< 2 Chroniques 26 >

1 Alors tout le peuple de Juda prit Hozias, alors âgé de seize ans, et le fit roi en la place de son père, Amatsia.
Nígbà náà gbogbo ènìyàn Juda mú Ussiah, ẹni tí ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún wọ́n sì fi jẹ ọba ní ipò baba rẹ̀ Amasiah.
2 Il rebâtit Eloth et la reconquit à Juda, après que le roi eut été couché à côté de ses pères.
Òun ni ẹni náà tí ó tún Elati kọ́, ó sì mú padà sí Juda lẹ́yìn ìgbà tí Amasiah ọba ti sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀.
3 Hozias avait seize ans à son avènement et il régna cinquante-deux ans à Jérusalem. Or le nom de sa mère était Jecholia de Jérusalem.
Ussiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjìléláàádọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Jekoliah; ó sì wá láti Jerusalẹmu.
4 Et il fit ce qui est bien aux yeux de l'Éternel en tout à l'exemple d'Amatsia, son père.
Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bi baba rẹ̀ Amasiah ti ṣe.
5 Et il fut cherchant Dieu du vivant de Zacharie, l'homme versé dans la contemplation de Dieu, et durant les jours où il chercha l'Éternel, Dieu le fit prospérer.
Ó sì wá Olúwa ní ọjọ́ Sekariah, ẹni tí ó ní òye nínú ìran Ọlọ́run. Níwọ́n ọjọ́ tí ó wá ojú Olúwa, Ọlọ́run fún un ní ohun rere.
6 Et il se mit en campagne et se battit contre les Philistins, et il renversa les murs de Gath et les murs de Jabné et les murs d'Asdod, et bâtit des villes en Asdod et parmi les Philistins.
Ó sì lọ sí ogun pẹ̀lú Filistini ó sì wó odi Gati lulẹ̀, Jabne àti Aṣdodu. Ó sì kó ìlú rẹ̀ tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ Aṣdodu àti níbìkan láàrín àwọn ará Filistini.
7 Et Dieu lui fut en aide contre les Philistins et contre les Arabes établis à Gurbaal, et les Meünites.
Ọlọ́run sì ràn án lọ́wọ́ lórí àwọn ará Filistini àti Arabia tí ń gbé ní Gur-baali àti lórí àwọn ará Mehuni.
8 Et les Ammonites firent des présents à Hozias, et son nom parvint jusqu'en Egypte; car il était extrêmement puissant.
Àwọn ará Ammoni gbé ẹ̀bùn wá fún Ussiah, orúkọ rẹ̀ sì tàn káàkiri títí ó fi dé àtiwọ Ejibiti, nítorí ó ti di alágbára ńlá.
9 Et Hozias construisit des tours à Jérusalem à la porte de l'angle et à la porte de la vallée, et au redan, et les mit en état de défense.
Ussiah sì kọ́ ilé ìṣọ́ ní Jerusalẹmu níbi ẹnu-bodè igun, àti níbi ẹnu-bodè àfonífojì àti níbi ìṣẹ́po odi ó sì mú wọn le
10 Et il bâtit des tours dans le Désert, et creusa une multitude de citernes, car il avait de nombreux troupeaux et dans le pays-bas et dans la plaine, des laboureurs et des vignerons sur les monts et au Carmel, car il aimait l'agriculture.
Ó sì tún ilé ìṣọ́ aginjù kọ́, ó sì gbẹ́ kànga púpọ̀, nítorí ó ni ẹran ọ̀sìn púpọ̀ ní ilẹ̀ ìsàlẹ̀ àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Ó sì ní àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ ní pápá àti ọgbà àjàrà ní orí òkè ní ilẹ̀ ọlọ́ràá, nítorí ó fẹ́ràn àgbẹ̀ ṣíṣe.
11 Et Hozias avait une force armée propre à la guerre, qui allait en campagne par bataillons, d'après le chiffre de leur recensement fait par Jehiel, le Scribe, et Maaseïa, le préposé, sous les ordres de Hanania, l'un des généraux du roi.
Ussiah sì ní àwọn ẹgbẹ́ ogun tí wọ́n kọ́ dáradára, wọ́n múra tán láti lọ pẹ̀lú ẹgbẹgbẹ́ gẹ́gẹ́ bí iye kíkà wọn gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ Jeieli akọ̀wé àti Maaseiah ìjòyè lábẹ́ ọwọ́ Hananiah, ọ̀kan lára àwọn olórí ogun ọba.
12 Le nombre total des patriarches des guerriers était de deux mille six cents.
Àpapọ̀ iye olórí àwọn alágbára akọni ogun jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá.
13 Et la milice sous leurs ordres était de trois cent sept mille cinq cents hommes faisant la guerre avec une force vaillante pour aider le roi contre l'ennemi.
Lábẹ́ olórí àti olùdarí wọn, wọ́n sì jẹ́ alágbára akọni ogun ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin, tí ó ti múra fún ogun ńlá náà, àti alágbára ńlá jagunjagun kan láti ran ọba lọ́wọ́ sí ọ̀tá rẹ̀.
14 Et Hozias leur procura, à toute l'armée, des boucliers et des lances et des casques et des cuirasses et des arcs et jusqu'à des pierres à fronde.
Ussiah sì pèsè ọ̀kọ̀, asà, akọ́rọ́, àti ohun èlò ìhámọ́ra ọrun títí dé òkúta kànnàkànnà fún ọwọ́ àwọn ọmọ-ogun.
15 Et il fit à Jérusalem des engins, ingénieux travail des ingénieurs, pour être placés sur les tours et aux redans pour tirer avec des flèches et de grosses pierres. Et son nom se répandit au loin, car il fut aidé merveilleusement à devenir puissant.
Ní Jerusalẹmu ó sì ṣe ohun ẹ̀rọ ìjagun, iṣẹ́ ọwọ́ ọlọ́gbọ́n ènìyàn, láti wà lórí ilé ìṣọ́ àti lórí igun odi láti fi tafà àti láti fi sọ òkúta ńlá. Orúkọ rẹ̀ sì tàn káàkiri, nítorí a ṣe ìrànlọ́wọ́ ìyanu fún un títí ó fi di alágbára.
16 Mais quand il fut puissant, son cœur s'éleva, pour sa perte; et il fut infidèle à l'Éternel, son Dieu; et il pénétra dans le Temple de l'Éternel pour encenser sur l'autel aux parfums.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí Ussiah jẹ́ alágbára tán, ìgbéraga rẹ̀ sì gbé e ṣubú. Ó sì di aláìṣòótọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. Ó sì wọ ilé Olúwa láti sun tùràrí lórí pẹpẹ tùràrí.
17 Alors il y fut suivi par le Prêtre Azaria accompagné de Prêtres de l'Éternel au nombre de quatre-vingts hommes de cœur,
Asariah àlùfáà pẹ̀lú àwọn ọgọ́rin alágbára àlùfáà Olúwa mìíràn sì tẹ̀lé e.
18 et ils s'opposèrent à Hozias, le roi, et lui dirent: Ce n'est pas à toi, Hozias, à offrir l'encens à l'Éternel, mais aux Prêtres, fils d'Aaron, qui sont consacrés pour l'encensement. Sors du sanctuaire, car tu forfais! et cet honneur ne t'a pas été décerné par l'Éternel, Dieu.
Wọ́n sì takò ọba Ussiah, wọn sì wí pé, “Kò dára fún ọ, Ussiah, láti sun tùràrí sí Olúwa. Èyí fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Aaroni, ẹni tí ó ti yà sí mímọ́ láti sun tùràrí. Fi ibi mímọ́ sílẹ̀, nítorí tí ìwọ ti jẹ́ aláìṣòótọ́, ìwọ kò sì ní jẹ́ ẹni ọlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run.”
19 Alors Hozias se courrouça, et il avait en main un encensoir pour encenser; et comme il se courrouçait contre les Prêtres, la lèpre éclata sur son front à la vue des Prêtres dans le Temple de l'Éternel à côté de l'autel aux parfums.
Ussiah, ẹni tí ó ní àwo tùràrí ní ọwọ́ rẹ̀ tó ṣetán láti sun tùràrí sì bínú. Nígbà tí ó sì ń bínú sí àwọn àlùfáà níwájú wọn, níwájú pẹpẹ tùràrí ní ilé Olúwa, ẹ̀tẹ̀ sì yọ jáde ní iwájú orí rẹ̀.
20 Et lorsque le Grand-Prêtre Azaria et tous les Prêtres arrêtèrent leurs regards sur lui, voilà qu'il avait la lèpre au front; et ils le chassèrent de là, et lui-même se hâta de sortir parce que l'Éternel l'avait frappé.
Nígbà tí Asariah olórí àlùfáà àti gbogbo àwọn àlùfáà yòókù sì wò ó, wọ́n sì rí i wí pé ó ní ẹ̀tẹ̀ níwájú orí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì sáré gbé e jáde pẹ̀lúpẹ̀lú, òun tìkára rẹ̀ ti fẹ́ láti jáde, nítorí tí Olúwa ti kọlù ú.
21 Et le roi Hozias fut lépreux jusqu'au jour de sa mort, et il logea dans une infirmerie en tant que lépreux: car il était exclu du Temple de l'Éternel. Et Jotham, son fils, fut préposé sur la maison du roi, et gouverna le peuple du pays.
Ọba Ussiah sì ní ẹ̀tẹ̀ títí di ọjọ́ ikú rẹ̀. Ó sì gbé ní ilé àwọn adẹ́tẹ̀, a sì ké e kúrò ní ilé Olúwa. Jotamu ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ lórí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
22 Le reste des actes d'Hozias, les premiers et les derniers, Ésaïe, fils d'Amots, le prophète, en a écrit l'histoire.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Ussiah láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ láti ọwọ́ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
23 Et Hozias reposa à côté de ses pères, et reçut la sépulture à côté de ses pères dans le champ sépulcral des rois; car l'on dit: Il est lépreux. Et Jotham, son fils, devint roi en sa place.
Ussiah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba, rẹ̀ a sì sin sí ẹ̀gbẹ́ wọn nínú oko ìsìnkú fún ti iṣẹ́ tí àwọn ọba, nítorí àwọn ènìyàn wí pé “Ó ní ààrùn ẹ̀tẹ̀,” Jotamu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< 2 Chroniques 26 >