< 2 Chroniques 18 >
1 Et Josaphat avait en abondance richesse et gloire, et il s'allia à Achab.
Nísinsin yìí Jehoṣafati sì ní ọrọ̀ àti ọlá púpọ̀, ó sì dá àna pẹ̀lú Ahabu nípa fífẹ́ ọmọ rẹ̀.
2 Et au bout de quelques années il descendit chez Achab à Samarie, et Achab tua pour lui nombre de moutons et des bœufs, ainsi que pour les gens de sa suite et l'invita à marcher contre Ramoth en Galaad.
Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, ó sọ̀kalẹ̀ láti lọ bá Ahabu lálejò ní Samaria. Ahabu sì pa àgùntàn àti màlúù púpọ̀ fún àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ó sì rọ̀ ọ́ láti dojú ìjà kọ Ramoti Gileadi.
3 Et Achab, roi d'Israël, dit à Josaphat, roi de Juda: Veux-tu marcher avec moi contre Ramoth en Galaad? Et il lui répondit: Nous serons de pair moi et toi, et ton peuple et mon peuple, et avec toi j'irai en guerre.
Ahabu ọba Israẹli sì béèrè lọ́wọ́ ọba Jehoṣafati, ọba Juda pé, “Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi sí Ramoti Gileadi?” Jehoṣafati sì dá a lóhùn pé, “Èmi wà gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe wà, àti àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ènìyàn rẹ àwa yóò pẹ̀lú rẹ nínú ogun náà”.
4 Et Josaphat dit au roi d'Israël: Qu'il te plaise requérir aujourd'hui la parole de l'Éternel!
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati náà sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
5 Et le roi d'Israël réunit les prophètes au nombre de quatre cents hommes, et leur dit: Marcherons-nous à l'attaque de Ramoth en Galaad? ou y renoncerai-je? Et ils dirent: Marche! et Dieu la livrera aux mains du roi.
Bẹ́ẹ̀ ọba Israẹli kó àwọn wòlíì papọ̀, irinwó ọkùnrin ó sì bi wọ́n pé, “Kí àwa kí lọ sí ogun Ramoti Gileadi tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ?” Wọ́n dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Ọlọ́run yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
6 Et Josaphat dit: N'y a-t-il point encore ici de prophète de l'Éternel, par qui nous puissions consulter?
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ṣé kò ha sí wòlíì Olúwa níbí ẹni tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
7 Et le roi d'Israël dit à Josaphat: Il y a encore un homme par qui nous pourrions consulter l'Éternel; mais je le hais parce que pour moi il ne prophétise jamais en bien, mais toujours en mal; c'est Michée, fils de Jimla. Et Josaphat dit: Que le roi ne parle pas de la sorte!
Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan wà síbẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí àwa ìbá tún béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n èmi kórìíra rẹ̀ nítorí kò jẹ́ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun rere kan nípa mi ṣùgbọ́n bí kò ṣe ohun búburú, ní gbogbo ìgbà òun náà ni Mikaiah ọmọ Imla.” Jehoṣafati sì dá lóhùn pé, “Ọba kò gbọdọ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
8 Alors le roi d'Israël appela un eunuque et lui dit: Fais vite venir Michée, fils de Jimla.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pe ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ó sì wí pé, “Ẹ mú Mikaiah ọmọ Imla kí ó yára wá.”
9 Cependant le roi d'Israël et Josaphat, roi de Juda, étaient assis, chacun sur son trône, revêtus de leur costume, et se tenaient dans une aire aux abords de la porte de Samarie, et tous les prophètes prophétisaient devant eux.
Wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn, ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda wọ́n jókòó sórí ìtẹ́ wọ́n ní ìta ẹnu-bodè Samaria, pẹ̀lú gbogbo àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
10 Et Sédécias, fils de Cnaana, se fit des cornes de fer et dit: Ainsi parle l'Éternel: Avec ceci tu heurteras les Syriens jusqu'à les achever.
Nísinsin yìí Sedekiah ọmọ Kenaana sì ti ṣe ìwo irin, ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Pẹ̀lú èyí ìwọ yóò kan àwọn ará Siria títí ìwọ ó fi pa wọ́n run.’”
11 Et tous les prophètes prophétisaient de même et disaient: Marche contre Ramoth en Galaad et tu viendras à bout d'elle, et l'Éternel la livrera aux mains du roi.
Gbogbo àwọn wòlíì tí ó kù ni wọn ń sọtẹ́lẹ̀ ní àkókò kan náà. Wọ́n sì wí pé, “Dojúkọ Ramoti Gileadi ìwọ yóò sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
12 Et le messager qui était allé quérir Michée, lui parla en ces termes: Voici, les discours des prophètes sont à l'unanimité favorables au roi, que ton discours soit donc comme celui de l'un d'eux, et parle favorablement.
Ìránṣẹ́ tí ó ti lọ pe Mikaiah sì wí fún un pé, “Ẹ wò ó, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin kan àti òmíràn wòlíì fi ẹnu kan sọ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kí ó dàbí ọ̀kan nínú tiwọn, kí o sì sọ rere.”
13 Et Michée dit: Par la vie de l'Éternel! ce que mon Dieu me dira, je le rendrai.
Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pe, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa ń bẹ láààyè, èmi yóò sọ ohun tí Ọlọ́run mi sọ.”
14 Et quand il fut arrivé vers le roi, le roi lui dit: Michée, marcherons-nous à l'attaque de Ramoth en Galaad? ou y renoncerai-je? Et il répondit: Marchez!…, et vous réussirez…, et elle sera livrée à vos mains!
Nígbà tí ó dé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, “Mikaiah, ṣe kí àwa ki ó lọ sí ogun ti Ramoti Gileadi, tàbí kí àwa kí ó fàsẹ́yìn?” Ó sì dáhùn pé, “Ẹ dojúkọ wọ́n kí ẹ sì ṣẹ́gun, nítorí a ó fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
15 Et le roi lui dit: Combien de fois faut-il que je t'adjure ils de ne me dire que la vérité au nom de l'Éternel!
Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi ó fi ọ́ búra láti sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe ọ̀rọ̀ òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
16 Et il dit: J'ai vu tout Israël épars sur les montagnes comme un troupeau sans pasteur. Et l'Éternel dit: Ils sont sans maîtres! qu'ils retournent chacun dans sa maison en paix!
Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
17 Alors le roi d'Israël dit à Josaphat: Ne te l'ai-je pas dit? pour moi il ne prophétise pas en bien, mais en mal.
Ọba Israẹli wí fún Jehoṣafati pé, “Ṣe èmi kò sọ fún ọ wí pé òun kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kankan nípa mi rí, ṣùgbọ́n búburú nìkan?”
18 Et il dit: En conséquence, écoutez la parole de l'Éternel: J'ai vu l'Éternel assis sur son trône, et toute l'armée des Cieux debout à sa droite et à sa gauche.
Mikaiah tẹ̀síwájú pé, “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ gbogbo ogun ọ̀run sì dúró lápá ọ̀tún àti lápá òsì.
19 Et l'Éternel dit: Qui veut suggérer à Achab, roi d'Israël, de marcher pour aller tomber à Ramoth en Galaad? Et l'un parla d'une manière, et l'autre d'une autre.
Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu ọba Israẹli lọ sí Ramoti Gileadi kí ó sì lọ kú ikú rẹ̀ níbẹ̀?’ “Èkínní sì sọ tìhín, òmíràn sì sọ tọ̀hún.
20 Alors l'Esprit sortit et parut devant l'Éternel et dit: Moi, je le lui suggérerai.
Ní ìparí, ni ẹ̀mí kan wá síwájú, ó dúró níwájú Olúwa ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’ “‘Nípa ọ̀nà wo?’ Olúwa béèrè.
21 Et l'Éternel lui dit: Comment? Et il dit: Je partirai et serai esprit de mensonge dans la bouche de tous ses prophètes. Et il dit: Suggère! et emporte-le! pars et ainsi fais!
“‘Èmi yóò lọ láti lọ di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì.’ “‘Ìwọ yóò sì borí nínú ìtànjẹ rẹ̀ báyìí,’ ni Olúwa wí. ‘Lọ kí ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
22 Eh bien! voici, l'Éternel a mis un esprit de mensonge dans la bouche de ces tiens prophètes, et l'Éternel a prononcé sur toi la ruine.
“Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
23 Alors Sédécias, fils de Cnaana, s'approcha et frappa Michée sur la joue et dit: Est-ce là la voie par où l'esprit de l'Éternel se serait retiré de moi pour communiquer avec toi?
Nígbà náà Sedekiah ọmọ Kenaana lọ sókè ó sì gbá Mikaiah ní ojú. Ó sì béèrè pé, “Ní ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà kọjá lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
24 Et Michée dit: Voici tu le verras le jour même où tu iras de chambre en chambre pour te cacher.
Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
25 Et le roi d'Israël dit: Arrêtez Michée et le menez à Amon, préfet de la ville, et à Joas, fils du roi,
Ọba Israẹli pa á láṣẹ pé, “Mú Mikaiah kí o sì ran padà sí Amoni olórí ìlú àti sí Joaṣi ọmọ ọba,
26 et dites: Ainsi parle le roi: Mettez cet homme en prison, et nourrissez-le de pain et d'eau de rigueur, jusqu'à ce que je revienne sain et sauf.
Ó sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí ọba sọ, ẹ fi ènìyàn yìí sínú túbú kí ẹ má sì ṣe fún un ní ohunkóhun ṣùgbọ́n àkàrà àti omi títí tí èmi yóò fi dé ní àlàáfíà.’”
27 Et Michée dit: Si tu reviens sain et sauf, l'Éternel n'a pas parlé par moi. Et il dit: Entendez, vous tous les peuples!
Mikaiah sì wí pe, “Tí ìwọ bá padà ní àlàáfíà, Olúwa kò sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà náà, ó sì fi kún un pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn!”
28 Et le roi d'Israël avec Josaphat, roi de Juda, marcha contre Ramoth en Galaad.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda lọ sókè ní Ramoti Gileadi.
29 Et le roi d'Israël dit à Josaphat: Je me travestirai pour aller au combat, mais toi, revêts-toi de ton costume. Le roi d'Israël se travestit donc, et ils vinrent au combat.
Ọba Israẹli sọ fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ rẹ̀ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
30 Et le roi de Syrie avait donné cet ordre aux commandants de ses chars: N'attaquez personne, ni petit, ni grand, sinon le roi d'Israël seul.
Nísinsin yìí ọba Siria ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ má ṣe jà pẹ̀lú ẹnìkankan, èwe tàbí àgbà àyàfi ọba Israẹli.”
31 Et lorsque les commandants des chars virent Josaphat, ils se dirent: C'est le roi d'Israël! et ils appuyèrent de son côté pour l'attaquer. Alors Josaphat fit un cri, et l'Éternel le secourut, et Dieu les écarta de lui;
Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rí Jehoṣafati, wọ́n rò wí pé, “Èyí ní ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yípadà láti bá a jà. Ṣùgbọ́n Jehoṣafati kégbe sókè, Olúwa sì ràn án lọ́wọ́. Ọlọ́run sì lé wọn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀,
32 et lorsque les commandants des chars virent que ce n'était pas le roi d'Israël, ils revinrent de sa poursuite.
Ó sì ṣe, nígbà tí olórí kẹ̀kẹ́ rí i wí pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì dáwọ́ lílé rẹ̀ dúró.
33 Cependant un homme banda son arc tout innocemment, et atteignit le roi d'Israël entre les pendants de la cuirasse et la cotte d'armes. Et celui-ci dit à son cocher: Tourne et mène-moi hors de la mêlée, car je suis blessé.
Ṣùgbọ́n ẹnìkan fa ọrun rẹ̀ láì pète, ó sì bá ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin, ọba sì sọ fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ padà, kí o sì wà mí jáde kúrò lójú ìjà. Nítorí èmi ti gbọgbẹ́.”
34 Et la bataille était intense pendant cette journée, et le roi d'Israël resta debout sur son char en vue des Syriens jusqu'au soir, et il mourut au moment du coucher du soleil.
Ní ọjọ́ pípẹ́, ìjà náà sì ń pọ̀ sí i, ọba Israẹli dúró nínú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ kọjú sí àwọn ará Siria títí ó fi di àṣálẹ́. Lẹ́yìn náà ní àkókò ìwọ oòrùn, ó sì kú.