< 1 Samuel 20 >

1 Et David s'enfuit de Naioth près Rama et il vint trouver Jonathan et dit: Qu'ai-je fait et quel est mon crime et quel est mon péché contre ton père pour qu'il attente à ma vie?
Nígbà náà ni Dafidi sá kúrò ní Naioti ti Rama ó sì lọ sọ́dọ̀ Jonatani ó sì béèrè pé, “Kí ni mo ṣe? Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Báwo ni mo ṣe ṣẹ baba rẹ, tí ó sì ń wá ọ̀nà láti gba ẹ̀mí mi?”
2 Et [Jonathan] lui dit: A Dieu ne plaise! Tu ne mourras point. Voici, mon père ne fait rien? chose grande ou petite, sans me mettre en part; et pourquoi mon père se cacherait-il de moi en ceci? Il n'en est rien.
Jonatani dáhùn pé, “Kí a má rí i! Ìwọ kò ní kú! Wò ó baba mi kì í ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí tí ó kéré, láìfi lọ̀ mí. Èéṣe tí yóò fi fi èyí pamọ́ fún mi? Kò rí bẹ́ẹ̀.”
3 Et David fit encore serment et dit: Ton père sait très bien que j'ai trouvé grâce à tes yeux, et il aura dit: Il ne faut pas que Jonathan en soit instruit de peur qu'il ne s'afflige. Mais certainement, par la vie de l'Éternel et par ta vie, il n'y a qu'un pas entre moi et la mort.
Ṣùgbọ́n Dafidi tún búra, ó sì wí pé, “Baba rẹ mọ̀ dáradára pé mo rí ojúrere ní ojú rẹ, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, ‘Jonatani kò gbọdọ̀ mọ èyí yóò sì bà á nínú jẹ́.’ Síbẹ̀ nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà láààyè, ìgbésẹ̀ kan ni ó wà láàrín ìyè àti ikú.”
4 Et Jonathan dit à David: Je ferai pour toi ce que ton âme dictera.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe, èmi yóò ṣe é fún ọ.”
5 Et David dit à Jonathan: Voici, demain, c'est lune nouvelle, et j'ai ma place à la table du Roi; mais laisse-moi libre et j'irai me cacher dans la campagne jusqu'à la troisième soirée.
Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Wò ó, ọ̀la ni oṣù tuntun, mo sì gbọdọ̀ bá ọba jẹun, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó lọ láti fi ara pamọ́ lórí pápá títí di àṣálẹ́ ọjọ́ kẹta.
6 Si ton père remarquait mon absence, dis: David m'a prié de lui permettre de faire une course à Bethléhem, sa cité, à l'occasion d'un sacrifice annuel qui s'y fait pour toute la famille.
Bí ó bá sì ṣe pé baba rẹ bá fẹ́ mi kù, kí o sì wí fún un pé, ‘Dafidi fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ béèrè ààyè láti sáré lọ sí Bẹtilẹhẹmu ìlú rẹ̀ nítorí wọ́n ń ṣe ẹbọ ọdọọdún ní ibẹ̀ fún gbogbo ìdílé rẹ̀.’
7 S'il reprend ainsi: C'est bon! il y a paix pour ton serviteur; mais s'il se courrouce, sache que ma perte est arrêtée par devers lui.
Tí o bá wí pé, ‘Àlàáfíà ni,’ nígbà náà, ìránṣẹ́ rẹ wà láìléwu. Ṣùgbọ́n tí ó bá bínú gidigidi, ìwọ yóò mọ̀ dájú pé ó pinnu láti ṣe ìpalára mi.
8 Montre donc de l'affection à ton serviteur, car tu as associé avec toi ton serviteur dans un contrat scellé devant l'Éternel. Or, s'il y a transgression de ma part, donne-moi la mort toi-même; pourquoi m'adresserais-tu à ton père?
Ṣùgbọ́n ní tìrẹ ìwọ, fi ojúrere wo ìránṣẹ́ rẹ; nítorí tí ìwọ ti bá a dá májẹ̀mú pẹ̀lú rẹ níwájú Olúwa. Tí mo bá jẹ̀bi, pa mí fún ara rẹ! Èéṣe tí ìwọ yóò fi fi mí lé baba rẹ lọ́wọ́?”
9 Et Jonathan dit: A Dieu ne plaise! Mais si j'apprends de science certaine que ta perte résolue chez mon père doit t'atteindre, ne t'en informerai-je pas?
Jonatani wí pé, “Kí a má rí i! Ti mo bá ti gbọ́ tí baba mi ti pinnu láti pa ọ́ lára, ṣé èmi kò ní sọ fún ọ?”
10 Et David dit à Jonathan: Qui m'informerait dans le cas où ton père te ferait quelque réponse dure?
Nígbà náà ni Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Ta ni yóò sọ fún mi tí baba rẹ̀ bá dá ọ lóhùn ní ohùn líle?”
11 Et Jonathan dit à David: Viens et sortons dans la campagne. Et ils gagnèrent tous deux la campagne.
Jonatani wí fún Dafidi pé, “Wá, jẹ́ kí a jáde lọ sórí pápá.” Nígbà náà wọ́n sì jáde lọ.
12 Et Jonathan dit à David: [Par] l'Éternel, Dieu d'Israël, si dans l'espace de demain à après-demain je sonde mon père, et s'il se montre bien disposé pour David, et que, le cas échéant, je ne te le mande pas et ne t'en informe pas…
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Mo fi Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli búra pé, èmi yóò rí i dájú pé mo gbọ́ ti ẹnu baba mi ní ìwòyí ọ̀la tàbí ní ọ̀túnla! Bí ó bá sì ní inú dídùn sí ọ, èmi yóò ránṣẹ́ sí ọ, èmi yóò sì jẹ́ kí o mọ̀?
13 que l'Éternel fasse ceci à Jonathan et pis encore. Si je vois chez mon père une disposition sinistre à ton égard, je t'en instruirai et te mettrai à même de partir de manière à t'en aller sain et sauf. Et que l'Éternel soit avec toi, comme il fut avec mon père.
Ṣùgbọ́n tí baba mi bá fẹ́ pa ọ́ lára, kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí Jonatani; tí èmi kò bá jẹ́ kí o mọ̀, kí n sì jẹ́ kí o lọ ní àlàáfíà. Kí Olúwa kí ó wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pẹ̀lú baba mi.
14 Et puisses-tu, si je dois vivre encore, puisses-tu en agir envers moi avec la bonté de l'Éternel,
Ṣùgbọ́n fi àìkùnà inú rere hàn mí bí inú rere Olúwa, níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè kí wọ́n má ba à pa mí.
15 et, si je viens à mourir, ne jamais retirer ta bienveillance de ma maison. Et si l'Éternel fait disparaître de la face de la terre les ennemis de David jusqu'au dernier,
Má ṣe ké àánú rẹ kúrò lórí ìdílé mi títí láé. Bí Olúwa tilẹ̀ ké gbogbo ọ̀tá Dafidi kúrò lórí ilẹ̀.”
16 que le nom de Jonathan ne disparaisse pas de la maison de David! Mais que l'Éternel tire satisfaction des ennemis de David!
Nígbà náà ni Jonatani bá ilé Dafidi dá májẹ̀mú wí pé, “Olúwa yóò pe àwọn àti Dafidi láti ṣírò.”
17 Et Jonathan réitéra son serment à David parce qu'il l'aimait; car il l'aimait comme son âme.
Jonatani mú kí Dafidi tún ìbúra ṣe nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí i, nítorí tí ó fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti fẹ́ràn ara rẹ̀.
18 Et Jonathan lui dit: Demain, c'est lune nouvelle, et ton absence sera remarquée, car ton siège sera vacant;
Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Lọ́la ní ibi àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun, a yóò fẹ́ ọ kù, nítorí ààyè rẹ yóò ṣófo.
19 après-demain donc hâte-toi de descendre et viens à l'endroit où tu t'es caché le jour de l'attentat et tiens-toi vers la pierre Azel.
Ní ọ̀túnla lọ́wọ́ alẹ́ lọ sí ibi tí o sá pamọ́ sí nígbà tí ìṣòro yìí bẹ̀rẹ̀, kí o sì dúró níbi òkúta Eselu.
20 Pour moi, je décocherai trois flèches dans cette direction pour tirer au but.
Èmi yóò ta ọfà mẹ́ta sí ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀, gẹ́gẹ́ bí i pé mo ta á sí àmì ibìkan.
21 Et voici, j'enverrai le valet en disant: « Va chercher les flèches! » Si je lui dis: « Voici, les flèches sont en deçà de toi, enlève-les! » viens, car tu es en sûreté, il n'y a rien, par la vie de l'Éternel.
Èmi yóò rán ọmọdékùnrin kan èmi yóò wí fún un wí pé, ‘Lọ, kí o lọ wá ọfà náà.’ Tí mo bá sọ fún un wí pé, ‘Wò ó, ọfà wọ̀nyí wà ní ibi báyìí ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ rẹ; kó wọn wá síbí,’ kí o sì wá, nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wà ní ààyè, o wà ní àlàáfíà; kò sí ewu.
22 Mais si j'adresse au jeune homme ces paroles: « Voilà, les flèches sont en avant de toi », va t'en, car l'Éternel te fait partir.
Ṣùgbọ́n tí mo bá sọ fún ọmọdékùnrin náà pé, ‘Wò ó, àwọn ọfà náà ń bẹ níwájú rẹ,’ ǹjẹ́ máa bá tìrẹ lọ, nítorí Olúwa ni ó rán ọ lọ.
23 Et quant à la parole que nous avons prononcée toi et moi, que l'Éternel reste entre toi et moi éternellement!
Nípa ọ̀rọ̀ tí èmi àti ìwọ jọ sọ, rántí Olúwa jẹ́ ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti èmi títí láéláé.”
24 David se cacha donc dans la campagne. Et c'était nouvelle lune et le Roi vint se mettre à table pour prendre son repas.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sá pamọ́ sínú pápá. Nígbà tí àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun sì dé, ọba sì jókòó láti jẹun.
25 Et le Roi, cette fois comme les autres, prit place sur son siège, le siège adossé à la muraille; et Jonathan s'étant levé, Abner prit place à côté de Saül et la place de David resta vide.
Ọba sì jókòó gẹ́gẹ́ bí ipò o rẹ̀ ní ibi tí ó máa ń jókòó lórí ìjókòó tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri, ní òdìkejì Jonatani, Abneri sì jókòó ti Saulu, ṣùgbọ́n ààyè Dafidi sì ṣófo.
26 Cependant ce jour-là Saül ne dit mot; car sa pensée était: il aura par aventure contracté quelque souillure; c'est qu'il n'est pas en état de pureté.
Saulu kò sọ nǹkan kan ní ọjọ́ náà, nítorí ó rò pé, “Nǹkan kan ti ṣẹlẹ̀ sí Dafidi láti jẹ́ kí ó di aláìmọ́ lóòtítọ́ ó jẹ́ aláìmọ́.”
27 Le lendemain de la nouvelle lune, le second jour, comme la place de David était encore vacante, Saül dit à Jonathan son fils: Pourquoi le fils d'Isaï n'a-t-il ni hier ni aujourd'hui paru à table?
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì, ní ọjọ́ kejì oṣù, ààyè Dafidi sì tún ṣófo. Nígbà náà ni Saulu wí fún ọmọ rẹ̀ Jonatani pé, “Kí ni ó dé tí ọmọ Jese kò fi wá sí ibi oúnjẹ, lánàá àti lónìí?”
28 Et Jonathan répondit à Saül: David m'a prié instamment de le laisser aller à Bethléhem,
Jonatani sì dáhùn pé, “Dafidi bẹ̀ mí tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ fún ààyè láti lọ sí Bẹtilẹhẹmu.
29 et il m'a dit: Donne-moi un congé car nous avons dans la ville un sacrifice de famille, et mon frère m'a mandé; si donc j'ai trouvé grâce à tes yeux, laisse-moi libre d'aller afin que je voie mes frères; telle est la raison pour laquelle il ne paraît pas à la table du Roi.
Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí n lọ, nítorí pé ìdílé wa ń ṣe ìrúbọ ní ìlú, àwọn ẹ̀gbọ́n ọ̀n mi sì ti pàṣẹ fún mi láti wà níbẹ̀; tí èmi bá rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí n lọ láti lọ rí àwọn ẹ̀gbọ́n mi.’ Ìdí nìyìí tí kò fi wá sí orí tábìlì oúnjẹ ọba.”
30 Alors la colère de Saül s'enflamma contre Jonathan et il lui dit: Fils d'une perverse obstinée! ne connaissé-je pas la préférence que tu as pour le fils d'Isaï, à ta honte et à la honte du ventre de ta mère?
Ìbínú Saulu sì ru sí Jonatani ó sì wí fún un pé, “Ìwọ ọmọ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀ búburú yìí, ṣé èmi kò ti mọ̀ pé, ìwọ ti yan ọmọ Jese fún ìtìjú ti ara rẹ àti fún ìtìjú màmá rẹ tí ó bí ọ?
31 Car tant que le fils d'Isaï sera vivant sur la terre, il n'y aura de position assurée ni pour toi ni pour ta souveraineté! Dépêche donc à l'instant et fais qu'on me l'amène, car c'est un enfant de la mort.
Níwọ́n ìgbà tí ọmọ Jese bá wà láààyè lórí ilẹ̀ ayé, a kì yóò fi ẹsẹ̀ ìwọ tàbí ti ìjọba rẹ múlẹ̀. Nísinsin yìí ránṣẹ́ kí o sì lọ mú un wá fún mi, nítorí ó gbọdọ̀ kú!”
32 Et Jonathan répondit à Saül, son père, et lui dit: Pourquoi le mettre à mort? qu'a-t-il fait?
Jonatani béèrè lọ́wọ́ baba rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwa yóò fi pa á? Kí ni ó ṣe?”
33 Alors Saül lança contre lui sa pique pour le percer, et Jonathan comprit que c'était parti arrêté chez son père que de faire mourir David.
Ṣùgbọ́n Saulu ju ọ̀kọ̀ rẹ̀ sí Jonatani láti gún un pa. Nígbà náà ni Jonatani mọ̀ pé baba rẹ̀ mọ̀ ọ́n mọ̀ fẹ́ pa Dafidi ni.
34 Et Jonathan se leva de table enflammé de colère, et le second jour de la nouvelle lune il ne mangea point, car il était chagriné au sujet de David parce que son père l'avait outragé.
Bẹ́ẹ̀ ni Jonatani sì fi ìbínú dìde kúrò ni ibi oúnjẹ, kò sì jẹun ni ọjọ́ kejì oṣù náà, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ gidigidi fún Dafidi, nítorí pé baba rẹ̀ dójútì í.
35 Et dès le matin Jonathan alla dans la campagne au rendez-vous fixé avec David, ayant avec lui un petit valet.
Ó sì ṣe, ní òwúrọ̀ ni Jonatani jáde lọ sí oko ní àkókò tí òun àti Dafidi ti fi àdéhùn sí, ọmọdékùnrin kan sì wá pẹ̀lú rẹ̀.
36 Et il dit à son valet: Cours, va chercher les flèches que je tire! Le valet courut et Jonathan tira la flèche de manière à le dépasser.
Ó si wí fún ọmọdékùnrin rẹ̀ pé, “Sáré, kí o si wá àwọn ọfà tí èmi ó ta.” Bí ọmọdé náà sì ti ń sáré, òun sì tafà rékọjá rẹ̀.
37 Et lorsque le valet fut venu jusqu'à la portée des flèches tirées par Jonathan, celui-ci lui cria par derrière: La flèche n'est-elle pas en avant de toi?
Nígbà tí ọmọdékùnrin náà sì dé ibi ọfà tí Jonatani ta, Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà ó sì wí pé, “Ọfà náà kò ha wà níwájú rẹ bi?”
38 Et Jonathan cria au valet par derrière: Fais diligence, hâte-toi, ne t'arrête pas! Et le valet de Jonathan ramassa les flèches et revint vers sont maître.
Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà pé, “Sáré! Yára! Má ṣe dúró!” Ọmọdékùnrin Jonatani sì ṣa àwọn ọfà náà, ó sì tọ olúwa rẹ̀ wá.
39 Or le valet ne se doutait de rien, Jonathan et David seuls savaient de quoi il s'agissait.
(Ọmọdékùnrin náà kò sì mọ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n Jonatani àti Dafidi ni ó mọ ọ̀ràn náà.)
40 Et Jonathan remit ses armes à son valet et lui dit: Va et les porte en ville.
Jonatani sì fi apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú.”
41 Le valet partit, et David sortit d'auprès [le tas de pierres] qu'il avait devant lui et se jeta la face contre terre et adora par trois fois, et ils se donnèrent l'un à l'autre le baiser, et ils pleurèrent ensemble, David jusqu'au sanglot.
Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dafidi sì dìde láti ibi ìhà gúúsù òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jonatani, wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sọkún, èkínní pẹ̀lú èkejì rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi sọkún púpọ̀ jù.
42 Et Jonathan dit à David: Va en paix! Nous en resterons à ce que nous avons juré tous les deux par le Nom de l'Éternel en disant que l'Éternel soit éternellement entre moi et toi, entre ma race et la tienne.
Jonatani sì wí fún Dafidi pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí jùmọ̀ búra ni orúkọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrín èmi àti ìwọ, láàrín irú-ọmọ mi àti láàrín irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jonatani sì lọ sí ìlú.

< 1 Samuel 20 >