< Proverbes 2 >

1 Mon fils, si tu reçois mes paroles, et si tu conserves avec toi mes commandements,
Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
2 Tellement que tu rendes ton oreille attentive à la sagesse, et que tu inclines ton cœur à l'intelligence;
tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
3 Si tu appelles à toi la prudence, et si tu adresses ta voix à l'intelligence;
àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
4 Si tu la cherches comme de l'argent, et si tu la recherches soigneusement comme un trésor;
bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
5 Alors tu comprendras la crainte de l'Éternel, et tu trouveras la connaissance de Dieu.
Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
6 Car l'Éternel donne la sagesse; de sa bouche procèdent la connaissance et l'intelligence.
Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
7 Il réserve le salut à ceux qui sont droits, et il est le bouclier de ceux qui marchent en intégrité,
Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
8 Pour suivre les sentiers de la justice. Il gardera la voie de ses bien-aimés.
Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
9 Alors tu connaîtras la justice, et le jugement, et l'équité, et tout bon chemin.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
10 Car la sagesse viendra dans ton cœur, et la connaissance sera agréable à ton âme;
Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
11 La prudence veillera sur toi, et l'intelligence te gardera;
Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
12 Pour te délivrer du mauvais chemin, et de l'homme qui parle avec perversité;
Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
13 De ceux qui abandonnent les chemins de la droiture, pour marcher dans les voies des ténèbres;
ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
14 Qui se réjouissent de mal faire et qui prennent plaisir dans les égarements du méchant;
ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
15 Dont les chemins sont détournés, et qui suivent des voies tortueuses.
ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
16 Tu seras aussi délivré de la femme étrangère, et de la femme d'autrui, dont les paroles sont flatteuses;
Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
17 Qui a abandonné le compagnon de sa jeunesse, et qui a oublié l'alliance de son Dieu.
ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
18 Car sa maison penche vers la mort, son chemin mène chez les morts.
Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
19 Pas un de ceux qui vont vers elle n'en revient, ni ne retrouve les sentiers de la vie.
Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
20 Ainsi tu marcheras dans la voie des gens de bien, tu garderas les sentiers des justes.
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
21 Car ceux qui sont droits habiteront la terre, et les hommes intègres y subsisteront.
Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
22 Mais les méchants seront retranchés de la terre, et ceux qui agissent perfidement, en seront arrachés.
Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.

< Proverbes 2 >