< Zacharie 4 >
1 Puis l'ange qui me parlait revint, et me réveilla, comme un homme qu'on réveille de son sommeil;
Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ sì tún dé, ó sì jí mi, bí ọkùnrin tí a jí lójú oorun rẹ̀,
2 Et il me dit: Que vois-tu? Et je dis: Je regarde, et voici il y a un chandelier tout d'or, avec son réservoir au sommet, et portant ses sept lampes, avec sept conduits pour les sept lampes qui sont au sommet du chandelier.
ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Mo sì wí pé, “Mo wò, sì kíyèsi i, ọ̀pá fìtílà tí gbogbo rẹ̀ jẹ́ wúrà, pẹ̀lú àwokòtò rẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú fìtílà méje rẹ̀ lórí rẹ̀, àti ẹnu méje fún fìtílà méjèèje, tí ó wà lórí rẹ̀.
3 Et il y a près de lui deux oliviers, l'un à droite du réservoir, et l'autre à gauche.
Igi olifi méjì sì wà létí rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àwokòtò náà, àti èkejì ní apá òsì rẹ̀.”
4 Et je pris la parole, et dis à l'ange qui me parlait: Que signifient ces choses, mon seigneur?
Mo sì dáhùn mo sì wí fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀, pé, “Kín ni wọ̀nyí, olúwa mi?”
5 Et l'ange qui me parlait répondit et me dit: Ne sais-tu pas ce que signifient ces choses? Et je dis: Non, mon seigneur.
Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n, olúwa mi.”
6 Alors il reprit et me dit: C'est ici la parole de l'Éternel, qu'il adresse à Zorobabel, disant: Ce n'est point par puissance, ni par force, mais par mon Esprit, a dit l'Éternel des armées.
Ó sì dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Serubbabeli tó wí pé: ‘Kì í ṣe nípa ipá, kì í ṣe nípa agbára, bí kò ṣe nípa Ẹ̀mí mi,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
7 Qu'es-tu, grande montagne, devant Zorobabel? Tu seras aplanie. Il fera paraître la pierre du faîte, aux cris de: Grâce, grâce sur elle!
“Ta ni ìwọ, ìwọ òkè ńlá? Ìwọ yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀ níwájú Serubbabeli: òun yóò sì fi ariwo mú òkúta téńté orí rẹ̀ wá, yóò máa kígbe wí pé, ‘Ọlọ́run bùkún fun! Ọlọ́run bùkún fun!’”
8 La parole de l'Éternel me fut encore adressée, en ces mots:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
9 Les mains de Zorobabel ont fondé cette maison, et ses mains l'achèveront, et tu sauras que l'Éternel des armées m'a envoyé vers vous.
“Ọwọ́ Serubbabeli ni a ti ṣe ìpìlẹ̀ ilé yìí, ọwọ́ rẹ̀ ni yóò sì parí rẹ̀; ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí i yín.
10 Car qui est-ce qui méprise le temps des petits commencements? Ils se réjouiront, en voyant la pierre du niveau dans la main de Zorobabel. Ces sept yeux sont les yeux de l'Éternel, qui parcourent toute la terre.
“Ṣùgbọ́n ta ni ha kẹ́gàn ọjọ́ ohun kékeré? Nítorí wọn ó yọ̀ nígbà ti wọ́n bá rí okùn ìwọ̀n nì lọ́wọ́ Serubbabeli. “(Àwọn méje wọ̀nyí ni àwọn ojú Olúwa, tí ó ń sáré síyìn-ín sọ́hùn-ún ní gbogbo ayé.)”
11 Et je pris la parole, et lui dis: Que signifient ces deux oliviers, à la droite du chandelier et à sa gauche?
Mo sì béèrè, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn igi olifi méjì wọ̀nyí jásí, tí ó wà ní apá ọ̀tún fìtílà àti ní apá òsì rẹ̀?”
12 Je pris la parole une seconde fois, et lui dis: Que signifient ces deux grappes d'olives qui sont à côté des deux conduits d'or, d'où découle l'or?
Mo sì tún dáhùn, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn ẹ̀ka méjì igi olifi wọ̀nyí jásí, tí ń tú òróró wúrà jáde nínú ara wọn láti ẹnu ọ̀pá oníhò wúrà méjì.”
13 Et il me parla, et me dit: Ne sais-tu pas ce qu'ils signifient? Et je dis: Non, mon seigneur.
Ó sì dáhùn, ó wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa à mi.”
14 Alors il dit: Ce sont les deux oints de l'Éternel, qui se tiennent devant le Seigneur de toute la terre.
Ó sì wí pé, “Àwọn méjì wọ̀nyí ni àwọn tí a fi òróró yàn, tí ó dúró ti Olúwa gbogbo ayé.”