin qu'il lui prêtât la main pour assurer la royauté dans sa propre main.
Nígbà náà, Pulu ọba Asiria, gbógun ti ilẹ̀ náà, Menahemu sì fún un ní ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì fàdákà láti fi gba àtìlẹ́yìn rẹ̀ àti láti fún ìdúró tirẹ̀ lágbára lórí ìjọba.
20 Et Menahem tira cette somme à payer au roi d'Assyrie, sur les Israélites, tous les gens à moyens, à raison de cinquante sicles d'argent par individu. Puis le roi d'Assyrie rebroussa sans séjourner alors dans le pays.
Menahemu fi agbára gba owó náà lọ́wọ́ Israẹli. Gbogbo ọkùnrin ọlọ́lá ní láti dá àádọ́ta ṣékélì fàdákà láti fún ọba Asiria. Bẹ́ẹ̀ ni ọba Asiria padà sẹ́yìn, kò sì dúró ní ilẹ̀ náà mọ́.
21 Le reste des actes de Menahem et toutes ses entreprises sont d'ailleurs consignés dans le livre des annales des rois d'Israël.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Menahemu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé ọba Israẹli?
22 Et Menahem reposa avec ses pères, et Pekachia, son fils, devint roi à sa place.
Menahemu sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Pekahiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
23 La cinquantième année d'Azaria roi de Juda, Pekachia, fils de Menahem, devint roi d'Israël à Samarie, pour deux ans.
Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún Asariah ọba Juda, Pekahiah ọmọ Menahemu di ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjì.
24 Et il fit ce qui est mal aux yeux de l'Éternel; il ne se départit point des péchés de Jéroboam, fils de Nebat, auxquels celui-ci avait entraîné Israël.
Pekahiah ṣe búburú lójú Olúwa. Kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó fa Israẹli láti dá.
25 Et Pékach, fils de Remalia, son aide-de-camp, conspira contre lui et lui porta le coup dans Samarie au donjon du palais royal, en même temps qu'à Argob et à Ariè; or il se trouvait avec lui cinquante hommes d'entre les fils des Galaadites; c'est ainsi qu'il lui donna la mort et devint roi en sa place.
Ọ̀kan lára àwọn olórí ìjòyè rẹ̀ Peka ọmọ Remaliah, dìtẹ̀ sí i. Ó mú àádọ́ta àwọn ọkùnrin ti àwọn ará Gileadi pẹ̀lú u rẹ̀. Ó pa Pekahiah pẹ̀lú Argobu àti Arie ní odi ààfin ọba ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni Peka pa Pekahiah, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
26 Le reste des actes de Pekachia et toutes ses entreprises sont d'ailleurs consignés dans le livre des annales des rois d'Israël.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Pekahiah, gbogbo ohun tí ó ṣe, ni a kọ sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
27 La cinquante-deuxième année d'Azaria roi de Juda, Pékach, fils de Remalia, devint roi d'Israël à Samarie pour vingt ans.
Ní ọdún kejìléláàádọ́ta Asariah ọba Juda, Peka ọmọ Remaliah di ọba Israẹli ní Samaria. Ó sì jẹ ọba fún ogún ọdún.
28 Et il fit ce qui est mal aux yeux de l'Éternel; il ne se départit point des péchés de Jéroboam, fils de Nebat, auxquels celui-ci avait entraîné Israël.
Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa, kò sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó fa Israẹli láti dá.
29 Au temps de Pékach, roi d'Israël, Thiglath-Piléser, roi d'Assyrie, vint et prit Ijon et Abel-Beth-Maacha et Janoha et Kédès et Hatsor et Galaad et la Galilée, tout le territoire de Nephthali, et il les emmena captifs en Assyrie.
Ní ìgbà Peka ọba Israẹli, Tiglat-Pileseri ọba Asiria wá, ó sì mú Ijoni, Abeli-Beti-Maaka, Janoa, Kedeṣi àti Hasori. Ó gba Gileadi àti Galili pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali. Ó sì kó àwọn ènìyàn ní ìgbèkùn lọ sí Asiria.
30 Et Hosée, fils d'Éla, forma une conspiration contre Pékach, fils de Remalia, et fit main basse sur lui et lui donna la mort et devint roi en sa place la vingtième année de Jotham, fils d'Hozias.
Nígbà náà, Hosea ọmọ Ela, dìtẹ̀ sí Peka ọmọ Remaliah. Ó dojúkọ ọ́, ó sì pa á, ó sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba ní ogún ọdún Jotamu ọmọ Ussiah.
31 Le reste des actes de Pékach et toutes ses entreprises, sont d'ailleurs consignés dans le livre des annales des rois d'Israël.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Peka, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
32 La seconde année de Pékach, fils de Remalia, roi d'Israël, Jotham, fils d'Hozias, roi de Juda, devint roi.
Ní ọdún keje Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli, Jotamu ọmọ Ussiah ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
33 Il avait vingt-cinq ans à son avènement et il régna seize ans à Jérusalem. Or le nom de sa mère était Jérusa, fille de Tsadoc.
Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jeruṣa ọmọbìnrin Sadoku.
34 Et il fit ce qui est droit aux yeux de l'Éternel; il agit en tout comme avait agi Hozias, son père.
Ó ṣe ohun tí ó tọ́ lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ Ussiah ti ṣe.
35 Seulement les tertres ne disparurent pas; le peuple offrait encore des victimes et de l'encens sur les tertres. Il construisit la porte supérieure du temple de l'Éternel.
Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò ṣí wọn kúrò àwọn ènìyàn tẹ̀síwájú láti rú ẹbọ àti láti sun tùràrí níbẹ̀: Jotamu tún ìlẹ̀kùn gíga tó ń kọ́ ní ti ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.
36 Le reste des actes, de Jotham et toutes ses entreprises sont d'ailleurs consignés dans le livre des annales des rois de Juda.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Jotamu, àti ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
37 Dans ce même temps l'Éternel commença à envoyer contre Juda, Retsin, roi de Syrie, et Pékach, fils de Remalia.
(Ní ayé ìgbàanì, Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní rán Resini ọba Siria àti Peka ọmọ Remaliah láti dojúkọ Juda).
38 Et Jotham reposa avec ses pères et reçut la sépulture avec ses pères dans la ville de David, son père, et Achaz, son fils, devint roi en sa place.
Jotamu sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi, ìlú ńlá ti baba rẹ̀. Ahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< 2 Rois 15 >