< 2 Chroniques 31 >

1 Et, toutes ces choses accomplies, tous les Israélites présents partirent pour les villes de Juda, et ils brisèrent les colonnes, coupèrent les Aschères et détruisirent les tertres et les autels dans tout Juda et Benjamin et dans Éphraïm et Manassé, jusqu'à ruine complète; puis tous les enfants d'Israël retournèrent chacun dans sa propriété, dans leurs villes.
Nígbà tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ti dé òpin, àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀ jáde lọ sí àwọn ìlú Juda, wọ́n fọ́ àwọn òkúta ìyàsọ́tọ̀ sí wẹ́wẹ́, wọ́n gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀. Wọ́n ba àwọn ibi gíga jẹ́ àti àwọn pẹpẹ jákèjádò Juda àti Benjamini àti ní Efraimu àti Manase. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti pa gbogbo wọn run, àwọn ọmọ Israẹli padà sí ìlú wọn àti sí nǹkan ìní wọn.
2 Et Ézéchias établit les classes des Prêtres et des Lévites, selon leur classification, chacun selon son office, les Prêtres et les Lévites pour les holocaustes et les sacrifices pacifiques, pour le ministère et l'action de grâces et la louange, aux portes du camp de l'Éternel.
Hesekiah fi lé àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi lọ́wọ́ sí àwọn ìpín olúkúlùkù wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí ará Lefi láti tẹ́ ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ láti fi ọpẹ́ fún àti láti kọ àwọn orin ìyìn ní ẹnu-ọ̀nà ibùgbé Olúwa.
3 Et le roi affecta une portion de son bien aux holocaustes, aux holocaustes du matin et du soir et aux holocaustes des sabbats et des nouvelles lunes et des fêtes prescrites dans la Loi de l'Éternel.
Ọba fi sílẹ̀ láti ara ohun ìní rẹ̀ fun ẹbọ sísun àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti fún ẹbọ sísun ní ọjọ́ ìsinmi, òṣùpá tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn gẹ́gẹ́ bi a ti ṣe kọ ọ́ nínú òfin Olúwa.
4 Et le roi dit au peuple, aux habitants de Jérusalem, de payer la part des Prêtres et des Lévites pour les mettre à même de s'appliquer à la Loi de l'Éternel.
Ó pàṣẹ fún àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu láti fi ìpín tí ó yẹ fún àlùfáà fún un àti àwọn ará Lefi, kí wọn kí ó lè fi ara wọn jì fún òfin Olúwa.
5 Et à la promulgation de cet édit les enfants d'Israël apportèrent en abondance les prémices du blé, du moût et de l'huile et du miel et de toutes les productions du sol, et ils apportèrent en masse les dîmes de toutes choses.
Ní kété tí àṣẹ náà jáde lọ, àwọn ọmọ Israẹli fi tìfẹ́tìfẹ́ fi àkọ́so ti ọkà wọn, ọtí tuntun, òróró àti oyin àti gbogbo ohun tí pápá mú jáde lélẹ̀. Wọ́n kó ọ̀pọ̀ iye, àti ìdámẹ́wàá gbogbo nǹkan wá.
6 Et les enfants d'Israël et de Juda domiciliés dans les villes de Juda, apportèrent eux aussi la dîme du gros et du menu bétail et la dîme des consécrations qui avaient été consacrées à l'Éternel, leur Dieu, et en firent des tas et des tas.
Àwọn ọkùnrin Israẹli àti Juda ti gbe inú àwọn ìlú Juda pẹ̀lú mú ìdámẹ́wàá agbo ẹran àti ohun èlò àti ohun ọ̀sìn àti ìdámẹ́wàá ti àwọn nǹkan mímọ́ tí a ti yà sọ́tọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì kó wọn jọ ní òkìtì.
7 Au troisième mois ils commencèrent à former des tas, et ils eurent achevé au septième mois.
Wọ́n bẹ̀rẹ̀ ṣíṣe èyí ní oṣù kẹta, wọ́n sì parí ní oṣù keje.
8 Et vinrent Ézéchias et les princes, qui à la vue des tas bénirent l'Éternel et son peuple d'Israël.
Nígbà tí Hesekiah àti àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ wá, tí wọ́n sì rí òkìtì náà, wọ́n yin Olúwa, pẹ̀lú ìbùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli.
9 Et Ézéchias consulta les Prêtres et les Lévites touchant les tas.
Hesekiah béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi nípa òkìtì;
10 Alors le Grand-Prêtre, Azaria, de la maison de Tsadoc, lui parla et dit: Depuis qu'on a commencé à apporter les dons dans le Temple de l'Éternel, nous avons mangé, et nous avons été rassasiés, et le reliquat est considérable; car l'Éternel a béni son peuple, et le reliquat, c'est le grand tas que voilà.
àti Asariah olórí àlùfáà ti ìdílé Sadoku sì dáhùn pé, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní mú ìdáwó wọn wá sí ilé Olúwa àti ní èyí tí yóò tó jẹ àti ọ̀pọ̀ láti tọ́jú pamọ́ nítorí Olúwa ti bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ṣẹ́kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.”
11 Et Ézéchias dit de disposer des cellules dans la Maison de l'Éternel. Et ils les disposèrent,
Hesekiah pàṣẹ láti tọ́jú àwọn yàrá ìṣúra nínú ilé Olúwa, wọ́n sì ṣe èyí.
12 et y apportèrent fidèlement les prémices et les dîmes et les consécrations. Et ils eurent pour surintendant Chanania, le Lévite, avec Siméï son frère, comme second.
Nígbà náà wọ́n mú ọrẹ àti ìdámẹ́wàá àti àwọn ẹ̀bùn tí a yà sí mímọ́ wọ ilé náà wá nítòótọ́. Lórí èyí tí Konaniah ọmọ Lefi, ń ṣe olórí, Ṣimei arákùnrin rẹ̀ ni igbákejì rẹ̀.
13 Et Jehiel et Azazia et Nahath et Asahel et Jerimoth et Jozabad et Eliel et Jismachia et Mahath et Benaïa étaient intendants sous les ordres de Chanania et de Siméï, son frère, d'après l'ordonnance du roi Ezéchias, et d'Azaria, surintendant de la Maison de Dieu.
Jehieli, Asasiah, Nahati, Asaheli, Jerimoti, Josabadi, Elieli, Ismakia, Mahati àti Benaiah jẹ́ àwọn alábojútó lábẹ́ Konaniah àti Ṣimei arákùnrin rẹ̀ nípa ipá ọba Hesekiah àti Asariah olórí ti ó wà ní ìkáwọ́ ilé Ọlọ́run.
14 Et Coré, fils de Jimna, Lévite, portier de l'orient, avait l'intendance des dons volontaires faits à Dieu, pour délivre la part réservée de l'Éternel, et les très saintes consécrations.
Kore ọmọ Imina ará Lefi olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn, wà ní ìkáwọ́ àwọn ọrẹ àtinúwá tí a fi fún Ọlọ́run, o ń pín ìdáwó tí a ṣe fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn tí a yà sọ́tọ̀
15 Et sous ses ordres étaient Eden et Miniamin et Jésua et Semaïa, Amaria et Sechonia dans les villes sacerdotales, laissés sur leur foi pour faire les délivrances à leurs frères selon leurs classes, au grand comme au petit,
Edeni, Miniamini, Jeṣua, Ṣemaiah, Amariah àti Ṣekaniah ràn án lọ́wọ́ tọkàntọkàn nínú àwọn ìlú àwọn àlùfáà tí ń dáwó fún àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àgbà àti kékeré.
16 non compris les mâles enregistrés dès l'âge de trois ans et au-dessus, tous ceux qui entraient journellement dans le Temple de l'Éternel pour les fonctions de leur office, dans leurs classes;
Ní àfikún, wọ́n pín sí àwọn ọkùnrin àgbà ọdún mẹ́ta tàbí ọ̀pọ̀ tí orúkọ wọn wà nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn. Gbogbo àwọn ti yóò wọ ilé Olúwa láti ṣe oríṣìí iṣẹ́ ti a gbà wọ́n fún gẹ́gẹ́ bí ìgbẹ́kẹ̀lé wọn àti ìpín wọn.
17 non compris les Prêtres enregistrés par maisons patriarcales, et les Lévites de vingt ans et plus en fonctions dans leurs classes,
Wọ́n sì pín àwọn àlùfáà, wọn kọ orúkọ àwọn ìdílé wọn sínú ìtàn ìdílé àti sí àwọn ará Lefi ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu àti ìpín wọn.
18 et tous les leurs enregistrés, enfants, femmes et fils et filles, de toute la corporation, car ils se consacraient fidèlement à leur saint service.
Wọ́n fi gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké sí i, àwọn ìyàwó, àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin gbogbo ará ìlú tí a kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé ti baba ńlá wọn fún ìrántí. Nítorí tí wọ́n ṣe òtítọ́ ní yíya ara wọn sí ọ̀tọ̀.
19 Et pour les Prêtres, fils d'Aaron, il y avait dans la banlieue de leurs villes, ville par ville, des hommes préposés, désignés par leurs noms, pour délivrer leur part à tous les mâles des Prêtres et à tous les Lévites enregistrés.
Ní ti àwọn àlùfáà, àwọn ìran ọmọ Aaroni, tí ń gbé ni àwọn ilẹ̀ oko lẹ́bàá àwọn ìlú wọn tàbí ní àwọn ìlú mìíràn. A yan àwọn ọkùnrin pẹ̀lú orúkọ láti pín ìlú fún gbogbo ọkùnrin láàrín wọn àti sí gbogbo àwọn tí a kọ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá àwọn ará Lefi.
20 Et ainsi fit Ezéchias dans tout Juda et il agit bien et avec droiture et fidélité devant l'Éternel, son Dieu,
Èyí ni Hesekiah ṣe jákèjádò Juda, ó sì ṣe ohun tí ó dára àti tí ó tọ́ àti ohun òtítọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
21 et dans toute l'œuvre qu'il entreprit pour le service de la Maison de Dieu, et pour la Loi et pour le commandement, cherchant son Dieu, il agit de tout son cœur et réussit.
Nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé ní ti iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Ọlọ́run àti ní ìgbọ́ràn sí òfin àti àwọn àṣẹ. Ó wá Ọlọ́run rẹ̀, ó sì ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn. Ó sì ṣe rere.

< 2 Chroniques 31 >